Luku 1 – YCB & PCB

Yoruba Contemporary Bible

Luku 1:1-80

1Ọ̀pọ̀ ènìyàn ni ó ti dáwọ́lé títo àwọn nǹkan wọ̀n-ọn-nì jọ lẹ́sẹẹsẹ, èyí tí ó ti múlẹ̀ ṣinṣin láàrín wa, 21.2: 1Jh 1.1; Ap 1.21; Hb 2.3.àní gẹ́gẹ́ bí àwọn ìránṣẹ́ ọ̀rọ̀ náà, tí ó ṣe ojú wọn láti ìbẹ̀rẹ̀ ti fi lé wa lọ́wọ́. 31.3: Ap 1.1.Nítorí náà, ó sì yẹ fún èmi pẹ̀lú, láti kọ̀wé sí ọ lẹ́sẹẹsẹ bí mo ti wádìí ohun gbogbo fínní fínní sí láti ìpilẹ̀ṣẹ̀, Teofilu ọlọ́lá jùlọ, 41.4: Jh 20.31.kí ìwọ kí ó le mọ òtítọ́ ohun wọ̀n-ọn-nì, tí a ti kọ́ ọ.

Àsọtẹ́lẹ̀ nípa ibí Johanu onítẹ̀bọmi

51.5: Mt 2.1; 1Ki 24.10; 2Ki 31.2.Nígbà ọjọ́ Herodu ọba Judea, àlùfáà kan wà, láti ìran Abijah, orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Sekariah: aya rẹ̀ sì ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin Aaroni, orúkọ rẹ̀ a sì máa jẹ́ Elisabeti. 6Àwọn méjèèjì sì ṣe olódodo níwájú Ọlọ́run, wọ́n ń rìn ní gbogbo òfin àti ìlànà Olúwa ní àìlẹ́gàn. 7Ṣùgbọ́n wọn kò ní ọmọ, nítorí tí Elisabeti yàgàn; àwọn méjèèjì sì di arúgbó.

8Ó sì ṣe, nígbà tí ó ń ṣe iṣẹ́ àlùfáà níwájú Ọlọ́run ni àkókò tirẹ̀ 91.9: Ek 30.7.Bí ìṣe àwọn àlùfáà, ipa tirẹ̀ ni láti máa fi tùràrí jóná, nígbà tí ó bá wọ inú tẹmpili Olúwa lọ. 10Gbogbo ìjọ àwọn ènìyàn sì ń gbàdúrà lóde ní àkókò sísun tùràrí.

111.11: Lk 2.9; Ap 5.19.Angẹli Olúwa kan sì fi ara hàn án, ó dúró ní apá ọ̀tún pẹpẹ tùràrí. 12Nígbà tí Sekariah sì rí i, orí rẹ̀ wú, ẹ̀rù sì bà á. 131.13: Lk 1.30,60.Ṣùgbọ́n angẹli náà wí fún un pé, “Má bẹ̀rù, Sekariah: nítorí tí àdúrà rẹ gbà; Elisabeti aya rẹ yóò sì bí ọmọkùnrin kan fún ọ, ìwọ ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Johanu. 14Òun yóò sì jẹ́ ayọ̀ àti ìdùnnú fún ọ: ènìyàn púpọ̀ yóò sì yọ̀ sí ìbí rẹ. 151.15: Nu 6.3; Lk 7.33.Nítorí òun ó pọ̀ níwájú Olúwa, kì yóò sì mu ọtí wáìnì, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò sì mu ọtí líle; yóò sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́ àní láti inú ìyá rẹ̀ wá. 16Òun ó sì yí ènìyàn púpọ̀ padà nínú àwọn ọmọ Israẹli sí Olúwa Ọlọ́run wọn. 171.17: Mt 11.14; 17.13; Ml 4.5.Ẹ̀mí àti agbára Elijah ni Olúwa yóò sì fi ṣáájú rẹ̀ lọ, láti pa ọkàn àwọn baba dà sí ti àwọn ọmọ, àti ti àwọn aláìgbọ́ràn sí ọgbọ́n àwọn olóòtítọ́; kí ó le pèsè àwọn ènìyàn tí a múra sílẹ̀ de Olúwa.”

