Naomi àti Rutu
1Ní ìgbà tí àwọn onídàájọ́ ń ṣe àkóso ilẹ̀ Israẹli, ìyàn kan mú ní ilẹ̀ náà, ọkùnrin kan láti Bẹtilẹhẹmu ti Juda, òun àti aya rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjì lọ láti máa gbé ní ilẹ̀ Moabu fún ìgbà díẹ̀. 2Orúkọ ọkùnrin náà ń jẹ́ Elimeleki, orúkọ ìyàwó rẹ̀ ni Naomi, orúkọ àwọn ọmọ rẹ̀ méjèèjì sì ni Maloni àti Kilioni àwọn ará Efrata, ti Bẹtilẹhẹmu ti Juda. Wọ́n sì lọ sí ilẹ̀ Moabu, wọ́n ń gbé níbẹ̀.
3Ní àsìkò tí wọ́n ń gbé ibẹ̀, Elimeleki, ọkọ Naomi kú, ó sì ku òun pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì. 4Wọ́n sì fẹ́ àwọn ọmọbìnrin ará Moabu méjì, orúkọ ọ̀kan ń jẹ́ Oripa, èkejì sì ń jẹ́ Rutu. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sì ti gbé níbẹ̀ fún bí ọdún mẹ́wàá, 5Maloni àti Kilioni náà sì kú, Naomi sì wà láìsí ọkọ tàbí ọmọ kankan fún un mọ́.
6Nígbà tí Naomi gbọ́ ní Moabu tí ó wà wí pé Olúwa ti bẹ àwọn ènìyàn rẹ̀ wò nípa fífún wọn ní ọ̀pọ̀ oúnjẹ. Ó sì dìde pẹ̀lú àwọn ìyàwó ọmọ rẹ̀ méjèèjì láti padà sí ìlú rẹ̀. 7Òun pẹ̀lú àwọn ìyàwó ọmọ rẹ̀ méjèèjì ni wọ́n jọ fi ibi tí ó ń gbé sílẹ̀ tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn padà sí ilẹ̀ Juda.
8Ṣùgbọ́n ní ojú ọ̀nà, Naomi wí fún àwọn aya ọmọ rẹ̀ méjèèjì pé, “Kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín padà sí ilé ìyá rẹ̀. Kí Olúwa ṣe àánú fún yín bí ẹ ti ṣe sí èmi àti àwọn ọkọ yín tí ó kú. 9Kí Olúwa kí ó fi yín lọ́kàn balẹ̀ ní ilé ọkọ mìíràn.”
Naomi sì fi ẹnu kò wọ́n ní ẹnu wí pé “Ó dìgbà,” Wọ́n sì sọkún kíkankíkan. 10Wọ́n sì wí fún un pé, “Rárá, a ó bà ọ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ.”
11Ṣùgbọ́n Naomi dáhùn wí pé, “Ẹ padà sílé ẹ̀yin ọmọ mi. Nítorí kí ni ẹ fi fẹ́ wá pẹ̀lú mi? Ṣé mo tún le bí àwọn ọmọkùnrin mìíràn ni, tí ó le ṣe ọkọ yin? 12Ẹ padà sílé, ẹ̀yin ọmọ mi, nítorí èmi ti di arúgbó jù láti ní ọkọ mìíràn. Bí èmí wí pé, Èmí ní ìrètí, bí èmí tilẹ̀ ní ọkọ mìíràn ní alẹ́ yìí, tí èmí sì bí àwọn ọmọkùnrin mìíràn, 13ẹ̀yin ha le è dúró dìgbà tí wọ́n yóò fi dàgbà? Ẹ̀yin ó le è dúró dè wọ́n láì fẹ́ ọkọ mìíràn? Rárá, ẹ̀yin ọmọbìnrin mi, nítorí pé inú mi bàjẹ́ gidigidi ju tiyín lọ, nítorí tí ọwọ́ Olúwa fi jáde sí mi!”
14Wọ́n sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì tún sọkún. Nígbà náà ní Oripa fi ẹnu ko ìyá ọkọ rẹ̀ ní ẹnu wí pé ó dìgbà, ṣùgbọ́n Rutu dì mọ́ ọn síbẹ̀.
15Naomi wí pé, “Wò ó, arábìnrin rẹ ti padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀ àti òrìṣà rẹ̀, ìwọ náà padà pẹ̀lú rẹ̀.”
16Ṣùgbọ́n Rutu dáhùn wí pé, “Má ṣe rọ̀ mí láti fi ọ́ sílẹ̀ tàbí láti padà lẹ́yìn rẹ. Ibi tí ìwọ bá lọ ní èmi yóò lọ, ibi ti ìwọ bá dúró ni èmi yóò dúró, àwọn ènìyàn rẹ ni yóò jẹ́ ènìyàn mi, Ọlọ́run rẹ ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run, mi, 17Níbi tí ìwọ bá kú sí ni èmi yóò kú sí, níbẹ̀ ni wọn yóò sì sin mí sí. Kí Olúwa jẹ mí ní ìyà tí ó lágbára, bí ohunkóhun bí kò ṣe ikú bá yà wá.” 18Nígbà tí Naomi rí i wí pé Rutu ti pinnu láti tẹ̀lé òun kò rọ̀ láti padà mọ́.
