Saamu 89 – YCB & BPH

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 89:1-52

Saamu 89

Maskili ti Etani ará Esra.

1Èmi kọrin títóbi ìfẹ́ Olúwa títí láé;

pẹ̀lú ẹnu mi ní èmi yóò jẹ́ kí a mọ òtítọ́ rẹ láti ìran dé ìran.

2Èmi ó wí pé, ìfẹ́ rẹ dúró títí láé,

pé ìwọ gbe òtítọ́ rẹ kalẹ̀ ní ọ̀run fúnrarẹ̀.

389.3-4: Sm 132.11; Ap 2.30.Ìwọ wí pé, “Èmi ti dá májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn àyànfẹ́ mi

mo ti búra fún Dafidi ìránṣẹ́ mi.

4‘Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ múlẹ̀ títí láé

èmí ó sì máa gbe ìtẹ́ rẹ ró láti ìran dé ìran.’ ”

5Àwọn ọ̀run yóò máa yin iṣẹ́ ìyanu rẹ, Olúwa,

òtítọ́ rẹ ni ìpéjọpọ̀ àwọn ẹni mímọ́.

6Ta ni ó wà ní ọ̀run tí a lè fiwé Olúwa?

Ta ni nínú àwọn ọmọ alágbára ti a lè fiwé Olúwa?

7Nínú àjọ ìgbìmọ̀ ẹni mímọ́, wọ́n bẹ̀rù Ọlọ́run gidigidi;

ó sì ní ìbùyìn fún ju gbogbo àwọn tí ó yí i ká.

8Olúwa Ọlọ́run alágbára, ta ló dàbí rẹ

ìwọ jẹ́ alágbára, Olúwa, òtítọ́ rẹ sì yí ọ ká.

9Ìwọ ń darí ríru omi Òkun;

nígbà tí ó ru àwọn omi sókè, ìwọ mú wọn parọ́rọ́.

10Ìwọ ni ó ti ya Rahabu pẹ́rẹpẹ̀rẹ

bí ẹni tí a pa;

ìwọ ti fi apá ọwọ́ agbára rẹ

tú àwọn ọ̀tá rẹ ká.

11Tìrẹ ní àwọn ọ̀run, ayé pẹ̀lú jẹ́ tìrẹ:

ayé àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀:

ìwọ ti gbé wọn kalẹ̀.

12Gúúsù àti àríwá ìwọ ni ó dá wọn;

Tabori àti Hermoni ń fi ayọ̀ yin orúkọ rẹ.

13Ìwọ ní apá agbára;

agbára ní ọwọ́ rẹ, gíga ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.

14Òdodo àti òtítọ́ ni ìpìlẹ̀ ìtẹ́ rẹ:

ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ àti òtítọ́ ń lọ síwájú rẹ.

15Ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn tí wọn mọ ohùn ayọ̀ nì,

Olúwa wọ́n ó máa rìn ní ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ.

16Wọn ń ṣògo nínú orúkọ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́,

wọn ń yin òdodo rẹ.

17Nítorí ìwọ ni ògo agbára wọn;

nípa ojúrere ni ìwo wá ń ṣògo.

18Nítorí ti Olúwa ni asà wa,

ọba wa sì ni Ẹni Mímọ́ Israẹli.

19Nígbà náà ni ìwọ sọ̀rọ̀ nínú ìran, sí àwọn olóòtítọ́ rẹ, wí pé:

“Èmi ti gbé adé kalẹ̀ sórí ẹni tí ó lágbára,

èmi ti gbé ẹni tí a yàn láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn ga.

2089.20: Ap 13.22.Èmi ti rí Dafidi ìránṣẹ́ mi;

pẹ̀lú òróró mímọ́ mi ni mo fi yàn án;

21Ìgbà gbogbo ni ọwọ́ mi yóò máa wà pẹ̀lú rẹ̀

apá mí yóò sì fi agbára fún un.

22Àwọn ọ̀tá kì yóò borí rẹ̀,

àwọn ènìyàn búburú kì yóò rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀

23Èmi yóò run àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ

èmi yóò lu àwọn tí ó kórìíra rẹ bolẹ̀

24Òtítọ́ mi àti ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ yóò wà pẹ̀lú rẹ

àti ní orúkọ mi ni a ó gbé ìwo rẹ ga.

25Èmi ó gbé ọwọ́ rẹ lórí Òkun

àti ọwọ́ ọ̀tún rẹ lórí àwọn odo ńlá

26Òun yóò kígbe sí mi pé, ‘ìwọ ni baba mi, Ọlọ́run mi, àti àpáta ìgbàlà mi!’