18Sekariah sì wí fún angẹli náà pé, “Ààmì wo ni èmi ó fi mọ èyí? Èmi sá ti di àgbà, àti Elisabeti aya mi sì di arúgbó.”

191.19: Da 8.16; 9.21; Mt 18.10.Angẹli náà sì dáhùn ó wí fún un pé, “Èmi ni Gabrieli, tí máa ń dúró níwájú Ọlọ́run; èmi ni a rán wá láti sọ fún ọ, àti láti mú ìròyìn ayọ̀ wọ̀nyí fún ọ wá. 20Sì kíyèsi i, ìwọ ó yadi, ìwọ kì yóò sì le fọhùn, títí ọjọ́ náà tí nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ, nítorí ìwọ kò gba ọ̀rọ̀ mi gbọ́ tí yóò ṣẹ ní àkókò wọn.”

21Àwọn ènìyàn sì ń dúró de Sekariah, ẹnu sì yà wọ́n nítorí tí ó pẹ́ nínú tẹmpili. 22Nígbà tí ó sì jáde wá, òun kò le bá wọn sọ̀rọ̀. Wọn sì kíyèsi wí pé ó ti rí ìran nínú tẹmpili, ó sì ń ṣe àpẹẹrẹ sí wọn, nítorí tí ó yadi.

23Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ iṣẹ́ ìsìn rẹ̀ pé, ó lọ sí ilé rẹ̀. 24Lẹ́yìn èyí ni Elisabeti aya rẹ̀ lóyún, ó sì fi ara rẹ̀ pamọ́ ní oṣù márùn-ún, 25Ó sì wí pé “Báyìí ni Olúwa ṣe fún mi ní ọjọ́ tí ó ṣíjú wò mí, láti mú ẹ̀gàn mi kúrò láàrín àwọn ènìyàn.”

Ìsọtẹ́lẹ̀ ibi Jesu

26Ní oṣù kẹfà Ọlọ́run sì rán angẹli Gabrieli sí ìlú kan ní Galili, tí à ń pè ní Nasareti, 27sí wúńdíá kan tí a ṣèlérí láti fẹ́ fún ọkùnrin kan, tí a ń pè ní Josẹfu, ti ìdílé Dafidi; orúkọ wúńdíá náà a sì máa jẹ́ Maria. 28Angẹli náà sì tọ̀ ọ́ wá, ó ní, “Àlàáfíà fun ọ, ìwọ ẹni tí a kọjú sí ṣe ní oore, Olúwa ń bẹ pẹ̀lú rẹ.”

29Ṣùgbọ́n ọkàn Maria kò lélẹ̀ nítorí ọ̀rọ̀ náà, ó sì rò nínú ara rẹ̀ pé, irú kíkí kín ni èyí. 301.30: Lk 1.13.Ṣùgbọ́n angẹli náà wí fún un pé, “Má bẹ̀rù, Maria: nítorí ìwọ ti rí ojúrere lọ́dọ̀ Ọlọ́run. 311.31: Lk 2.21; Mt 1.21.Ìwọ yóò lóyún nínú rẹ, ìwọ ó sì bí ọmọkùnrin kan, ìwọ ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jesu. 32Òun ó pọ̀, Ọmọ Ọ̀gá-ògo jùlọ ni a ó sì máa pè é: Olúwa Ọlọ́run yóò sì fi ìtẹ́ Dafidi baba rẹ̀ fún: 331.33: Mt 28.18; Da 2.44.Yóò sì jẹ ọba lórí ilé Jakọbu títí láé; ìjọba rẹ̀ kì yóò sì ní ìpẹ̀kun.”

341.34: Lk 1.18.Nígbà náà ni Maria béèrè lọ́wọ́ angẹli náà pé, “Èyí yóò ha ti ṣe rí bẹ́ẹ̀, nígbà tí èmi kò tí ì mọ ọkùnrin.”

