Luku 1 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Luku 1:1-80

1Ọ̀pọ̀ ènìyàn ni ó ti dáwọ́lé títo àwọn nǹkan wọ̀n-ọn-nì jọ lẹ́sẹẹsẹ, èyí tí ó ti múlẹ̀ ṣinṣin láàrín wa, 21.2: 1Jh 1.1; Ap 1.21; Hb 2.3.àní gẹ́gẹ́ bí àwọn ìránṣẹ́ ọ̀rọ̀ náà, tí ó ṣe ojú wọn láti ìbẹ̀rẹ̀ ti fi lé wa lọ́wọ́. 31.3: Ap 1.1.Nítorí náà, ó sì yẹ fún èmi pẹ̀lú, láti kọ̀wé sí ọ lẹ́sẹẹsẹ bí mo ti wádìí ohun gbogbo fínní fínní sí láti ìpilẹ̀ṣẹ̀, Teofilu ọlọ́lá jùlọ, 41.4: Jh 20.31.kí ìwọ kí ó le mọ òtítọ́ ohun wọ̀n-ọn-nì, tí a ti kọ́ ọ.

Àsọtẹ́lẹ̀ nípa ibí Johanu onítẹ̀bọmi

51.5: Mt 2.1; 1Ki 24.10; 2Ki 31.2.Nígbà ọjọ́ Herodu ọba Judea, àlùfáà kan wà, láti ìran Abijah, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Sekariah: aya rẹ̀ sì ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin Aaroni, orúkọ rẹ̀ a sì máa jẹ́ Elisabeti. 6Àwọn méjèèjì sì ṣe olódodo níwájú Ọlọ́run, wọ́n ń rìn ní gbogbo òfin àti ìlànà Olúwa ní àìlẹ́gàn. 7Ṣùgbọ́n wọn kò ní ọmọ, nítorí tí Elisabeti yàgàn; àwọn méjèèjì sì di arúgbó.

8Ó sì ṣe, nígbà tí ó ń ṣe iṣẹ́ àlùfáà níwájú Ọlọ́run ni àkókò tirẹ̀ 91.9: Ek 30.7.Bí ìṣe àwọn àlùfáà, ipa tirẹ̀ ni láti máa fi tùràrí jóná, nígbà tí ó bá wọ inú tẹmpili Olúwa lọ. 10Gbogbo ìjọ àwọn ènìyàn sì ń gbàdúrà lóde ní àkókò sísun tùràrí.

111.11: Lk 2.9; Ap 5.19.Angẹli Olúwa kan sì fi ara hàn án, ó dúró ní apá ọ̀tún pẹpẹ tùràrí. 12Nígbà tí Sekariah sì rí i, orí rẹ̀ wú, ẹ̀rù sì bà á. 131.13: Lk 1.30,60.Ṣùgbọ́n angẹli náà wí fún un pé, “Má bẹ̀rù, Sekariah: nítorí tí àdúrà rẹ gbà; Elisabeti aya rẹ yóò sì bí ọmọkùnrin kan fún ọ, ìwọ ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Johanu. 14Òun yóò sì jẹ́ ayọ̀ àti ìdùnnú fún ọ: ènìyàn púpọ̀ yóò sì yọ̀ sí ìbí rẹ. 151.15: Nu 6.3; Lk 7.33.Nítorí òun ó pọ̀ níwájú Olúwa, kì yóò sì mu ọtí wáìnì, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò sì mu ọtí líle; yóò sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́ àní láti inú ìyá rẹ̀ wá. 16Òun ó sì yí ènìyàn púpọ̀ padà nínú àwọn ọmọ Israẹli sí Olúwa Ọlọ́run wọn. 171.17: Mt 11.14; 17.13; Ml 4.5.Ẹ̀mí àti agbára Elijah ni Olúwa yóò sì fi ṣáájú rẹ̀ lọ, láti pa ọkàn àwọn baba dà sí ti àwọn ọmọ, àti ti àwọn aláìgbọ́ràn sí ọgbọ́n àwọn olóòtítọ́; kí ó le pèsè àwọn ènìyàn tí a múra sílẹ̀ de Olúwa.”