2789.27: If 1.5.Èmi yóò ṣe é ni àkọ́bí mi,

Ẹni gíga ju àwọn ọba ayé.

28Títí láé ni èmi yóò pa ìfẹ́ dídúró ṣinṣin mọ́ fún un,

àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ̀ yóò dúró gbọingbọin.

29Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ̀ múlẹ̀ títí láé,

àti ìtẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti wà láé.

30“Bí àwọn ọmọ rẹ̀ bá kọ òfin mi sílẹ̀

tí wọn kò sì rìn gẹ́gẹ́ bí ìlànà mi.

31Tí wọn bá ba ìlànà mi jẹ́

tí wọn kò sì pa àṣẹ mi mọ́,

32Nígbà náà ni èmi ó fì ọ̀gọ̀ bẹ ìrékọjá wọn wò;

àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn pẹ̀lú pàṣán:

33Ṣùgbọ́n èmi kò ní mú ìfẹ́ mi tí ó dúró ṣinṣin kúrò lọ́dọ̀ rẹ,

bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò jẹ́ kí òtítọ́ mi kí ó yẹ̀.

34Èmi kì yóò sẹ́ májẹ̀mú mi,

bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọ̀rọ̀ tí ó ti ẹnu mi jáde padà.

35Lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo ni èmi ti fi ìwà mímọ́ mi búra;

èmi kì yóò purọ́ fún Dafidi.

36Irú-ọmọ rẹ yóò dúró títí láé,

àti ìtẹ́ rẹ̀ yóò dúró bí oòrùn níwájú mi.

3789.37: If 1.5; 3.14.A ó fi múlẹ̀ títí láé bí òṣùpá,

àti bi ẹlẹ́rìí òtítọ́ ni ọ̀run”. Sela.

38Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ ti ṣá tì, ìwọ sì kórìíra;

ìwọ kún fún ìrunú sí ẹni ààmì òróró rẹ.

39Ìwọ ti sọ májẹ̀mú ìránṣẹ́ rẹ di òfo;

ìwọ tàbùkù adé rẹ nínú eruku

40Ìwọ ti wó gbogbo àwọn odi rẹ̀

ìwọ sọ ibi gíga rẹ̀ di ahoro.

41Àwọn tí ń kọjá lọ fi ṣe ìjẹ;

ó ti di ẹ̀gàn àwọn olùbágbé rẹ̀.

42Ìwọ ti gbé ọwọ́ ọ̀tún ọ̀tá rẹ̀ sókè;

ìwọ mú gbogbo ọ̀tá rẹ̀ yọ̀.

43Pẹ̀lú, ìwọ ti yí ojú idà rẹ̀ padà,

ìwọ kò sì dúró tì í nínú ogun.

44Ìwọ ti mú ògo rẹ̀ kùnà,

ìwọ si wó ìtẹ́ rẹ̀ palẹ̀ sílẹ̀ẹ́lẹ̀.

45Ìwọ ti gé ọjọ́ èwe rẹ̀ kúrú;

ìwọ sì fi ìtìjú bò ó.

46Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa?

Tí ìwọ ó ha fi ara rẹ pamọ́ títí láé?

Yóò ti pẹ́ to tí ìbínú rẹ yóò máa jó bí iná?

47Rántí bí ọjọ́ mi ti kúrú tó

nítorí asán ha ni ìwọ fi ṣẹ̀dá àwọn ènìyàn!

48Ta ni yóò wà láààyè tí kò ní rí ikú rẹ̀?

Ta ló lè sá kúrò nínú agbára isà òkú?

49Olúwa, níbo ni ìṣeun ìfẹ́ rẹ àtijọ́ wà,

tí ìwọ ti fi òtítọ́ rẹ búra fún Dafidi?

50Rántí, Olúwa, bí a ti ń gan àwọn ìránṣẹ́ rẹ;

bí èmi ti gbà ní àyà mi láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn,

51Ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá rẹ gàn, Olúwa,

tí wọn gan ipasẹ̀ Ẹni ààmì òróró rẹ.

52Olùbùkún ní Olúwa títí láé.

Àmín àti Àmín.

Bibelen på hverdagsdansk

Salmernes Bog 89:1-53

Guds løfte til David

1En visdomssang af ezraitten Etan.

2Herre, jeg vil altid synge om din nåde,

tale om din trofasthed fra slægt til slægt.

3Din nåde forandres aldrig,

din trofasthed kan umuligt høre op.

