Jobu 1 – YCB & BPH

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 1:1-22

Ìbẹ̀rẹ̀ ìgbé ayé Jobu

1Ọkùnrin kan wà ní ilẹ̀ Usi, orúkọ ẹni tí í jẹ́ Jobu; ọkùnrin náà sì ṣe olóòtítọ́, ó dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó kórìíra ìwà búburú, 2A sì bi ọmọkùnrin méje àti ọmọbìnrin mẹ́ta fún un. 3Ohun ọ̀sìn rẹ̀ sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin (7,000) àgùntàn, àti ẹgbẹ̀ẹ́dógún (3,000) ìbákasẹ, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta (500) àjàgà ọ̀dá màlúù, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta (500) abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì pọ̀; bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin yìí sì pọ̀jù gbogbo àwọn ará ìlà-oòrùn lọ.

4Àwọn ọmọ rẹ̀ a sì máa lọ í jẹun àsè nínú ilé ara wọn, olúkúlùkù ní ọjọ́ rẹ̀; wọn a sì máa ránṣẹ́ pé arábìnrin wọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta láti jẹun àti láti pẹ̀lú wọn. 5Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ àsè wọn pé yíká, ni Jobu ránṣẹ́ lọ í yà wọ́n sí mímọ́, ó sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀, ó sì rú ẹbọ sísun níwọ̀n iye gbogbo wọn; nítorí tí Jobu wí pé: bóyá àwọn ọmọ mi ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣọpẹ́ fún Ọlọ́run lọ́kàn wọn. Bẹ́ẹ̀ ní Jobu máa ń ṣe nígbà gbogbo.

Ìdánwò Jobu àkọ́kọ́

6Ǹjẹ́ ó di ọjọ́ kan, nígbà tí àwọn ọmọ Ọlọ́run wá í pé níwájú Olúwa, Satani sì wá pẹ̀lú wọn. 7Olúwa sì bi Satani wí pé, “Níbo ni ìwọ ti wá?”

Nígbà náà ní Satani dá Olúwa lóhùn wí pé, “Ní ìlọ-síwá-sẹ́yìn lórí ilẹ̀ ayé, àti ní ìrìnkèrindò nínú rẹ̀.”

8Olúwa sì sọ fún Satani pé, “Ìwọ ha kíyèsi Jobu ìránṣẹ́ mi, pé kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ̀ ní ayé, ọkùnrin tí í ṣe olóòtítọ́, tí ó sì dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, ti ó sì kórìíra ìwà búburú.”

9Nígbà náà ni Satani dá Olúwa lóhùn wí pé, “Jobu ha bẹ̀rù Ọlọ́run ní asán bí?” 10“Ìwọ kò ha ti ṣọgbà yìí ká, àti yí ilé rẹ̀ àti yí ohun tí ó ní ká, ní ìhà gbogbo? Ìwọ bùsi iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀, ohun ọ̀sìn rẹ̀ sì ń pọ̀ si ní ilẹ̀. 11Ǹjẹ́, nawọ́ rẹ nísinsin yìí, kí ó sì fi tọ́ ohun gbogbo tí ó ni; bí kì yóò sì bọ́hùn ni ojú rẹ.”

12Olúwa sì dá Satani lóhùn wí pé, “Kíyèsi i, ohun gbogbo tí ó ní ń bẹ ní ìkáwọ́ rẹ, kìkì òun tìkára rẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ fi ọwọ́ rẹ kàn.”

Bẹ́ẹ̀ ni Satani jáde lọ kúrò níwájú Olúwa.

13Ó sì di ọjọ́ kan nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti obìnrin, tí wọ́n mu ọtí wáìnì nínú ilé ẹ̀gbọ́n wọn ọkùnrin, 14oníṣẹ́ kan sì tọ Jobu wá wí pé: “Àwọn ọ̀dá màlúù ń tulẹ̀, àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì ń jẹ ní ẹ̀gbẹ́ wọn; 15Àwọn ará Sabeani sì kọlù wọ́n, wọ́n sì ń kó wọn lọ pẹ̀lú, wọ́n ti fi idà sá àwọn ìránṣẹ́ pa, èmi nìkan ṣoṣo ní ó sá àsálà láti ròyìn fún ọ.”

16Bí ó ti ń sọ ní ẹnu; ẹnìkan dé pẹ̀lú tí ó sì wí pé, “Iná ńlá Ọlọ́run ti ọ̀run bọ́ sí ilẹ̀, ó sì jó àwọn àgùntàn àti àwọn ìránṣẹ́; èmi nìkan ṣoṣo ní ó sálà láti ròyìn fún ọ.”

17Bí ó sì ti ń sọ ní ẹnu, ẹnìkan sì dé pẹ̀lú tí ó wí pé, “Àwọn ará Kaldea píngun sí ọ̀nà mẹ́ta, wọ́n sì kọlù àwọn ìbákasẹ, wọ́n sì kó wọn lọ, pẹ̀lúpẹ̀lú wọ́n sì fi idà sá àwọn ìránṣẹ́ pa; èmi nìkan ṣoṣo ni ó sá àsálà láti ròyìn fún ọ!”

