Romu 1 – YCB & LB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Romu 1:1-32

Ọ̀rọ̀ ìkíni Paulu sí àwọn àyànfẹ́

11.1: Ap 9.15; 13.2; 1Kọ 1.1; 2Kọ 1.1; Ga 1.15.Paulu, ìránṣẹ́ Jesu Kristi, ẹni tí a ti pè láti jẹ́ aposteli, tí a sì ti yà sọ́tọ̀ láti wàásù ìhìnrere Ọlọ́run, 2ìhìnrere tí ó ti ṣe ìlérí tẹ́lẹ̀ rí láti ẹnu àwọn wòlíì rẹ̀ nínú ìwé Mímọ́. 3Ní ti Ọmọ rẹ̀, ẹni tí a bí láti inú irú-ọmọ Dafidi nípa ti ara, 4ẹni tí a pinnu rẹ̀ láti jẹ́ Ọmọ Ọlọ́run nínú agbára gẹ́gẹ́ bí Ẹ̀mí ìwà mímọ́, nípa àjíǹde kúrò nínú òkú, àní Jesu Kristi Olúwa wa. 51.5: Ap 26.16-18; Ro 15.18; Ga 2.7,9.Láti ọ̀dọ̀ ẹni tí àwa rí oore-ọ̀fẹ́ àti jíjẹ́ aposteli gbà, fún ìgbọ́ràn ìgbàgbọ́ láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè, nítorí orúkọ rẹ̀. 6Ẹ̀yin pẹ̀lú si wa lára àwọn tí a pè sọ́dọ̀ Jesu Kristi.

71.7: 1Kọ 1.3; 2Kọ 1.2; Ga 1.3; Ef 1.2; Fp 1.2; Kl 1.2; 1Tẹ 1.2; 2Tẹ 1.2; 1Tm 1.2; 2Tm 1.2; Tt 1.4; Fm 3; 2Jh 3.Sí gbogbo àwọn àyànfẹ́ Ọlọ́run tí ó wà ní Romu tí a ti pè láti jẹ́ ènìyàn mímọ́:

Oore-ọ̀fẹ́ àti àlàáfíà fún yín láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wa àti láti ọ̀dọ̀ Olúwa wa Jesu Kristi.

Ìfojúsọ́nà Paulu láti bẹ Romu wò

81.8: Ro 16.19.Ní àkọ́kọ́, mo dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run nípasẹ̀ Jesu Kristi fún gbogbo yín, nítorí a ń ròyìn ìgbàgbọ́ yin káàkiri gbogbo ayé. 9Ọlọ́run ṣá à ni ẹlẹ́rìí mi, ẹni tí èmí ń fi gbogbo ẹ̀mí mi sìn nínú ìhìnrere Ọmọ rẹ̀, bí ó ti ṣe pé ní àìsimi ni èmí ń rántí yín nígbà gbogbo nínú àdúrà mi 101.10: Ro 15.23,32; Ap 19.21.nínú àdúrà mi ìgbà gbogbo; mo tún ń gbàdúrà wí pé nípa oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run kí ọ̀nà ó ṣí fún mi láti wá sọ́dọ̀ yín.

11Nítorí èmi ń fẹ́ gidigidi láti tọ̀ yín wá, kí èmi lè fún yín ní ẹ̀bùn ẹ̀mí díẹ̀, kí a bá a le sọ yín di alágbára nínú Olúwa, 12èyí nì ni pé, kí a lè jẹ́ ìwúrí fún ara wa nípa ìgbàgbọ́ ẹnìkọ̀ọ̀kan wa. 131.13: Ro 15.22.Mo fẹ́ kí ẹ mọ èyí, ẹ̀yin ará mi, pé mo ti gbìyànjú lọ́pọ̀ ìgbà láti tọ̀ yín wá, (ṣùgbọ́n ìdíwọ́ wà fún mi), kí èmi ki ó lè jèrè ọkàn díẹ̀ láàrín yín, gẹ́gẹ́ bí mo ti ní láàrín àwọn aláìkọlà yòókù.

