Romu 2 – YCB & LB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Romu 2:1-29

Ìdájọ́ òdodo Ọlọ́run

12.1: Ro 14.22.Nítorí náà, aláìríwí ni ẹnikẹ́ni tí ó wù kí ó jẹ́ tí ń dá ni lẹ́jọ́: nítorí nínú ohun tí ìwọ ń ṣe ìdájọ́ ẹlòmíràn, ìwọ ń dá ara rẹ lẹ́bi; nítorí ìwọ tí ń dájọ́ ń ṣe ohun kan náà nínú èyí tí ìwọ ń dá ni lẹ́jọ́. 2Ṣùgbọ́n àwa mọ̀ pé ìdájọ́ Ọlọ́run jẹ́ òtítọ́ si gbogbo àwọn tí ó ń ṣe irú ohun báwọ̀nyí. 3Nítorí bí ìwọ tí ń ṣe ènìyàn lásán bá ń ṣe ìdájọ́ àwọn tí ń ṣe irú ohun báwọ̀nyí, tí ìwọ tìkára rẹ ń ṣe bẹ́ẹ̀, ìwọ ro èyí pé ìwọ o yọ nínú ìdájọ́ Ọlọ́run bí? 42.4: Ef 1.7; 2.7; Fp 4.19; Kl 1.27.Tàbí ìwọ ń gàn ọrọ̀ oore àti ìpamọ́ra àti sùúrù rẹ̀? Ìwọ kò ha mọ̀ pé oore Ọlọ́run ni ó ń fà ọ́ lọ sì ìrònúpìwàdà?

5Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí líle àti àìronúpìwàdà ọkàn rẹ̀, ìwọ ń to ìbínú jọ fún ara rẹ de ọjọ́ ìbínú àti ìfihàn ìdájọ́ òdodo Ọlọ́run. 62.6: Mt 16.27; 1Kọ 3.8; 2Kọ 5.10; If 22.12.Ọlọ́run yóò san án fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀: 7Àwọn ẹni tí ń fi sùúrù nínú rere ṣíṣe, wá ògo àti ọlá àti àìdíbàjẹ́ ni yóò fi ìyè àìnípẹ̀kun fún. 8Ṣùgbọ́n fún àwọn onímọ̀-tara-ẹni-nìkan, tí wọn kò sì gba òtítọ́ gbọ́, ṣùgbọ́n tí wọn ń tẹ̀lé ọ̀nà búburú, wọn yóò ní ìrírí ìrunú àti ìbínú rẹ̀. 9Ìpọ́njú àti ìrora, yóò wà lórí olúkúlùkù ọkàn ènìyàn tí ń hùwà ibi: ti Júù ṣáájú, àti àwọn Helleni pẹ̀lú; 10ṣùgbọ́n ògo, àti ọlá, àti àlàáfíà, fún olúkúlùkù ẹni tí ń hùwà rere, fún Júù, ṣáájú àti fún àwọn Helleni pẹ̀lú: 11Nítorí Ọlọ́run kì í ṣe ojúsàájú ènìyàn.

122.12: Ro 3.19; 1Kọ 9.21.Gbogbo àwọn tí ó ṣẹ̀ ní àìlófin wọn ó sì ṣègbé láìlófin: àti iye àwọn tí ó ṣẹ̀ lábẹ́ òfin, àwọn ni a ó fi òfin dá lẹ́jọ́; 132.13: Jk 1.22-23,25.Nítorí kì í ṣe àwọn olùgbọ́ òfin ni ẹni ìdáláre lọ́dọ̀ Ọlọ́run, ṣùgbọ́n àwọn olùṣe òfin ni a ó dá láre. 14Nítorí nígbà tí àwọn aláìkọlà, tí kò ní òfin, bá ṣe ohun tí ó wà nínú òfin nípa ìwà ẹ̀dá, àwọn wọ̀nyí, jẹ́ òfin fún ara wọn bí wọn kò tilẹ̀ ní òfin. 15Àwọn ẹni tí ó fihàn pé, a kọ̀wé iṣẹ́ òfin sí wọn lọ́kàn, tí ẹ̀rí ọkàn wọn pẹ̀lú sì tún ń jẹ́ wọn lẹ́rìí, àti pé, èrò ọkàn wọn tí ó jẹ́ ọ̀nà ìfinisùn, sì ń gbè wọ́n lẹ́yìn ní ìsinsin yìí. 162.16: Su 12.14; Ro 16.25; 1Kọ 4.5.Èyí yóò farahàn ní ọjọ́ náà nígbà tí Ọlọ́run yóò tipasẹ̀ Jesu Kristi ṣe ìdájọ́ àwọn àṣírí ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ìhìnrere mi.

