Saamu 37 – YCB & NVI-PT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 37:1-40

Saamu 37

Ti Dafidi.

1Má ṣe ìkanra nítorí àwọn olùṣe búburú,

kí ìwọ má sì ṣe ṣe ìlara nítorí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀;

2nítorí pé wọn yóò gbẹ bí i koríko,

wọn yóò sì rẹ̀ dànù bí ewéko tútù.

3Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, kí o sì máa ṣe rere;

torí pé ìwọ yóò gbé ilẹ̀ náà, kí o sì gbádùn ààbò rẹ̀.

4Ṣe inú dídùn sí Olúwa;

òun yóò sì fún ọ ní ìfẹ́ inú rẹ̀.

5Fi ọ̀nà rẹ lé Olúwa lọ́wọ́;

gbẹ́kẹ̀lé pẹ̀lú, òun yóò sì ṣe é.

6Yóò sì mú kí òdodo rẹ̀ jáde bí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀,

àti ìdájọ́ rẹ̀ bí ọ̀sán gangan.

7Ìwọ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa,

kí o sì fi sùúrù dúró dè é;

má ṣe ṣe ìkanra nítorí àwọn tí ń rí rere ní ọ̀nà wọn,

nítorí ọkùnrin náà ti mú èrò búburú ṣẹ.

8Fàsẹ́yìn nínú inúbíbí, kí o sì kọ ìkáàánú sílẹ̀,

má ṣe ṣe ìkanra, kí ó má ba à ṣé búburú pẹ̀lú.

9Nítorí tí á ó gé àwọn olùṣe búburú kúrò,

ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá dúró de Olúwa àwọn ni yóò jogún ilẹ̀ náà.

10Síbẹ̀ nígbà díẹ̀ sí i, àwọn ènìyàn búburú kì yóò sí mọ̀;

nítòótọ́ ìwọ yóò fi ara balẹ̀ wo ipò rẹ̀, wọn kì yóò sí níbẹ̀.

11Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́kàn tútù ni yóò jogún ilẹ̀ náà,

wọn yóò sì máa ṣe inú dídùn nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà.

12Ènìyàn búburú di rìkíṣí sí olóòtítọ́,

wọ́n sì pa eyín wọn keke sí wọn;

13ṣùgbọ́n Olúwa rẹ́rìn-ín sí àwọn ènìyàn búburú,

nítorí tí ó rí wí pé ọjọ́ wọn ń bọ̀.

14Ènìyàn búburú fa idà yọ,

wọ́n sì tẹ àwọn ọrun wọn,

láti sọ tálákà àti aláìní kalẹ̀,

láti pa àwọn tí ó dúró ṣinṣin.

15Idà wọn yóò wọ àyà wọn lọ,

àti wí pé ọrun wọn yóò sì ṣẹ́.

16Ohun díẹ̀ tí olódodo ní,

sàn ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ènìyàn búburú;

17nítorí pé a óò ṣẹ́ ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú,

ṣùgbọ́n Olúwa gbé olódodo sókè.

18Olúwa mọ àwọn ọjọ́ àwọn tó dúró ṣinṣin,

àti wí pé ilẹ̀ ìní wọn yóò wà títí ayérayé;

19Ojú kì yóò tì wọ́n ní àkókò ibi,

àti ní ọjọ́ ìyàn, a ó tẹ́ wọn lọ́rùn.

20Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn búburú yóò ṣègbé.

Àwọn ọ̀tá Olúwa yóò dàbí ẹwà oko tútù;

wọn fò lọ; bi èéfín ni wọn yóò fò lọ kúrò.

21Àwọn ènìyàn búburú yá, wọn kò sì san án padà,

ṣùgbọ́n àwọn olódodo a máa ṣàánú, a sì máa fi fún ni;

22Nítorí àwọn tí Olúwa bá bùkún ni yóò jogún ilẹ̀ náà,

àwọn tí ó fi bú ni a ó gé kúrò.

23Ìlànà ìgbésẹ̀ ènìyàn rere wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá,

o sì ṣe inú dídùn sí ọ̀nà rẹ̀;

24Bí ó tilẹ̀ ṣubú a kì yóò ta á nù pátápátá,

nítorí tí Olúwa di ọwọ́ rẹ̀ mú.

25Èmi ti wà ni èwe, báyìí èmi sì dàgbà;

síbẹ̀ èmi kò ì tí ì ri kí a kọ olódodo sílẹ̀,

tàbí kí irú-ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe oúnjẹ.

26Aláàánú ni òun nígbà gbogbo a máa yá ni;

a sì máa bùsi i fún ni.

27Lọ kúrò nínú ibi, kí o sì máa ṣe rere;

nígbà náà ni ìwọ yóò gbé ní ilẹ̀ náà títí láéláé.

28Nítorí pé Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òtítọ́,

kò sì kọ àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀.

Àwọn olódodo ni a ó pamọ́ títí ayérayé,

ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ènìyàn búburú ni a ó ké kúrò.

29Olódodo ni yóò jogún ilẹ̀ náà,

yóò sì máa gbé ibẹ̀ títí ayérayé.

30Ẹnu olódodo sọ̀rọ̀ ọgbọ́n,

ahọ́n rẹ̀ a sì máa sọ̀rọ̀ ìdájọ́.

31Òfin Ọlọ́run rẹ̀ ń bẹ ní àyà wọn;

àwọn ìgbésẹ̀ rẹ̀ kì yóò yẹ̀.

32Ènìyàn búburú ń ṣọ́ olódodo,

Ó sì ń wá ọ̀nà láti pa á.