141.14: 1Kọ 9.16.Nítorí mo jẹ́ ajigbèsè sí Giriki àti sí àwọn aláìgbédè tí kì í ṣe Giriki, sí àwọn ọlọ́gbọ́n àti sí àwọn aṣiwèrè. 15Nítorí ìdí èyí ni mo ṣe ń làkàkà láti wá sí Romu àti láti fi gbogbo agbára mi wàásù ìhìnrere Ọlọ́run sí i yín.

161.16: 1Kọ 1.18,24.Èmi kò tijú ìhìnrere Jesu, nítorí agbára Ọlọ́run ní ín ṣe láti gba gbogbo àwọn tí ó bá gbàgbọ́ là, ọ̀rọ̀ yìí ni a kọ́kọ́ wàásù sí àwọn Júù nìkan, ṣùgbọ́n nísinsin yìí fún àwọn Helleni pẹ̀lú. 171.17: Ro 3.21; Ga 3.11; Fp 3.9; Hb 10.38; Hk 2.4.Nítorí nínú ìhìnrere ni òdodo Ọlọ́run ti farahàn, òdodo Ọlọ́run nípa ìgbàgbọ́ láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé Mímọ́ pé, “Olódodo yóò yè nípa ìgbàgbọ́ rẹ̀.”

Ìbínú Ọlọ́run sí orílẹ̀ ayé

181.18: Ef 5.6; Kl 3.6.Ṣùgbọ́n Ọlọ́run fi ìbínú rẹ̀ hàn láti ọ̀run wá sí gbogbo àìwà-bí-Ọlọ́run àti gbogbo àìṣòdodo ènìyàn, àwọn tí ń fi ìwà búburú dènà ìmọ̀ òtítọ́ lọ́dọ̀ ènìyàn. 19Nítorí pé, nǹkan gbogbo tí a lè mọ nípa Ọlọ́run ni a ti fihàn fún wọn, nítorí Ọlọ́run ti fi í hàn fún wọn. 201.20: Sm 19.1-4.Nítorí pé láti ìgbà dídá ayé, gbogbo ohun àìlèfojúrí rẹ̀: bí agbára ayérayé àti ìwà-bí-Ọlọ́run rẹ̀ ni a rí gbangba tí a sì ń fi òye ohun tí a dá mọ̀ ọ́n kí ènìyàn má ba à wá àwáwí.

211.21: Ef 4.17-18.Lóòótọ́, wọn ní òye nípa Ọlọ́run dáradára, ṣùgbọ́n wọn kò yìn ín lógo bí Ọlọ́run, wọ́n kò sí dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ̀; wọ́n ń ro èrò asán, ọkàn aṣiwèrè wọn sì ṣókùnkùn. 22Níwọ́n bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé wọ́n pe ara wọn ní ọlọ́gbọ́n ṣùgbọ́n wọ́n di òmùgọ̀ pátápátá, 231.23: Ap 17.29.wọ́n sì yí ògo Ọlọ́run tí kì í díbàjẹ́ sí àwọn àwòrán ère bí i ti ènìyàn tí í díbàjẹ́ àti ti ẹyẹ, àti ti ẹranko ẹlẹ́sẹ̀ mẹ́rin àti ti ẹranko afàyàfà.

24Nítorí náà Ọlọ́run fà wọ́n lé ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ọkàn wọn lọ́wọ́ láti máa ṣe ohun ìríra pẹ̀lú ara wọn èyí tí kò tọ́. 25Wọ́n yí òtítọ́ Ọlọ́run sí èké, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ láti máa sin ẹ̀dá dípò ẹlẹ́dàá—ẹni tí ìyìn tọ́ sí láéláé. Àmín.

26Nítorí èyí yìí ni Ọlọ́run ṣe fi wọ́n fún ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́: nítorí àwọn obìnrin wọn tilẹ̀ ń yí ìṣẹ̀dá ìbáṣepọ̀ tí ó tọ̀nà, sí èyí tí kò tọ̀nà. 27Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin pẹ̀lú, wọn a máa fi ìbálòpọ̀ obìnrin nípa ti ẹ̀dá sílẹ̀, wọn a máa fẹ́ ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí ara wọn, ọkùnrin ń bá ọkùnrin ṣe èyí tí kò yẹ, wọ́n sì ǹ jẹ èrè ìṣìnà wọn nínú ara wọn bí ó ti yẹ sí.

