Jobu 15 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 15:1-35

Elifasi tako ọrọ̀ Jobu

1Ìgbà náà ní Elifasi, ará Temani, dáhùn wí pé:

2“Ọlọ́gbọ́n a máa sọ̀rọ̀ ìmọ̀ asán, kí

ó sì máa fi afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn kún ara rẹ̀ nínú?

3Òun lè máa fi àròyé sọ̀rọ̀ tí kò ní

èrè, tàbí pẹ̀lú ọ̀rọ̀ nínú èyí tí kò lè fi ṣe rere?

4Ṣùgbọ́n ìwọ ṣá ìbẹ̀rù tì,

ìwọ sì dí iṣẹ́ ìsìn lọ́nà níwájú Ọlọ́run.

5Nítorí pé ẹnu ara rẹ̀ ni ó jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀

rẹ̀, ìwọ sì yàn ahọ́n alárékérekè ni ààyò.

6Ẹnu ara rẹ̀ ni ó dá lẹ́bi, kì í ṣe èmi;

àní ètè ara rẹ̀ ni ó jẹ́rìí gbè ọ́.

7“Ìwọ ha í ṣe ọkùnrin tí a kọ́ bí?

Tàbí a ha dá ọ ṣáájú àwọn òkè?

8Ìwọ gbúròó àṣírí Ọlọ́run rí, tàbí

ìwọ ha dá ọgbọ́n dúró sọ́dọ̀ ara rẹ?

9Kí ni ìwọ mọ̀ tí àwa kò mọ̀?

Òye kí ní ó yé ọ tí kò sí nínú wa?

10Àwọn arúgbó àti ògbólógbòó ènìyàn wà pẹ̀lú wa,

tí wọ́n dàgbà ju baba rẹ lọ.

11Ìtùnú Ọlọ́run ha kéré lọ́dọ̀ rẹ?

Ọ̀rọ̀ kan sì ṣe jẹ́jẹ́ jù lọ́dọ̀ rẹ?

12Èéṣe ti ọkàn rẹ fi ń ti ọ kiri,

kí ni ìwọ tẹjúmọ́ tóbẹ́ẹ̀.

13Tí ìwọ fi yí ẹ̀mí rẹ padà lòdì sí Ọlọ́run,

tí ó fi ń jẹ́ ki ọ̀rọ̀kọ́rọ̀ kí ó máa bọ́ ní ẹnu rẹ̀ bẹ́ẹ̀?

14“Kí ni ènìyàn tí ó fi jẹ mímọ́,

àti ẹni tí a tinú obìnrin bí tí yóò fi ṣe olódodo?

15Kíyèsi i, bi Ọlọ́run ko ba gbẹ́kẹ̀lé àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀,

àní àwọn ọ̀run kò mọ́ ní ojú rẹ̀,

16mélòó mélòó ni ènìyàn, ẹni ìríra àti eléèérí,

tí ń mu ẹ̀ṣẹ̀ bi ẹní mu omi.

17“Èmi ó fihàn ọ́, gbọ́ ti èmi;

Èyí tí èmi sì rí, òun ni èmi ó sì sọ,

18ohun tí àwọn ọlọ́gbọ́n ti pa ní ìtàn láti

ọ̀dọ̀ àwọn baba wọn wá, ti wọ́n kò sì fi pamọ́,

19Àwọn tí a fi ilẹ̀ ayé fún nìkan,

ti àlejò kan kò sì là wọ́n kọjá.

20Ènìyàn búburú ń ṣe làálàá,

pẹ̀lú ìrora, ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo,

àti iye ọdún ní a dá sílẹ̀ fún aninilára.

21Ìró ìbẹ̀rù ń bẹ ní etí rẹ̀;

nínú ìrora ni apanirun yóò dìde sí i.

22Kò gbàgbọ́ pé òun ó jáde kúrò nínú òkùnkùn;

a sì ṣà á sápá kan fún idà.

23Ó ń wò káàkiri fún oúnjẹ wí pé, níbo ní ó wà?

Ó mọ̀ pé ọjọ́ òkùnkùn súnmọ́ tòsí.

24Ìpọ́njú pẹ̀lú ìrora ọkàn yóò mú un

bẹ̀rù, wọ́n ó sì ṣẹ́gun rẹ̀ bi ọba ti ìmúra ogun.

25Nítorí pé ó ti nawọ́ rẹ̀ jáde lòdì

sí Ọlọ́run, ó sì múra rẹ̀ le lòdì sí Olódùmarè,

26Ó súre, ó sì fi ẹ̀yìn gíga,

àní fi ike-kókó àpáta rẹ̀ tí ó nípọn kọlù ú.