18Sekariah sì wí fún angẹli náà pé, “Ààmì wo ni èmi ó fi mọ èyí? Èmi sá ti di àgbà, àti Elisabeti aya mi sì di arúgbó.”

191.19: Da 8.16; 9.21; Mt 18.10.Angẹli náà sì dáhùn ó wí fún un pé, “Èmi ni Gabrieli, tí máa ń dúró níwájú Ọlọ́run; èmi ni a rán wá láti sọ fún ọ, àti láti mú ìròyìn ayọ̀ wọ̀nyí fún ọ wá. 20Sì kíyèsi i, ìwọ ó yadi, ìwọ kì yóò sì le fọhùn, títí ọjọ́ náà tí nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ, nítorí ìwọ kò gba ọ̀rọ̀ mi gbọ́ tí yóò ṣẹ ní àkókò wọn.”

21Àwọn ènìyàn sì ń dúró de Sekariah, ẹnu sì yà wọ́n nítorí tí ó pẹ́ nínú tẹmpili. 22Nígbà tí ó sì jáde wá, òun kò le bá wọn sọ̀rọ̀. Wọn sì kíyèsi wí pé ó ti rí ìran nínú tẹmpili, ó sì ń ṣe àpẹẹrẹ sí wọn, nítorí tí ó yadi.

23Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ iṣẹ́ ìsìn rẹ̀ pé, ó lọ sí ilé rẹ̀. 24Lẹ́yìn èyí ni Elisabeti aya rẹ̀ lóyún, ó sì fi ara rẹ̀ pamọ́ ní oṣù márùn-ún, 25Ó sì wí pé “Báyìí ni Olúwa ṣe fún mi ní ọjọ́ tí ó ṣíjú wò mí, láti mú ẹ̀gàn mi kúrò láàrín àwọn ènìyàn.”

Ìsọtẹ́lẹ̀ ibi Jesu

26Ní oṣù kẹfà Ọlọ́run sì rán angẹli Gabrieli sí ìlú kan ní Galili, tí à ń pè ní Nasareti, 27sí wúńdíá kan tí a ṣèlérí láti fẹ́ fún ọkùnrin kan, tí a ń pè ní Josẹfu, ti ìdílé Dafidi; orúkọ wúńdíá náà a sì máa jẹ́ Maria. 28Angẹli náà sì tọ̀ ọ́ wá, ó ní, “Àlàáfíà fun ọ, ìwọ ẹni tí a kọjú sí ṣe ní oore, Olúwa ń bẹ pẹ̀lú rẹ.”

29Ṣùgbọ́n ọkàn Maria kò lélẹ̀ nítorí ọ̀rọ̀ náà, ó sì rò nínú ara rẹ̀ pé, irú kíkí kín ni èyí. 301.30: Lk 1.13.Ṣùgbọ́n angẹli náà wí fún un pé, “Má bẹ̀rù, Maria: nítorí ìwọ ti rí ojúrere lọ́dọ̀ Ọlọ́run. 311.31: Lk 2.21; Mt 1.21.Ìwọ yóò lóyún nínú rẹ, ìwọ ó sì bí ọmọkùnrin kan, ìwọ ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jesu. 32Òun ó pọ̀, Ọmọ Ọ̀gá-ògo jùlọ ni a ó sì máa pè é: Olúwa Ọlọ́run yóò sì fi ìtẹ́ Dafidi baba rẹ̀ fún: 331.33: Mt 28.18; Da 2.44.Yóò sì jẹ ọba lórí ilé Jakọbu títí láé; ìjọba rẹ̀ kì yóò sì ní ìpẹ̀kun.”

341.34: Lk 1.18.Nígbà náà ni Maria béèrè lọ́wọ́ angẹli náà pé, “Èyí yóò ha ti ṣe rí bẹ́ẹ̀, nígbà tí èmi kò tí ì mọ ọkùnrin.”