33Olúwa kì yóò fi lé e lọ́wọ́ kì yóò sì dá a lẹ́bi,

nígbà tí a bá ń ṣe ìdájọ́ rẹ̀.

34Dúró de Olúwa,

kí o sì máa pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́.

Yóò sì gbé ọ lékè láti jogún ilẹ̀ náà;

nígbà tí a bá gé àwọn ènìyàn búburú kúrò ìwọ yóò ri.

35Èmi ti rí ènìyàn búburú tí ń hu ìwà ìkà,

ó sì fi ara rẹ̀ gbilẹ̀ bí igi tútù ńlá,

36ṣùgbọ́n ní ìṣẹ́jú kan sí i ó kọjá lọ, sì kíyèsi, kò sì sí mọ́;

bi ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé mo wá a kiri, ṣùgbọ́n a kò le è ri.

37Máa kíyèsi ẹni pípé, kí o sì wo ẹni tó dúró ṣinṣin;

nítorí àlàáfíà ni òpin ọkùnrin náà.

38Ṣùgbọ́n àwọn olùrékọjá ni a ó parun papọ̀;

ìran àwọn ènìyàn búburú ni a ó gé kúrò.

39Ìgbàlà àwọn onídùúró ṣinṣin wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa;

òun ni ààbò wọn ní ìgbà ìpọ́njú

40Olúwa yóò ràn wọ́n lọ́wọ́ yóò sì gbà wọ́n;

yóò gbà wọ́n lọ́wọ́ ènìyàn búburú, yóò sì gbà wọ́n là,

nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé e.

Nova Versão Internacional

Salmos 37:1-40

Salmo 3737 O salmo 37 é um poema organizado em ordem alfabética, no hebraico.

Davídico.

1Não se aborreça por causa dos homens maus

e não tenha inveja dos perversos;

2pois como o capim logo secarão,

como a relva verde logo murcharão.

3Confie no Senhor e faça o bem;

assim você habitará na terra e desfrutará segurança.

4Deleite-se no Senhor,

e ele atenderá aos desejos do seu coração.

5Entregue o seu caminho ao Senhor;

confie nele, e ele agirá:

6ele deixará claro como a alvorada que você é justo,

e como o sol do meio-dia que você é inocente.

7Descanse no Senhor

e aguarde por ele com paciência;

não se aborreça com o sucesso dos outros

nem com aqueles que maquinam o mal.

8Evite a ira e rejeite a fúria;

não se irrite: isso só leva ao mal.

9Pois os maus serão eliminados,

mas os que esperam no Senhor

receberão a terra por herança.

10Um pouco de tempo, e os ímpios não mais existirão;

por mais que você os procure, não serão encontrados.

11Mas os humildes receberão a terra por herança

e desfrutarão pleno bem-estar.

12Os ímpios tramam contra os justos

e rosnam contra eles;

13o Senhor, porém, ri dos ímpios,

pois sabe que o dia deles está chegando.

14Os ímpios desembainham a espada e preparam o arco

para abater o necessitado e o pobre,

para matar os que andam na retidão.

15Mas as suas espadas irão atravessar-lhes o coração,

e os seus arcos serão quebrados.

16Melhor é o pouco do justo

do que a riqueza de muitos ímpios;

17pois o braço forte dos ímpios será quebrado,

mas o Senhor sustém os justos.

18O Senhor cuida da vida dos íntegros,

e a herança deles permanecerá para sempre.

19Em tempos de adversidade não ficarão decepcionados;

em dias de fome desfrutarão fartura.

20Mas os ímpios perecerão;

os inimigos do Senhor murcharão como a beleza dos campos;

desvanecerão como fumaça.

21Os ímpios tomam emprestado e não devolvem,

mas os justos dão com generosidade;

22aqueles que o Senhor abençoa receberão a terra por herança,

mas os que ele amaldiçoa serão eliminados.

23O Senhor firma os passos de um homem,

quando a conduta deste o agrada;

24ainda que tropece, não cairá,

pois o Senhor o toma pela mão.

25Já fui jovem e agora sou velho,

mas nunca vi o justo desamparado

nem seus filhos mendigando o pão.

26Ele é sempre generoso e empresta com boa vontade;

seus filhos serão abençoados.

27Desvie-se do mal e faça o bem;

e você terá sempre onde morar.

28Pois o Senhor ama quem pratica a justiça,

e não abandonará os seus fiéis.

Para sempre serão protegidos,

mas a descendência dos ímpios será eliminada;

29os justos herdarão a terra

e nela habitarão para sempre.

30A boca do justo profere sabedoria,

e a sua língua fala conforme a justiça.

31Ele traz no coração a lei do seu Deus;

nunca pisará em falso.

32O ímpio fica à espreita do justo,

querendo matá-lo;

33mas o Senhor não o deixará cair em suas mãos

nem permitirá que o condenem quando julgado.

34Espere no Senhor

e siga a sua vontade.

Ele o exaltará, dando-lhe a terra por herança;

quando os ímpios forem eliminados, você o verá.

35Vi um homem ímpio e cruel

florescendo como frondosa árvore nativa,

36mas logo desapareceu e não mais existia;

embora eu o procurasse, não pôde ser encontrado.

37Considere o íntegro, observe o justo;

há futuro37.37 Ou haverá posteridade; também no versículo 38. para o homem de paz.

38Mas todos os rebeldes serão destruídos;

futuro para os ímpios nunca haverá.

39Do Senhor vem a salvação dos justos;

ele é a sua fortaleza na hora da adversidade.

40O Senhor os ajuda e os livra;

ele os livra dos ímpios e os salva,

porque nele se refugiam.