Romu 3 – YCB & LB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Romu 3:1-31

Ìṣòtítọ́ Ọlọ́run

1Ǹjẹ́ àǹfààní wo ní Júù ní? Tàbí kín ni èrè ilà kíkọ? 23.2: Sm 147.19; Ro 9.4.Púpọ̀ lọ́nà gbogbo; pàtàkì jùlọ ni pé àwọn ni a fi ọ̀rọ̀ Ọlọ́run lé lọ́wọ́.

3Ǹjẹ́ kí ha ni bí àwọn kan jẹ́ aláìgbàgbọ́? Àìgbàgbọ́ wọn yóò ha sọ òtítọ́ Ọlọ́run di asán bí? 43.4: Sm 51.4.Kí a má rí! Kí Ọlọ́run jẹ́ olóòtítọ́, àti olúkúlùkù ènìyàn jẹ́ èké; gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé:

“Kí a lè dá ọ láre nínú ọ̀rọ̀ rẹ,

ṣùgbọ́n kí ìwọ lè borí nígbà tí ìwọ bá wá sí ìdájọ́.”

53.5: Ro 5.9; 6.19; 1Kọ 9.8; Ga 3.15.Ṣùgbọ́n bí àìṣòdodo wa bá fi òdodo Ọlọ́run hàn, kín ni àwa ó wí? Ọlọ́run ha jẹ́ àìṣòdodo bí? Nígbà tí ó bá ń fi ìbínú rẹ̀ hàn (Mo fi ṣe àkàwé bí ènìyàn). 6Kí a má rí i. Bí bẹ́ẹ̀ bá ni, Ọlọ́run yóò ha ṣe lè dájọ́ aráyé? 7Nítorí bí òtítọ́ Ọlọ́run bá di púpọ̀ sí ìyìn rẹ̀ nítorí èké mi, èéṣe tí a fi ń dá mi lẹ́jọ́ bí ẹlẹ́ṣẹ̀? 83.8: Ro 6.1,15.Èéṣe tí a kò fi ṣe búburú kí rere lè jáde wá? Bí àwọn kan tí ń fi ẹnu àtẹ́ sọ wí pé a ń sọ bẹ́ẹ̀; ti àwọn kan sì ń tẹnumọ́ ọn pé a sọ; àwọn ẹni tí ìdálẹ́bi wọn tọ́.

Kò sí olóòtítọ́ kan

93.9: Ro 1.18-32; 2.1-29; 11.32; 3.23.Ǹjẹ́ kí ha ni? Àwa ha sàn ju wọn lọ bí? Kò rí bẹ́ẹ̀ rárá: nítorí a fihàn ṣáájú pé àti àwọn Júù àti àwọn Giriki, gbogbo wọn ni ó wà lábẹ́ ẹ̀ṣẹ̀; 103.10-12: Sm 14.1-3; 53.1-3.Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé:

“Kò sí ẹni tí í ṣe olódodo, kò sí ẹnìkan

11Kò sí ẹni tí òye yé,

kò sí ẹni tí ó ń wá Ọlọ́run.

12Gbogbo wọn ni ó ti yapa,

wọ́n jùmọ̀ di aláìlérè;

kò sí ẹni tí ń ṣe rere,

kò tilẹ̀ sí ẹnìkan.”

133.13: Sm 5.9; 140.3.“Ibojì tí ó ṣí sílẹ̀ ní ọ̀fun wọn:

ahọ́n wọn n sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.”

“Oró paramọ́lẹ̀ ń bẹ lábẹ́ ètè wọn.”

143.14: Sm 10.7.“Ẹnu ẹni tí ó kún fún èpè àti fún oró kíkorò.”

153.15-17: Isa 59.7-8.“Ẹsẹ̀ wọn yára láti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀:

16ìparun àti ìpọ́njú wà lọ́nà wọn.

17Ọ̀nà àlàáfíà ni wọn kò sì mọ̀:”

183.18: Sm 36.1.“Ìbẹ̀rù Ọlọ́run kò sí níwájú wọn.”

193.19: Ro 2.12.Àwa sì mọ̀ pé ohunkóhun tí òfin bá wí, ó ń wí fún àwọn tí ó wà lábẹ́ òfin: kí gbogbo ẹnu bá à lè dákẹ́ àti kí a lè mú gbogbo aráyé wá sábẹ́ ìdájọ́ Ọlọ́run. 203.20: Sm 143.2; Ap 13.39; Ga 2.16; 3.11; Ro 7.7.Nítorí pé nípa iṣẹ́ òfin, a kì yóò dá ẹnikẹ́ni láre níwájú rẹ̀: nítorí nípa òfin ni ìmọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ ti wá.

