Jobu 36 – YCB & OL

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 36:1-33

1Elihu sì tún sọ̀rọ̀ wí pé:

2“Fún mi láyè díẹ̀ èmi ó sì fihàn ọ́,

nítorí ọ̀rọ̀ sísọ ní ó kún fún Ọlọ́run.

3Èmi ó mú ìmọ̀ mi ti ọ̀nà jíjìn wá,

èmi ó sì fi òdodo fún Ẹlẹ́dàá mi.

4Rí i dájú pé ọ̀rọ̀ mi kì yóò ṣèké

nítòótọ́; ẹni tí ó pé ní ìmọ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.

5“Kíyèsi i, Ọlọ́run ni alágbára, òun kò i sì

gàn ènìyàn; ó ní agbára ní ipá àti òye.

6Òun kì í dá ẹ̀mí ènìyàn búburú sí,

ṣùgbọ́n ó fi òtítọ́ fún àwọn tálákà.

7Òun kì í mú ojú rẹ̀ kúrò lára olódodo,

ṣùgbọ́n àwọn ọba ni wọ́n wà lórí ìtẹ́;

àní ó fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé, a sì gbé wọn lékè.

8Bí ó bá sì dè wọ́n nínú àbà, tí a

sì fi okùn ìpọ́njú dè wọ́n,

9Nígbà náà ni ó ń sọ àwọn ohun tí wọn ti ṣe fún wọn,

wí pé wọ́n ti ṣẹ̀ pẹ̀lú ìgbéraga wọn.

10Ó sí wọn létí pẹ̀lú sí ọ̀nà ẹ̀kọ́,

ó sì pàṣẹ kí wọn kí ó padà kúrò nínú àìṣedédé.

11Bí wọ́n bá gbàgbọ́ tí wọ́n sì sìn ín,

wọn ó lo ọjọ́ wọn ní ìrọ̀rùn,

àti ọdún wọn nínú afẹ́.

12Ṣùgbọ́n, bí wọn kò bá gbàgbọ́,

wọ́n ó ti ọwọ́ idà ṣègbé,

wọ́n á sì kú láìní òye.

13“Ṣùgbọ́n àwọn àgàbàgebè ní ayé kó ìbínú jọ;

wọn kò kígbe fún ìrànlọ́wọ́ nígbà tí ó bá wọ́n wí.

14Nígbà náà ni ọkàn wọn yóò kú ní èwe,

ní àárín àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà.

15Òun gba òtòṣì nínú ìpọ́njú wọn,

a sì sọ̀rọ̀ sí wọn ní etí nínú ìnira wọn.

16“Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lúpẹ̀lú ó fa wọn yọ láti inú ìhágágá sí ibi gbòòrò,

sí ibi tí ó ní ààyè tí kò ní wàhálà nínú rẹ̀,

ohun tí a sì gbé kalẹ̀ ní tábìlì rẹ̀ jẹ́ kìkì ọ̀rá oúnjẹ tí ó fẹ́.

17Ṣùgbọ́n ìwọ kún fún ìdájọ́ àwọn búburú;

ìdájọ́ àti òtítọ́ dì ọ́ mú.

18Nítorí ìbínú ń bẹ, ṣọ́ra kí òtítọ́ rẹ máa bá a tàn ọ;

láti jẹ́ kí títóbi rẹ mú ọ ṣìnà.

19Ọrọ̀ rẹ pọ̀ tó, tí wàhálà kì yóò fi dé bá ọ bí?

Tàbí ipa agbára rẹ?

20Má ṣe ìfẹ́ òru, nígbà tí a ń ké

àwọn orílẹ̀-èdè kúrò ní ipò wọn.

21Máa ṣọ́ra kí ìwọ ki ó má yí ara rẹ̀ padà sí búburú;

Nítorí èyí tí ìwọ rò pé ó dára jù ìpọ́njú lọ.

22“Kíyèsi i, Ọlọ́run ni gbéga nípa agbára rẹ̀;

ta ni jẹ́ olùkọ́ni bí rẹ̀?

23Ta ni ó là ọ̀nà iṣẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ fún un,

tàbí ta ni ó lè wí pé ìwọ ti ń ṣe àìṣedéédéé?

24Rántí kí ìwọ kí ó gbé iṣẹ́ rẹ̀ ga,

ti ènìyàn ni yín nínú orin.

25Olúkúlùkù ènìyàn a máa rí i;

ẹni ikú a máa wò ó ní òkèrè,

26Kíyèsi i, Ọlọ́run tóbi, àwa kò sì mọ̀ bí ó ti ní òye tó,

bẹ́ẹ̀ ni a kò lè wádìí iye ọdún rẹ̀ rí.

