Jobu 12 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 12:1-25

Ìdáhùn Jobu

1Jobu sì dáhùn, ó sì wí pé:

2“Kò sí àní àní níbẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni àwọn ènìyàn náà,

ọgbọ́n yóò sì kú pẹ̀lú yín!

3Ṣùgbọ́n èmi ní ìyè nínú gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin:

èmi kò kéré sí i yín:

àní, ta ni kò mọ gbogbo nǹkan wọ̀nyí?

4“Èmi dàbí ẹni tí a ń fi ṣe ẹlẹ́yà lọ́dọ̀ aládùúgbò rẹ̀,

tí ó ké pe Ọlọ́run, tí ó sì dá a lóhùn:

à ń fi olóòtítọ́ ẹni ìdúró ṣinṣin rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà.

5Ó rọrùn fún ènìyàn láti fi ìbànújẹ́ ẹlòmíràn ṣe ẹlẹ́yà,

gẹ́gẹ́ bí ìpín àwọn ẹni tí ẹsẹ̀ wọn ṣetán láti yọ̀.

6Àgọ́ àwọn ìgárá ọlọ́ṣà wá láìní ìbẹ̀rù;

àwọn tí ó sì ń mú Ọlọ́run bínú wà láìléwu,

àwọn ẹni tí ó sì gbá òrìṣà mú ní ọwọ́ wọn.

7“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí bí àwọn ẹranko léèrè, wọn o kọ́ ọ ní ẹ̀kọ́,

àti ẹyẹ ojú ọ̀run, wọn ó sì sọ fún ọ.

8Tàbí ba ilẹ̀ ayé sọ̀rọ̀, yóò sì kọ́ ọ,

àwọn ẹja inú Òkun yóò sì sọ fún ọ.

9Ta ni kò mọ̀ nínú gbogbo nǹkan

wọ̀nyí pé, ọwọ́ Olúwa ni ó ṣe nǹkan yìí?

10Ní ọwọ́ ẹni tí ẹ̀mí ohun alààyè gbogbo gbé wà,

Àti ẹ̀mí gbogbo aráyé.

11Etí kì í dán ọ̀rọ̀ wò bí

tàbí adùn ẹnu kì í sì í tọ́ oúnjẹ rẹ̀ wò bí?

12Àwọn arúgbó ni ọgbọ́n wà fún,

àti nínú gígùn ọjọ́ ni òye.

13“Ti Ọlọ́run ni ọgbọ́n àti agbára:

Òun ló ni ìmọ̀ àti òye.

14Kíyèsi i, ó bì wó, a kò sì lè gbe ró mọ́;

Ó sé ènìyàn mọ́, kò sì sí ìtúsílẹ̀ kan.

15Kíyèsi i, ó dá àwọn omi dúró, wọ́n sì gbẹ;

Ó sì rán wọn jáde, wọ́n sì ṣẹ̀ bo ilẹ̀ ayé yípo.

16Tìrẹ ni agbára àti ìṣẹ́gun;

Ẹni tí ń ṣìnà àti ẹni tí ń mú ni ṣìnà, tirẹ̀ ni wọ́n ń ṣe.

17Ó mú àwọn ìgbìmọ̀ lọ ní ìhòhò,

A sì sọ àwọn onídàájọ́ di òmùgọ̀.

18Ó tú ìdè ọba,

Ó sì fi àmùrè gbà wọ́n ní ọ̀já.

19Ó mú àwọn àlùfáà lọ ní ìhòhò,

Ó sì tẹ orí àwọn alágbára ba.

20Ó mú ọ̀rọ̀ ẹnu ẹni ìgbẹ́kẹ̀lé kúrò,

Ó sì ra àwọn àgbàgbà ní iyè.

21Ó bu ẹ̀gàn lu àwọn ọmọ ọlọ́lá,

Ó sì tú àmùrè àwọn alágbára.

22Ó hú ìdí ohun ìjìnlẹ̀ jáde láti inú òkùnkùn wá,

Ó sì mú òjìji ikú wá sínú ìmọ́lẹ̀.

23Òun a mú orílẹ̀-èdè bí sí i, a sì run wọ́n;

Òun a sọ orílẹ̀-èdè di ńlá, a sì tún ṣẹ̀ wọn kù.

24Òun a gba òye àwọn olórí àwọn ènìyàn aráyé,

A sì máa mú wọn rin kiri nínú ijù níbi tí ọ̀nà kò sí.

25Wọn a máa fi ọwọ́ ta ilẹ̀ nínú òkùnkùn níbi tí kò sí ìmọ́lẹ̀,

Òun a sì máa mú ìrìn ìsìn wọn bí ọ̀mùtí.

New International Reader’s Version

Job 12:1-25

Job’s Reply

1Job replied,

2“You people think you are the only ones who matter!

You are sure that wisdom will die with you!

3But I have a brain, just like you.

I’m as clever as you are.

In fact, everyone knows as much as you do.

4“My friends laugh at me all the time,

even though I called out to God and he answered.

My friends laugh at me,

even though I’m honest and right.

5People who have an easy life look down on those who have problems.

They think trouble comes only to those whose feet are slipping.

6Why doesn’t anyone bother the tents of robbers?

Why do those who make God angry remain secure?

They are in God’s hands!

7“But ask the animals what God does.

They will teach you.

Or ask the birds in the sky.

They will tell you.

8Or speak to the earth. It will teach you.

Or let the fish in the ocean educate you.

9Are there any of these creatures that don’t know

what the powerful hand of the Lord has done?

10He holds the life of every creature in his hand.

He controls the breath of every human being.

11Our tongues tell us what tastes good and what doesn’t.

And our ears tell us what’s true and what isn’t.

12Old people are wise.

Those who live a long time have understanding.

13“Wisdom and power belong to God.

Advice and understanding also belong to him.

14What he tears down can’t be rebuilt.

The people he puts in prison can’t be set free.

15If he holds back the water, everything dries up.

If he lets the water loose, it floods the land.

16Strength and understanding belong to him.

Those who tell lies and those who believe them also belong to him.

17He removes the wisdom of rulers and leads them away.

He makes judges look foolish.

18He sets people free from the chains that kings put on them.

Then he dresses the kings in the clothes of slaves.

19He removes the authority of priests and leads them away.

He removes from their positions

officials who have been in control for a long time.

20He shuts the mouths of trusted advisers.

He takes away the understanding of elders.

21He looks down on proud leaders.

He takes away the strength of those who are mighty.

22He tells people the secrets of darkness.

He brings total darkness out into the light.

23He makes nations great, and then he destroys them.

He makes nations grow, and then he scatters them.

24He takes away the understanding of the leaders of the earth.

He makes them wander in a desert where no one lives.

25Without any light, they feel their way along in darkness.

God makes them unsteady like those who get drunk.