Jobu 16 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 16:1-22

Ìdáhùn Jobu fún Elifasi

1Ìgbà náà ní Jobu dáhùn, ó sì wí pé:

2“Èmi ti gbọ́ irú ohun púpọ̀ bẹ́ẹ̀ rí

ayọnilẹ́nu onítùnú ènìyàn ní gbogbo yín.

3Ọ̀rọ̀ asán lè ni òpin?

Tàbí kí ni ó gbó ọ láyà tí ìwọ fi dáhùn?

4Èmi pẹ̀lú le sọ bí ẹ̀yin;

bí ọkàn yín bá wà ní ipò ọkàn mi,

èmi le sọ ọ̀rọ̀ dáradára púpọ̀ sí yín ní ọrùn,

èmi a sì mi orí mi sí i yín.

5Èmi ìbá fi ọ̀rọ̀ ẹnu mi gbà yín ni

ìyànjú, àti ṣíṣí ètè mi ìbá sì tu ìbìnújẹ́ yín.

6“Bí èmi tilẹ̀ sọ̀rọ̀, ìbìnújẹ́ mi kò lọ;

bí mo sì tilẹ̀ dákẹ́, níbo ni ìtùnú mí ko kúrò?

7Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó dá mi lágara;

Ìwọ Ọlọ́run mú gbogbo ẹgbẹ́ mi takété.

8Ìwọ fi ìhunjọ kùn mí lára, èyí tí o jẹ́rìí tì mí;

àti rírù tí ó hàn lára mi, ó jẹ́rìí tì mí ní ojú.

9Ọlọ́run fi i ìbínú rẹ̀ fà mí ya, ó sì gbóguntì mí;

ó pa eyín rẹ̀ keke sí mi,

ọ̀tá mi sì gbójú rẹ̀ sí mi.

10Wọ́n ti fi ẹnu wọn yẹ̀yẹ́ mi;

Wọ́n gbá mi ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ ni ìgbá ẹ̀gàn;

Wọ́n kó ara wọn pọ̀ sí mi.

11Ọlọ́run ti fi mí lé ọwọ́ ẹni

búburú, ó sì mú mi ṣubú sí ọwọ́ ènìyàn ìkà.

12Mo ti jókòó jẹ́ẹ́, ṣùgbọ́n ó fà mí já;

ó sì dì mí ni ọrùn mú, ó sì gbọ̀n mí túútúú,

ó sì gbé mi kalẹ̀ láti ṣe ààmì ìtafàsí rẹ̀;

13àwọn tafàtafà rẹ̀ dúró yí mi káàkiri.

Ó là mí láyà pẹ̀rẹ̀, kò si dá sí,

ó sì tú òróòro ara mi dà sílẹ̀.

14Ìbàjẹ́ lórí ìbàjẹ́ ní ó fi bà mí jẹ́;

ó súré kọlù mi bí jagunjagun.

15“Mo rán aṣọ ọ̀fọ̀ bò ara mi,

mo sì rẹ̀ ìwo mi sílẹ̀ nínú erùpẹ̀.

16Ojú mi ti pọ́n fún ẹkún,

òjìji ikú sì ṣẹ́ sí ìpéǹpéjú mi.

17Kì í ṣe nítorí àìṣòótọ́ kan ní ọwọ́

mi; àdúrà mi sì mọ́ pẹ̀lú.

18“Háà! Ilẹ̀ ayé, ìwọ má ṣe bò ẹ̀jẹ̀ mi,

kí ẹkún mi má ṣe wà ní ipò kan.

19Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi i, ẹlẹ́rìí mi ń bẹ ní ọ̀run,

ẹ̀rí mi sì ń bẹ lókè ọ̀run.

20Àwọn ọ̀rẹ́ mi ń fi mí ṣẹ̀sín,

ṣùgbọ́n ojú mi ń da omijé sọ́dọ̀ Ọlọ́run;

21Ìbá ṣe pé ẹnìkan le è máa ṣe alágbàwí fún ẹnìkejì lọ́dọ̀ Ọlọ́run,

bí ènìyàn kan ti í ṣe alágbàwí fún ẹnìkejì rẹ̀.

22“Nítorí nígbà tí iye ọdún díẹ̀ rékọjá tán,

nígbà náà ni èmi ó lọ sí ibi tí èmi kì yóò padà bọ̀.

New International Reader’s Version

Job 16:1-22

Job’s Reply

1Job replied,

2“I’ve heard many of these things before.

All of you are terrible at comforting me!

3Your speeches go on forever.

Won’t they ever end?

What’s wrong with you?

Why do you keep on arguing?

4If you and I changed places,

I could say the same things you are saying.

I could make fine speeches against you.

I could shake my head at you.

5But what I might say would give you hope.

My words of comfort would help you.

6“If I speak, it doesn’t help me.

And if I keep quiet, my pain doesn’t go away.

7God has worn me out completely.

He has destroyed my whole family.

8People can see the condition he has put me in.

My thin body stands as a witness against me.

9God is angry with me.

He attacks me and tears me up.

He grinds his teeth at me.

He stares at me as if he were my enemy.

10People make fun of me.

They slap my face and laugh at me.

All of them join together against me.

11God has turned me over to sinful people.

He has handed me over to them.

12Everything was going well with me.

But he broke me into pieces like a clay pot.

He grabbed me by the neck and crushed me.

He has taken aim at me.

13He shoots his arrows at me from all sides.

Without pity, he stabs me in the kidneys.

He spills my insides on the ground.

14He smashes through me as if I were a wall.

He rushes at me like a fighting man.

15“I’ve sewed rough clothing over my skin.

All I can do is sit here in the dust.

16My face is red from crying.

I have dark circles under my eyes.

17But I haven’t harmed anyone.

My prayers to God are pure.

18“Earth, please don’t cover up my blood!

May God always hear my cry for help!

19Even now my witness is in heaven.

The one who speaks up for me is there.

20My go-between is my friend

as I pour out my tears to God.

21He makes his appeal to God to help me

as a person pleads for a friend.

22“Only a few years will pass by.

Then I’ll take the path of no return.