Àwọn Júù àti òfin

17Ṣùgbọ́n bí a bá ń pe ìwọ ní Júù, tí o sì sinmi lé òfin, tí o sì ń ṣògo nínú ìbálòpọ̀ rẹ̀ sí Ọlọ́run, 182.18: Fp 1.10.tí o sì mọ ìfẹ́ rẹ̀, tí o sì fọwọ́sí ohun tí ó dára jùlọ, nítorí tí a ti kọ́ ọ ní òfin; 19tí o sì dá ara rẹ lójú pé ìwọ ni amọ̀nà àwọn afọ́jú, ìmọ́lẹ̀ fún àwọn tí ó wà ni òkùnkùn, 202.20: Ro 6.17; 2Tm 1.13.Olùkọ́ àwọn aláìmòye, olùkọ́ àwọn ọmọdé, ẹni tí ó ní ètò ìmọ̀ àti òtítọ́ òfin lọ́wọ́, 212.21: Mt 23.3-4.Ǹjẹ́ ìwọ tí o ń kọ́ ẹlòmíràn, ìwọ kò kọ́ ara rẹ? Ìwọ tí ó ń wàásù kí ènìyàn má jalè, ìwọ ha ń jalè bí? 22Ìwọ tí o wí pé, kí ènìyàn má ṣe panṣágà, ìwọ ń ṣe panṣágà bí? Ìwọ tí o kórìíra òrìṣà, ìwọ ń ja tẹmpili ní olè bí? 23Ìwọ ti ń ṣògo nínú òfin, ìwọ ha ń bu Ọlọ́run ni ọlá kù nípa rírú òfin? 242.24: Isa 52.5.Nítorí gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́, “Orúkọ Ọlọ́run sá à di ìsọ̀rọ̀-òdì sí láàrín àwọn aláìkọlà nítorí yín.”

252.25: Jr 9.25.Nítorí ìkọlà ní èrè nítòótọ́, bí ìwọ bá pa òfin mọ́; ṣùgbọ́n bí ìwọ bá jẹ́ arúfin, ìkọlà rẹ di àìkọlà. 262.26: 1Kọ 7.19; Ap 10.35.Nítorí náà bí àwọn aláìkọlà bá pa ìlànà òfin mọ́, a kì yóò ha kà wọ́n sí àwọn tí a kọ nílà bí? 272.27: Mt 12.41.Aláìkọlà nípa àdánidá, bí ó bá pa òfin mọ́, yóò dá ẹ̀bi fún ìwọ tí ó jẹ́ arúfin nípa ti àkọsílẹ̀ òfin àti ìkọlà.

282.28: Mt 3.9; Jh 8.39; Ro 9.6-7; Ga 6.15.Kì í ṣe èyí tí ó farahàn ní òde ni Júù, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe èyí tí ó farahàn ní ara ni ìkọlà: 292.29: 2Kọ 3.6; Fp 3.3; Kl 2.11; 1Pt 3.4.Ṣùgbọ́n Júù ti inú ni Júù, àti ìkọlà sì ni ti ọkàn nínú ẹ̀mí tí kì í ṣe ti àkọsílẹ̀, ìyìn ẹni tí kò sí lọ́dọ̀ ènìyàn, bí kò ṣe lọ́dọ̀ Ọlọ́run.

En Levende Bok

Romerne 2:1-29

Guds dom over synden

1Selv om Gud en dag vil straffe menneskene, har du ingen rett til å dømme andre, hvem du enn er. Om du dømmer en annen for det han gjør, da dømmer du jo samtidig deg selv, etter som du handler på samme måten som han. Det finnes ingen unnskyldning for deg som dømmer! 2Vi vet at Gud har rett når han dømmer dem som lever på denne måten. 3Men du som dømmer dine medmennesker, du tror vel ikke at Gud bare skal dømme de andre, og ha overbærenhet med deg når du handler på samme måten? 4Du skal ikke undervurdere Gud, når han på grunn av sin godhet og sin tålmodighet ikke straffer deg! Innser du ikke at han ved sin godhet vil få deg til å vende om til ham?

