Jobu 35 – YCB & OL

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 35:1-16

Olóòtítọ́ ni Ọlọ́run

1Elihu sì wí pe:

2“Ìwọ rò pé èyí ha tọ́, tí ìwọ wí pé,

òdodo mi ni èyí níwájú Ọlọ́run?

3Nítorí tí ìwọ wí pé èrè kí ní yóò jásí fún ọ,

tàbí èrè kí ni èmi yóò fi jẹ́ ju èrè ẹ̀ṣẹ̀ mi lọ.

4“Èmi ó dá ọ lóhùn

àti àwọn ẹgbẹ́ rẹ pẹ̀lú rẹ.

5Síjú wo ọ̀run; kí o rí i, kí ó sì

bojú wo àwọsánmọ̀ tí ó ga jù ọ́ lọ.

6Bí ìwọ bá dẹ́ṣẹ̀, kí ni ìwọ fi sẹ̀ sí?

Tàbí bí ìrékọjá rẹ di púpọ̀, kí ni ìwọ fi èyí nì ṣe sí i?

7Bí ìwọ bá sì ṣe olódodo, kí ni ìwọ fi fún un,

tàbí kí ni òun rí gbà láti ọwọ́ rẹ wá?

8Ìwà búburú rẹ ni fún ènìyàn bí ìwọ;

òdodo rẹ sì ni fún ọmọ ènìyàn.

9“Nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìninilára, wọ́n mú ni kígbe;

wọ́n kígbe nípa apá àwọn alágbára.

10Ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó wí pé,

‘Níbo ni Ọlọ́run Ẹlẹ́dàá mi wà tí ó sì fi orin fún mi ní òru;

11Tí òun kọ́ wa ní ẹ̀kọ́ jù àwọn ẹranko ayé lọ,

tí ó sì mú wa gbọ́n ju àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run lọ?’

12Nígbà náà ni wọ́n ń ké ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò dáhùn

nítorí ìgbéraga ènìyàn búburú.

13Nítòótọ́ Ọlọ́run kì yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ asán;

bẹ́ẹ̀ ní Olódùmarè kì yóò kà á sí.

14Bí ó tilẹ̀ ṣe pé ìwọ wí pé ìwọ kì í rí i,

ọ̀rọ̀ ìdájọ́ ń bẹ níwájú rẹ,

ẹni tí ìwọ sì gbọdọ̀ dúró dè.

15Ṣùgbọ́n nísinsin yìí nítorí tí ìbínú rẹ̀ kò tí fìyà jẹ ni,

òun kò ni ka ìwà búburú si?

16Nítorí náà ní Jobu ṣe ya ẹnu rẹ̀

lásán ó sọ ọ̀rọ̀ di púpọ̀ láìsí ìmọ̀.”

O Livro

Job 35:1-16

1E Eliú prosseguiu:

2“Achas que é justo dizeres:

‘Maior é a minha justiça do que a de Deus?’

3Ainda dizes: ‘Que vantagem tenho eu,

ou que ganho teria se abandonasse o meu pecado?’

4Vou responder-te,

assim como a todos os teus amigos.

5Olha para o céu,

vê como as nuvens estão bem acima de ti.

6Se pecares, que mal poderás fazer contra Deus?

Se multiplicas os teus crimes, nenhum prejuízo lhe causas.

7Da mesma forma, se fores justo, o que lhe darás?

O que receberá das tuas mãos?

8Os teus pecados podem, sim, afetar os outros homens;

igualmente, os teus atos de justiça poderão beneficiá-los.

9Os que vivem oprimidos podem gritar, sob o efeito de injúrias,

e gemer sob o braço dos poderosos.

10Contudo, nenhum deles pergunta:

‘Onde está Deus, o meu Criador,

aquele que inspira cânticos durante a noite?

11Que nos ensina mais que aos animais de toda a Terra

e nos torna mais sábios que as aves dos altos céus?’

12Se alguém lhe lançar essa questão,

ele não replicará com o castigo próprio de tiranos.

13Pois Deus não ouve clamores sem sinceridade,

nem para eles atentará o Todo-Poderoso.

14Muito menos te ouvirá, se disseres que não o vês!

A tua causa está diante dele, portanto, espera nele.

15Imaginas que, na sua ira, Deus parou de castigar,

que não leva em consideração o orgulho e a iniquidade dos homens.

16Assim, Job, falas demais,

porém, não sabes o que estás a dizer!”