Sekariah 14 – YCB & BDS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Sekariah 14:1-21

Olúwa Wa Jọba

1Kíyèsi i, ọjọ́ Olúwa ń bọ̀, a ó sì pín ìkógun rẹ̀ láàrín rẹ̀.

2Nítorí èmi ó kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ sí Jerusalẹmu fún ogun; a ó sì ko ìlú naà, a ó sì kó àwọn ilé, a ó sì ba àwọn obìnrin jẹ́, ààbọ̀ ìlú náà yóò lọ sí ìgbèkùn, a kì yóò sì gé ìyókù àwọn ènìyàn náà kúrò ni ìlú náà. 3Nígbà náà ni Olúwa yóò jáde lọ, yóò sì bá àwọn orílẹ̀-èdè náà jà, gẹ́gẹ́ bí í ti ìjà ní ọjọ́ ogun. 4Ẹsẹ̀ rẹ̀ yóò sì dúró ni ọjọ́ náà lórí òkè Olifi, tí ó wà níwájú Jerusalẹmu ni ìlà-oòrùn, òkè Olifi yóò sì là á sí méjì, sí ìhà ìlà-oòrùn àti ìhà ìwọ̀-oòrùn, Àfonífojì ńláńlá yóò wà: ìdajì òkè náà yóò sì ṣí síhà àríwá, àti ìdajì rẹ̀ síhà gúúsù. 5Ẹ̀yin ó sì sá sí àfonífojì àwọn òkè mi: nítorí pé àfonífojì òkè náà yóò dé Aseli: nítòótọ́, ẹ̀yin ó sá bí ẹ tí sá fún ìmìmì-ilẹ̀ ni ọjọ́ Ussiah ọba Juda: Olúwa Ọlọ́run mi yóò sì wá, àti gbogbo àwọn Ẹni mímọ́ pẹ̀lú rẹ̀.

6Yóò sì ṣe ni ọjọ́ náà, ìmọ́lẹ̀ kì yóò mọ́, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ṣókùnkùn. 7Ṣùgbọ́n yóò jẹ́ ọjọ́ kan mímọ́ fún Olúwa, kì í ṣe ọ̀sán, kì í ṣe òru; ṣùgbọ́n yóò ṣe pé, ni àṣálẹ́ ìmọ́lẹ̀ yóò wà.

8Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, omi ìyè yóò tí Jerusalẹmu sàn lọ; ìdajì wọn síhà Òkun ìlà-oòrùn, àti ìdajì wọn síhà okùn ẹ̀yìn: nígbà ẹ̀rùn àti nígbà òtútù ni yóò rí bẹ́ẹ̀.

9Olúwa yóò sì jẹ ọba lórí gbogbo ayé; ni ọjọ́ náà ni Olúwa kan yóò wa orúkọ rẹ̀ nìkan náà ni orúkọ.

10A ó yí gbogbo ilẹ̀ padà bi pẹ̀tẹ́lẹ̀ kan láti Geba dé Rimoni lápá gúúsù Jerusalẹmu: yóò di bí aginjù, ṣùgbọ́n a ó sì gbé Jerusalẹmu sókè, yóò sì gbe ipò rẹ̀, láti ibodè Benjamini títí dé ibi ibodè èkínní, dé ibodè igun nì, àti láti ilé ìṣọ́ Hananeli dé ibi ìfúntí wáìnì ọba. 1114.11: If 22.3.Ènìyàn yóò sì máa gbé ibẹ̀, kì yóò sì sí ìparun mọ́; ṣùgbọ́n a ó máa gbé Jerusalẹmu láìléwu.

