Sekariah 13 – YCB & BDS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Sekariah 13:1-9

Ìwẹ̀nùmọ́ kúrò nínú ẹsẹ̀

1“Ní ọjọ́ náà ìsun kan yóò ṣí sílẹ̀ fún ilé Dafidi àti fún àwọn ará Jerusalẹmu, láti wẹ̀ wọ́n mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ àti àìmọ́ wọn.

2“Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ni èmi ó gé orúkọ àwọn òrìṣà kúrò ni ilẹ̀ náà, a kì yóò sì rántí wọn mọ́: àti pẹ̀lú èmi ó mú àwọn wòlíì èké àti àwọn ẹ̀mí àìmọ́ kúrò ni ilẹ̀ náà. 3Yóò sì ṣe, nígbà tí ẹnìkan yóò sọtẹ́lẹ̀ síbẹ̀, ni baba rẹ̀ àti ìyá rẹ̀ tí ó bí í yóò wí fún un pé, ‘Ìwọ ki yóò yè: nítorí ìwọ ń sọ ọ̀rọ̀ èké ni orúkọ Olúwa.’ Àti baba rẹ̀ àti ìyá rẹ̀ tí o bí í yóò gun un ni àgúnpa nígbà tí ó bá sọtẹ́lẹ̀.

4“Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, ojú yóò tí àwọn wòlíì èké olúkúlùkù nítorí ìran rẹ̀, nígbà tí òun ba tí sọtẹ́lẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò sì wọ aṣọ wòlíì onírun rẹ̀ tí o fi ń tan ní jẹ. 5Ṣùgbọ́n òun o wí pé, ‘Èmi kí í ṣe wòlíì, àgbẹ̀ ni èmi; nítorí tí a ti fi mí ṣe ìránṣẹ́ láti ìgbà èwe mi wá.’ 6Ẹnìkan ó sì wí fún un pé, ‘Ọgbẹ́ kín ní wọ̀nyí ni ẹ̀yìn rẹ?’ Òun o sì dáhùn pé, ‘Wọ̀nyí ni ibi tí a ti sá mi ní ilé àwọn ọ̀rẹ́ mi.’

A lu olùṣọ́-àgùntàn, agbo ẹran fọ́nká

713.7: Mt 26.31; Mk 14.27.“Dìde, ìwọ idà, sí olùṣọ́-àgùntàn mi,

àti sí ẹni tí í ṣe ẹnìkejì mi,”

ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí:

“Kọlu Olùṣọ́-àgùntàn,

àwọn àgùntàn a sì túká:

èmi o sì yí ọwọ́ mi sí àwọn kéékèèkéé.

8Yóò sì ṣe, ni gbogbo ilẹ̀,” ni Olúwa wí,

“a ó gé apá méjì nínú rẹ̀ kúrò yóò sì kú;

ṣùgbọ́n apá kẹta yóò kù nínú rẹ̀.

9Èmi ó sì mú apá kẹta náà la àárín iná,

èmi yóò sì yọ́ wọn bí a ti yọ́ fàdákà,

èmi yóò sì dán wọn wò, bi a tí ń dán wúrà wò:

wọn yóò sì pé orúkọ mi,

èmi yóò sì dá wọn lóhùn:

èmi yóò wí pé, ‘Àwọn ènìyàn mi ni,’

àwọn yóò sì wí pé, ‘Olúwa ni Ọlọ́run wa.’ ”

La Bible du Semeur

Zacharie 13:1-9

1En ce jour-là, jaillira une source pour purifier de leurs péchés et de leurs impuretés, la famille de David et les habitants de Jérusalem.

Le jugement des adorateurs d’idoles

2Et il arrivera en ce jour-là, déclare l’Eternel, le Seigneur des armées célestes, que j’extirperai du pays jusqu’au nom des idoles : et l’on ne s’en souviendra plus. J’ôterai aussi du pays les faux prophètes et les dispositions impures. 3Si quelqu’un prophétise encore, alors son propre père et sa mère elle-même, eux qui l’ont engendré, lui déclareront : « Tu ne resteras pas en vie. Car tu dis des mensonges au nom de l’Eternel. » Et son père et sa mère, eux qui l’ont engendré, transperceront leur fils pendant qu’il prophétisera13.3 Voir Dt 13.6-9.. 4Et il arrivera en ce jour-là, que tous les faux prophètes seront remplis de honte alors qu’ils prophétiseront, à cause des révélations qu’ils auront apportées. Ils ne porteront plus de manteau de poil13.4 Signe distinctif de certains prophètes (1 R 19.13, 19 ; 2 R 1.8). pour tromper. 5Chacun protestera : « Je ne suis pas prophète, moi, je cultive la terre et l’on a loué mes services13.5 l’on a loué mes services. Autre traduction : je possède la terre. depuis le temps de ma jeunesse. » 6Et quand on lui dira : « Que sont donc ces blessures que l’on voit sur ton corps ? » alors il répondra : « C’est la trace des coups reçus dans la maison de mes amis13.6 Autre traduction : mes amants. Les faux prophètes se faisaient parfois des incisions pour attirer l’attention de leur divinité sur eux (voir 1 R 18.28). Les faux prophètes auront eux-mêmes honte et n’oseront plus se donner pour prophètes.. »

L’alliance renouvelée

7Epée, réveille-toi ╵contre mon berger, le chef de mon peuple,

contre mon compagnon13.7 Cité en Mt 26.31 ; Mc 14.27.,

demande l’Eternel, ╵le Seigneur des armées célestes.

Va, frappe le berger :

que les brebis soient dispersées !

Je porterai la main ╵sur les petits.

8Alors dans le pays entier,

l’Eternel le déclare,

les deux tiers des humains ╵seront exterminés, ╵ils périront,

seul un tiers survivra.

9Et je ferai passer ╵ce tiers-là par le feu,

oui, je l’épurerai

ainsi qu’on épure l’argent.

Et je l’éprouverai

comme on éprouve l’or.

Ce tiers m’invoquera

et je l’exaucerai.

Je dirai : « C’est mon peuple. »

Lui, il confessera : ╵« L’Eternel est mon Dieu13.9 Voir Ex 6.7 ; 19.5-6 ; 20.1 ; Dt 29.12.. »