19Àwọn méjèèjì sì ń lọ títí wọ́n fi dé ìlú Bẹtilẹhẹmu. Nígbà tí wọ́n dé ibẹ̀, ariwo ìpadàbọ̀ wọn gba ìlú kan, àwọn obìnrin ibẹ̀ sì kígbe ní ohùn rara wí pé, “Naomi ni èyí bí?”
20Naomi sì dáhùn wí pé, “Ẹ má ṣe pè mí ní Naomi. Ẹ pè mí ní Mara (Ìkorò), nítorí wí pé Olódùmarè ti mú kí ayé mi di kíkorò. 21Mo jáde ní kíkún, ṣùgbọ́n Olúwa mú mi padà ní òfo. Nítorí náà kín ló dé tí ẹ fi ń pè mí ní Naomi, nígbà tí Olódùmarè ti kọ̀ mí sílẹ̀, tí ó sì mú ìdààmú bá mi?”
22Báyìí ni Naomi ṣe padà láti Moabu pẹ̀lú Rutu, ará Moabu ìyàwó ọmọ rẹ̀. Wọ́n gúnlẹ̀ sí Bẹtilẹhẹmu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìkórè ọkà barle.
نعومی و روت
1-2در زمانی كه هنوز پادشاهی بر قوم اسرائيل حكومت نمیكرد، سرزمين اسرائيل دچار خشكسالی شد. مردی از اهالی افراته به نام اليملک كه در بيتلحم زندگی میكرد، در اثر اين خشكسالی از وطن خود به سرزمين موآب كوچ كرد. زن او نعومی و دو پسرش مَحلون و كِليون نيز همراه او بودند. 3در طی اقامتشان در موآب، اليملک درگذشت و نعومی با دو پسرش تنها ماند.
4-5پسران نعومی با دو دختر موآبی به نامهای عرفه و روت ازدواج كردند. ده سال بعد محلون و كليون نيز مردند. بدين ترتيب نعومی، هم شوهر و هم پسرانش را از دست داد و تنها ماند. 6-7او تصميم گرفت با دو عروسش به زادگاه خود بازگردد، زيرا شنيده بود كه خداوند به قوم خود بركت داده و محصول زمين دوباره فراوان شده است.
اما وقتی به راه افتادند، تصميم نعومی عوض شد 8و به عروسهايش گفت: «شما همراه من نياييد. به خانهٔ پدری خود بازگرديد. خداوند به شما بركت بدهد همانگونه كه شما به من و پسرانم خوبی كرديد. 9اميدوارم به لطف خداوند بتوانيد بار ديگر شوهر كنيد و خوشبخت شويد.»
سپس نعومی آنها را بوسيد و آنها گريستند 10و به نعومی گفتند: «ما میخواهيم همراه تو نزد قوم تو بياييم.»
11ولی نعومی در جواب آنها گفت: «ای دخترانم بهتر است برگرديد. چرا میخواهيد همراه من بياييد؟ مگر من میتوانم صاحب پسران ديگری شوم كه برای شما شوهر باشند؟1:11 طبق رسم آن روزگار هرگاه شوهر زنی میمرد برادر شوهر آن زن میبايست او را به عقد خود در میآورند (تثنيه 25:5-10). 12-13نه، ای دخترانم، نزد قوم خود بازگرديد، زيرا از من گذشته است كه بار ديگر شوهر كنم. حتی اگر همين امشب شوهر كنم و صاحب پسرانی شوم، آيا تا بزرگ شدن آنها صبر خواهيد كرد و با كس ديگری ازدواج نخواهيد نمود؟ از وضعی كه برای شما پيش آمده متأسفم. خداوند طوری مرا تنبيه نموده كه موجب آزردگی شما نيز شدهام.»
14آنها بار ديگر با صدای بلند گريستند. عرفه مادر شوهرش را بوسيد و از او خداحافظی كرد و به خانه بازگشت. اما روت از او جدا نشد. 15نعومی به روت گفت: «ببين دخترم، زن برادر شوهرت نزد قوم و خدايان خود بازگشت. تو هم همين كار را بكن.»
16اما روت به او گفت: «مرا مجبور نكن كه تو را ترک كنم، چون هر جا بروی با تو خواهم آمد و هر جا بمانی با تو خواهم ماند. قوم تو، قوم من و خدای تو، خدای من خواهد بود. 17میخواهم جايی كه تو میميری بميرم و در كنار تو دفن شوم. خداوند بدترين بلا را بر سر من بياورد، اگر بگذارم چيزی جز مرگ مرا از تو جدا كند.»
18نعومی چون ديد تصميم روت قطعی است و به هيچ وجه نمیشود او را منصرف كرد، ديگر اصرار ننمود. 19پس هر دو روانهٔ بيتلحم شدند. وقتی بدانجا رسيدند تمام اهالی به هيجان آمدند و زنها از همديگر میپرسيدند: «آيا اين خود نعومی است؟» 20نعومی به ايشان گفت: «مرا نعومی (يعنی ”خوشحال“) نخوانيد. مرا ماره (يعنی ”تلخ“) صدا كنيد؛ زيرا خدای قادر مطلق زندگی مرا تلخ كرده است. 21پُر رفتم و خداوند مرا خالی بازگردانيد. برای چه مرا نعومی میخوانيد، حال آنكه خداوند قادر مطلق روی خود را از من برگردانيده و اين مصيبت بزرگ را بر من وارد آورده است؟»
22(وقتی نعومی و روت از موآب به بيتلحم رسيدند، هنگام درو جو بود.)