Òwe 1 – YCB & OL

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 1:1-33

Èròǹgbà àti kókó-ọ̀rọ̀

1Àwọn òwe ti Solomoni, ọmọ Dafidi, ọba Israẹli.

2Láti le ní ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́,

Láti ní òye àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀.

3Láti gba ẹ̀kọ́ ọgbọ́n, òdodo,

àti ìdájọ́, àti àìṣègbè;

4láti fi òye fún onírẹ̀lẹ̀,

ìmọ̀ àti ìṣọ́ra fún àwọn èwe.

5Jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n tẹ́tí kí ó sì ní ìmọ̀ kún ìmọ̀,

sì jẹ́ kí ẹni òye gba ìtọ́sọ́nà.

6Láti mọ ìtumọ̀ òwe àti ìtán-dòwe,

àwọn ọ̀rọ̀ àti àlọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n.

7Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìbẹ̀rẹ̀ ìmọ̀,

ṣùgbọ́n aláìgbọ́n kẹ́gàn ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́.

Ọ̀rọ̀ ìyànjú láti ṣàfẹ́rí ọgbọ́n

8Tẹ́tí, ìwọ ọmọ mi sí ẹ̀kọ́ baba rẹ,

má ṣe kọ ẹ̀kọ́ màmá rẹ sílẹ̀.

9Wọn yóò jẹ́ òdòdó ẹ̀yẹ olóòórùn dídùn lórí rẹ

àti ọ̀ṣọ́ tí ó dára yí ọrùn rẹ ká.

10Ọmọ mi, bí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ bá ń tàn ọ́,

má ṣe gbà fún wọn.

11Bí wọn bá wí pé, “Wá pẹ̀lú wa;

jẹ́ kí á ba ní ibùba fún ẹ̀jẹ̀ ẹnìkan,

jẹ́ kí á lúgọ ní ìkọ̀kọ̀ de aláìṣẹ̀ ní àìnídìí;

12Jẹ́ ká gbé wọn mì láààyè, bí ibojì òkú,

àti lódidi, bí àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sínú kòtò;

13A ó rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan tó níye lórí

a ó sì fi ìkógun kún inú ilé wa;

14Da ìpín rẹ pọ̀ mọ́ àárín wa,

a ó sì jọ pawó sínú àpò kan náà”

15Ọmọ mi, má ṣe bá wọn lọ,

má ṣe rìn ní ojú ọ̀nà wọn;

16Nítorí ẹsẹ̀ wọn ń sáré sí ẹ̀ṣẹ̀,

wọ́n yára láti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀.

17Wàhálà asán ni kí ènìyàn máa dẹ àwọ̀n sílẹ̀,

ní ojú ẹyẹ!

18Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ń lúgọ fún ẹ̀jẹ̀ ara wọn.

Ara wọn ni wọ́n ń dá lọ́nà

19Báyìí ni ìgbẹ̀yìn gbogbo àwọn tí ń wá èrè àìtọ́;

yóò mú ẹ̀mí gbogbo ẹni tí ó rí i lọ.

Ìkìlọ̀ láti má ṣe kọ ọgbọ́n sílẹ̀

201.20,21: Òw 8.1-3.Ọgbọ́n kígbe sókè ní pópó

ó gbé ohùn rẹ̀ sókè láàrín ọjà;

21Láàrín ọjà ni ó ti kígbe jáde

Ní ibodè ìlú ni ó ti sọ̀rọ̀ ọ rẹ̀:

22“Yóò ha ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin aláìmọ̀kan yóò fi fẹ́ àìmọ̀kan yín tó?

Yóò ha ti pẹ́ tó tí àwọn ẹlẹ́gàn yóò ṣe inú dídùn sí ìpẹ̀gàn tó?

Àwọn aláìgbọ́n kórìíra ìmọ̀?

23Bí ẹ bá ti gbọ́ ìbáwí ì mi ni,

Ǹ bá ti tú ohun tí ó wà nínú ọkàn mi jáde fún yín

kí n sì fi inú mi hàn sí i yín.

24Ṣùgbọ́n níwọ̀n bí ẹ ti kọ ìpè ní ìgbà tí mo pè

kò sì sí ẹni tí ó kọ ibi ara sí mi gbà tí mo na ọwọ́ sí wọn,

25Níwọ́n bí ẹ ti kọ gbogbo ìmọ̀ràn mi,

tí ẹ̀yin kò sì gba ìbáwí mi,

26Èmi pẹ̀lú yóò fi ìdààmú yín rẹ́rìn-ín;

èmi yóò ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín.

27Nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín bí ìjì líle,

Nígbà tí ìdààmú bá dé bá ọ bí ààjà,

nígbà tí wàhálà àti ìbànújẹ́ ọkàn bá bò ọ́ mọ́lẹ̀.