27“Nítorí tí òun fi ọ̀rá rẹ̀ bo ara rẹ̀

lójú, o sì ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀.

28Òun sì gbé inú ahoro ìlú,

àti nínú ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé

mọ́, tí ó múra tán láti di àlàpà.

29Òun kò lé di ọlọ́rọ̀, bẹ́ẹ̀ ohun ìní rẹ̀ kò

lè dúró pẹ́; Bẹ́ẹ̀ kò lè mú pípé rẹ̀ dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.

30Òun kì yóò jáde kúrò nínú òkùnkùn;

ọ̀wọ́-iná ni yóò jó ẹ̀ka rẹ̀,

àti nípasẹ̀ ẹ̀mí ẹnu Ọlọ́run ní a ó gba kúrò.

31Kí òun kí ó má ṣe gbẹ́kẹ̀lé asán, kí ó má sì ṣe tan ara rẹ̀ jẹ.

Nítorí pé asán ní yóò jásí èrè rẹ̀.

32A ó mú un ṣẹ ṣáájú pípé ọjọ́ rẹ̀,

ẹ̀ka rẹ̀ kì yóò sì tutù.

33Yóò dàbí àjàrà tí a gbọn èso àìpọ́n rẹ̀ dànù,

yóò sì rẹ̀ ìtànná rẹ̀ dànù bí i ti igi Olifi.

34Nítorí pé ayọ̀ àwọn àgàbàgebè

yóò túká, iná ní yóò sì jó àgọ́ àwọn tí ó fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀.

35Wọ́n lóyún ìwà ìkà, wọ́n sì bí ẹ̀ṣẹ̀,

ikùn wọn sì pèsè ẹ̀tàn.”

New International Reader’s Version

Job 15:1-35

The Second Speech of Eliphaz

1Then Eliphaz the Temanite replied,

2“Job, would a wise person answer with a lot of meaningless talk?

Would they fill their stomach with the hot east wind?

3Would they argue with useless words?

Would they give worthless speeches?

4But you even cause others to lose their respect for God.

You make it hard for them to be faithful to him.

5Your sin makes you say evil things.

You talk like people who twist the truth.

6Your own mouth judges you, not mine.

Your own lips witness against you.

7“Are you the first man who was ever born?

Were you created before the hills?

8Do you listen in when God speaks with his angels?

Do you think you are the only wise person?

9What do you know that we don’t know?

What understanding do you have that we don’t have?

10People who are old and gray are on our side.

And they are even older than your parents!

11Aren’t God’s words of comfort enough for you?

He speaks them to you gently.

12Why have you let your wild ideas carry you away?

Why do your eyes flash with anger?

13Why do you get so angry with God?

Why do words like those pour out of your mouth?

14“Can human beings really be pure?

Can those who are born really be right with God?

15God doesn’t trust his holy angels.

Even the heavens aren’t pure in his sight.

16So he’ll certainly find fault with human beings.

After all, they are evil and sinful.

They drink up evil as if it were water.

17“Listen to me. I’ll explain things to you.

Let me tell you what I’ve seen.

18I’ll tell you what those who are wise have said.

They don’t hide anything they’ve received

from their people of long ago.

19The land was given only to those people.

Their wisdom didn’t come from outsiders.

And here’s what those who are wise have said.

20Sinful people always suffer pain.

Mean people suffer all their lives.

21Terrifying sounds fill their ears.

When everything seems to be going well,

robbers attack them.

22They lose all hope of escaping the darkness of death.

They will certainly be killed by swords.

23Like vultures, they look around for food.

They know that the day they will die is near.

24Suffering and pain terrify them.

Their troubles overpower them,

like a king ready to attack his enemies.

25They shake their fists at God.

They brag about themselves and oppose the Mighty One.

26They boldly charge against him

with their thick, strong shields.

27“Their faces are very fat.

Their stomachs hang out.

28They’ll live in towns that have been destroyed.

They’ll live in houses where no one else lives.

The houses will crumble to pieces.

29They won’t be rich anymore. Their wealth won’t last.

Their property will no longer spread out over the land.

30They won’t escape the darkness of death.

A flame will dry up everything they have.

The breath of God will blow them away.

31Don’t let them fool themselves

by trusting in what is worthless.

They won’t get anything out of it.

32Even before they die, they will dry up.

No matter what they do, it won’t succeed.

33They’ll be like vines

that are stripped of their unripe grapes.

They’ll be like olive trees

that drop their flowers.

34People who are ungodly won’t have any children.

Fire will burn up the tents of people who accept money

from those who want special favors.

35Instead of having children,

ungodly people create suffering.

All they produce is evil.

They are full of lies.”