12Èyí ni yóò sì jẹ́ ààrùn tí Olúwa yóò fi kọlu gbogbo àwọn ènìyàn ti ó tí ba Jerusalẹmu jà; ẹran-ara wọn yóò rù nígbà tí wọn dúró ni ẹsẹ̀ wọn, ojú wọn yóò sì rà ni ihò wọn, ahọ́n wọn yóò sì bàjẹ́ ni ẹnu wọn. 13Yóò sì ṣe ni ọjọ́ náà, ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá yóò wà láàrín wọn; wọn ó sì di ọwọ́ ara wọn mú, ọwọ́ èkínní yóò sì dìde sì ọwọ́ èkejì rẹ̀. 14Juda pẹ̀lú yóò sì jà ni Jerusalẹmu: ọrọ̀ gbogbo àwọn kèfèrí tí ó wà káàkiri ni a ó sì kójọ, wúrà àti fàdákà, àti aṣọ, ní ọ̀pọ̀lọpọ̀. 15Bẹ́ẹ̀ ni ààrùn ẹṣin, ìbáaka, ìbákasẹ, àti tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, yóò sì wà, àti gbogbo ẹranko tí ń bẹ nínú àgọ́.

16Yóò sì ṣe, olúkúlùkù ẹni tí o kù nínú gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó dìde sí Jerusalẹmu yóò máa gòkè lọ lọ́dọọdún láti sìn ọba, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, àti láti ṣe àjọyọ̀ àsè àgọ́ náà. 17Yóò sì ṣe, ẹnikẹ́ni tí kì yóò gòkè wá nínú gbogbo ìdílé ayé sí Jerusalẹmu láti sín ọba, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, òjò kì yóò rọ̀ fún wọn. 1814.18-19: Isa 19; Jr 46; El 29–32.Bí ìdílé Ejibiti kò bá sì gòkè lọ, tí wọn kò sì wá, fi ara wọn hàn tí wọn kò ní òjò; ààrùn náà yóò wà, tí Olúwa yóò fi kọlù àwọn kèfèrí tí kò gòkè wá láti ṣe àjọyọ̀ àsè àgọ́ náà 19Èyí ni yóò sì jẹ́ ìyà Ejibiti, àti ìyà gbogbo orílẹ̀-èdè tí kò gòkè wá láti pa àsè àgọ́ mọ́.

20Ní ọjọ́ náà ni “mímọ́ sí Olúwa” yóò wà lára ṣaworo ẹṣin: àti àwọn ìkòkò ni ilé Olúwa yóò sì dàbí àwọn ọpọ́n tí ń bẹ níwájú pẹpẹ. 21Nítòótọ́, gbogbo ìkòkò ni Jerusalẹmu àti ni Juda yóò jẹ́ mímọ́ sí Olúwa àwọn ọmọ-ogun: àti gbogbo àwọn tí ń rú ẹbọ yóò wá, wọn ó sì mú ìkòkò díẹ̀, wọn ó sì bọ ẹran wọn nínú rẹ̀, ni ọjọ́ náà ni àwọn Kenaani kò ní sí mọ́ ni ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun.

La Bible du Semeur

Zacharie 14:1-21

Le combat final

1Voici venir le jour de l’Eternel14.1 Voir Es 13.6-9 ; Ez 20.2-3 ; Am 5.18 ; Ab 15 ; Jl 1.15 ; 2.1-2, 10-11 ; 3.3-4 ; 4.14-16 ; So 1.7., où l’on partagera dans tes murs mêmes le butin pris chez toi. 2J’assemblerai alors l’ensemble des peuples étrangers devant Jérusalem pour la combattre. La ville sera prise, les maisons saccagées et les femmes violées, la moitié de la ville partira en exil, mais le reste du peuple ne sera pas éliminé de la ville.

3Puis l’Eternel viendra combattre ces peuples comme il le fait quand il combat au jour de la bataille. 4En ce jour-là, il posera ses pieds sur le mont des Oliviers14.4 Voir Ac 1.11-12., près de Jérusalem, du côté du levant. Le mont des Oliviers se fendra d’est en ouest en deux parties ; une immense vallée se creusera entre les deux. Une moitié du mont reculera au nord, l’autre moitié au sud. 5Et la vallée de mes montagnes sera comblée14.5 D’après l’ancienne version grecque et le targoum, en adoptant une autre vocalisation que le texte hébreu traditionnel qui a : et vous fuirez alors par la vallée de mes montagnes., car elle s’étendra jusqu’à Atsal14.5 Atsal: site inconnu d’une localité à l’est de Jérusalem.. Elle sera comblée, ce jour-là, comme elle a été comblée lors du14.5 Elle sera comblée… comme elle a été comblée lors du: en adoptant une autre vocalisation du texte hébreu traditionnel qui a : vous fuirez… comme vous avez fui. tremblement de terre au temps d’Ozias, roi de Juda. Puis l’Eternel mon Dieu viendra, avec tous les saints anges.