28“Nígbà náà ni wọn yóò ké pè mí ṣùgbọ́n, èmi kò ní dáhùn;

wọn yóò fi ara balẹ̀ wá mi ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí mi.

29Níwọ́n bí wọ́n ti kórìíra ìmọ̀

tí wọ́n sì kọ̀ láti bẹ̀rù Olúwa.

30Níwọ́n bí wọn kò ti gbà ìmọ̀ràn mi

tí wọ́n sì kẹ́gàn ìmọ̀ràn mi,

31Wọn yóò jẹ èrè iṣẹ́ ọwọ́ wọn

wọn yóò sì jèrè èso ètè wọn ní kíkún

32Nítorí ìrìnkurìn àwọn aláìmọ̀kan ni yóò pa wọ́n

ìkáwọ́gbera aláìgbọ́n ni yóò pa á run;

33Ṣùgbọ́n ẹnìkan tí ó bá fetí sí mi, yóò gbé láìléwu

yóò sì wà nínú ìdẹ̀ra, láìsí ìbẹ̀rù ìpalára.”

O Livro

Provérbios 1:1-33

Propósito e tema

1Provérbios de Salomão, filho de David, rei de Israel, 2destinados a dar a conhecer a sabedoria, dar educação e ensinar também a compreender palavras cheias de profundo sentido. 3Para que se tenha um entendimento esclarecido e para que se seja justo, reto, íntegro na vida. 4Destinam-se ainda a formar e a enriquecer a mente de pessoas simples e a dar capacidade de compreensão aos jovens. 5Quanto aos que têm instrução, que aprofundem a sabedoria; 6tornem-se hábeis na exploração do significado dos ditos e enigmas dos sábios.

7O temor do Senhor é o princípio de todo o conhecimento; só os loucos recusam ser ensinados.

Exortações para abraçar a sabedoria

8Ouve o teu pai e a tua mãe e não desprezes o que te ensinarem. 9Porque o que aprenderes com eles será como um diadema na tua cabeça e um colar no teu pescoço.

10Meu filho, se pecadores quiserem aliciar-te, nunca lhes cedas! 11Se te disserem: “Vem connosco!”, volta-lhes as costas. Dir-te-ão: “Vamos lá! A gente, sem ninguém saber, rouba este aqui, mata aquele inocente além; 12apanhamo-los vivos e mandamo-los inteirinhos para a cova! 13Ficará para nós o belo quinhão que cá deixarem e assim encheremos os bolsos! 14Tiramos à sorte e tu terás a tua parte connosco.”

15Não, meu filho! Não vás com eles! Desvia-te de gente semelhante! 16Porque o seu modo de vida é o crime; são especialistas no assassínio. 17Apesar de até uma ave saber desviar-se, quando lhe preparam uma armadilha, 18estas pessoas deixam-se apanhar pelas suas próprias ciladas. 19Este é o destino de todo aquele que vive da rapina, e esta levá-lo-á à violência e à morte.

O perigo de rejeitar a sabedoria

20A sabedoria clama, em voz bem alta, pelas ruas da cidade e nos cruzamentos; 21sobre os muros eleva a sua voz, diante das portas da cidade, na frente de todos: 22“Ó gente insensata! Até quando continuarão a viver contentes com a loucura? Até quando continuarão a desprezar a sabedoria e a contestar a evidência dos factos? 23Venham ouvir e convençam-se com os meus argumentos. Derramarei sobre vocês um espírito de sabedoria e dar-vos-ei a conhecer a minha mensagem.

24Tantas vezes vos chamei e não quiseram vir; insisti convosco, estendendo a mão, mas ninguém me deu atenção. 25Rejeitaram os meus conselhos; não fizeram caso da minha repreensão. 26Por isso, quando se encontrarem em dificuldades, será a minha vez de me rir e de me divertir com os vossos medos. 27Quando esses medos vos sobrevierem, como uma tenebrosa tempestade, quando estiverem submergidos pela angústia e pelo pânico, 28então, ao gritarem pela minha ajuda, não responderei; embora me procurem ansiosamente, não me acharão. 29Porque preferiram desprezar a sabedoria e rejeitaram o temor do Senhor. 30Voltaram-me as costas e desprezaram o meu juízo. 31Essa é a razão por que terão de vir a comer o fruto amargo da vossa própria conduta e terão de fartar-se com as consequências desastrosas das vossas opções. 32Porque é pela sua imprudência que a gente insensata morrerá; a segurança dos doidos matá-los-á. 33Mas todos os que me derem ouvidos viverão em paz e segurança, e sem medo.”