18Bí ó ti ń sọ ní ẹnu, ẹnìkan dé pẹ̀lú tí ó sì wí pé àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin ń jẹ, wọ́n ń mu ọtí wáìnì nínú ilé ẹ̀gbọ́n. 19Sì kíyèsi i, ẹ̀fúùfù ńláńlá ti ìhà ijù fẹ́ wá kọlu igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilé, ó sì wó lu àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin náà, wọ́n sì kú, èmi nìkan ṣoṣo ni ó yọ láti ròyìn fún ọ.

20Nígbà náà ni Jobu dìde, ó sì fa aṣọ ìgúnwà rẹ̀ ya, ó sì fá orí rẹ̀ ó wólẹ̀ ó sì gbàdúrà 21wí pé:

“Ní ìhòhò ní mo ti inú ìyá mi jáde wá,

ni ìhòhò ní èmi yóò sì tún padà lọ.

Olúwa fi fún ni, Olúwa sì gbà á lọ,

ìbùkún ni fún orúkọ Olúwa.”

22Nínú gbogbo èyí Jobu kò ṣẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sì fi òmùgọ̀ pe Ọlọ́run lẹ́jọ́.

Bibelen på hverdagsdansk

Jobs Bog 1:1-22

Jobs rigdom og gudfrygtighed

1En mand ved navn Job boede i området Utz.1,1 Dette område menes at ligge i det nuværende Jordan, ikke langt fra Amman. Han var en retskaffen og gudfrygtig mand, der gjorde sit bedste for ikke at synde imod Gud. 2-3Han havde syv sønner og tre døtre, og han var meget rig. Han ejede 7000 får, 3000 kameler, 500 par okser, 500 hunæsler samt et stort antal tjenestefolk, så han var den rigeste mand i området øst for Israel.

4Jobs sønner elskede at holde fest på omgang hos hinanden. De inviterede altid deres tre søstre med, og der blev spist og drukket i flere dage. 5Hver gang en sådan fest var forbi, sendte Job bud efter dem, for at de kunne gennemgå en renselsesceremoni. Han stod op tidligt om morgenen og bragte et brændoffer for hver af dem for at bede Gud om tilgivelse, hvis de i festens kådhed var kommet til at synde mod Gud og i tankerne havde forbandet ham.

Gud tillader Satan at sætte Job på prøve

6En dag, da englene1,6 Ordret: „Guds sønner”, som her henviser til de overnaturlige væsener, Gud skabte og brugte som sine sendebud og tjenere. Det samme gælder for Job 2,1 og 38,7. trådte frem for Herren, var også Satan1,6 Navnet „Satan” betyder „modstander, anklager”. iblandt dem.

7„Hvad har du bedrevet, Satan?” spurgte Herren.

„Jeg har gennemtravet jorden på kryds og tværs!” svarede Satan.

8„Nå, det har du,” fortsatte Herren. „Lagde du mærke til min tjener Job? Han er enestående blandt mennesker, en retskaffen og gudfrygtig mand, der gør sit bedste for ikke at begå nogen synd.”

9„Det er da klart,” indvendte Satan. 10„Du har jo altid holdt hånden over ham og hans familie og alt, hvad han ejer. Du har velsignet ham på alle måder. Se bare, hvor rig han er blevet! 11Men prøv engang at tage hans rigdom fra ham, så skal jeg love dig for, at han vil forbande dig lige op i dit åbne ansigt!”

12Da svarede Herren: „Gør, hvad du vil, med hans rigdom, Satan, men du må ikke gøre ham selv fortræd.”

Så gik Satan bort fra Herren.

13Ulykken ramte Job en dag, hvor hans sønner og døtre holdt fest hjemme hos den ældste bror. 14-15Først kom en mand løbende hen til Job og råbte: „Da vi var ved at pløje med okserne, og æslerne gik og græssede i nærheden, overfaldt sabæerne1,14-15 Sabæerne boede øst for Det Røde Hav og er bl.a. kendt fra dronningen af Saba. os pludselig! De stjal alle dyrene og dræbte dine arbejdere. Jeg var den eneste, der undslap.”

16Mens han endnu talte, kom en anden mand løbende med følgende besked: „Der brød et uvejr løs, og lynene slog ned og dræbte både fårene og hyrderne. Jeg var den eneste, der undslap.”

17Mens han endnu talte, kom en tredje mand løbende med flere dårlige nyheder: „Vi blev pludselig overfaldet af tre kaldæiske røverbander, som stjal alle kamelerne og dræbte dine arbejdere. Jeg var den eneste, der undslap.”

18Mens han endnu talte, kom en fjerde mand løbende med den værste besked af alle: „Dine sønner og døtre var samlet til fest i din ældste søns hus. 19Men pludselig kom en kraftig ørkenstorm og rystede huset så voldsomt, at det styrtede sammen og begravede dine børn. De omkom alle, og jeg var den eneste, der undslap.”

20Da rejste Job sig og rev sin kappe itu som udtryk for sin dybe sorg og fortvivlelse. Derefter barberede han alt sit hår af og kastede sig til jorden for Guds ansigt. 21„Nøgen kom jeg til verden, og nøgen skal jeg herfra!” sagde han. „Herren gav, og Herren tog. Al ære tilkommer ham!”

22På trods af denne tragedie syndede Job ikke. Han anklagede ikke Gud for det, der var sket.