Jobu 14 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 14:1-22

Jobu tẹ̀síwájú nínú àròyé rẹ̀

1“Ènìyàn tí a bí nínú obìnrin,

ọlọ́jọ́ díẹ̀ ni, ó sì kún fún ìpọ́njú.

2Ó jáde wá bí ìtànná ewéko, a sì ké e lulẹ̀;

ó sì ń fò lọ bí òjìji, kò sì dúró pẹ́.

3Ìwọ sì ń ṣíjú rẹ wò irú èyí ni?

Ìwọ sì mú mi wá sínú ìdájọ́ pẹ̀lú rẹ?

4Ta ni ó lè mú ohun mímọ́ láti inú àìmọ́ jáde wá?

Kò sí ẹnìkan!

5Ǹjẹ́ a ti pinnu ọjọ́ rẹ̀,

iye oṣù rẹ̀ ń bẹ ní ọwọ́ rẹ;

Ìwọ ti pààlà rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ní òun kò le kọjá rẹ̀.

6Yípadà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, kí ó lè

sinmi, títí yóò fi pé ọjọ́ rẹ̀ bí alágbàṣe.

7“Nítorí pé ìrètí wà fún igi, bí a bá

ké e lulẹ̀, pé yóò sì tún sọ,

àti pé ẹ̀ka rẹ̀ tuntun kì yóò gbẹ.

8Bí gbòǹgbò rẹ̀ tilẹ̀ di ogbó nínú ilẹ̀,

tí kùkùté rẹ̀ si kú ni ilẹ̀;

9Síbẹ̀ nígbà tí ó bá gbóòórùn omi,

yóò sọ, yóò sì yọ ẹ̀ka jáde bí irúgbìn.

10Ṣùgbọ́n ènìyàn kú, a sì dàánù;

Àní ènìyàn jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀ lọ́wọ́: Òun kò sì sí mọ́.

Àgékúrú ọjọ́ ọmọ ènìyàn

11“Bí omi ti í tán nínú ipa odò,

àti bí odò ṣì tí í fà tí sì gbẹ,

12bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn dùbúlẹ̀ tí kò sì dìde mọ́;

títí ọ̀run kì yóò fi sí mọ́,

wọ́n kì yóò jí, a kì yóò jí wọn kúrò lójú oorun wọn.

13“Háà! ìwọ ìbá fi mí pamọ́ ní ipò òkú,

kí ìwọ kí ó fi mí pamọ́ ní ìkọ̀kọ̀,

títí ìbínú rẹ yóò fi rékọjá,

ìwọ ìbá lànà ìgbà kan sílẹ̀ fún mi, kí ó si rántí mi!

14Bí ènìyàn bá kú yóò sì tún yè bí?

Gbogbo ọjọ́ ìgbà tí a là sílẹ̀

fún mi ni èmi dúró dè, títí àmúdọ̀tún mi yóò fi dé.

15Ìwọ ìbá pè, èmi ìbá sì dá ọ lóhùn;

ìwọ ó sì ní ìfẹ́ sì iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.

16Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ ń kaye ìṣísẹ̀ mi;

ìwọ kò fa ọwọ́ rẹ kúrò nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mi?

17A fi èdìdì di ìrékọjá mi sínú àpò,

ìwọ sì rán àìṣedéédéé mi pọ̀.

18“Àti nítòótọ́ òkè ńlá tí ó ṣubú, ó dasán,

a sì ṣí àpáta kúrò ní ipò rẹ̀.

19Omi a máa yinrin òkúta, ìwọ a sì

mú omi sàn bo ohun tí ó hù jáde lórí ilẹ̀,

ìwọ sì sọ ìrètí ènìyàn dí òfo.

20Ìwọ ṣẹ́gun rẹ̀ láéláé, òun sì kọjá lọ!

Ìwọ pa awọ ojú rẹ̀ dà, o sì rán an lọ kúrò.

21Àwọn ọmọ rẹ̀ bọ́ sí ipò ọlá, òun kò sì mọ̀;

wọ́n sì rẹ̀ sílẹ̀, òun kò sì kíyèsi i lára wọn.

22Ṣùgbọ́n ẹran-ara rẹ̀ ni yóò rí

ìrora. Ọkàn rẹ̀ ni yóò sì máa ní ìbìnújẹ́ nínú rẹ̀.”

New International Reader’s Version

Job 14:1-22

1“Human beings have only a few days to live.

Their lives are full of trouble.

2They grow like flowers, and then they dry up.

They are like shadows that quickly disappear.

3“God, do you even notice them?

Will you let them appear in your court?

4Who can bring what is pure from something that isn’t pure?

No one!

5You decide how long anyone will live.

You have established the number of his months.

You have set a limit to the number of his days.

6So look away from him. Leave him alone.

Let him put in his time like a hired worker.

7“At least there is hope for a tree.

If it’s cut down, it will begin to grow again.

New branches will appear on it.

8Its roots may grow old in the ground.

Its stump may die in the soil.

9But when it smells water, it will begin to grow.

It will send out new growth like a plant.

10No man is like that. When he dies, he is buried in a grave.

He takes his last breath. Then he is gone.

11Water dries up from lakes.

Riverbeds become empty and dry.

12In the same way, people lie down and never get up.

People won’t wake or rise from their sleep

until the heavens are gone.

13“I wish you would hide me in a grave!

I wish you would cover me up until your anger passes by!

I wish you would set the time for me to spend in the grave

and then bring me back up!

14If someone dies, will they live again?

All the days of my hard work

I will wait for the time when you give me new life.

15You will call out to me, and I will answer you.

You will long for the person your hands have made.

16Then you will count every step I take.

But you won’t keep track of my sin.

17The wrong things I’ve done will be sealed up in a bag.

You will wipe out my sins by forgiving them.

18“A mountain wears away and crumbles.

A rock is moved from its place.

19Water wears away stones.

Storms wash away soil.

In the same way, you destroy a person’s hope.

20You overpower them completely, and then they’re gone.

You change the way they look and send them to their graves.

21If their children are honored, they don’t even know it.

If their children are dishonored, they don’t even see it.

22All they feel is the pain of their own bodies.

They are full of sadness only for themselves.”