Saamu 36 – YCB & NVI-PT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 36:1-12

Saamu 36

Fún adarí orin. Ti Dafidi ìránṣẹ́ Olúwa

136.1: Ro 3.18.Ìré-òfin-kọjá ènìyàn búburú

jẹ́ kí n mọ̀ nínú ọkàn mi pé;

Ìbẹ̀rù Ọlọ́run kò sí

níwájú wọn.

2Nítorí pé wọ́n pọ́n ara wọn ní ojú ara wọn

títí tí a kò fi le rí ẹ̀ṣẹ̀ wọn láti kórìíra.

3Ọ̀rọ̀ ẹnu wọn ni ẹ̀ṣẹ̀ òhun ẹ̀tàn;

wọ́n ti fi ọgbọ́n àti ṣíṣe rere sílẹ̀;

4Wọ́n gbìmọ̀ ìwà ìkà nígbà tí wọ́n wà lórí ibùsùn wọn:

wọ́n gba ọ̀nà tí kò dára

wọn kò sì kọ ọ̀nà ibi sílẹ̀.

5Ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ, ìwọ Olúwa, ó ga dé ọ̀run,

òtítọ́ ọ̀ rẹ ga dé àwọsánmọ̀.

6Òdodo rẹ dàbí àwọn òkè Ọlọ́run,

àwọn ìdájọ́ rẹ dàbí ibú ńlá;

ìwọ gba ẹranko àti ènìyàn là, Olúwa.

7Báwo ni ìṣeun ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ ti tó! Ọlọ́run!

Kí gbogbo ọmọ ènìyàn le sá sí abẹ́ òjìji ìyẹ́ rẹ.

8Àsè ilé rẹ yóò tẹ́ wọn lọ́rùn gidigidi;

ìwọ yóò sì mú wọn mu nínú odò inú dídùn rẹ.

9Nítorí pé pẹ̀lú rẹ ni orísun ìyè wà:

nínú ìmọ́lẹ̀ rẹ ni àwa yóò rí ìmọ́lẹ̀.

10Mú ìṣeun ìfẹ́ ẹ̀ rẹ sí àwọn tí ó mọ̀ ọ́n

àti ìgbàlà rẹ sí àwọn tí ó ní ìdúró ṣinṣin ọkàn!

11Má ṣe jẹ́ kí ẹsẹ̀ agbéraga kí ó wá sí orí mi,

kí o má sì jẹ́ kí ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú sí mi ní ipò.

12Níbẹ̀ ni àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ gbé ṣubú sí:

a rẹ̀ wọ́n sílẹ̀, wọn kì yóò le è dìde!

Nova Versão Internacional

Salmos 36:1-12

Salmo 36

Para o mestre de música. De Davi, servo do Senhor.

1Há no meu íntimo um oráculo

a respeito da maldade do ímpio:

Aos seus olhos é inútil temer a Deus.

2Ele se acha tão importante,

que não percebe nem rejeita o seu pecado.

3As palavras da sua boca são maldosas e traiçoeiras;

abandonou o bom senso e não quer fazer o bem.

4Até na sua cama planeja maldade;

nada há de bom no caminho a que se entregou,

e ele nunca rejeita o mal.

5O teu amor, Senhor, chega até os céus;

a tua fidelidade até as nuvens.

6A tua justiça é firme como as altas montanhas;

as tuas decisões, insondáveis como o grande mar.

Tu, Senhor, preservas tanto os homens quanto os animais.

7Como é precioso o teu amor, ó Deus!

Os homens encontram refúgio à sombra das tuas asas.

8Eles se banqueteiam na fartura da tua casa;

tu lhes dás de beber do teu rio de delícias.

9Pois em ti está a fonte da vida;

graças à tua luz, vemos a luz.

10Estende o teu amor aos que te conhecem;

a tua justiça, aos que são retos de coração.

11Não permitas que o arrogante me pisoteie

nem que a mão do ímpio me faça recuar.

12Lá estão os malfeitores caídos,

lançados ao chão, incapazes de levantar-se!