Ìṣòdodo nípa ìgbàgbọ́

213.21: Ro 1.17; Fp 3.9; 2Pt 1.1.Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, a ti fi òdodo Ọlọ́run hàn láìsí òfin, tí a ti ń jẹ́rìí sí nípa òfin àti nípa àwọn wòlíì; 223.22: Ro 4.5; 9.30; 10.12; Ga 2.16.Àní òdodo Ọlọ́run nípa ìgbàgbọ́ nínú Jesu Kristi, sí gbogbo ènìyàn àti gbogbo àwọn tí ó gbàgbọ́: nítorí tí kò sí ìyàtọ̀ láàrín Júù àti Helleni. 233.23: Ro 3.9.Gbogbo ènìyàn ni ó ṣá ti ṣẹ̀, tí wọ́n sì kùnà ògo Ọlọ́run: 243.24: Ro 4.16; 5.9; Ef 2.8; Tt 3.7; Ef 1.7; Kl 1.14; Hb 9.15.Àwọn ẹni tí a ń dá láre lọ́fẹ̀ẹ́ nípa oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀, nípa ìdáǹdè tí ó wà nínú Kristi Jesu: 25Ẹni tí Ọlọ́run ti gbé kalẹ̀ láti jẹ́ ètùtù nípa ìgbàgbọ́ nípa ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, láti fi òdodo rẹ̀ hàn nítorí ìdáríjì àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti kọjá, nínú ìpamọ́ra Ọlọ́run: 263.26: 1Jh 2.2; Kl 1.20.Láti fi òdodo rẹ̀ hàn ní ìgbà ìsinsin yìí: kí ó lè jẹ́ olódodo àti olùdáláre ẹni tí ó gba Jesu gbọ́.

27Ọ̀nà ìṣògo dà? A ti mú un kúrò. Nípa òfin wo? Nípa iṣẹ́? Bẹ́ẹ̀ kọ́: Ṣùgbọ́n nípa òfin ìgbàgbọ́. 283.28: Ap 13.39; Ro 5.1; Ef 2.9.Nítorí náà a parí rẹ̀ sí pé nípa ìgbàgbọ́ ni a ń dá ènìyàn láre láìsí iṣẹ́ òfin. 293.29: Ro 9.24; Ap 10.34-35.Ọlọ́run àwọn Júù nìkan ha ni bí? Kì í ha ṣe ti àwọn aláìkọlà pẹ̀lú? Bẹ́ẹ̀ ni, ti àwọn aláìkọlà pẹ̀lú: 303.30: Ro 4.11-12,16.Bí ó ti jẹ́ pé Ọlọ́run kan ni, yóò dá àwọn akọlà láre nípa Ìgbàgbọ́ àti àwọn aláìkọlà nípa ìgbàgbọ́ wọn. 313.31: Ro 8.4; Mt 5.17.Àwa ha ń sọ òfin dasán nípa ìgbàgbọ́ bí? Kí a má rí i: ṣùgbọ́n a ń fi òfin múlẹ̀.

En Levende Bok

Romerne 3:1-31

Gud holder løftet sitt

1Hvilken fordel er det å være jøde? Finnes det noen verdi i den jødiske seremonien å omskjære sønner? 2Ja, å være jøde er en enorm fordel. Den fremste grunnen er at det var jødene som fikk Guds budskap for å spre det videre til andre. 3At visse jøder på et seinere tidspunkt ga opp troen på Gud, det forandrer ingenting. Skulle Gud bryte løftene sine, bare fordi disse menneskene ikke holdt det de hadde lovet? 4Selvfølgelig ikke! Selv om hvert eneste menneske lyver, så snakker Gud alltid sant. Det står i Skriften3:4 ”Skriften” for jødene er Bibelens første del, den som vi kaller Det gamle testamente.:

”De skal se at du har rett i alt du sier,

og at du vinner seier når de anklager deg.”3:4 Se Salmenes bok 51:6.

5”Men”, sier noen, ”det må være bra for Gud dersom vi handler galt, for da forstår alle at han handler rett. Derfor er det også urettferdig at han straffer oss.” Ja, slik tenker noen mennesker. 6Nei, Gud er ikke urettferdig! Hvordan skulle han da kunne dømme menneskene? 7Noen sier kanskje: ”Hvorfor skal jeg bli kalt for en synder og bli dømt? Det er jo bra for Gud om jeg lyver, for da ser alle klart og tydelig at han snakker sant. Da kommer alle til å ære ham.” 8Men tenker de på denne måten, da kunne de like gjerne si: ”Jo mer vi synder, desto bedre, for da kommer Gud til å bli æret for sin godhet!” Noen påstår at det er på denne måten jeg underviser, men de som snakker slik, skal få den straffen de fortjener.

