Galatia 1 – YCB & SZ-PL

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Galatia 1:1-24

1Paulu, aposteli tí a rán kì í ṣe láti ọ̀dọ̀ ènìyàn wá, tàbí nípa ènìyàn, ṣùgbọ́n nípa Jesu Kristi àti Ọlọ́run Baba, ẹni tí ó jí i dìde kúrò nínú òkú. 2Àti gbogbo àwọn arákùnrin tí ó wà pẹ̀lú mi,

Sí àwọn ìjọ ní Galatia:

31.3: Ro 1.7.Oore-ọ̀fẹ́ sí yín àti àlàáfíà láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wá àti Jesu Kristi Olúwa, 41.4: Ga 2.20; 1Tm 2.6.ẹni tí ó fi òun tìkára rẹ̀ dípò ẹ̀ṣẹ̀ wa, kí ó lè gbà wá kúrò nínú ayé búburú ìsinsin yìí, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ Ọlọ́run àti Baba wa, 51.5: Ro 16.27.ẹni tí ògo wà fún láé àti láéláé. Àmín.

Kò sí ìyìnrere mìíràn

6Ó yà mi lẹ́nu pé ẹ tètè yapa kúrò lọ́dọ̀ ẹni tí ó pè yín sínú oore-ọ̀fẹ́ Kristi, sí ìyìnrere mìíràn. 7Nítòótọ́, kò sí ìyìnrere mìíràn bí ó tilẹ̀ ṣe pé àwọn kan wà, tí ń yọ yín lẹ́nu, tí wọ́n sì ń fẹ́ yí ìyìnrere Kristi padà. 81.8: 2Kọ 11.4.Ṣùgbọ́n bí ó ṣe àwa ni tàbí angẹli kan láti ọ̀run wá, ni ó bá wàásù ìyìnrere mìíràn fún yín ju èyí tí a tí wàásù rẹ̀ fún yín lọ, jẹ́ kí ó di ẹni ìfibú títí láéláé! 9Bí àwa ti wí ṣáájú, bẹ́ẹ̀ ni mo sì tún wí nísinsin yìí pé, bí ẹnìkan bá wàásù ìyìnrere mìíràn fún yín ju èyí tí ẹ̀yin tí gbà lọ, jẹ́ kí ó di ẹni ìfibú títí láéláé!

101.10: 1Tẹ 2.4.Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ènìyàn ni èmi ń wá ojúrere rẹ̀ ní tàbí Ọlọ́run? Tàbí ènìyàn ni èmi ń fẹ́ láti wù bí? Bí èmi bá ń fẹ́ láti wu ènìyàn, èmi kò lè jẹ́ ìránṣẹ́ Kristi.

Paulu ẹni tí Ọlọ́run pè

111.11: Ro 1.16-17.Mo fẹ́ kí ẹ mọ̀, ará, pé ìyìnrere tí mo tí wàásù kì í ṣe láti ipa ènìyàn. 12N kò gbà á lọ́wọ́ ènìyàn kankan, bẹ́ẹ̀ ni a kò fi kọ́ mi, ṣùgbọ́n mo gbà á nípa ìfihàn láti ọ̀dọ̀ Jesu Kristi.

131.13: Ap 8.3.Nítorí ẹ̀yin ti gbúròó ìgbé ayé mi nígbà àtijọ́ nínú ìsìn àwọn Júù, bí mo tí ṣe inúnibíni sí ìjọ ènìyàn Ọlọ́run rékọjá ààlà, tí mo sì lépa láti bà á jẹ́. 141.14: Ap 22.3.Mo sì ta ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ẹlẹgbẹ́ mi yọ nínú ìsìn àwọn Júù láàrín àwọn ìran mi, mo sì ni ìtara lọ́pọ̀lọ́pọ̀ sì òfin àtọwọ́dọ́wọ́ àwọn baba mi. 151.15: Ap 9.1-19; Isa 49.1; Jr 1.5.Ṣùgbọ́n nígbà tí ó wú Ọlọ́run ẹni tí ó yà mí sọ́tọ̀ láti inú ìyá mi wá, tí ó sì pé mi nípa oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀. 16Láti fi ọmọ rẹ̀ hàn nínú mi, kì èmi lè máa wàásù ìyìnrere rẹ̀ láàrín àwọn aláìkọlà; èmi kò wá ìmọ̀ lọ sọ́dọ̀ ẹnikẹ́ni, 17bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gòkè lọ sì Jerusalẹmu tọ àwọn tí í ṣe aposteli ṣáájú mi, ṣùgbọ́n mo lọ sí Arabia, mo sì tún padà wá sí Damasku.