351.35: Mt 1.20.Angẹli náà sì dáhùn ó sì wí fún un pé, “Ẹ̀mí Mímọ́ yóò tọ̀ ọ́ wá, agbára Ọ̀gá-ògo jùlọ yóò ṣíji bò ọ́. Nítorí náà ohun mímọ́ tí a ó ti inú rẹ bí, Ọmọ Ọlọ́run ni a ó máa pè é. 36Sì kíyèsi i, Elisabeti ìbátan rẹ náà yóò sì ní ọmọkùnrin kan ní ògbólógbòó rẹ̀. Èyí sì ni oṣù kẹfà fún ẹni tí à ń pè ní àgàn. 371.37: Gẹ 18.14.Nítorí kò sí ohun tí Ọlọ́run kò le ṣe.”

38Maria sì dáhùn wí pé, “Wò ó ọmọ ọ̀dọ̀ Olúwa; kí ó rí fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.” Angẹli náà sì fi í sílẹ̀ lọ.

Maria bẹ Elisabeti wò

39Ní àkókò náà ni Maria sì dìde, ó lọ kánkán sí ilẹ̀ òkè, sí ìlú kan ní Judea; 40Ó sì wọ ilé Sekariah lọ ó sì kí Elisabeti. 41Ó sì ṣe, nígbà tí Elisabeti gbọ́ kíkí Maria, ọlẹ̀ sọ nínú rẹ̀; Elisabeti sì kún fún Ẹ̀mí mímọ́; 421.42: Lk 11.27-28.Ó sì ké ní ohùn rara, ó sì wí pé, “Alábùkún fún ni ìwọ nínú àwọn obìnrin, alábùkún fún sì ni ọmọ tí ìwọ yóò bí. 43Èéṣe tí èmi fi rí irú ojúrere yìí, tí ìyá Olúwa mi ìbá fi tọ̀ mí wá? 44Sá wò ó, bí ohùn kíkí rẹ ti bọ́ sí mi ní etí, ọlẹ̀ sọ nínú mi fún ayọ̀. 45Alábùkún fún sì ni ẹni tí ó gbàgbọ́: nítorí nǹkan wọ̀nyí tí a ti sọ fún un láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá yóò ṣẹ.”

Orin Maria

46Maria sì dáhùn, ó ní:

“Ọkàn mi yin Olúwa lógo,

47Ẹ̀mí mi sì yọ̀ sí Ọlọ́run Olùgbàlà mi.

48Nítorí tí ó ṣíjú wo ìwà ìrẹ̀lẹ̀

ọmọbìnrin ọ̀dọ̀ rẹ̀: Sá wò ó.

Láti ìsinsin yìí lọ gbogbo ìran ènìyàn ni yóò máa pè mí ní alábùkún fún.

49Nítorí ẹni tí ó ní agbára ti ṣe ohun tí ó tóbi fún mi;

Mímọ́ sì ni orúkọ rẹ̀.

50Àánú rẹ̀ sì ń bẹ fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀

láti ìrandíran.

51Ó ti fi agbára hàn ní apá rẹ̀;

o ti tú àwọn onígbèéraga ká ní ìrònú ọkàn wọn.

52Ó ti mú àwọn alágbára kúrò lórí ìtẹ́ wọn,

o sì gbé àwọn onírẹ̀lẹ̀ lékè.

53Ó ti fi ohun tí ó dára kún àwọn tí ebi ń pa

ó sì rán àwọn ọlọ́rọ̀ padà ní òfo.

54Ó ti ran Israẹli ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ lọ́wọ́,

Ní ìrántí àánú rẹ̀;

551.55: Mt 7.20; Gẹ 17.7; 18.18; 22.17.sí Abrahamu àti àwọn ìran rẹ̀ láéláé, baba wa,

àti bí ó ti sọ fún àwọn baba wa.”

56Maria sì jókòó tì Elisabeti níwọ̀n oṣù mẹ́ta, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀.

Ìbí Johanu onítẹ̀bọmi

57Nígbà tí ọjọ́ Elisabeti pé tí yóò bí; ó sì bí ọmọkùnrin kan. 58Àwọn aládùúgbò, àti àwọn ìbátan rẹ̀ gbọ́ bí Olúwa ti fi àánú ńlá hàn fún un, wọ́n sì bá a yọ̀.