Alle har syndet

9Hva har vi nå kommet fram til? Er vi jøder bedre enn andre?3:9 På gresk: Er da vi bedre enn andre? Nei, slett ikke, for jeg har allerede forklart at alle mennesker uten unntak er syndere enten det er jøder eller ikke.

10Det står i Skriften3:10 ”Skriften” for jødene er Bibelens første del, den som vi kaller Det gamle testamente.:

”Ikke noe menneske er skyldfri innfor Gud, ikke et eneste.

11Ikke noen er forstandig, ingen søker Gud.

12Alle har vendt ham ryggen, alle er like fulle av synd.

Ingen gjør det som er rett, ikke en eneste.3:12 Se Salmenes bok 14:1-3 og 53:1-3.

13Deres prat er motbydelig og råtten, lik stanken fra en åpen grav.

De lyver og bedrar. Deres ord er som giften fra huggormen.3:13 Se Salmenes bok 5:10 og 140:4.

14Alt de sier, er fylt av forbannelser og bitterhet.3:14 Se Salmenes bok 10:7.

15De er raske å gripe til vold og død,

16hvor de enn drar fram etterlater de seg nød og elendighet.

17De kjenner ikke til den veien som leder til fred.3:17 Se Jesaja 59:7-8.

18De kommer ikke på den tanken å vise respekt for Gud.3:18 Se Salmenes bok 36:2.

19Selvfølgelig gjelder Moseloven3:19 Moseloven, eller den jødiske loven, finnes skrevet ned i Første til Femte Mosebok. for jødene. Hensikten med loven er at ingen skal ha noen unnskyldninger å komme med, og at alle mennesker skal bli dømt av Gud.

20Ingen kan noen gang stå skyldfri innfor Gud gjennom det å holde alt som står i loven. Nei, loven kan bare få oss til å innse at vi er syndere.

Jesus Kristus tok straffen vår

21Men nå har Gud vist oss en annen vei til å bli skyldfri innfor ham enn gjennom det å holde alt som står i Moseloven. Denne veien har Gud hele tiden vist oss i Moseloven og profetene3:21 Moseloven og profetenes bok er to av delene i den jødiske Skriften, det vil si Bibelens første del, den som vi kaller Det gamle testamente. Den tredje delen er salmene.. 22Vi kan bli skyldfri for Gud gjennom å tro på Jesus Kristus. Dette gjelder alle, hvem vi enn er. 23Alle har syndet og mistet fellesskapet med Gud, han som kan frelse oss. 24Men nå har han gitt oss en mulighet som vi ikke fortjener. Han har vist oss nåde og latt oss bli skyldfri innfor ham gjennom å la Jesus Kristus kjøpe oss fri fra vårt slaveri under synden. 25-26Gud lot Jesus ofre sitt blod, og han tok straffen for syndene våre på seg for at alle som tror, skal få tilgivelse. Gud ville gjennom dette vise hvor fullkommen god og rettferdig han er. I sin store tålmodighet lot han straffen vente for de syndene som menneskene gjorde for lenge siden. I vår egen tid lot han Jesus dø, og han tok straffen vår. Ja, Gud viste sin godhet ved å la oss bli skyldfrie dersom vi tror på Jesus.

27Har vi da noe å skryte av når det gjelder vårt forhold til Gud? Nei, slett ikke, for det er ikke gjennom våre gode gjerninger vi har blitt forsonet med Gud, men gjennom troen. 28Vi er nemlig fullt overbevist om at menneskene blir skyldfri innfor Gud på grunn av troen, og ikke ved at de forsøker å holde alt som står i Moseloven. 29Ellers ville jo Gud bare være Gud for jødene. Sikkert nok er han Gud for alle folk? Ja, selvfølgelig er han Gud for alle, 30etter som det bare finnes en Gud. Han lar alle mennesker bli skyldfri innfor ham gjennom det at de tror. Det gjelder både jøder og andre folk. 31Når vi sier at troen er så viktig, betyr da det at vi kan være likegyldige til Moseloven? Nei, tvert imot! Gjennom det å tro på Jesus respekterer vi det som står i loven.