4„Jeg har sluttet pagt med min udvalgte,

højtideligt lovet min tjener David,

5at jeg altid vil tage vare på hans slægt

og bygge ham en evig trone.”

6Englene lovpriser dine undere, Herre,

himmelske skarer synger om din trofasthed.

7Er der nogen, der kan sammenlignes med Gud?

Hvem af englene kan måle sig med ham?

8Den himmelske forsamling skælver foran dig,

alle omkring dig bøjer sig i ærefrygt.

9Hvem er som du, almægtige Gud?

Altid er du omgivet af din trofasthed.

10Du hersker over det oprørte hav,

du befaler over de brusende bølger.

11Du knuste Rahab, det stolte uhyre,

du fejede dine fjender langt væk.

12Himlen er din, jorden tilhører dig,

du skabte dem med alt, hvad de rummer.

13Du skabte både nord og syd.

Tabor og Hermon priser dig med glæde.

14Din arm er umådelig stærk,

din højre hånd kan besejre alt.

15Din trone er bygget på retfærdighed,

du kendetegnes ved nåde og sandhed.

16Lykkelige er de, som lovsynger dig,

de lever i lyset af dit nærvær.

17De glæder sig over dig dagen lang,

soler sig i din godhed.

18Du er grunden til deres styrke,

vi sejrer på grund af din nåde og accept.

19Vor konge89,19 Ordret „skjold”, da kongen skulle beskytte og hjælpe sit folk. er indsat af Herren,

Israels almægtige Gud udvalgte ham.

20Du sagde engang i et syn til din profet:

„Jeg har valgt at støtte en ung helt,

udvalgt en konge blandt almindelige mennesker.

21Jeg udtog David som min tjener,

salvede ham med olie til konge.

22Min hånd skal altid støtte ham,

min arm give ham styrke.

23Hans fjender kan ikke få ram på ham,

de onde kan ikke overmande ham.

24Jeg vil selv gøre det af med hans fjender,

jeg tilintetgør dem, der hader ham.

25Min trofaste kærlighed følger ham altid,

han får styrke ved at stole på mig.

26Jeg giver ham magt over havet,

han skal herske over floderne.

27Han skal kalde mig ‚Far’ og ‚Gud’

og ‚Redningsmand’.

28Jeg vil gøre ham til min førstefødte søn,

den mægtigste konge på jorden.

29Jeg vil være ham tro for evigt,

min pagt med ham står fast.

30Hans slægt skal altid bestå,

hans rige vare ved, så længe himlen er til.

31Men hvis hans børn svigter mig

og ikke adlyder mine bud,

32hvis de bryder mine love

og ikke gør, som jeg siger,

33så må jeg straffe dem for deres oprør,

drage dem til ansvar for deres ulydighed.

34Men jeg vil altid være ham tro

og holde fast ved mit løfte.

35Jeg bryder ikke min pagt,

og svigter ikke mit ord.

36Jeg har én gang aflagt et højtideligt løfte,

og jeg kan ikke lyve overfor David.

37Hans slægt skal altid bestå,

hans rige vare ved, så længe solen står op,

38så længe månen er til,

så længe himlen består.”

Bøn om national befrielse

39Men nu har du forkastet din udvalgte konge,

du har udøst din vrede over mig.

40Du har svigtet pagten med din tjener,

du har kastet min kongekrone i støvet.

41Du har nedbrudt vore forsvarsmure,

lagt vore fæstninger i ruiner.

42Alle, der kommer forbi, udplyndrer os,

vi er til spot for vore naboer.

43Du har givet vore fjender sejren,

og gjort vore modstandere glade.

44Min hær er slået tilbage,

du hjalp mig ikke mod fjenden.

45Du har gjort ende på min herlighed,

væltet min trone omkuld.

46Du gjorde mig gammel før tiden,

jeg blev til skamme for øjnene af alle.

47Åh, Herre, hvor længe skal det fortsætte?

Hvor længe vil du skjule dig for os?

Hvor længe vil din vrede brænde som ild?

48Husk på, at mit liv er kort.

Hvorfor skal mennesker være så magtesløse?

49Kan man leve evigt og aldrig dø?

Kan man undslippe dødsrigets magt?

50Herre, hvor er din trofasthed blevet af?

Hvor er den godhed, du lovede David?

51Herre, se, hvordan din tjener foragtes,

hvordan jeg må udholde folkenes hån.

52Dine fjender ler ad mig, Herre,

de puster mig i nakken med deres hån.

53Lovet være Herren for evigt.

Amen, amen.