591.59: Le 12.3; Gẹ 17.12.Ó sì ṣe, ní ọjọ́ kẹjọ wọ́n wá láti kọ ọmọ náà nílà; wọ́n sì fẹ́ sọ orúkọ rẹ̀ ní Sekariah, gẹ́gẹ́ bí orúkọ baba rẹ̀. 60Ìyá rẹ̀ sì dáhùn, ó ní, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Johanu ni a ó pè é.”

61Wọ́n sì wí fún un pé, “Kò sí ọ̀kan nínú àwọn ará rẹ̀ tí à ń pè ní orúkọ yìí.”

62Wọ́n sì ṣe àpẹẹrẹ sí baba rẹ̀, bí ó ti ń fẹ́ kí a pè é. 63Ó sì béèrè fún wàláà, ó sì kọ ọ wí pé, “Johanu ni orúkọ rẹ̀.” Ẹnu sì ya gbogbo wọn. 64Ẹnu rẹ̀ sì ṣí lọ́gán, okùn ahọ́n rẹ̀ sì tú, ó sì sọ̀rọ̀, ó sì ń yin Ọlọ́run. 65Ẹ̀rù sì ba gbogbo àwọn tí ń bẹ ní agbègbè wọn: a sì ròyìn gbogbo nǹkan wọ̀nyí ká gbogbo ilẹ̀ òkè Judea. 66Ó sì jẹ́ ohun ìyanu fún gbogbo àwọn tí ó gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n sì tò ó sínú ọkàn wọn, wọ́n ń wí pé, “Irú-ọmọ kín ni èyí yóò jẹ́?” Nítorí tí ọwọ́ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀.

Orin Ṣakariah

67Sekariah baba rẹ̀ sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó sì sọtẹ́lẹ̀, ó ní:

68“Olùbùkún ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli;

nítorí tí ó ti bojú wò, tí ó sì ti dá àwọn ènìyàn rẹ̀ nídè,

69Ó sì ti gbé ìwo ìgbàlà sókè fún wa

ní ilé Dafidi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀;

70(bí ó ti sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì rẹ̀ mímọ́ tipẹ́tipẹ́),

71Pé, a ó gbà wá là lọ́wọ́

àwọn ọ̀tá wa àti lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra wá.

72Láti ṣe àánú tí ó ṣèlérí fún àwọn baba wa,

àti láti rántí májẹ̀mú rẹ̀ mímọ́,

73ìbúra tí ó ti bú fún Abrahamu baba wa,

74láti gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa,

kí àwa kí ó lè máa sìn láìfòyà,

75ni ìwà mímọ́ àti ní òdodo níwájú rẹ̀, ní ọjọ́ ayé wa gbogbo.

761.76: Lk 7.26; Ml 4.5.“Àti ìwọ, ọmọ mi, wòlíì Ọ̀gá-ògo jùlọ ni a ó máa pè ọ́:

nítorí ìwọ ni yóò ṣáájú Olúwa láti tún ọ̀nà rẹ̀ ṣe;

771.77: Mk 1.4.láti fi ìmọ̀ ìgbàlà fún àwọn ènìyàn rẹ̀

fún ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀ wọn,

781.78: Ml 4.2; Ef 5.14.nítorí ìyọ́nú Ọlọ́run wà;

nípa èyí tí ìlà-oòrùn láti òkè wá bojú wò wá,

791.79: Isa 9.2; Mt 4.16.Láti fi ìmọ́lẹ̀ fún àwọn tí ó jókòó ní

òkùnkùn àti ní òjìji ikú,

àti láti fi ẹsẹ̀ wa lé ọ̀nà àlàáfíà.”

801.80: Lk 2.40; 2.52.Ọmọ náà sì dàgbà, ó sì le ní ọkàn, ó sì ń gbé ní ijù títí ó fi di ọjọ́ ìfihàn rẹ̀ fún Israẹli.