351.35: Mt 1.20.Angẹli náà sì dáhùn ó sì wí fún un pé, “Ẹ̀mí Mímọ́ yóò tọ̀ ọ́ wá, agbára Ọ̀gá-ògo jùlọ yóò ṣíji bò ọ́. Nítorí náà ohun mímọ́ tí a ó ti inú rẹ bí, Ọmọ Ọlọ́run ni a ó máa pè é. 36Sì kíyèsi i, Elisabeti ìbátan rẹ náà yóò sì ní ọmọkùnrin kan ní ògbólógbòó rẹ̀. Èyí sì ni oṣù kẹfà fún ẹni tí à ń pè ní àgàn. 371.37: Gẹ 18.14.Nítorí kò sí ohun tí Ọlọ́run kò le ṣe.”

38Maria sì dáhùn wí pé, “Wò ó ọmọ ọ̀dọ̀ Olúwa; kí ó rí fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.” Angẹli náà sì fi í sílẹ̀ lọ.

Maria bẹ Elisabeti wò

39Ní àkókò náà ni Maria sì dìde, ó lọ kánkán sí ilẹ̀ òkè, sí ìlú kan ní Judea; 40Ó sì wọ ilé Sekariah lọ ó sì kí Elisabeti. 41Ó sì ṣe, nígbà tí Elisabeti gbọ́ kíkí Maria, ọlẹ̀ sọ nínú rẹ̀; Elisabeti sì kún fún Ẹ̀mí mímọ́; 421.42: Lk 11.27-28.Ó sì ké ní ohùn rara, ó sì wí pé, “Alábùkún fún ni ìwọ nínú àwọn obìnrin, alábùkún fún sì ni ọmọ tí ìwọ yóò bí. 43Èéṣe tí èmi fi rí irú ojúrere yìí, tí ìyá Olúwa mi ìbá fi tọ̀ mí wá? 44Sá wò ó, bí ohùn kíkí rẹ ti bọ́ sí mi ní etí, ọlẹ̀ sọ nínú mi fún ayọ̀. 45Alábùkún fún sì ni ẹni tí ó gbàgbọ́: nítorí nǹkan wọ̀nyí tí a ti sọ fún un láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá yóò ṣẹ.”

Orin Maria

46Maria sì dáhùn, ó ní:

“Ọkàn mi yin Olúwa lógo,

47Ẹ̀mí mi sì yọ̀ sí Ọlọ́run Olùgbàlà mi.

48Nítorí tí ó ṣíjú wo ìwà ìrẹ̀lẹ̀

ọmọbìnrin ọ̀dọ̀ rẹ̀: Sá wò ó.

Láti ìsinsin yìí lọ gbogbo ìran ènìyàn ni yóò máa pè mí ní alábùkún fún.

49Nítorí ẹni tí ó ní agbára ti ṣe ohun tí ó tóbi fún mi;

Mímọ́ sì ni orúkọ rẹ̀.

50Àánú rẹ̀ sì ń bẹ fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀

láti ìrandíran.

51Ó ti fi agbára hàn ní apá rẹ̀;

o ti tú àwọn onígbèéraga ká ní ìrònú ọkàn wọn.

52Ó ti mú àwọn alágbára kúrò lórí ìtẹ́ wọn,

o sì gbé àwọn onírẹ̀lẹ̀ lékè.

53Ó ti fi ohun tí ó dára kún àwọn tí ebi ń pa

ó sì rán àwọn ọlọ́rọ̀ padà ní òfo.

54Ó ti ran Israẹli ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ lọ́wọ́,

Ní ìrántí àánú rẹ̀;

551.55: Mt 7.20; Gẹ 17.7; 18.18; 22.17.sí Abrahamu àti àwọn ìran rẹ̀ láéláé, baba wa,

àti bí ó ti sọ fún àwọn baba wa.”

56Maria sì jókòó tì Elisabeti níwọ̀n oṣù mẹ́ta, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀.

Ìbí Johanu onítẹ̀bọmi

57Nígbà tí ọjọ́ Elisabeti pé tí yóò bí; ó sì bí ọmọkùnrin kan. 58Àwọn aládùúgbò, àti àwọn ìbátan rẹ̀ gbọ́ bí Olúwa ti fi àánú ńlá hàn fún un, wọ́n sì bá a yọ̀.