28Àti gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti kọ̀ láti gba Ọlọ́run nínú ìmọ̀ tí ó tọ́, Ọlọ́run fi wọ́n fún iyè ríra láti ṣe ohun tí kò tọ́ fún wọn láti ṣe: 29Wọ́n kún fún onírúurú àìṣòdodo gbogbo, àgbèrè, ìkà, ojúkòkòrò, àrankàn; wọ́n kún fún ìlara, ìpànìyàn, ìjà, ìtànjẹ, ìwà búburú; wọ́n jẹ́ a fi-ọ̀rọ̀-kẹ́lẹ́-banijẹ́. 30Asọ̀rọ̀ ẹni lẹ́yìn, akórìíra Ọlọ́run, aláfojúdi, agbéraga, ahalẹ̀, aláròṣe ohun búburú, aṣàìgbọràn sí òbí, 31aláìníyè nínú, ọ̀dàlẹ̀, aláìnígbàgbọ́, ọ̀dájú, aláìláàánú: 32Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé wọ́n mọ ìlànà Ọlọ́run pé, ẹni tí ó bá ṣe irú nǹkan wọ̀nyí yẹ sí ikú, wọn kò ní inú dídùn sí àwọn nǹkan wọ̀nyí nìkan ṣùgbọ́n wọ́n ní inú dídùn sí àwọn tí ń ṣe wọ́n.

En Levende Bok

Romerne 1:1-32

Hilsen

1-2Hilsen fra Paulus, som er Jesu Kristi1:1-2 ”Kristus” betyr ”den salvede” på gresk. Blant Israels folk ble konger, prester og profeter salvet med olje før de begynte oppgaven sin. Gud hadde ved profetene lovet å sende en salvet konge som skulle herske over alle folk. Det hebraisk ordet ”Messias” betyr også ”den salvede”. tjener. Jeg er valgt ut av Gud for å være hans utsending1:1-2 Kalles også apostel. og spre det glade budskapet som han for lenge siden lovet oss ved profetene sine i den Hellige Skriften1:1-2 ”Skriften” for jødene er Bibelens første del, den som vi kaller Det gamle testamente. Profetenes bok er en av delene i Skriften.. 3-4Dette er det glade budskapet om hans Sønn, Jesus Kristus, vår Herre. Han kom til verden som et menneske og ble født inn i slekten til kong David. Jesus Kristus var ikke bare menneske. Samtidig var han Guds sønn, noe som Gud på en mektig måte ga bevis på ved å la sin Hellige Ånd reise ham opp fra de døde.

5Jesus Kristus har gitt meg den forretten å få være hans utsending og fortelle alle folk om det han har gjort, slik at de kan begynne å tro og lyde ham. Gjennom dette livet kan alle gi Gud ære. 6Blant dem som har fått innbydelsen for å høre Jesus Kristus til, er også dere.

7Til alle dere som bor i Roma, som er elsket av Gud og har takket ja til innbydelsen hans om å tilhøre ham.

Jeg ber om at Gud, vår Far, og Herren Jesus Kristus, vil vise dere godhet og fylle dere med fred.

Paulus lengter etter menigheten

8Først av alt vil jeg si at jeg takker Gud for dere alle på grunn av det Jesus Kristus har gjort. Jeg takker Gud, etter som de over alt snakker om den troen dere har. 9Gud selv vet at jeg stadig ber for dere. Det er ham jeg tjener av hele hjertet mens jeg sprer det glade budskapet om Guds sønn. 10En ting jeg alltid ber om, er at jeg en dag må få muligheten til å reise til dere, om Gud vil. 11Jeg lengter etter å treffe dere og dele alt godt med dere som Gud ved sin Ånd vil gi oss, slik at dere blir styrket i troen. 12Eller rettere sagt: Slik at jeg kan oppmuntre dere, og dere meg, gjennom den tro vi har felles.

