Oniwaasu 12 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Oniwaasu 12:1-14

1Rántí Ẹlẹ́dàá rẹ

ní ọjọ́ èwe rẹ,

nígbà tí ọjọ́ ibi kò tí ì dé

àti tí ọdún kò tí ì ní súnmọ́ etílé, nígbà tí ìwọ yóò wí pé,

“Èmi kò ní ìdùnnú nínú wọn”

2Kí oòrùn àti ìmọ́lẹ̀

àti òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀ tó ṣókùnkùn,

àti kí àwọsánmọ̀ tó padà lẹ́yìn òjò;

3Nígbà tí olùṣọ́ ilé yóò wárìrì

tí àwọn ọkùnrin alágbára yóò tẹríba,

nígbà tí àwọn tí ó ń lọ dákẹ́ nítorí pé wọn kò pọ̀,

tí àwọn tí ń wo òde láti ojú fèrèsé yóò ṣókùnkùn;

4Nígbà tí ìlẹ̀kùn sí ìgboro yóò tì

tí ariwo ọlọ yóò dákẹ́;

nígbà tí àwọn ènìyàn yóò dìde sí ariwo àwọn ẹyẹ

ṣùgbọ́n gbogbo orin wọn yóò máa lọ ilẹ̀.

5Nígbà tí ènìyàn yóò bẹ̀rù ibi gíga

àti ti ìfarapa ní ìgboro;

nígbà tí igi almondi yóò tanná

àti tí ẹlẹ́ǹgà yóò wọ́ ara rẹ̀ lọ

tí ìfẹ́ kò sì ní ru sókè mọ́

nígbà náà ni ènìyàn yóò lọ ilé rẹ́ ayérayé

tí àwọn aṣọ̀fọ̀ yóò máa rìn kiri ìgboro.

6Rántí rẹ̀ kí okùn fàdákà tó já,

tàbí kí ọpọ́n wúrà tó fọ́;

kí iṣà tó fọ́ níbi ìsun,

tàbí kí àyíká kẹ̀kẹ́ kí ó tó kán níbi kànga.

7Tí erùpẹ̀ yóò sì padà sí ilẹ̀ ibi tí ó ti wà,

tí ẹ̀mí yóò sì padà sọ́dọ̀ Ọlọ́run tí ó fi í fún ni.

8“Asán! Asán!” ni Oniwaasu wí.

“Gbogbo rẹ̀ asán ni!”

Òpin gbogbo ọrọ̀

9Kì í ṣe wí pé Oniwaasu jẹ́ ọlọ́gbọ́n nìkan, ṣùgbọ́n ó tún kọ́ àwọn ènìyàn ní ìmọ̀. Ó rò ó dáradára ó sì ṣe àwárí, ó sì gbé ọ̀pọ̀lọpọ̀ òwe kalẹ̀ lẹ́sẹẹsẹ. 10Oniwaasu wádìí láti rí àwọn ọ̀rọ̀ tí ó tọ̀nà, ohun tí ó kọ sì dúró ṣinṣin ó sì jẹ́ òtítọ́.

11Ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n dàbí ẹ̀gún, àkójọpọ̀ ọ̀rọ̀ wọn sì dàbí ìṣó tí a kàn pọ̀ dáradára, tí olùṣọ́-àgùntàn kan fi fún ni. 12Àti síwájú láti inú èyí, Ọmọ mi, gba ìmọ̀ràn.

Nínú ìwé púpọ̀, òpin kò sí, ìwé kíkà púpọ̀ a máa mú ara ṣàárẹ̀.

13Nísinsin yìí,

òpin gbogbo ọ̀rọ̀ tí a gbọ́ ni pé:

Bẹ̀rù Ọlọ́run, kí o sì pa òfin rẹ̀ mọ́,

nítorí èyí ni ojúṣe gbogbo ènìyàn.

14Nítorí Ọlọ́run yóò ṣe ìdájọ́ olúkúlùkù iṣẹ́

àti ohun ìkọ̀kọ̀,

kì bá à ṣe rere kì bá à ṣe búburú.

Persian Contemporary Bible

جامعه 12:1‏-14

آفرينندهٔ خود را در روزهای جوانيت به ياد آور، قبل از اينكه روزهای سخت زندگی فرا رسد روزهايی كه ديگر نتوانی از آنها لذت ببری. 1‏-2آفرينندهٔ خود را به ياد آور قبل از اينكه ابرهای تيره آسمان زندگی تو را فرا گيرند، و ديگر خورشيد و ماه و ستارگان در آن ندرخشند؛ 3دستهای تو كه از تو محافظت می‌كنند، بلرزند و پاهای قوی تو ضعيف گردند؛ دندانهايت كم شوند و ديگر نتوانند غذا را بجوند و چشمانت كم سو گردند و نتوانند چيزی را ببينند؛ 4گوشهايت سنگين شوند و نتوانند سر و صدای كوچه و صدای آسياب و نغمهٔ موسيقی و آواز پرندگان را بشنوند؛ 5به سختی راه روی و از هر بلندی بترسی؛ موهايت سفيد شوند، قوت تو از بين برود و اشتهايت كور شود؛ به خانهٔ جاودانی بروی و مردم در كوچه‌ها برای تو سوگواری كنند.

6بلی، آفرينندهٔ خويش را به ياد آور، قبل از آنكه رشتهٔ نقره‌ای عمرت پاره شود و جام طلا بشكند، كوزه كنار چشمه خرد شود و چرخ بر سر چاه آب متلاشی گردد، 7بدن به خاک زمين كه از آن سرشته شده برگردد و روح به سوی خداوند كه آن را عطا كرده، پرواز كند.

8«حكيم»12‏:8 نگاه کنيد به 1‏:1.‏ می‌گويد: «بيهودگی است! بيهودگی است! همه چيز بيهودگی است!»

خاتمه

9«حكيم» آنچه را كه می‌دانست به مردم تعليم می‌داد، زيرا مرد دانايی بود. او پس از تفكر و تحقيق، مثلهای بسياری تأليف كرد. 10«حكيم» كوشش كرد با سخنان دلنشين، حقايق را صادقانه بيان كند.

11سخنان مردان حكيم مانند چوبهای تيزی هستند كه شبانان با آنها گوسفندان را هدايت می‌كنند و مثل ميخهايی هستند كه محكم به زمين كوبيده شده باشند. اين سخنان جماعت را هدايت می‌كنند، زيرا همهٔ آنها توسط يک شبان يعنی خداوند داده می‌شوند. 12ولی پسرم، از همهٔ اينها گذشته، بدان كه نوشتن كتابها تمامی ندارد و مطالعهٔ آنها بدن را خسته می‌كند.

13در خاتمه، حاصل كلام را بشنويم: انسان بايد از خداوند بترسد و احكام او را نگاه دارد، زيرا تمام وظيفهٔ او همين است. 14خدا هر عمل خوب يا بد ما را، حتی اگر در خفا نيز انجام شود، داوری خواهد كرد.