591.59: Le 12.3; Gẹ 17.12.Ó sì ṣe, ní ọjọ́ kẹjọ wọ́n wá láti kọ ọmọ náà nílà; wọ́n sì fẹ́ sọ orúkọ rẹ̀ ní Sekariah, gẹ́gẹ́ bí orúkọ baba rẹ̀. 60Ìyá rẹ̀ sì dáhùn, ó ní, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Johanu ni a ó pè é.”

61Wọ́n sì wí fún un pé, “Kò sí ọ̀kan nínú àwọn ará rẹ̀ tí à ń pè ní orúkọ yìí.”

62Wọ́n sì ṣe àpẹẹrẹ sí baba rẹ̀, bí ó ti ń fẹ́ kí a pè é. 63Ó sì béèrè fún wàláà, ó sì kọ ọ wí pé, “Johanu ni orúkọ rẹ̀.” Ẹnu sì ya gbogbo wọn. 64Ẹnu rẹ̀ sì ṣí lọ́gán, okùn ahọ́n rẹ̀ sì tú, ó sì sọ̀rọ̀, ó sì ń yin Ọlọ́run. 65Ẹ̀rù sì ba gbogbo àwọn tí ń bẹ ní agbègbè wọn: a sì ròyìn gbogbo nǹkan wọ̀nyí ká gbogbo ilẹ̀ òkè Judea. 66Ó sì jẹ́ ohun ìyanu fún gbogbo àwọn tí ó gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n sì tò ó sínú ọkàn wọn, wọ́n ń wí pé, “Irú-ọmọ kín ni èyí yóò jẹ́?” Nítorí tí ọwọ́ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀.

Orin Ṣakariah

67Sekariah baba rẹ̀ sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó sì sọtẹ́lẹ̀, ó ní:

68“Olùbùkún ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli;

nítorí tí ó ti bojú wò, tí ó sì ti dá àwọn ènìyàn rẹ̀ nídè,

69Ó sì ti gbé ìwo ìgbàlà sókè fún wa

ní ilé Dafidi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀;

70(bí ó ti sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì rẹ̀ mímọ́ tipẹ́tipẹ́),

71Pé, a ó gbà wá là lọ́wọ́

àwọn ọ̀tá wa àti lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra wá.

72Láti ṣe àánú tí ó ṣèlérí fún àwọn baba wa,

àti láti rántí májẹ̀mú rẹ̀ mímọ́,

73ìbúra tí ó ti bú fún Abrahamu baba wa,

74láti gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa,

kí àwa kí ó lè máa sìn láìfòyà,

75ni ìwà mímọ́ àti ní òdodo níwájú rẹ̀, ní ọjọ́ ayé wa gbogbo.

761.76: Lk 7.26; Ml 4.5.“Àti ìwọ, ọmọ mi, wòlíì Ọ̀gá-ògo jùlọ ni a ó máa pè ọ́:

nítorí ìwọ ni yóò ṣáájú Olúwa láti tún ọ̀nà rẹ̀ ṣe;

771.77: Mk 1.4.láti fi ìmọ̀ ìgbàlà fún àwọn ènìyàn rẹ̀

fún ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀ wọn,

781.78: Ml 4.2; Ef 5.14.nítorí ìyọ́nú Ọlọ́run wà;

nípa èyí tí ìlà-oòrùn láti òkè wá bojú wò wá,

791.79: Isa 9.2; Mt 4.16.Láti fi ìmọ́lẹ̀ fún àwọn tí ó jókòó ní

òkùnkùn àti ní òjìji ikú,

àti láti fi ẹsẹ̀ wa lé ọ̀nà àlàáfíà.”

801.80: Lk 2.40; 2.52.Ọmọ náà sì dàgbà, ó sì le ní ọkàn, ó sì ń gbé ní ijù títí ó fi di ọjọ́ ìfihàn rẹ̀ fún Israẹli.