13Jeg vil at dere skal vite, kjære søsken1:13 På gresk: brødre. Samme tolkning blir brukt gjennom hele brevet., at jeg flere ganger har tenkt å komme til dere, for at troen skal få det samme gode resultat hos dere, som den har fått hos andre folk. Alltid er det blitt noe som hindret meg i å komme. 14Det inngår i oppdraget mitt å nå ut til folk, både i vår kultur og i andre kulturer1:14 På gresk: til både greker og barbarer. Barbarene var et folkeslag som ikke tilhørte den gresk-romerske kulturen. De ble ansett for å være usiviliserte og ulærde., både til dem som er velutdannet og til vanlig enkle mennesker. 15Derfor vil jeg gjerne komme til dere i Roma, slik at jeg kan spre det glade budskapet også der.

Kraften i det glade budskapet

16Jeg skammer meg ikke for det glade budskapet om Jesus. Det handler om Guds kraft til å frelse hver og en som tror. Jødene var de første som fikk høre budskapet, men det gjelder for alle folk. 17Det glade budskapet gjør klart at vi gjennom helhjertet å tro på Jesus, kan bli skyldfri innfor Gud. Det står i Skriften1:17 ”Skriften” for jødene er Bibelens første del, den som vi kaller Det gamle testamente.: ”Den som tror, blir skyldfri innfor Gud og får leve.”1:17 Se Habakkuk 2:4.

Gud hater synden

18Gud viser fra himmelen sitt sinne mot alle mennesker som lever i synd og ondskap, og som hindrer andre fra å kjenne til sannheten om ham. 19De blir straffet fordi de ikke vil lyde Gud til tross for at de allerede kjenner til det vi kan vite om ham. Gud har vist hvem han er. 20Helt siden verden ble skapt har menneskene kunne se Guds grenseløse makt og forstå at han virkelig er Gud. De kan ikke med sitt blotte øye oppdage egenskapene hans, men de kan forstå hvem Gud er gjennom å betrakte alt han har skapt. Derfor finnes det ingen unnskyldning for dem som ikke vil lyde Gud!

21Til tross for at menneskene kjente Gud, nektet de å tilbe ham som Gud og takke ham. I stedet henga de seg til egne fantasier om tilværelsen. Deres forvirrede sinn ble fylt av et åndelig mørke. 22De påsto seg å være kloke, men endte i stedet i den komplette dårskap. 23I stedet for å tilbe Gud, han som har all makt og aldri kan dø, tilba de avguder, bilder av vanlige dødelige mennesker og alle slags dyr, både slike som flyr og slike som lever på land.

24Gud lot folkene følge sine egne begjær. De utførte motbydelige og skammelige seksuelle handlinger med hverandre. 25I stedet for å tro på Gud, han som er sannheten, valgte de å tro på løgn og bedrag. De tilba og tjente det skapte i stedet for Skaperen. Han er den som skal bli hyllet for evig. Ja, dette er sant!1:25 I grunnteksten: Amen!

26Etter som de trodde på løgn og bedrag, lot Gud dem hengi seg til homoseksuelle aktiviteter. Til og med kvinnene byttet ut sin naturlige seksualitet og tilfredsstilte sine behov med hverandre. 27Mennene sluttet å ha naturlige seksuelle forhold til kvinner og begynte å bli tent av begjær til hverandre, slik at de utførte skammelige handlinger med andre menn. På denne måten ble de selv årsaken til den rettferdige straffen de fikk for sin ondskap. 28Ja, etter som de ikke brydde seg om å kjenne Gud, lot Gud dem få følge sine egne onde tanker, slik at de gjorde det de ikke skulle ha gjort. 29Menneskene ble fylt av all slags ondskap, umoral, egoisme, hat, misunnelse, mordlyst, aggresjon, svik og ond vilje. 30Ja, de sladrer og lyver om andre. De håner Gud. De er storsnutet, arrogante og skrytende. De finner stadig nye måter til å gjøre det som er ondt, de er ulydige mot foreldrene sine. 31De tenker aldri på andre, men bryter stadig løftene sine, etter som de mangler både kjærlighet og medfølelse. 32De vet at Gud en dag skal straffe dem med døden for det de gjør, men likevel fortsetter de. Ikke nok med det: De roser også andre som lever på dette viset.