Jobu 34 – YCB & OL

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 34:1-37

Elihu pe Jobu níjà

1Nígbà náà ni Elihu dáhùn, ó sì wí pé:

2“Ẹ̀yin ọlọ́gbọ́n ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi,

kí ẹ sì fi etí sílẹ̀ sí mi ẹ̀yin tí ẹ ní ìmòye.

3Nítorí pé etí a máa dán ọ̀rọ̀ wò,

bí adùn ẹnu ti ń tọ́ oúnjẹ wò.

4Ẹ jẹ́ kí a mọ òye ohun tí o tọ́ fún ara wa;

ẹ jẹ́ kí a mọ ohun tí ó dára láàrín wa.

5“Nítorí pé Jobu wí pé, ‘Aláìlẹ́ṣẹ̀ ni èmi;

Ọlọ́run sì ti gba ìdájọ́ mi lọ.

6Èmi ha purọ́ sí ẹ̀tọ́ mi bí,

bí mo tilẹ̀ jẹ́ aláìjẹ̀bi,

ọfà rẹ̀ kò ní àwòtán ọgbẹ́.’

7Ọkùnrin wo ni ó dàbí Jobu,

tí ń mu ẹ̀gàn bí ẹní mú omi?

8Tí ń bá àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kẹ́gbẹ́ tí ó

sì ń bá àwọn ènìyàn búburú rìn.

9Nítorí ó sá ti wí pé, ‘Èrè kan kò sí fún ènìyàn,

tí yóò fi máa ṣe inú dídùn sí Ọlọ́run.’

10“Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ fetísílẹ̀ sí mi,

ẹ fi etí sí mi ẹ̀yin ènìyàn amòye:

Ó di èèwọ̀ fún Ọlọ́run ti ìbá fi hùwà búburú,

àti fún Olódùmarè, tí yóò fi ṣe àìṣedéédéé!

11Nítorí pé ó ń sán fún ènìyàn fún gẹ́gẹ́ bi ohun tí a bá ṣe,

yóò sì mú olúkúlùkù kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ipa ọ̀nà rẹ̀.

12Nítòótọ́ Ọlọ́run kì yóò hùwàkiwà;

bẹ́ẹ̀ ni Olódùmarè kì yóò yí ìdájọ́ po.

13Ta ni ó fi ìtọ́jú ayé lé e lọ́wọ́,

tàbí ta ni ó fi gbogbo ayé lé e lọ́wọ́?

14Bí ó bá gbé ayé rẹ̀ lé kìkì ara rẹ̀

tí ó sì gba ọkàn rẹ̀ àti ẹ̀mí rẹ̀ sọ́dọ̀ ara rẹ̀,

15gbogbo ènìyàn ni yóò parun pọ̀,

ènìyàn a sì tún padà di erùpẹ̀.

16“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, bí ìwọ bá ní òye,

gbọ́ èyí; fetísí ohùn ẹnu mi.

17Ẹni tí ó kórìíra òtítọ́ ha le ṣe olórí bí?

Ìwọ ó ha sì dá olóòótọ́ àti ẹni ńlá lẹ́bi?

18O ha tọ́ láti wí fún ọba pé, ‘ènìyàn búburú ní ìwọ,’

tàbí fún àwọn ọmọ-aládé pé, ‘ìkà ni ẹ̀yin,’

19Mélòó mélòó fún ẹni tí kì í ṣe ojúsàájú àwọn ọmọ-aládé

tàbí tí kò kà ọlọ́rọ̀ sí ju tálákà lọ,

nítorí pé iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni gbogbo wọn í ṣe?

20Ní ìṣẹ́jú kan ni wọn ó kú,

àwọn ènìyàn á sì di yíyọ́ lẹ́nu láàrín ọ̀gànjọ́, wọn a sì kọjá lọ;

a sì mú àwọn alágbára kúrò láìsí ọwọ́ ènìyàn níbẹ̀.

21“Nítorí pé ojú rẹ̀ ń bẹ ní ipa ọ̀nà ènìyàn,

òun sì rí ìrìn rẹ̀ gbogbo.

22Kò sí ibi òkùnkùn, tàbí òjìji ikú,

níbi tí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ yóò gbé sápamọ́ sí.

23Nítorí pé òun kò pẹ́ àti kíyèsi ẹnìkan,

kí òun kí ó sì mú lọ sínú ìdájọ́ níwájú Ọlọ́run.

24Òun ó sì fọ́ àwọn alágbára túútúú láìní ìwádìí,

a sì fi ẹlòmíràn dípò wọn,

25nítorí pé ó mọ iṣẹ́ wọn,

ó sì yí wọn po ní òru, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n di ìtẹ̀mọ́lẹ̀.

26Ó kọlù wọ́n nítorí ìwà búburú wọn

níbi tí àwọn ẹlòmíràn ti lè rí i,

27nítorí pé wọ́n padà pẹ̀yìndà sí i,

wọn kò sì fiyèsí ipa ọ̀nà rẹ̀ gbogbo,

28kí wọn kí ó sì mú igbe ẹkún àwọn tálákà lọ dé ọ̀dọ̀ rẹ̀,

òun sì gbọ́ igbe ẹkún aláìní.

29Ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá dákẹ́ síbẹ̀, ta ni yóò dá lẹ́bi?

Nígbà tí ó bá pa ojú rẹ̀ mọ́, ta ni yóò lè rí i?

Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe si orílẹ̀-èdè tàbí sí ènìyàn kan ṣoṣo;

30Kí aláìwà bi Ọlọ́run kí ó má bá à jẹ ọba

kí wọn kí ó má di ìdẹwò fún ènìyàn.