181.18: Ap 9.26-30; 11.30.Lẹ́yìn ọdún mẹ́ta, nígbà náà ni mo gòkè lọ sì Jerusalẹmu láti lọ kì Peteru, mo sì gbé ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní ìjọ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún, 19èmi kò ri ẹlòmíràn nínú àwọn tí ó jẹ́ aposteli, bí kò ṣe Jakọbu arákùnrin Olúwa. 20Nǹkan tí èmi ń kọ̀wé sí yín yìí, kíyèsi i, níwájú Ọlọ́run èmi kò ṣèké.

21Lẹ́yìn náà mo sì wá sí agbègbè Siria àti ti Kilikia. 22Mo sì jẹ́ ẹni tí a kò mọ̀ lójú fún àwọn ìjọ tí ó wà nínú Kristi ni Judea. 23Wọ́n kàn gbọ́ ìròyìn wí pé, “Ẹni tí ó tí ń ṣe inúnibíni sí wa rí, ní ìsinsin yìí ti ń wàásù ìgbàgbọ́ náà tí ó ti gbìyànjú láti bàjẹ́ nígbà kan rí.” 24Wọ́n sì yin Ọlọ́run lógo nítorí mi.

Słowo Życia

Galacjan 1:1-24

Pozdrowienie

1Ja, Paweł, nie zostałem powołany na apostoła przez ludzi, lecz przez samego Jezusa Chrystusa i Boga Ojca, który wskrzesił Go z martwych. 2Dlatego razem z wierzącymi, którzy są ze mną, piszę do kościołów w Galicji. 3Niech Bóg, nasz Ojciec, i Pan, Jezus Chrystus, obdarzają was swoją łaską i pokojem!

4Jezus ofiarował siebie za nasze grzechy, aby wyrwać nas z tego złego świata. A dokonał tego zgodnie z planem Boga, naszego Ojca, 5któremu należy się wieczna chwała. Amen!

Nie ma innej dobrej nowiny

6Jestem zdumiony tym, że tak szybko odchodzicie od Boga, który w swojej łasce powołał was do życia w Chrystusie, i że szukacie innej dobrej nowiny. Ale innej dobrej nowiny nie ma! 7Są tylko ludzie, którzy oszukują was i chcą zmienić treść nowiny o Chrystusie.

8Gdyby jednak ktoś—nawet jakiś wierzący z naszego grona albo anioł z nieba!—przedstawił wam dobrą nowinę inną od tej, którą od nas usłyszeliście, niech będzie przeklęty! 9Jeszcze raz to powtórzę: Jeśli ktokolwiek głosiłby wam dobrą nowinę inną od tej, którą już przyjęliście, niech będzie przeklęty!

10Jak myślicie? Czy mówiąc to chcę zdobyć przychylność ludzi, czy Boga? Czy chcę w ten sposób zadowolić jakiegoś człowieka? Jeśli taki byłby mój cel, nie byłbym dobrym sługą Chrystusa.

Paweł powołany przez Boga

11Przyjaciele, zapewniam was, że głoszona przeze mnie dobra nowina nie została wymyślona przez ludzi. 12Nie przekazał mi jej żaden człowiek ani od nikogo się jej nie nauczyłem. Objawił mi ją osobiście sam Jezus Chrystus!

13Wiecie zapewne, że kiedyś, jako wyznawca judaizmu, bezlitośnie prześladowałem kościół Boży i próbowałem go zniszczyć. 14Byłem chyba najgorliwszy ze wszystkich ludzi w kraju—stałem się wręcz fanatykiem tradycji naszych przodków. 15Bóg jednak wybrał mnie jeszcze przed moim urodzeniem i przyciągnął mnie do siebie swoją łaską. 16Uczynił to, aby przeze mnie objawić światu swojego Syna i abym przekazał poganom dobrą nowinę o Jezusie.

Gdy poznałem Jezusa, nikogo nie pytałem, co mam robić. 17Nie poszedłem nawet do Jerozolimy—do tych, którzy zostali apostołami wcześniej ode mnie. Skierowałem się wówczas do Arabii, a potem wróciłem do Damaszku. 18Dopiero po trzech latach udałem się do Jerozolimy, aby odwiedzić Piotra. Spędziłem z nim jednak tylko piętnaście dni. 19Spośród innych apostołów nie spotkałem wówczas nikogo oprócz Jakuba, brata naszego Pana. 20A Bóg mi świadkiem, że mówiąc to, nie kłamię. 21Zaraz po tym skierowałem się w okolice Syrii i Cylicji, 22tak że wierzący z kościołów Chrystusa w Judei nie wiedzieli nawet, jak wyglądam. 23Słyszeli jedynie wieści o tym, że ich dawny prześladowca głosi teraz wiarę, którą przedtem zwalczał. 24I z mojego powodu wielbili Boga.