Malaki 1 – YCB & BDS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Malaki 1:1-14

1Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀: ọ̀rọ̀ Olúwa sí Israẹli láti ẹnu Malaki.

Ọlọ́run fẹ́ràn Jakọbu, o sì kórìíra Esau

21.2-3: Ro 9.13.1.2-5: Isa 34; 63.1-6; Jr 49.7-22; El 25.12-14; 35; Am 1.11-12; Ọd.“Èmí ti fẹ́ ẹ yín,” ni Olúwa wí.

“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni ìwọ ṣe fẹ́ wa?’

“Esau kì í ha ṣe arákùnrin Jakọbu bí?” ni Olúwa wí. “Síbẹ̀ èmi fẹ́ràn Jakọbu, 3ṣùgbọ́n Esau ni mo kórìíra, mo ti sọ àwọn òkè ńlá rẹ̀ di aṣálẹ̀, mo sì fi ìní rẹ̀ fún àwọn akátá aginjù.”

4Edomu lè wí pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a run wá, àwa yóò padà wá, a ó sì tún ibùgbé náà kọ́.”

Ṣùgbọ́n èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Àwọn lè kọ́, ṣùgbọ́n èmi yóò wó palẹ̀. Wọn yóò sì pè wọ́n ní ilẹ̀ búburú, àwọn ènìyàn tí wọ́n máa ń wà ní ìbínú Olúwa. 5Ẹ̀yin yóò sì fi ojú yín rí i, ẹ̀yin yóò sì wí pé, ‘Títóbi ni Olúwa, títóbi rẹ̀ tayọ kọjá agbègbè Israẹli.’

Ẹbọ àìmọ́

6“Ọmọ a máa bu ọ̀wọ̀ fún baba rẹ̀, ọmọ ọ̀dọ̀ a sì máa bu ọlá fún olúwa rẹ̀. Ǹjẹ́ bí èmí bá jẹ́ baba, ọlá tí ó tọ́ sí mi ha dà? Bí èmi bá sì jẹ́ olúwa, ẹ̀rù tí ó tọ́ sí mi dà?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

“Ẹ̀yin ni, ẹ̀yin àlùfáà, ni ẹ ń gan orúkọ mi.

“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe gan orúkọ rẹ?’

7“Ẹ̀yin gbé oúnjẹ àìmọ́ sí orí pẹpẹ mi.

“Ẹ̀yin sì tún béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe ṣe àìmọ́ sí ọ?’

“Nípa sísọ pé tábìlì Olúwa di ẹ̀gàn. 8Nígbà tí ẹ̀yin mú afọ́jú ẹran wá fún ìrúbọ, ṣé èyí kò ha burú bí? Nígbà tí ẹ̀yin fi amúnkùn ún àti aláìsàn ẹran rú ẹbọ, ṣé èyí kò ha burú gidigidi bí? Ẹ dán an wò, ẹ fi wọ́n rú ẹbọ sí àwọn baálẹ̀ yín! Ṣé inú rẹ̀ yóò dùn sí yín? Ṣé yóò gbà yín?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

9“Ní ìsinsin yìí, ẹ bẹ Ọlọ́run kí ó ṣàánú fún wa. Ṣùgbọ́n pẹ̀lú irú àwọn ẹbọ wọ̀nyí láti ọwọ́ yín wá, ṣé yóò gbà yín?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

10“Hó ò! Ẹnìkan ìbá jẹ́ wà láàrín yín ti yóò sé ìlẹ̀kùn tẹmpili, pé kí ẹ má ba à ṣe dá iná asán lórí pẹpẹ mi mọ́! Èmi kò ní inú dídùn sí i yín,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò gba ọrẹ kan lọ́wọ́ yín. 11Orúkọ mi yóò tóbi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, láti ìlà-oòrùn títí ó sì fi dé ìwọ̀-oòrùn. Ní ibi gbogbo ni a ó ti mú tùràrí àti ọrẹ mímọ́ wá fún orúkọ mi, nítorí orúkọ mi tóbi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

12“Nítorí ẹ̀yin ti sọ ọ́ di àìmọ́, nínú èyí tí ẹ wí pé, ‘Tábìlì Olúwa di àìmọ́ àti èso rẹ̀,’ àní oúnjẹ rẹ̀ ni ohun ẹ̀gàn. 13Ẹ̀yin wí pẹ̀lú pé, ‘Wò ó, irú àjàgà kín ni èyí!’ Ẹ̀yin sì yínmú sí i,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

“Nígbà tí ẹ̀yin sì mú èyí tí ó fi ara pa, arọ àti ọlọkùnrùn ẹran tí ẹ sì fi rú ẹbọ, Èmi o ha gba èyí lọ́wọ́ yín?” ni Olúwa wí. 14“Ṣùgbọ́n ègún ni fún ẹlẹ́tàn náà, tí ó ni akọ nínú ọ̀wọ́ ẹran rẹ̀, tí ó sì ṣe ìlérí láti fi lélẹ̀ tí ó sì fi ẹran tó lábùkù rú ẹbọ sí Olúwa; nítorí ọba ńlá ni Èmi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “ẹ̀rù sì ni orúkọ mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.

