Òwe 1 – YCB & PCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 1:1-33

Èròǹgbà àti kókó-ọ̀rọ̀

1Àwọn òwe ti Solomoni, ọmọ Dafidi, ọba Israẹli.

2Láti le ní ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́,

Láti ní òye àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀.

3Láti gba ẹ̀kọ́ ọgbọ́n, òdodo,

àti ìdájọ́, àti àìṣègbè;

4láti fi òye fún onírẹ̀lẹ̀,

ìmọ̀ àti ìṣọ́ra fún àwọn èwe.

5Jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n tẹ́tí kí ó sì ní ìmọ̀ kún ìmọ̀,

sì jẹ́ kí ẹni òye gba ìtọ́sọ́nà.

6Láti mọ ìtumọ̀ òwe àti ìtán-dòwe,

àwọn ọ̀rọ̀ àti àlọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n.

7Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìbẹ̀rẹ̀ ìmọ̀,

ṣùgbọ́n aláìgbọ́n kẹ́gàn ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́.

Ọ̀rọ̀ ìyànjú láti ṣàfẹ́rí ọgbọ́n

8Tẹ́tí, ìwọ ọmọ mi sí ẹ̀kọ́ baba rẹ,

má ṣe kọ ẹ̀kọ́ màmá rẹ sílẹ̀.

9Wọn yóò jẹ́ òdòdó ẹ̀yẹ olóòórùn dídùn lórí rẹ

àti ọ̀ṣọ́ tí ó dára yí ọrùn rẹ ká.

10Ọmọ mi, bí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ bá ń tàn ọ́,

má ṣe gbà fún wọn.

11Bí wọn bá wí pé, “Wá pẹ̀lú wa;

jẹ́ kí á ba ní ibùba fún ẹ̀jẹ̀ ẹnìkan,

jẹ́ kí á lúgọ ní ìkọ̀kọ̀ de aláìṣẹ̀ ní àìnídìí;

12Jẹ́ ká gbé wọn mì láààyè, bí ibojì òkú,

àti lódidi, bí àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sínú kòtò;

13A ó rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan tó níye lórí

a ó sì fi ìkógun kún inú ilé wa;

14Da ìpín rẹ pọ̀ mọ́ àárín wa,

a ó sì jọ pawó sínú àpò kan náà”

15Ọmọ mi, má ṣe bá wọn lọ,

má ṣe rìn ní ojú ọ̀nà wọn;

16Nítorí ẹsẹ̀ wọn ń sáré sí ẹ̀ṣẹ̀,

wọ́n yára láti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀.

17Wàhálà asán ni kí ènìyàn máa dẹ àwọ̀n sílẹ̀,

ní ojú ẹyẹ!

18Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ń lúgọ fún ẹ̀jẹ̀ ara wọn.

Ara wọn ni wọ́n ń dá lọ́nà

19Báyìí ni ìgbẹ̀yìn gbogbo àwọn tí ń wá èrè àìtọ́;

yóò mú ẹ̀mí gbogbo ẹni tí ó rí i lọ.

Ìkìlọ̀ láti má ṣe kọ ọgbọ́n sílẹ̀

201.20,21: Òw 8.1-3.Ọgbọ́n kígbe sókè ní pópó

ó gbé ohùn rẹ̀ sókè láàrín ọjà;

21Láàrín ọjà ni ó ti kígbe jáde

Ní ibodè ìlú ni ó ti sọ̀rọ̀ ọ rẹ̀:

22“Yóò ha ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin aláìmọ̀kan yóò fi fẹ́ àìmọ̀kan yín tó?

Yóò ha ti pẹ́ tó tí àwọn ẹlẹ́gàn yóò ṣe inú dídùn sí ìpẹ̀gàn tó?

Àwọn aláìgbọ́n kórìíra ìmọ̀?

23Bí ẹ bá ti gbọ́ ìbáwí ì mi ni,

Ǹ bá ti tú ohun tí ó wà nínú ọkàn mi jáde fún yín

kí n sì fi inú mi hàn sí i yín.

24Ṣùgbọ́n níwọ̀n bí ẹ ti kọ ìpè ní ìgbà tí mo pè

kò sì sí ẹni tí ó kọ ibi ara sí mi gbà tí mo na ọwọ́ sí wọn,

25Níwọ́n bí ẹ ti kọ gbogbo ìmọ̀ràn mi,

tí ẹ̀yin kò sì gba ìbáwí mi,

26Èmi pẹ̀lú yóò fi ìdààmú yín rẹ́rìn-ín;

èmi yóò ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín.

27Nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín bí ìjì líle,

Nígbà tí ìdààmú bá dé bá ọ bí ààjà,

nígbà tí wàhálà àti ìbànújẹ́ ọkàn bá bò ọ́ mọ́lẹ̀.

28“Nígbà náà ni wọn yóò ké pè mí ṣùgbọ́n, èmi kò ní dáhùn;

wọn yóò fi ara balẹ̀ wá mi ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí mi.