Persian Contemporary Bible

لوقا 1:1-80

1بسیاری دست به تألیف حکایت اموری زده‌اند که نزد ما به انجام رسیده است. 2برای انجام این کار، آنها از مطالبی استفاده کرده‌اند که از طریق شاهدان عینی وقایع و شاگردان اولیه، در دسترس ما قرار گرفته است. 3از آنجا که من خود، این مطالب را از آغاز تا پایان، با دقت بررسی و مطالعه کرده‌ام، چنین صلاح دیدم که ماجرا را به طور کامل و به ترتیب برای شما، عالیجناب تِئوفیلوس، بنویسم، 4تا از درستی تعلیمی که یافته‌اید، اطمینان حاصل کنید.

مژدهٔ تولد یحیای تعمیددهنده

5ماجرا را از کاهنی یهودی آغاز می‌کنم، با نام زکریا، که در زمان هیرودیس، پادشاه یهودیه، زندگی می‌کرد. او عضو دسته‌ای از کاهنان معبد بود که اَبیّا نام داشت. همسرش الیزابت نیز مانند خود او از قبیلهٔ کاهنان یهود و از نسل هارون برادر موسی بود. 6زکریا و الیزابت هر دو در نظر خدا بسیار درستکار بودند و با جان و دل تمام احکام و فرایض خداوند را رعایت می‌کردند. 7اما آنها فرزندی نداشتند، زیرا الیزابت نازا بود؛ از این گذشته، هر دو بسیار سالخورده بودند.

8یکبار که گروه زکریا در معبد خدمت می‌کرد، و او به انجام وظایف کاهنیِ خود مشغول بود، 9به حکم قرعه نوبت به او رسید که به جایگاه مقدّس معبد داخل شود و در آنجا بخور بسوزاند. 10به هنگام سوزاندن بخور، جمعیت انبوهی در صحن معبد مشغول عبادت بودند. 11ناگهان فرشته‌ای بر زکریا ظاهر شد و در طرف راست مذبح بخور ایستاد. 12زکریا از دیدن فرشته مبهوت و هراسان شد.

13فرشته به او گفت: «ای زکریا، نترس! چون آمده‌ام به تو خبر دهم که خدا دعایت را شنیده است، و همسرت الیزابت برایت پسری به دنیا خواهد آورد که نامش را یحیی خواهی گذاشت. 14این پسر باعث شادی و سُرور شما خواهد شد، و بسیاری نیز از تولدش شادی خواهند نمود. 15زیرا او در نظر خداوند بزرگ خواهد بود. او هرگز نباید شراب و مشروبات سُکرآور بنوشد، چون حتی پیش از تولد، از روح‌القدس پر خواهد بود! 16بسیاری از بنی‌اسرائیل توسط او به سوی خداوند، خدای خود بازگشت خواهند نمود. 17او خدمت خود را با همان روح و قدرت ایلیای نبی انجام خواهد داد. او پیشاپیش مسیح خواهد آمد تا مردم را برای ظهور او آماده کند و دل پدران را به سوی فرزندان بازگرداند. او سبب خواهد شد افراد سرکش، حکمت خداترسان را بپذیرند.»

18زکریا به فرشته گفت: «ولی این غیرممکن است، چون من پیر شده‌ام و همسرم نیز سالخورده است!»

19فرشته در جواب گفت: «من جبرائیل هستم که در حضور خدا می‌ایستم و اوست که مرا فرستاده تا این خبر خوش را به تو بدهم. 20اما حال که سخنان مرا باور نکردی، لال خواهی شد و تا زمانی که کودک به دنیا بیاید یارای سخن گفتن نخواهی داشت؛ زیرا آنچه گفتم، در زمان مقرر واقع خواهد شد.»

21در این میان، مردم در صحن معبد منتظر زکریا بودند و از اینکه او در بیرون آمدن از جایگاه مقدّس این همه تأخیر می‌کرد، در حیرت بودند. 22سرانجام وقتی بیرون آمد و نتوانست با ایشان سخن گوید، از اشارات او پی بردند که در جایگاه مقدّس معبد رؤیایی دیده است.