27“Nítorí pé òun ni ó fa ìkán omi òjò sílẹ̀,

kí wọn kí ó kán bí òjò ní ìkùùkuu rẹ̀,

28tí àwọsánmọ̀ ń rọ̀ ìrì rẹ̀ sílẹ̀,

tí ó sì fi ń sẹ̀ lọ́pọ̀lọpọ̀ lórí ènìyàn.

29Pẹ̀lúpẹ̀lú ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè ní ìmọ̀ ìtànká àwọsánmọ̀,

tàbí ariwo àrá láti àgọ́ rẹ̀?

30Kíyèsi i, ó tan ìmọ́lẹ̀ yí ara rẹ̀ ká

ó sì bo ìsàlẹ̀ Òkun mọ́lẹ̀.

31Nítorí pé nípa wọn ní ń ṣe dájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ènìyàn;

ó sí ń pèsè oúnjẹ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.

32Ó fi ìmọ́lẹ̀ bo ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì

ó sì rán an sí ẹni olódì.

33Ariwo àrá rẹ̀ fi ìjì hàn ní;

ọ̀wọ́ ẹran pẹ̀lú wí pé, ó súnmọ́ etílé!

O Livro

Job 36:1-33

1Disse ainda mais Eliú:

2“Deixa-me continuar, provar-te-ei aquilo que afirmo;

ainda não acabei de defender Deus!

3Dar-te-ei ilustrações sobre a justiça do meu Criador.

4Vou dizer-te a verdade, com toda a honestidade,

pois sou pessoa com largos conhecimentos.

5Deus é poderoso e, apesar disso,

não põe de parte ninguém!

6Não poupa a vida do ímpio,

mas faz justiça aos aflitos.

7Não desvia o olhar dos que são justos,

antes os honra, colocando-os sobre tronos reais, eternos.

8Se estão presos a grilhões,

e a aflição os atormenta,

9então dar-se-á ao trabalho de lhes indicar

as razões de tal situação, aquilo que fizeram de mal,

ou como se terão conduzido com altivez.

10Ajudá-los-á a ouvirem a sua instrução,

a fim de se desviarem dos seus pecados.

11Se o ouvirem e obedecerem,

então serão abençoados com prosperidade,

todo o tempo das suas vidas.

12Se, pelo contrário, lhe fecharem os ouvidos,

perecerão no meio das lutas,

morrerão em consequência da sua falta de bom senso.

13A verdade é que os ímpios colherão a ira de Deus;

mesmo agrilhoados, recusam-se a clamar por socorro.

14Acabarão por morrer novos,

como jovens entregues à prostituição36.14 O termo aqui refere-se a jovens e homens que praticavam a prostituição em templos pagãos..

15Mas ele livra o aflito da sua aflição

e isto faz com que o escutem!

16Também ele quer conduzir-te do meio da opressão,

para um lugar amplo, tranquilo e livre,

para a fartura da tua mesa cheia de gordura.

17Porém, acumulaste sobre ti mesmo o juízo dos ímpios;

por isso, a justiça e o castigo estão sobre a tua cabeça.

18Que a raiva não te leve a excessos,

nem te deixes seduzir pelas riquezas!

19Pensas, realmente, que se gritasses com força,

ou se te esforçasses muito, isso poria um fim ao teu aperto?

20Não desejes a noite

em que os povos se revoltam.

21Desvia-te do mal,

pois escolheste isso em vez do sofrimento.

22Repara, Deus é todo-poderoso!

Quem, melhor do que ele, sabe ensinar?

23Quem ousaria dizer-lhe o que deve fazer,

ou dizer-lhe: ‘Cometeste uma injustiça!’

24Portanto, engrandece-o pela sua obra,

que tem sido contada pelos homens.

25São coisas que toda a gente vê;

de longe os homens as contemplam.

26Deus é tão grande que ninguém pode pretender conhecê-lo.

Ninguém pode calcular os anos da sua existência.

27Ele concentra o vapor de água

e depois transforma-o em correntes de água,

28que as nuvens despejam em aguaceiros sobre os seres humanos.

29Poderá alguém entender perfeitamente o caminho das nuvens

e os trovões dentro delas?

30Vê como dispara os relâmpagos à sua volta

e como cobre os cimos das montanhas!

31Com a chuva alimenta os povos,

dando-lhes recursos em abundância.

32Enche as mãos com raios faiscantes;

lança cada um deles sobre um alvo certo.

33O trovão anuncia a sua chegada

e o rebanho pressente a chegada da tempestade!