29Níwọ́n bí wọ́n ti kórìíra ìmọ̀

tí wọ́n sì kọ̀ láti bẹ̀rù Olúwa.

30Níwọ́n bí wọn kò ti gbà ìmọ̀ràn mi

tí wọ́n sì kẹ́gàn ìmọ̀ràn mi,

31Wọn yóò jẹ èrè iṣẹ́ ọwọ́ wọn

wọn yóò sì jèrè èso ètè wọn ní kíkún

32Nítorí ìrìnkurìn àwọn aláìmọ̀kan ni yóò pa wọ́n

ìkáwọ́gbera aláìgbọ́n ni yóò pa á run;

33Ṣùgbọ́n ẹnìkan tí ó bá fetí sí mi, yóò gbé láìléwu

yóò sì wà nínú ìdẹ̀ra, láìsí ìbẹ̀rù ìpalára.”

Persian Contemporary Bible

امثال 1:1-33

ارزش مثلها

1مثلهای سليمان، پادشاه اسرائيل، كه پسر داوود بود:

2اين مثلها به شما كمک خواهند كرد تا حكمت و ادب بياموزيد و بتوانيد معنی سخنان پرمغز را درک كنيد. 3آنها به شما ياد خواهند داد چگونه رفتار عاقلانه داشته باشيد و با صداقت و عدالت و انصاف عمل كنيد. 4اين مثلها به جاهلان حكمت می‌بخشند و به جوانان فهم و بصيرت. 5‏-6با شنيدن و درک اين مثلها، حتی دانايان داناتر می‌شوند و دانشمندان چاره انديشی كسب می‌كنند تا بتوانند معانی گفتار پيچيدهٔ حكيمان را بفهمند.

نصيحت به جوانان

7نخستين قدم برای كسب دانش، خداترسی است. كسی كه حكمت و ادب را خوار می‌شمارد، احمق است. 8ای جوان، نصيحت پدرت را بشنو و از تعليم مادرت رويگردان نشو، 9زيرا سخنان ايشان مانند تاج و جواهر، سيرت تو را زيبا خواهند ساخت.

10وقتی گناهكاران تو را وسوسه می‌كنند، تسليم نشو. 11اگر آنها به تو بگويند: «بيا در كمين مردم بنشينيم و آنها را بكشيم 12و مانند قبر، آنها را ببلعيم و از هستی ساقط كنيم؛ 13از اين راه ما اشیا قيمتی فراوان به چنگ خواهيم آورد و خانه‌های خود را از اين غنايم پر خواهيم ساخت؛ 14هر چه به دست بياوريم به تساوی بين خود تقسيم خواهيم كرد؛ پس بيا و با ما همدست شو!» 15پسرم تو با آنها نرو و خود را از چنين افرادی دور نگه دار؛ 16زيرا آنها هميشه در پی گناه و قتل هستند. 17يک پرنده وقتی می‌بيند برايش دام گذاشته‌اند، از آن دوری می‌كند. 18ولی اين افراد اينطور نيستند. آنها خودشان را به دام می‌اندازند و با دست خود گور خود را می‌كنند. 19اين است سرنوشت تمام كسانی كه در پی سود نامشروع هستند. چنين اشخاص خود را نابود می‌كنند.

ندای حكمت

20حكمت در كوچه‌ها ندا می‌دهد. 21مردم را كه در سر چهارراه‌ها و نزد دروازهٔ شهر جمع شده‌اند صدا كرده، می‌گويد: 22«ای احمق‌ها! تا كی می‌خواهيد احمق بمانيد؟ تا كی می‌خواهيد دانايی را مسخره كنيد و از آن متنفر باشيد؟ 23اگر سرزنش مرا می‌پذيرفتيد من روح خود را بر شما نازل می‌كردم و شما را دانا می‌ساختم. 24بارها شما را صدا كردم ولی توجه نكرديد، التماس نمودم اما اعتنا ننموديد. 25شما نصيحت و نكوهش مرا نپذيرفتيد. 26من نيز در روز مصيبتتان به شما خواهم خنديد، و هنگامی كه بلا دامنگيرتان شود شما را مسخره خواهم كرد. 27وقتی بلا مانند طوفان شما را فرا گيرد و مصيبت مثل گردباد شما را احاطه كند، و سختی و بدبختی شما را از پای درآورد، 28به داد شما نخواهم رسيد، و اگرچه با اشتياق به دنبالم بگرديد، مرا نخواهيد يافت؛ 29زيرا از دانايی متنفر بوده‌ايد و از خداوند اطاعت نكرده‌ايد. 30نصيحت مرا گوش نگرفته‌ايد و نكوهش مرا نپذيرفته‌ايد. 31بنابراين ثمرهٔ راهی را كه در پيش گرفته‌ايد خواهيد ديد. 32زيرا سركشی احمقان، ايشان را خواهد كشت و بی‌خيالی نادانان آنها را از پای در خواهد آورد. 33ولی همهٔ كسانی كه به من گوش دهند، از هيچ بلايی نخواهند ترسيد و در امنيت زندگی خواهند كرد.»