23زکریا پس از پایان دوره خدمتش، به خانهٔ خود بازگشت. 24طولی نکشید که همسرش الیزابت باردار شد. او برای مدت پنج ماه گوشه‌نشینی اختیار کرد و می‌گفت: 25«سرانجام خداوند بر من نظر لطف انداخت و کاری کرد که دیگر در میان مردم شرمگین نباشم!»

مژدهٔ تولد عیسی

26در ششمین ماه بارداری الیزابت، خدا فرشته خود جبرائیل را به ناصره، یکی از شهرهای ایالت جلیل فرستاد، 27تا نزد دختری1‏:27 یا «باکره‌ای». به نام مریم برود. مریم نامزدی داشت به نام یوسف، از نسل داوود پادشاه.

28جبرائیل بر مریم ظاهر شد و گفت: «درود بر تو، که بسیار مورد لطف هستی! خداوند با توست!»

29مریم از این سخنان پریشان و متحیّر شد، و نمی‌دانست این چه نوع تحیّتی می‌تواند باشد.

30فرشته به او گفت: «ای مریم، نترس! زیرا خدا بر تو نظر لطف انداخته است! 31تو به‌زودی باردار شده، پسری به دنیا خواهی آورد و نامش را عیسی خواهی نهاد. 32او بسیار بزرگ خواهد بود و پسر خدای متعال نامیده خواهد شد، و خداوند تخت سلطنت جدّش، داوود را به او خواهد سپرد، 33تا برای همیشه بر نسل یعقوب1‏:33 خدا نام یعقوب، نوۀ ابراهیم را به «اسرائیل» تغییر داد. سلطنت کند، سلطنتی که هرگز پایانی نخواهد داشت!»

34مریم از فرشته پرسید: «اما چگونه چنین چیزی امکان دارد؟ دست هیچ مردی هرگز به من نرسیده است!»

35فرشته پاسخ داد: «روح‌القدس بر تو خواهد آمد، و قدرت خدای متعال بر تو سایه خواهد افکند. از این رو، آن نوزاد مقدّس بوده، پسر خدا خوانده خواهد شد. 36بدان که خویشاوند تو، الیزابت نیز شش ماه پیش در سن پیری باردار شده و به‌زودی پسری به دنیا خواهد آورد؛ بله، همان کس که همه او را نازا می‌خواندند. 37زیرا برای خدا هیچ کاری محال نیست!»

38مریم گفت: «من خدمتگزار خداوند هستم. هر چه دربارۀ من گفتی، همان بشود.» آنگاه فرشته او را ترک گفت.

مریم از الیزابت دیدار می‌کند

39پس از چند روز، مریم تدارک سفر دید و شتابان به کوهستان یهودیه رفت، 40جایی که زکریا زندگی می‌کرد. مریم وارد خانه شده، به الیزابت سلام کرد. 41به محض اینکه صدای سلام مریم به گوش الیزابت رسید، آن طفل در رحم او به حرکت درآمد. آنگاه الیزابت از روح‌القدس پر شد، 42و با صدای بلند به مریم گفت: «تو در میان زنان خجسته‌ای، و فرزندت نیز خجسته است. 43چه افتخار بزرگی است برای من، که مادر خداوندم به دیدنم بیاید! 44وقتی وارد شدی و به من سلام کردی، به محض اینکه صدایت را شنیدم، بچه از شادی در رَحِمِ من به حرکت درآمد! 45خوشا به حال تو، زیرا ایمان آوردی که هر چه خدا به تو گفته است، به انجام خواهد رسید!»

سرود شکرگزاری مریم

46مریم گفت: «خداوند را با تمام وجود ستایش می‌کنم، 47و روح من، به سبب نجات‌دهنده‌ام خدا، شاد و مسرور است! 48چون او منِ ناچیز را مورد عنایت قرار داده است. از این پس، همهٔ نسلها مرا خوشبخت خواهند خواند، 49زیرا خدای قادر و قدوس در حق من کارهای بزرگ کرده است.

