1Elihu sì tún sọ̀rọ̀ wí pé:
2“Fún mi láyè díẹ̀ èmi ó sì fihàn ọ́,
nítorí ọ̀rọ̀ sísọ ní ó kún fún Ọlọ́run.
3Èmi ó mú ìmọ̀ mi ti ọ̀nà jíjìn wá,
èmi ó sì fi òdodo fún Ẹlẹ́dàá mi.
4Rí i dájú pé ọ̀rọ̀ mi kì yóò ṣèké
nítòótọ́; ẹni tí ó pé ní ìmọ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.
5“Kíyèsi i, Ọlọ́run ni alágbára, òun kò i sì
gàn ènìyàn; ó ní agbára ní ipá àti òye.
6Òun kì í dá ẹ̀mí ènìyàn búburú sí,
ṣùgbọ́n ó fi òtítọ́ fún àwọn tálákà.
7Òun kì í mú ojú rẹ̀ kúrò lára olódodo,
ṣùgbọ́n àwọn ọba ni wọ́n wà lórí ìtẹ́;
àní ó fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé, a sì gbé wọn lékè.
8Bí ó bá sì dè wọ́n nínú àbà, tí a
sì fi okùn ìpọ́njú dè wọ́n,
9Nígbà náà ni ó ń sọ àwọn ohun tí wọn ti ṣe fún wọn,
wí pé wọ́n ti ṣẹ̀ pẹ̀lú ìgbéraga wọn.
10Ó sí wọn létí pẹ̀lú sí ọ̀nà ẹ̀kọ́,
ó sì pàṣẹ kí wọn kí ó padà kúrò nínú àìṣedédé.
11Bí wọ́n bá gbàgbọ́ tí wọ́n sì sìn ín,
wọn ó lo ọjọ́ wọn ní ìrọ̀rùn,
àti ọdún wọn nínú afẹ́.
12Ṣùgbọ́n, bí wọn kò bá gbàgbọ́,
wọ́n ó ti ọwọ́ idà ṣègbé,
wọ́n á sì kú láìní òye.
13“Ṣùgbọ́n àwọn àgàbàgebè ní ayé kó ìbínú jọ;
wọn kò kígbe fún ìrànlọ́wọ́ nígbà tí ó bá wọ́n wí.
14Nígbà náà ni ọkàn wọn yóò kú ní èwe,
ní àárín àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà.
15Òun gba òtòṣì nínú ìpọ́njú wọn,
a sì sọ̀rọ̀ sí wọn ní etí nínú ìnira wọn.
16“Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lúpẹ̀lú ó fa wọn yọ láti inú ìhágágá sí ibi gbòòrò,
sí ibi tí ó ní ààyè tí kò ní wàhálà nínú rẹ̀,
ohun tí a sì gbé kalẹ̀ ní tábìlì rẹ̀ jẹ́ kìkì ọ̀rá oúnjẹ tí ó fẹ́.
17Ṣùgbọ́n ìwọ kún fún ìdájọ́ àwọn búburú;
ìdájọ́ àti òtítọ́ dì ọ́ mú.
18Nítorí ìbínú ń bẹ, ṣọ́ra kí òtítọ́ rẹ máa bá a tàn ọ;
láti jẹ́ kí títóbi rẹ mú ọ ṣìnà.
19Ọrọ̀ rẹ pọ̀ tó, tí wàhálà kì yóò fi dé bá ọ bí?
Tàbí ipa agbára rẹ?
20Má ṣe ìfẹ́ òru, nígbà tí a ń ké
àwọn orílẹ̀-èdè kúrò ní ipò wọn.
21Máa ṣọ́ra kí ìwọ ki ó má yí ara rẹ̀ padà sí búburú;
Nítorí èyí tí ìwọ rò pé ó dára jù ìpọ́njú lọ.
22“Kíyèsi i, Ọlọ́run ni gbéga nípa agbára rẹ̀;
ta ni jẹ́ olùkọ́ni bí rẹ̀?
23Ta ni ó là ọ̀nà iṣẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ fún un,
tàbí ta ni ó lè wí pé ìwọ ti ń ṣe àìṣedéédéé?
24Rántí kí ìwọ kí ó gbé iṣẹ́ rẹ̀ ga,
ti ènìyàn ni yín nínú orin.
25Olúkúlùkù ènìyàn a máa rí i;
ẹni ikú a máa wò ó ní òkèrè,
26Kíyèsi i, Ọlọ́run tóbi, àwa kò sì mọ̀ bí ó ti ní òye tó,
bẹ́ẹ̀ ni a kò lè wádìí iye ọdún rẹ̀ rí.
