Jobu 13 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 13:1-28

Jobu gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run

1“Wò ó, ojú mi ti rí gbogbo èyí rí,

etí mí sì gbọ́, ó sì ti yé mi.

2Ohun tí ẹ̀yin mọ̀, èmi mọ̀ pẹ̀lú,

èmi kò kéré sí i yin.

3Nítòótọ́ èmi ó bá Olódùmarè

sọ̀rọ̀, èmi sì ń fẹ́ bá Ọlọ́run sọ àsọyé.

4Ẹ̀yin fi irọ́ bá mi sọ̀rọ̀,

oníṣègùn lásán ni gbogbo yín.

5Háà! ẹ̀yin kì bá kúkú dákẹ́!

Èyí ni kì bá sì ṣe ọgbọ́n yín.

6Ẹ gbọ́ àwíyé mi nísinsin yìí;

ẹ sì fetísílẹ̀ sí àròyé ẹnu mi.

7Ẹ̀yin fẹ́ sọ ìsọkúsọ fún Ọlọ́run?

Ki ẹ sì fi ẹ̀tàn sọ̀rọ̀ gbè é?

8Ẹ̀yin fẹ́ ṣe ojúsàájú rẹ̀?

Ẹ̀yin fẹ́ gbèjà fún Ọlọ́run?

9Ó ha dára to tí yóò hú àṣírí yín síta,

Tàbí kí ẹ̀yin tàn án bí ẹnìkan ti í tan ẹnìkejì?

10Yóò máa bá yín wí nítòótọ́,

bí ẹ̀yin bá ṣe ojúsàájú ènìyàn níkọ̀kọ̀.

11Ìwà ọlá rẹ̀ kì yóò bà yín lẹ́rù bí?

Ìpayà rẹ̀ kì yóò pá yín láyà?

12Àwọn òwe yín dàbí eérú;

Bẹ́ẹ̀ ni àwọn odi ìlú yin dàbí amọ̀.

13“Ẹ pa ẹnu yín mọ́ kúrò lára mi, kí èmi kí ó lè sọ̀rọ̀,

ki ohun tí ń bọ̀ wá í bá mi, le è máa bọ̀.

14Ǹjẹ́ nítorí kí ni èmi ṣe ń fi eyín mi bu ẹran-ara mi jẹ,

Tí mo sì gbé ẹ̀mí mi lé ara mi lọ́wọ́?

15Bí ó tilẹ̀ pa mí, síbẹ̀ èmi ó máa gbẹ́kẹ̀lé e;

Ṣùgbọ́n èmi ó máa tẹnumọ́ ọ̀nà mi níwájú rẹ̀.

16Èyí ni yóò sì ṣe ìgbàlà mi,

Àgàbàgebè kì yóò wá síwájú rẹ̀.

17Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu mi ní ìfarabalẹ̀,

jẹ́ kí ọ̀rọ̀ mí dún ni etí yín.

18Wò ó nísinsin yìí, èmi ti mura ọ̀ràn mi sílẹ̀;

èmi mọ̀ pé a ó dá mi láre.

19Ta ni òun ti yóò bá mi ṣàròyé?

Ǹjẹ́ nísinsin yìí, èmi fẹ́ pa ẹnu mi mọ́,

èmi ó sì jọ̀wọ́ ẹ̀mí mi lọ́wọ́.

20“Ṣùgbọ́n, má ṣe ṣe ohun méjì yìí sí mi,

Nígbà náà ni èmi kì yóò sì fi ara mi pamọ́ kúrò fún ọ:

21Fa ọwọ́ rẹ sẹ́yìn kúrò lára mi,

má sì jẹ́ kí ẹ̀rù rẹ kí ó pá mi láyà.

22Nígbà náà ni kí ìwọ kí ó pè, èmi o sì dáhùn;

Ta ni jẹ́ kí ń máa sọ̀rọ̀, ki ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.

23Mélòó ní àìṣedéédéé àti ẹ̀ṣẹ̀ mi?

Mú mi mọ̀ ìrékọjá àti ẹ̀ṣẹ̀ mi.

24Nítorí kí ni ìwọ ṣe pa ojú rẹ mọ́,

tí o sì yàn mí ní ọ̀tá rẹ?

25Ìwọ ó fa ewé ti afẹ́fẹ́ ń fẹ́ síhìn-ín sọ́hùn-ún ya bi?

Ìwọ a sì máa lépa ìyàngbò?

26Nítorí pé ìwọ kọ̀wé ohun kíkorò sí mi,

o sì mú mi jogún àìṣedéédéé èwe mi.

27Ìwọ kàn àbà mọ́ mi lẹ́sẹ̀ pẹ̀lú,

ìwọ sì ń wò ipa ọ̀nà ìrìn mi ní àwòfín;

nípa fífi ìlà yí gígísẹ̀ mi ká.

28“Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn ń ṣègbé bí ohun ìdíbàjẹ́,

Bi aṣọ tí kòkòrò jẹ.

New International Reader’s Version

Job 13:1-28

1“My eyes have seen everything God has done.

My ears have heard it and understood it.

2What you know, I also know.

I’m as clever as you are.

3In fact, I long to speak to the Mighty One.

I want to argue my case with God.

4But you spread lies about me and take away my good name.

If you are trying to heal me,

you aren’t very good doctors!

5I wish you would keep your mouths shut!

Then people would think you were wise.

6Listen to my case.

Listen as I make my appeal.

7Will you say evil things in order to help God?

Will you tell lies for him?

8Do you want to be on God’s side?

Will you argue his case for him?

9Would it turn out well if he looked you over carefully?

Could you fool him as you might fool human beings?

10He would certainly hold you responsible

if you took his side in secret.

11Wouldn’t his glory terrify you?

Wouldn’t the fear of him fall on you?

12Your sayings are as useless as ashes.

The answers you give are as weak as clay.

13“So be quiet and let me speak.

Then I won’t care what happens to me.

14Why do I put myself in danger?

Why do I take my life in my hands?

15Even if God kills me, I’ll still put my hope in him.

I’ll argue my case in front of him.

16No matter how things turn out,

I’m sure I’ll still be saved.

After all, no ungodly person

would dare to come into his court.

17Listen carefully to what I’m saying.

Pay close attention to my words.

18I’ve prepared my case.

And I know I’ll be proved right.

19Can others bring charges against me?

If they can, I’ll keep quiet and die.

20“God, I won’t hide from you.

Here are the only two things I want.

21Stop treating me this way.

And stop making me so afraid.

22Then send for me, and I’ll answer.

Or let me speak, and you reply.

23How many things have I done wrong?

How many sins have I committed?

Show me my crime. Show me my sin.

24Why do you turn your face away from me?

Why do you think of me as your enemy?

25I’m already like a leaf that is blown by the wind.

Are you going to terrify me even more?

I’m already like dry straw.

Are you going to keep on chasing me?

26You write down bitter things against me.

You make me suffer for the sins

I committed when I was young.

27You put my feet in chains.

You watch every step I take.

You do it by putting marks on the bottom of my feet.

28“People waste away like something that is rotten.

They are like clothes that are eaten by moths.