50«لطف و رحمت او، نسل اندر نسل شامل حال آنانی می‌شود که از او می‌ترسند. 51او دست خود را با قدرت دراز کرده و متکبران را همراه نقشه‌هایشان پراکنده ساخته است. 52سلاطین را از تخت به زیر کشیده و فروتنان را سربلند کرده است. 53گرسنگان را با نعمتهای خود سیر کرده، اما ثروتمندان را تهی دست روانه نموده است. 54او رحمت خود را به یاد آورده، و خادم خویش اسرائیل را یاری داده است. 55بله، او که وعدهٔ ابدی خود را که به ابراهیم و فرزندانش داده بود، به یاد آورده است.»

56مریم حدود سه ماه نزد الیزابت ماند. سپس به خانه خود بازگشت.

تولد یحیای تعمیددهنده

57سرانجام، انتظار الیزابت پایان یافت و زمان وضع حملش فرا رسید و پسری به دنیا آورد. 58وقتی که همسایگان و بستگان او از این خبر آگاهی یافتند و دیدند که خداوند چه لطف بزرگی در حق او نموده است، نزد او آمده، در شادی‌اش شریک شدند.

59چون نوزاد هشت روزه شد، تمام بستگان و دوستانشان برای مراسم ختنه گرد آمدند و قصد داشتند نام پدرش، زکریا را بر او بگذارند. 60اما الیزابت نپذیرفت و گفت: «نام او یحیی خواهد بود.»

61گفتند: «اما در خانواده تو، کسی چنین نامی نداشته است.»

62پس با اشاره، از پدر نوزاد پرسیدند که می‌خواهد نام او را چه بگذارد.

63زکریا با اشاره، تخته‌ای خواست و در برابر چشمان حیرت‌زدهٔ همه نوشت: «نامش یحیی است!» 64در همان لحظه زبانش باز شد و قدرت سخن گفتن را بازیافت و به شکرگزاری خدا پرداخت. 65همسایگان با دیدن تمام این وقایع بسیار متعجب شدند، و خبر این ماجرا در سراسر کوهستان یهودیه پخش شد. 66هر که این خبر را می‌شنید، به فکر فرو می‌رفت و از خود می‌پرسید: «این طفل، در آینده چه خواهد شد؟»، زیرا همه می‌دیدند که او مورد توجه خاص خداوند قرار دارد.

نبوّت زکریا

67آنگاه پدرش زکریا، از روح‌القدس پر شد و نبوّت کرده، چنین گفت:

68«خداوند، خدای اسرائیل را سپاس باد، زیرا به یاری قوم خود شتافته و ایشان را رهایی بخشیده است. 69او به‌زودی برای ما نجات‌دهنده‌ای قدرتمند از نسل داوود خواهد فرستاد؛ 70چنانکه از دیرباز، از زبان انبیای مقدّس خود وعده می‌داد 71که شخصی را خواهد فرستاد تا ما را از چنگ دشمنانمان و از دست همه آنانی که از ما نفرت دارند، رهایی بخشد.

72«او نسبت به نیاکان ما، رحیم و مهربان بوده است. بله، او عهد و پیمان مقدّس خود را به یاد آورده است، 73همان عهدی را که با سوگند با جدّ ما، ابراهیم بست، 74که ما را از دست دشمنانمان رهایی بخشد تا بتوانیم بدون ترس و واهمه او را عبادت کنیم 75و تمام روزهای عمر خود را در حضور او با پاکی و عدالت بگذرانیم.

76«و تو ای فرزند من، نبی خدای متعال نامیده خواهی شد، زیرا پیشاپیش خداوند حرکت خواهی کرد تا راه او را آماده نمایی، 77و قوم او را آگاه سازی که با آمرزش گناهانشان نجات خواهند یافت. 78اینها، همه به سبب رحمت و شفقت بی‌پایان خدای ماست. به‌زودی سپیده صبح از افق آسمان بر ما طلوع خواهد کرد 79تا بر کسانی که در تاریکی و سایۀ مرگ ساکن هستند، بتابد و همهٔ ما را به سوی آرامش و صلح و صفا هدایت نماید.»

80آن کودک رشد می‌کرد و در روح، نیرومند می‌شد. او در بیابانها به سر می‌بُرد، تا روزی فرا رسید که می‌بایست خدمت خود را به‌طور علنی در میان قوم اسرائیل آغاز کند.