27“Nítorí pé òun ni ó fa ìkán omi òjò sílẹ̀,
kí wọn kí ó kán bí òjò ní ìkùùkuu rẹ̀,
28tí àwọsánmọ̀ ń rọ̀ ìrì rẹ̀ sílẹ̀,
tí ó sì fi ń sẹ̀ lọ́pọ̀lọpọ̀ lórí ènìyàn.
29Pẹ̀lúpẹ̀lú ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè ní ìmọ̀ ìtànká àwọsánmọ̀,
tàbí ariwo àrá láti àgọ́ rẹ̀?
30Kíyèsi i, ó tan ìmọ́lẹ̀ yí ara rẹ̀ ká
ó sì bo ìsàlẹ̀ Òkun mọ́lẹ̀.
31Nítorí pé nípa wọn ní ń ṣe dájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ènìyàn;
ó sí ń pèsè oúnjẹ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
32Ó fi ìmọ́lẹ̀ bo ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì
ó sì rán an sí ẹni olódì.
33Ariwo àrá rẹ̀ fi ìjì hàn ní;
ọ̀wọ́ ẹran pẹ̀lú wí pé, ó súnmọ́ etílé!
1Disse ainda mais Eliú:
2“Deixa-me continuar, provar-te-ei aquilo que afirmo;
ainda não acabei de defender Deus!
3Dar-te-ei ilustrações sobre a justiça do meu Criador.
4Vou dizer-te a verdade, com toda a honestidade,
pois sou pessoa com largos conhecimentos.
5Deus é poderoso e, apesar disso,
não põe de parte ninguém!
6Não poupa a vida do ímpio,
mas faz justiça aos aflitos.
7Não desvia o olhar dos que são justos,
antes os honra, colocando-os sobre tronos reais, eternos.
8Se estão presos a grilhões,
e a aflição os atormenta,
9então dar-se-á ao trabalho de lhes indicar
as razões de tal situação, aquilo que fizeram de mal,
ou como se terão conduzido com altivez.
10Ajudá-los-á a ouvirem a sua instrução,
a fim de se desviarem dos seus pecados.
11Se o ouvirem e obedecerem,
então serão abençoados com prosperidade,
todo o tempo das suas vidas.
12Se, pelo contrário, lhe fecharem os ouvidos,
perecerão no meio das lutas,
morrerão em consequência da sua falta de bom senso.
13A verdade é que os ímpios colherão a ira de Deus;
mesmo agrilhoados, recusam-se a clamar por socorro.
14Acabarão por morrer novos,
como jovens entregues à prostituição36.14 O termo aqui refere-se a jovens e homens que praticavam a prostituição em templos pagãos..
15Mas ele livra o aflito da sua aflição
e isto faz com que o escutem!
16Também ele quer conduzir-te do meio da opressão,
para um lugar amplo, tranquilo e livre,
para a fartura da tua mesa cheia de gordura.
17Porém, acumulaste sobre ti mesmo o juízo dos ímpios;
por isso, a justiça e o castigo estão sobre a tua cabeça.
18Que a raiva não te leve a excessos,
nem te deixes seduzir pelas riquezas!
19Pensas, realmente, que se gritasses com força,
ou se te esforçasses muito, isso poria um fim ao teu aperto?
20Não desejes a noite
em que os povos se revoltam.
21Desvia-te do mal,
pois escolheste isso em vez do sofrimento.
22Repara, Deus é todo-poderoso!
Quem, melhor do que ele, sabe ensinar?
23Quem ousaria dizer-lhe o que deve fazer,
ou dizer-lhe: ‘Cometeste uma injustiça!’
24Portanto, engrandece-o pela sua obra,
que tem sido contada pelos homens.
25São coisas que toda a gente vê;
de longe os homens as contemplam.
26Deus é tão grande que ninguém pode pretender conhecê-lo.
Ninguém pode calcular os anos da sua existência.
27Ele concentra o vapor de água
e depois transforma-o em correntes de água,
28que as nuvens despejam em aguaceiros sobre os seres humanos.
29Poderá alguém entender perfeitamente o caminho das nuvens
e os trovões dentro delas?
30Vê como dispara os relâmpagos à sua volta
e como cobre os cimos das montanhas!
31Com a chuva alimenta os povos,
dando-lhes recursos em abundância.
32Enche as mãos com raios faiscantes;
lança cada um deles sobre um alvo certo.
33O trovão anuncia a sua chegada
e o rebanho pressente a chegada da tempestade!