6En ce jour-là, il n’y aura plus de luminaire14.6 Voir Ap 21.23., plus de froid, plus de gel14.6 plus de froid, plus de gel: selon la lecture proposée en marge par les copistes juifs. Le texte hébreu contient une expression traduite diversement : car les luminaires se condenseront ou que des choses précieuses en condensation.. 7Ce jour sera unique, il est connu de l’Eternel, il n’y aura ni jour ni nuit, et même le soir, la lumière brillera. 8En ce jour-là, des eaux vives jailliront de Jérusalem et couleront, moitié vers la mer Morte, et moitié vers la Méditerranée14.8 Voir Ez 47.1-12.. Il en sera ainsi l’été comme l’hiver.

9En ce jour-là, l’Eternel sera roi de toute la terre. En ce jour-là, l’Eternel sera le seul Dieu et on le priera lui seul. 10Le pays tout entier depuis Guéba jusqu’à Rimmôn, qui se trouve au sud14.10 Tout le pays depuis la frontière nord (2 R 23.8) jusqu’à celle du sud (Jos 15.32) sera nivelé et abaissé pour que Jérusalem puisse apparaître exaltée. Voir Es 2.2 ; Mi 4.1 ; Ap 21.9. de Jérusalem, sera changé en plaine. Jérusalem sera surélevée sur place, de la porte de Benjamin jusqu’à l’emplacement de la Première Porte, jusqu’à celle de l’Angle, de la tour de Hananéel jusqu’aux pressoirs du roi. 11On y habitera, il n’y aura plus d’anathème14.11 Voir Ap 22.3., Jérusalem vivra dans la sécurité.

12Et voici de quel fléau l’Eternel frappera tous les peuples qui auront combattu contre Jérusalem : la chair de tous les hommes se décomposera tandis qu’ils seront sur pieds, et leurs yeux pourriront dans leurs orbites, et, dans leur bouche, leur langue pourrira. 13En ce jour-là, une immense panique causée par l’Eternel s’emparera d’eux tous. Ils s’empoigneront les uns les autres par le bras et chacun lèvera la main contre son compagnon. 14Les hommes de Juda se joindront au combat au milieu de Jérusalem, et l’on amassera les richesses de tous les peuples de partout : de l’or et de l’argent avec des vêtements en quantité énorme. 15Un fléau identique frappera les chevaux, les mulets, les chameaux et les ânes, et tout animal parqué dans leur camp. Oui, tous les animaux seront frappés du même fléau.

16Et il arrivera que tous ceux qui subsisteront de tous les peuples qui seront venus attaquer Jérusalem, monteront tous les ans pour se prosterner devant le Roi, le Seigneur des armées célestes, et pour célébrer la fête des Cabanes14.16 Voir Lv 23.24 ; Dt 16.13 ; en même temps que la fête des Récoltes (Ex 23.16).. 17Si l’un des clans familiaux de la terre refuse de monter jusqu’à Jérusalem pour adorer le Roi, le Seigneur des armées célestes, il ne recevra pas de pluie. 18Et si les Egyptiens ne montent pas, oui, s’ils refusent de venir, ils subiront aussi la plaie dont l’Eternel frappera tous les peuples qui ne monteront pas pour célébrer la fête des Cabanes. 19Ce sera la sanction du péché de l’Egypte et celle de toute nation qui ne montera pas pour célébrer la fête des Cabanes.

20En ce jour-là, les grelots des chevaux porteront l’inscription : « Consacré à l’Eternel14.20 Voir Ex 28.36-38. ». Et même les marmites dans le temple de l’Eternel seront tout aussi saintes que les coupes placées devant l’autel.

21Et dans Jérusalem, et partout en Juda, les marmites seront toutes consacrées à l’Eternel, le Seigneur des armées célestes, et tous ceux qui viendront offrir des sacrifices les utiliseront pour y cuire la viande, et il n’y aura plus de marchands dans le temple du Seigneur des armées célestes, en ce jour-là.