Persian Contemporary Bible

لوقا 1:1-80

1عاليجناب تِئوفيلوس:

بسياری كوشيده‌اند شرح زندگی عيسی مسيح را به نگارش درآورند؛ 2‏-3و برای انجام اين كار، از مطالبی استفاده كرده‌اند كه از طريق شاگردان او و شاهدان عينی وقايع، در دسترس ما قرار گرفته است. اما از آنجا كه من خود، اين مطالب را از آغاز تا پايان، با دقت بررسی و مطالعه كرده‌ام، چنين صلاح ديدم كه ماجرا را به طور كامل و به ترتيب برايتان بنويسم، 4تا از درستی تعليمی كه يافته‌ايد، اطمينان حاصل كنيد.

مژدهٔ تولد يحيای تعميددهنده

5ماجرا را از كاهنی يهودی آغاز می‌كنم، با نام زكريا، كه در زمان هيروديس، پادشاه يهوديه، زندگی می‌كرد. او عضو دسته‌ای از خدمهٔ خانهٔ خدا بود كه ابيا نام داشت. همسرش اليزابت نيز مانند خود او از قبيلهٔ كاهنان يهود و از نسل هارون برادر موسی بود. 6زكريا و اليزابت هر دو در نظر خدا بسيار درستكار بودند و با جان و دل تمام احكام الهی را بجا می‌آوردند. 7اما آنها فرزندی نداشتند، زيرا اليزابت نازا بود؛ از اين گذشته، هر دو بسيار سالخورده بودند.

8‏-9يكبار كه دستهٔ ابيا در خانهٔ خدا خدمت می‌كرد، و زكريا نيز به انجام وظايف كاهنی خود مشغول بود، به حكم قرعه نوبت به او رسيد كه به جايگاه مقدس خانهٔ خدا داخل شود و در آنجا بخور بسوزاند. 10به هنگام سوزاندن بخور، جمعيت انبوهی در صحن خانهٔ خدا مشغول عبادت بودند. 11‏-12ناگهان فرشته‌ای بر زكريا ظاهر شد و در طرف راست قربانگاه بخور ايستاد. زكريا از ديدن فرشته مبهوت و هراسان شد.

13فرشته به او گفت: «ای زكريا، نترس! چون آمده‌ام به تو خبر دهم كه خدا دعايت را شنيده است، و همسرت اليزابت برايت پسری به دنیا خواهد آورد كه نامش را يحيی خواهی گذارد. 14اين پسر باعث شادی و سُرور شما خواهد شد، و بسياری نيز از تولدش شادی خواهند نمود. 15زيرا او يكی از مردان بزرگ خدا خواهد شد. او هرگز نبايد شراب و مشروبات سُكرآور بنوشد، چون حتی پيش از تولد، از روح‌القدس پر خواهد بود! 16بسياری از بنی‌اسرائيل توسط او به سوی خداوند، خدای خود بازگشت خواهند نمود. 17او خدمت خود را با همان روح و قدرت الياس، آن نبی قديم انجام خواهد داد. او پيشاپيش مسيح خواهد آمد تا مردم را برای ظهور او آماده كند، دلهای پدران را به پسران نزديک سازد و به افراد سركش بياموزد كه همچون اجداد خويش خداوند را دوست داشته و مردم خداترسی باشند.»

18زكريا به فرشته گفت: «ولی اين غيرممكن است، چون من پير شده‌ام و همسرم نيز سالخورده است!»

19فرشته در جواب گفت: «من جبرائيل هستم كه در حضور خدا می‌ايستم و اوست كه مرا فرستاده تا اين خبر خوش را به تو دهم. 20اما حال كه سخنان مرا باور نكردی، قدرت تكلم را از دست خواهی داد و تا زمانی كه كودک به دنیا بيايد يارای سخن گفتن نخواهی داشت؛ زيرا آنچه گفتم، در زمان مقرر واقع خواهد شد.»

21در اين ميان، مردم در صحن خانهٔ خدا منتظر زكريا بودند و از اينكه او در بيرون آمدن از جايگاه مقدس اين همه تأخير می‌كرد، در حيرت بودند. 22سرانجام وقتی بيرون آمد و نتوانست با ايشان سخن گويد، از اشارات او پی بردند كه در جايگاه مقدس خانهٔ خدا رؤيايی ديده است.