La Bible du Semeur

Malachie 1:1-14

1Proclamation, parole que l’Eternel a adressée à Israël par l’intermédiaire de Malachie1.1 Malachie: voir l’introduction..

L’amour de l’Eternel pour son peuple

2Moi, je vous ai aimés, déclare l’Eternel. Et vous me demandez : « En quoi donc nous as-tu aimés ? » Esaü n’est-il pas le frère de Jacob ? demande l’Eternel. Or, j’ai aimé Jacob, 3et j’ai écarté Esaü1.3 Cité en Rm 9.13. : j’ai fait de ses montagnes un pays désolé, et j’ai livré son patrimoine aux chacals du désert. 4Edom peut bien dire : « Nous avons été démolis, mais nous rebâtirons ce qui n’est plus que ruines. » Mais le Seigneur des armées célestes déclare : Eux, ils rebâtiront, moi, je démolirai. On appellera leur pays : « le territoire de la méchanceté, le peuple contre qui, toujours, l’Eternel sera en colère ». 5Et vous le verrez de vos yeux, et vous direz : « L’Eternel est très grand, même au-delà du territoire d’Israël. »

L’honneur dû à l’Eternel

6Le Seigneur des armées célestes s’adresse à vous les prêtres, vous qui me méprisez : Un fils honore un père, un serviteur son maître. Si je suis votre père, où donc sont les honneurs qui me sont dus ? Si je suis votre maître, où est la crainte qui m’est due ? Et puis vous demandez : « En quoi t’avons-nous méprisé ? » 7Vous apportez sur mon autel des aliments impurs1.7 Parce que non conformes aux règles de la Loi (voir v. 8 ; Lv 22.17-30 ; Dt 15.21). et puis vous demandez : « En quoi t’avons-nous profané ? » C’est en disant : « La table de l’Eternel est chose méprisable. » 8Quand, pour le sacrifice, vous venez présenter un animal aveugle, n’y a-t-il rien de mal ? Et quand vous présentez une bête éclopée ou malade, n’y a-t-il rien de mal ? Offrez-le donc à votre gouverneur ! Sera-t-il content de vous ? Ou vous fera-t-il bon accueil ? dit l’Eternel, le Seigneur des armées célestes. 9Ensuite, après avoir agi ainsi, vous venez supplier Dieu d’avoir pitié de vous ! Vous fera-t-il bon accueil ? demande le Seigneur des armées célestes. 10Qui enfin, parmi vous, se décidera à fermer les portes de mon temple, pour que vous n’allumiez plus inutilement le feu sur mon autel ? Je n’ai aucun plaisir en vous, dit l’Eternel, le Seigneur des armées célestes. Je n’agrée pas l’offrande de vos mains.

11Car, du soleil levant jusqu’au soleil couchant, ma renommée sera très grande au milieu des peuples non israélites, et partout, en tout lieu, de l’encens me sera offert et des offrandes pures. Car, parmi ces peuples, ma renommée sera très grande, dit l’Eternel, le Seigneur des armées célestes1.11 Autre traduction : Car, du soleil levant jusqu’au soleil couchant, ma renommée est très grande au milieu des nations, et partout, en tout lieu, de l’encens m’est offert et des offrandes pures. Car, parmi les nations, ma renommée est très grande, dit l’Eternel, le Seigneur des armées célestes..

12Mais vous, vous me profanez lorsque vous dites : « La table du Seigneur est impure, et ce qu’elle nous rapporte en aliments est vraiment méprisable. » 13« Quel fardeau ! », dites-vous, et vous me dédaignez, déclare l’Eternel, le Seigneur des armées célestes. Vous apportez ici des bêtes dérobées, boiteuses ou malades ; ce sont là vos offrandes. Croyez-vous que je vais les agréer de votre part ? demande l’Eternel.

14Maudit soit le tricheur qui a dans son troupeau un mâle, qui s’engage par un vœu, puis qui offre au Seigneur une bête tarée. Car je suis un grand Roi, déclare l’Eternel, le Seigneur des armées célestes, et les peuples non israélites me craindront.