5Dersom du gjenstridig nekter å vende om til Gud, da gjør du din straff verre på dommens dag, for på den dagen skal det vise seg at Gud dømmer alle rettferdig. 6Da skal hver og en få lønn etter sine gjerninger. 7Gud skal gi evig liv til dem som uten å bli trette fortsetter å gjøre det gode og søker herlighet, ære og udødelighet sammen med Gud. 8Men han skal i sitt sinne straffe dem som bare tenker på seg selv, og som i stedet for å gjøre det som er rett, lever i ondskap. 9Nød og angst skal ramme hvert mennesker som gjør det onde. Dette gjelder jødene, som først fikk høre Guds budskap, men også alle andre folk. 10På samme måten skal herlighet, ære og fred bli gitt til hver og en som gjør det gode. Det skal bli gitt til jødene, som først fikk høre Guds budskap, men også til alle andre folk. 11Gud behandler alle likt.

12Gud skal straffe alle folk for syndene deres, også om de ikke kjenner til Moseloven2:12 Moseloven, eller den jødiske loven, finnes skrevet ned i Første til Femte Mosebok. som Gud ga til jødene. Men han skal også straffe jødene for syndene deres, etter som de har fått loven. 13Det rekker nemlig ikke å bare kjenne teoretisk til loven for å bli skyldfri innfor Gud. Vi må også følge den. 14Bare jødene har fått Guds lov skriftlig. Men når andre folk, uten å kjenne til loven, likevel lyder det som står i den, da forstår vi at de vet forskjell på godt og ondt. 15De viser ved handlingene sine at loven er skrevet i hjertene deres. Deres samvittighet reagerer alt etter om de handler rett eller galt. 16At det er slik, vil vise seg den dagen da Jesus Kristus på Guds befaling skal dømme oss alle etter våre innerste tanker og motiv. Dette er det budskapet jeg har fått fra Gud.

Jødene og Moseloven

17Dere som er jøder, stoler på den loven dere har fått fra Gud. Dere er stolte over det spesielle forholdet dere har til ham. 18Dere sier at dere kjenner Guds vilje og vet hvordan alle bør handle, etter som dere har fått lære dere det som står i Moseloven. 19Dere sier at dere kan peke ut Guds vei for de blinde og være et lys for dem som lever i åndelig mørke. 20Dere vil veilede uforstandige og undervise de umodne. Deres tro på loven har gitt dere den fullkomne kunnskapen om det som er rett og galt. 21Ja, dere underviser andre, men ikke dere selv! Dere sier til andre at de ikke skal stjele, men dere er selv tyver. 22Dere sier at det er galt å være utro i ekteskapet, men dere er selv utro. Dere sier at de ikke skal tilbe avguder, men dere plyndrer avgudstemplene for å tjene penger.

23Dere er stolte over å ha Moseloven, men bringer skam over Gud ved å bryte den. 24Det står i Skriften2:24 ”Skriften” for jødene er Bibelens første del, den som vi kaller Det gamle testamente.: ”Andre folk håner Gud på grunn av dere.”2:24 Se Jesaja 52:5.

25Dere jøder som tror dere holder paktene med Gud ved å omskjære2:25 Omskjærelse, det vil si å skjære bort forhuden på mannens penis og var en måte å inngå pakter på som ble praktisert av mange folk. Men jødene inngikk pakter med Gud selv. Med denne handling la de en frivillig forbannelse over seg selv, med konsekvensen: ”Om jeg bryter pakten, har Gud rett å skjære bort meg og mine avkom på samme måten.” Se Første Mosebok 17:9-14. sønnene deres, dere har bare nytte av denne seremonien dersom dere samtidig lyder hele Moseloven. Dersom dere ikke gjør det, da er dere ikke noe bedre enn andre folk, som ikke omskjærer sønnene sine. 26Om noen fra et annet folk lyder loven, skulle ikke da den personen få det privilegiet å tilhøre Guds eget folk? 27Jo, og på dommens dag skal de som ikke er omskåret rent fysisk, men likevel følger loven, anklage dere jøder, dere som omskjærer sønnene deres og har fått loven, men ikke følger den.

28Alle som kaller seg jøder, tilhører altså ikke Guds eget folk. Det har ikke noe med den fysiske omskjærelsen å gjøre. 29Nei, den som vil tilhøre Guds eget folk, må ha et rett forhold til Gud. Det virkelige tegnet på dem som tilhører Guds folk, altså den virkelige omskjærelsen, er ikke det bokstavelige, fysiske inngrepet som Moseloven beskriver, men det handler om at Guds Ånd får forvandle hjertet. Og den som har gjennomgått en slik forvandling, blir æret av Gud, ikke av mennesker.