Saamu 35 – YCB & NVI-PT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 35:1-28

Saamu 35

Ti Dafidi.

1Olúwa, gbógun ti àwọn tí ń gbóguntì mí;

kí o sì kọ ojú ìjà sí àwọn tí ó ń bá mi í jà!

2Di asà àti àpáta mú,

kí o sì dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi!

3Fa idà àti ọ̀kọ̀ yọ

kí o sì dojúkọ àwọn tí ń lé mi.

Sọ fún ọkàn mi pé,

“Èmi ni ìgbàlà rẹ.”

4Kí wọn kí ó dààmú,

kí a sì ti àwọn tí ń lépa ọkàn mi lójú;

kí a sì mú wọn padà,

kí a sì dààmú àwọn tí ń gbèrò ìpalára mi.

5Jẹ́ kí wọn dàbí ìyàngbò níwájú afẹ́fẹ́,

kí angẹli Olúwa kí ó máa lé wọn kiri.

6Jẹ́ kí ọ̀nà wọn kí ó ṣókùnkùn, kí ó sì máa yọ́,

kí angẹli Olúwa kí ó máa lépa wọn!

7Nítorí pé, ní àìnídìí ni wọ́n dẹ àwọ̀n wọn sílẹ̀ fún mi,

ní àìnídìí ni wọ́n wa kòtò sílẹ̀ fún ọkàn mi.

8Kí ìparun kí ó wá sí orí rẹ̀ ní òjijì.

Àwọ̀n rẹ̀ tí ó dẹ, kí ó mú òun tìkára rẹ̀;

kí wọn ṣubú sínú kòtò sí ìparun ara rẹ̀.

9Nígbà náà ni ọkàn mi yóò yọ̀ nínú Olúwa,

àní, yóò sì máa yọ̀ nínú ìgbàlà rẹ̀.

10Gbogbo egungun mi yóò wí pé,

“Ta ni ó dàbí ì ìwọ Olúwa?

O gba tálákà lọ́wọ́ àwọn tí ó lágbára jù ú lọ,

tálákà àti aláìní lọ́wọ́ ẹni tí ń fi ṣe ìkógun?”

11Àwọn ẹlẹ́rìí èké dìde;

wọ́n ń bi mi ní ohun tí èmi kò mọ̀.

12Wọ́n fi búburú san ìre fún mi;

láti sọ ọkàn mi di òfo.

13Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni, nígbà tí wọn ń ṣe àìsàn, mo wọ aṣọ ọ̀fọ̀;

mo fi àwẹ̀ pọ́n ara mi lójú.

Mo gba àdúrà pẹ̀lú ìtẹríba ní oókan àyà mi;

14èmí ń lọ kiri bí ẹni ń ṣọ̀fọ̀

bí i ẹni wí pé fún ọ̀rẹ́ tàbí ẹ̀gbọ́n mi ni.

Èmí tẹríba nínú ìbànújẹ́

bí ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ ìyà rẹ̀.

15Ṣùgbọ́n nínú ìkọ̀sẹ̀ mi wọ́n sì yọ̀, wọ́n sì kó ara wọn jọ;

wọ́n kó ara wọn jọ sí mi; àní àwọn tí èmi kò mọ̀.

Wọ́n fà mí ya wọ́n kò sì dákẹ́.

16Bí àwọn àgàbàgebè tí ń ṣe ẹlẹ́yà ní àpèjẹ

wọ́n pa eyín wọn keke sí mi.

17Yóò ti pẹ́ tó Olúwa, tí ìwọ yóò máa wò wọ́n lọ?

Yọ mí kúrò nínú ìparun wọn,

àní ẹ̀mí ì mi kúrò lọ́wọ́ kìnnìún.

18Nígbà náà ni èmi yóò ṣọpẹ́ fún Ọ nínú àjọ ńlá;

èmi yóò máa yìn Ọ́ ní àwùjọ ọ̀pọ̀ ènìyàn.

1935.19: Sm 69.4; Jh 15.25.Má ṣe jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi

kí ó yọ̀ lórí ì mi;

bẹ́ẹ̀ ni kí o má ṣe àwọn tí ó kórìíra mi

ní àìnídìí máa ṣẹ́jú sí mi.

20Nítorí pé wọn kò sọ ọ̀rọ̀ àlàáfíà,

ṣùgbọ́n wọ́n lóyún ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn

sí àwọn ènìyàn dídákẹ́ ilẹ̀ náà.

21Wọ́n ya ẹnu wọn gbòòrò sí mi; wọ́n wí pé, “Háà! Háà!

Ojú wa sì ti rí i.”

22Ìwọ́ ti rí i Olúwa; má ṣe dákẹ́!

Olúwa má ṣe jìnnà sí mi!

23Dìde! ru ara rẹ̀ sókè fún ààbò mi,

àti sí ọ̀ràn mi, Ọlọ́run mi àti Olúwa mi!

24Ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa Ọlọ́run mi, gẹ́gẹ́ bí òdodo rẹ,

kí o má sì ṣe jẹ́ kí wọn kí ó yọ̀ lórí mi!

25Má ṣe jẹ́ kí wọn wí nínú ara wọn pé, “Háà! A ti rí ohun tí ọkàn wa ń fẹ́!”

Má ṣe jẹ́ kí wọn kí ó wí pé, “A ti gbé e mì.”

26Kí ojú kí ó tì wọ́n,

kí wọn kí ó sì dààmú pọ̀,

àní àwọn tí ń yọ̀ sí ìyọnu mi

kí a fi ìtìjú àti àbùkù wọ̀ wọ́n ní aṣọ tí ń gbéraga sí mi.

27Jẹ́ kí àwọn tí ó fẹ́ ìdáláre mi

fò fún ayọ̀ àti ìdùnnú;

kí wọn máa sọ ọ́ títí lọ, “Pé gbígbéga ni Olúwa,

sí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ̀.”

28Nígbà náà ni ahọ́n mi yóò máa sọ̀rọ̀ òdodo rẹ,

àti ìyìn rẹ ní gbogbo ọjọ́.

Nova Versão Internacional

Salmos 35:1-28

Salmo 35

Davídico.

1Defende-me, Senhor, dos que me acusam;

luta contra os que lutam comigo.

2Toma os escudos, o grande e o pequeno;

levanta-te e vem socorrer-me.

3Empunha a lança e o machado de guerra35.3 Ou e bloqueia o caminho

contra os meus perseguidores.

Dize à minha alma: “Eu sou a sua salvação”.

4Sejam humilhados e desprezados

os que procuram matar-me;

retrocedam envergonhados

aqueles que tramam a minha ruína.

5Que eles sejam como a palha ao vento,

quando o anjo do Senhor os expulsar;

6seja a vereda deles sombria e escorregadia,

quando o anjo do Senhor os perseguir.

7Já que, sem motivo, prepararam contra mim uma armadilha oculta

e, sem motivo, abriram uma cova para mim,

8que a ruína lhes sobrevenha de surpresa:

sejam presos pela armadilha que prepararam,

caiam na cova que abriram,

para a sua própria ruína.

9Então a minha alma exultará no Senhor

e se regozijará na sua salvação.

10Todo o meu ser exclamará:

“Quem se compara a ti, Senhor?

Tu livras os necessitados daqueles que são

mais poderosos do que eles,

livras os necessitados e os pobres

daqueles que os exploram.”

11Testemunhas maldosas enfrentam-me

e questionam-me sobre coisas de que nada sei.

12Elas me retribuem o bem com o mal

e procuram tirar-me a vida35.12 Ou e estou abandonado.

13Contudo, quando estavam doentes,

usei vestes de lamento,

humilhei-me com jejum

e recolhi-me em oração35.13 Ou orei por eles sem cessar; ou ainda Ah! Se eu pudesse cancelar minhas orações.

14Saí vagueando e pranteando,

como por um amigo ou por um irmão.

Eu me prostrei enlutado,

como quem lamenta por sua mãe.

15Mas, quando tropecei,

eles se reuniram alegres;

sem que eu o soubesse, ajuntaram-se para me atacar.

Eles me agrediram sem cessar.

16Como ímpios caçoando do meu refúgio,

rosnaram contra mim.

17Senhor, até quando ficarás olhando?

Livra-me dos ataques deles,

livra a minha vida preciosa desses leões.

18Eu te darei graças na grande assembleia;

no meio da grande multidão te louvarei.

19Não deixes que os meus inimigos traiçoeiros

se divirtam à minha custa;

não permitas que aqueles que sem razão me odeiam

troquem olhares de desprezo.

20Não falam pacificamente,

mas planejam acusações falsas

contra os que vivem tranquilamente na terra.

21Com a boca escancarada,

riem de mim e me acusam: “Nós vimos! Sabemos de tudo!”

22Tu viste isso, Senhor! Não fiques calado.

Não te afastes de mim, Senhor,

23Acorda! Desperta! Faze-me justiça!

Defende a minha causa, meu Deus e Senhor.

24Senhor, meu Deus, tu és justo;

faze-me justiça para que eles não se alegrem à minha custa.

25Não deixes que pensem: “Ah! Era isso que queríamos!”

nem que digam: “Acabamos com ele!”

26Sejam humilhados e frustrados

todos os que se divertem à custa do meu sofrimento;

cubram-se de vergonha e desonra

todos os que se acham superiores a mim.

27Cantem de alegria e regozijo

todos os que desejam ver provada a minha inocência

e sempre repitam: “O Senhor seja engrandecido!

Ele tem prazer no bem-estar do seu servo”.

28Minha língua proclamará a tua justiça

e o teu louvor o dia inteiro.