23زكريا پس از پايان دوره خدمتش، به خانهٔ خود بازگشت. 24طولی نكشيد كه همسرش اليزابت باردار شد. او برای مدت پنج ماه گوشه‌نشينی اختيار كرد و می‌گفت: 25«سرانجام خداوند بر من نظر لطف انداخت و كاری كرد كه ديگر در ميان مردم شرمگين نباشم!»

مژدهٔ تولد عيسی

26در ششمين ماه بارداری اليزابت، خدا فرشته خود جبرائيل را به ناصره، يكی از شهرهای استان جليل فرستاد، 27تا وحی او را به دختری به نام مريم برساند. مريم نامزدی داشت به نام يوسف، از نسل داوود پادشاه.

28جبرائيل به مريم ظاهر شد و گفت: «سلام بر تو ای دختری كه مورد لطف پروردگار قرار گرفته‌ای! خداوند با توست!»

29مريم سخت پريشان و متحير شد، چون نمی‌توانست بفهمد منظور فرشته از اين سخنان چيست.

30فرشته به او گفت: «ای مريم، نترس! زيرا خدا بر تو نظر لطف انداخته است! 31تو بزودی باردار شده، پسری به دنیا خواهی آورد و نامش را عيسی خواهی نهاد. 32او مردی بزرگ خواهد بود و پسر خدا ناميده خواهد شد و خداوند تخت سلطنت جدش داوود را به او واگذار خواهد كرد 33تا برای هميشه بر قوم اسرائيل سلطنت كند. سلطنت او هرگز پايان نخواهد يافت!»

34مريم از فرشته پرسيد: «اما چگونه چنين چيزی امكان دارد؟ دست هيچ مردی هرگز به من نرسيده است!»

35فرشته جواب داد: «روح‌القدس بر تو نازل خواهد شد و قدرت خدا بر تو سايه خواهد افكند. از اين رو آن نوزاد مقدس بوده، فرزند خدا خوانده خواهد شد. 36بدان كه خويشاوند تو اليزابت نيز شش ماه پيش در سن پيری باردار شده و بزودی پسری به دنیا خواهد آورد؛ بلی، همان كسی كه همه او را نازا می‌خواندند. 37زيرا برای خدا هيچ كاری محال نيست!»

38مريم گفت: «من خدمتگزار خداوند هستم و هر چه او بخواهد، با كمال ميل انجام می‌دهم. از خدا می‌خواهم كه هر چه گفتی، همان بشود.» آنگاه فرشته ناپديد شد.

مريم از اليزابت ديدار می‌کند

39‏-40پس از چند روز، مريم تدارک سفر ديد و شتابان نزد اليزابت رفت، كه با همسرش زكريا، در يكی از شهرهای واقع در منطقه كوهستان يهوديه زندگی می‌كرد. مريم وارد خانه شد و سلام كرد. 41به محض اينكه صدای سلام مريم به گوش اليزابت رسيد، بچه در رحم او به حركت درآمد. اليزابت از روح‌القدس پر شد 42و با صدای بلند به مريم گفت: «خدا تو را بيش از همهٔ زنان ديگر مورد لطف خود قرار داده است! فرزندت نيز سرچشمهٔ بركات برای انسانها خواهد بود. 43چه افتخار بزرگی است برای من، كه مادر خداوندم به ديدنم بيايد! 44وقتی وارد شدی و به من سلام كردی، به محض اينكه صدايت را شنيدم، بچه از شادی در رَحِمِ من به حركت درآمد! 45خوشا به حال تو، زيرا ايمان آوردی كه هر چه خدا به تو گفته است، به انجام خواهد رسيد!»

سرود شکرگزاری مريم

46مريم گفت: «خداوند را با تمام وجود ستايش می‌كنم، 47و روح من، به سبب نجات‌دهنده‌ام خدا، شاد و مسرور می‌گردد! 48چون او منِ ناچيز را مورد عنايت قرار داده است. از اين پس، همهٔ نسلها مرا خوشبخت خواهند خواند، 49زيرا خدای قادر و قدوس در حق من كارهای بس بزرگ كرده است.

