Saamu 73 – YCB & OL

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 73:1-28

ÌWÉ KẸTA

Saamu 73–89

Saamu 73

Saamu ti Asafu.

1Nítòótọ́ Ọlọ́run dára fún Israẹli,

fún àwọn ọlọ́kàn funfun.

2Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi, ẹsẹ̀ mi ti yẹ̀ tán;

ìrìn mi fẹ́rẹ̀ yọ̀ tán.

3Nítorí èmi ń ṣe ìlara àwọn tó ń ṣe féfé

nígbà tí mo bá rí àlàáfíà àwọn ènìyàn búburú.

4Wọn kò ṣe wàhálà;

ara wọn mókun wọn sì lágbára.

5Wọn kò ní ìpín nínú àjàgà tó ń ṣẹlẹ̀ sí ènìyàn;

a kò pọ́n wọn lójú nípa ẹlòmíràn.

6Ìgbéraga ni ọ̀ṣọ́ ọrùn wọn;

ìwà ipá bò wọ́n mọ́lẹ̀ bí aṣọ.

7Láti inú ọkàn àrékérekè ni àìṣòdodo ti wá;

ẹ̀rí ọkàn búburú wọn kò ní òdínwọ̀n

8Wọn ń ṣẹ̀sín, wọn sì ń sọ̀rọ̀-òdì ní ti

ìnilára, wọ́n ń sọ̀rọ̀ láti ibi gíga.

9Wọ́n ń gbé ẹ̀mí wọn lé ọ̀run

ahọ́n wọn gba ipò ayé.

10Nítorí náà àwọn ènìyàn wọn yípadà sí wọn

wọ́n sì mu omi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.

11Wọ́n wí pé, “Báwo ni Ọlọ́run yóò ṣe mọ̀?

Ọ̀gá-ògo ha ní ìmọ̀ bí?”

12Bí àwọn ènìyàn búburú ṣe rí nìyí

ènìyàn asán, wọ́n ń pọ̀ ní ọrọ̀.

13Nítòótọ́ nínú asán ni mo pa ọkàn mi mọ́;

nínú asán ni mo wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́ṣẹ̀.

14Ní gbogbo ọjọ́ ni a ń yọ mí lẹ́nu;

a sì ń jẹ mí ní yà ní gbogbo òwúrọ̀.

15Bí mo bá wí pé, “Èmi ó wí báyìí,”

Èmi ó ṣẹ̀ sí ìran àwọn ọmọ rẹ̀.

16Nígbà tí mo gbìyànjú láti mọ èyí,

Ó jẹ́ ìnilára fún mi.

17Títí mo fi wọ ibi mímọ́ Ọlọ́run;

Nígbà náà ni òye ìgbẹ̀yìn wọn yé mi.

18Lóòtítọ́ ìwọ gbé wọn lórí ilẹ̀ yíyọ́

ìwọ jù wọ́n sílẹ̀ sínú ìparun.

19Báwo ní a ti mú wọn lọ sínú ìdahoro yìí

bí ẹni pé ní ìṣẹ́jú kan!

Ìbẹ̀rù ni a fi ń run wọ́n pátápátá!

20Bí àlá nígbà tí ènìyàn bá jí,

bẹ́ẹ̀ ni nígbà tí ìwọ bá dìde, Olúwa,

ìwọ yóò ṣe àbùkù àwòrán wọn.

21Nígbà tí inú mi bàjẹ́

àti ọkàn mi ṣì korò,

22Mo jẹ́ aṣiwèrè àti aláìlóye;

mo jẹ́ ẹranko ní iwájú rẹ.

23Síbẹ̀ mo wà pẹ̀lú rẹ nígbà gbogbo;

ìwọ di ọwọ́ ọ̀tún mi mú.

24Ìwọ fi ìmọ̀ràn rẹ tọ́ mi

ní ìkẹyìn ìwọ ó mú mi lọ sí inú ògo

25Ta ni mo ní ní ọ̀run, bí kò ṣe ìwọ?

Àti ní ayé kò sí ohun tí mo fẹ́ lẹ́yìn rẹ.

26Ara mi àti ọkàn mi le è kùnà

ṣùgbọ́n Ọlọ́run ni agbára ẹ̀mí mi

àti ìpín mi títí láé.

27Àwọn tí ó jìnnà sí ọ yóò ṣègbé

ìwọ ti pa gbogbo wọn run;

tí ń ṣe àgbèrè kiri kúrò lọ́dọ̀ rẹ

28Ṣùgbọ́n ní ti èmi, ó dára láti súnmọ́ Ọlọ́run

Èmi ti fi Olúwa Olódùmarè ṣe ààbò mi;

Kí èmi ó lè máa sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ.

O Livro

Salmos 73:1-28

Terceiro Livro

(Salmos 73–89)

Salmo 73

Salmo de Asafe.

1Deus é verdadeiramente bom para com Israel,

para com todos os que têm um coração puro.

2Quanto a mim,

por pouco me ia desviando do caminho reto;

quase escorregava.

3Pois tive inveja do bem-estar dos soberbos

e dos maus.

4Eles não têm medo de morrer;

o seu poder é garantido.

5Não se veem metidos em dificuldades,

como toda a gente,

nem rodeados de problemas.

6O orgulho é como um ornamento nas suas vidas;

vestem-se de violência como da melhor roupa.

7Têm os olhos arregalados de cobiça

e a mente cheia de ambições.

8É gente corrompida,

que só sabe tratar com maldade e opressão;

tudo o que dizem é sempre com arrogância.

9Quando abrem a boca,

têm sempre de praguejar contra o céu;

a sua língua maldizente é capaz de varrer a Terra.

10Assim o povo de Deus fica frustrado e confuso,

aceitando tudo o que eles dizem.

11E vão-se perguntando a si próprios:

“Será que Deus, lá no alto, sabe o que está a acontecer?”

12Esta gente é contra Deus e vive em plena segurança;

estão sempre a ver as suas riquezas a aumentar.

13Não terá sido em vão que me tenho preocupado,

com a pureza das minhas intenções,

e procurado manter-me sempre isento de maldade?

14Afinal, tudo o que tenho obtido, em cada dia,

é só problemas e aborrecimentos!

15Mas se eu falasse realmente assim

estaria traindo o teu povo, ó Deus!

16Na verdade, isto é muito difícil de entender;

quando procurava uma resposta ficava confuso.

17Até que entrei no santuário de Deus

e compreendi, enfim, o destino dessa gente.

18Tu os colocas em caminhos escorregadios

e os farás cair na destruição.

19De um momento para o outro cairão na ruína

e ficarão consumidos pelo terror.

20A imagem deles varrerás das memórias, Senhor,

como quando alguém acorda dum pesadelo.

21Quando vi isto, o meu coração ficou perturbado.

22Senti-me tão estúpido e ignorante;

eu parecia um animal diante de ti, Senhor.

23Mas eu estou sempre contigo;

tu seguras-me pela mão.

24Guiar-me-ás com a tua sabedoria

e depois me receberás na tua glória.

25A quem tenho eu no céu, além de ti?

És, na Terra, quem eu mais desejo!

26A minha saúde e o meu espírito enfraquecem,

mas Deus é a força do meu coração.

Ele é meu para a eternidade!

27Aqueles que se afastam de ti, Senhor, perecerão;

destruirás os que te são infiéis.

28Quanto a mim, sinto-me feliz em aproximar-me de Deus.

O Senhor Deus é o meu refúgio;

hei de anunciar todos os teus feitos!