31“Nítorí pé ẹnìkan ha lè wí fún Ọlọ́run pé,

èmi jẹ̀bi, èmi kò sì ní ṣẹ̀ mọ́?

32Èyí tí èmi kò rí ìwọ fi kọ́ mi

bi mo bá sì dẹ́ṣẹ̀ èmi kì yóò ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́.

33Ǹjẹ́ bí ti inú rẹ̀ ni ki òun ó san ẹ̀ṣẹ̀ padà?

Ǹjẹ́ òun yóò san án padà bí ìwọ bá kọ̀ ọ́ láti jẹ́wọ́,

ìwọ gbọdọ̀ yan, kì í ṣe èmi.

Nítorí náà sọ ohun tí o mọ̀;

Pẹ̀lúpẹ̀lú ohun tí ìwọ mọ̀, sọ ọ́!

34“Àwọn ènìyàn amòye yóò wí fún mi,

àti pẹ̀lúpẹ̀lú ẹnikẹ́ni tí í ṣe ọlọ́gbọ́n tí ó sì gbọ́ mi pé,

35‘Jobu ti fi àìmọ̀ sọ̀rọ̀,

ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì ṣe aláìgbọ́n.’

36Ìfẹ́ mi ni kí a dán Jobu wò dé òpin,

nítorí ìdáhùn rẹ̀ dàbí i ti ènìyàn búburú:

37Nítorí pe ó fi ìṣọ̀tẹ̀ kún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀;

ó pàtẹ́wọ́ ní àárín wa,

ó sì sọ ọ̀rọ̀ odi púpọ̀ sí Ọlọ́run.”

O Livro

Job 34:1-37

1Eliú continuou:

2“Escutem-me, vocês, os sábios,

ouçam vocês que são entendidos.

3Porque o ouvido testa as palavras,

tal como a língua faz com aquilo que se come.

4Da mesma forma, deveríamos saber escolher aquilo que é reto;

antes de mais, deveríamos definir, entre nós, o que é bom.

5Porque Job disse: ‘Estou inocente e Deus diz-me que não.

6Sou chamado de mentiroso e, no entanto, estou inocente.

Sou tremendamente castigado pelas suas flechas, mesmo sem ter pecado!’

7Haverá alguém semelhante a Job

que bebe zombarias como água?

8Isto é mesmo de pessoas

que passam muito tempo no meio de gente má.

9Pois diz: ‘Para que serve

perder tempo a agradar a Deus?’

10Deem-me atenção, gente de entendimento;

o Deus Todo-Poderoso não pratica o mal,

nem comete qualquer injustiça!

11Mas ele retribui às pessoas conforme o que fazem,

compensa-as segundo merece a sua conduta.

12É coisa que não se discute;

o Deus Todo-Poderoso nunca é mau nem injusto.

13Quem é que lhe entregou o governo da Terra?

Quem pôs o mundo inteiro ao seu cuidado?

14Se Deus viesse a retirar o seu Espírito

e o seu sopro dos homens,

15toda a vida desapareceria

e a humanidade tornar-se-ia novamente em pó.

16Ouçam-me, pois, e tentem compreender.

17Poderia Deus governar, se odiasse a justiça?

Queres tu condenar aquele que é justo e poderoso?

18Quem ousaria condenar este Deus que diz a reis e nobres:

‘Vocês são maus e injustos!’?

19Porque não olha a posição social das pessoas,

nem dá mais atenção ao rico do que ao pobre,

pois de todos foi o Criador.

20Todos podem passar desta vida, dum momento para o outro;

em plena noite, grandes ou pequenos podem partir,

sem qualquer intervenção humana.

21Deus vigia cuidadosamente os caminhos de cada um;

vê todos os seus passos.

22Não há escuridão suficientemente espessa

para ocultar os ímpios aos seus olhos.

23É por isso que Deus não necessita de mais tempo

para analisar os seres humanos

e conduzi-los à sua presença para julgamento.

24Sem questionar, Deus simplesmente destrói,

até o maior dos seres humanos, e o substitui por outro.

25Sabe tudo o que fazem

e, numa só noite, pode deitá-los abaixo.

26À vista de toda a gente,

pode castigá-los como ímpios que são,

27visto que se desviaram de Deus

e não procuraram seguir os seus caminhos.

28Assim, o grito do pobre chegou a Deus.

Sim, ele ouve os gritos dos oprimidos!

29E mesmo que Deus prefira não falar,

quem iria criticá-lo por isso?

Se encobrir a sua face, quem conseguirá contemplá-lo,

seja uma nação inteira ou um indivíduo?

30Pode, igualmente, evitar que um homem ruim governe

e que não haja quem iluda toda uma nação.

31Pois quem jamais disse a Deus:

‘Sofri, apesar de não ter pecado!

32Ensina-me a compreender o que não posso ver!

Se agi mal, não voltarei a fazê-lo!’?

33Deveria Deus recompensar-te, se não confessas a tua culpa?

És tu que tens de fazer a melhor escolha e não eu!

Agora, pois, diz lá o que pensas!

34As pessoas com discernimento e com inteligência estão,

com toda a certeza, comigo.

35Ao afirmarem que Job falou sem conhecimento

não há sabedoria nas suas palavras!

36Job deveria ser provado até ao fim,

pela forma condenável como falou de Deus.

37É que dessa forma acrescenta rebelião, arrogância e blasfémia

aos seus outros pecados contra Deus.”