50«لطف و رحمت او، نسل اندر نسل شامل حال آنانی می‌شود كه از او می‌ترسند. 51او دست خود را با قدرت دراز كرده و متكبران را همراه نقشه‌هايشان پراكنده ساخته است. 52سلاطين را از تخت به زير كشيده و فروتنان را سربلند كرده است. 53گرسنگان را با نعمتهای خود سير كرده، اما ثروتمندان را تهی دست روانه نموده است. 54او رحمت خود را كه به اجداد ما وعده داده بود، به ياد آورده و به ياری قوم خود، اسرائيل، آمده است. 55بلی، او وعدهٔ ابدی خود را كه به ابراهيم و فرزندان او داده بود، به ياد آورده است.»

56مريم حدود سه ماه نزد اليزابت ماند. سپس به خانه خود بازگشت.

تولد يحيای تعميددهنده

57سرانجام، انتظار اليزابت پايان يافت و زمان وضع حملش فرا رسيد و پسری به دنیا آورد. 58وقتی كه همسايگان و بستگان او از اين خبر آگاهی يافتند و ديدند كه خداوند چه لطف بزرگی در حق او نموده است، نزد او آمده، در شادی‌اش شريک شدند.

59چون نوزاد هشت روزه شد، تمام بستگان و دوستان برای مراسم ختنه گرد آمدند و قصد داشتند نام پدرش، زكريا را بر او بگذارند. 60اما اليزابت نپذيرفت و گفت: «نام او يحيی خواهد بود.»

61گفتند: «اما در خانواده تو، كسی به اين نام نبوده است.»

62پس با اشاره، از پدر نوزاد پرسيدند كه نام او را چه بگذارند.

63زكريا با اشاره، تخته‌ای خواست و در برابر چشمان حيرت‌زدهٔ همه نوشت: «نامش يحيی است!» 64در همان لحظه زبانش باز شد و قدرت سخن گفتن را باز يافت و به شكرگزاری خدا پرداخت. 65همسايگان با ديدن تمام اين وقايع بسيار متعجب شدند، و خبر اين ماجرا در سراسر كوهستان يهوديه پخش شد. 66هر كه اين خبر را می‌شنيد، به فكر فرو می‌رفت و از خود می‌پرسيد: «اين بچه، در آينده چه خواهد شد؟» زيرا همه می‌ديدند كه او مورد توجه خداوند قرار دارد.

نبوت زکريا

67آنگاه پدرش زكريا، از روح‌القدس پر شد و چنين نبوت كرد:

68«خداوند، خدای اسرائيل را سپاس باد، زيرا به ياری قوم خود شتافته و ايشان را رهايی بخشيده است. 69او بزودی برای ما نجات دهنده‌ای قدرتمند از نسل داوود خواهد فرستاد؛ 70چنانكه از گذشته‌های دور، از زبان انبيای مقدس خود وعده می‌داد 71كه شخصی را خواهد فرستاد تا ما را از چنگ دشمنانمان و از دست همه آنانی كه از ما نفرت دارند، رهايی بخشد.

72‏-73«خداوند نسبت به نياكان ما، رحيم و مهربان بوده است. بلی، او عهد و پيمان مقدسی را كه با ابراهيم بست، از ياد نبرده 74و اين افتخار را نصيب ما كرده كه از دست دشمنانمان رهايی يابيم و بدون ترس و واهمه از آنان، او را عبادت نماييم 75و تمام روزهای عمر خود را در حضور او با پاكی و عدالت بگذرانيم.

76«و تو ای فرزند، نبی خدای تعالی ناميده خواهی شد، زيرا پيشاپيش خداوند حركت خواهی كرد تا راه او را آماده نمايی، 77و قوم او را آگاه سازی كه با آمرزش گناهانشان نجات خواهند يافت. 78‏-79اينها، همه به سبب رحمت و شفقت بی‌پايان خدای ماست. بزودی سپيده صبح از افق آسمان بر ما طلوع خواهد كرد تا بر كسانی كه در تاريكی و سايه مرگ ساكن هستند، بتابد و همهٔ ما را به سوی آرامش و صفا هدايت نمايد.»

80آن كودک رشد كرد و صاحب روحی توانا شد. او در بيابانها به سر می‌برد؛ تا روزی فرا رسيد كه می‌بايست خدمت خود را در ميان قوم اسرائيل آغاز كند.