Jeremiah 51 – YCB & CCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 51:1-64

1Ohùn ti Olúwa wí nìyìí:

“Wò ó èmi yóò ru afẹ́fẹ́ apanirun sókè

sí Babeli àti àwọn ènìyàn Lebikamai

2Èmi yóò rán àwọn àjèjì ènìyàn sí Babeli

láti fẹ́ ẹ, tí yóò sì sọ ilẹ̀ rẹ̀ di òfo;

wọn yóò takò ó ní gbogbo ọ̀nà

ní ọjọ́ ìparun rẹ̀.

3Má ṣe jẹ́ kí tafàtafà yọ ọfà rẹ̀

jáde tàbí kí ó di ìhámọ́ra rẹ̀;

má ṣe dá àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin

sí, pátápátá ni kí o pa àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.

4Gbogbo wọn ni yóò ṣubú

ní Babeli tí wọn yóò sì

fi ara pa yánnayànna ní òpópónà.

5Nítorí pé Juda àti Israẹli ni

Ọlọ́run wọn tí í ṣe Olúwa àwọn ọmọ-ogun,

kò gbàgbọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ilé wọn

kún fún kìkì ẹ̀bi níwájú ẹni mímọ́ Israẹli.

651.6,9,45: Jr 50.8; 2Kọ 6.17; If 18.4.“Sá kúrò ní Babeli! Sá àsálà

fún ẹ̀mí rẹ! Má ṣe ṣègbé torí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.

Àsìkò àti gbẹ̀san Ọlọ́run ni èyí,

yóò sán fún òun gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́.

751.7-8: Jr 25.15; If 14.8,10; 16.19; 17.4; 18.3.Ife wúrà ni Babeli ní ọwọ́ Olúwa;

ó sọ gbogbo ayé di ọ̀mùtí.

Gbogbo orílẹ̀-èdè mu ọtí rẹ̀,

wọ́n sì ti ya òmùgọ̀ kalẹ̀.

8Babeli yóò ṣubú lójijì, yóò sì fọ́;

Ẹ hu fun un!

Ẹ mú ìkunra fún ìrora rẹ,

bóyá yóò le wo ọ́ sàn.

9“ ‘À bá ti wo Babeli sàn,

ṣùgbọ́n kò lè sàn, ẹ jẹ́ kí a fi sílẹ̀,

kí oníkálùkù lọ sí ilẹ̀ rẹ̀ torí ìdájọ́ rẹ̀ tó gòkè,

ó ga àní títí dé òfúrufú.’

10“ ‘Olúwa ti dá wa láre,

wá jẹ́ kí a sọ ọ́ ní Sioni ohun tí Olúwa

Ọlọ́run wa ti ṣe.’

11“Ṣe ọfà rẹ ní mímú,

mú apata!

Olúwa ti ru ọba Media sókè,

nítorí pé ète rẹ̀ ni láti pa Babeli run.

Olúwa yóò gbẹ̀san, àní ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.

12Gbé àsíá sókè sí odi Babeli!

Ẹ ṣe àwọn ọmọ-ogun gírí,

ẹ pín àwọn olùṣọ́ káàkiri,

ẹ ṣètò àwọn tí yóò sápamọ́

Olúwa! Yóò gbé ète rẹ̀ jáde,

òfin rẹ̀ sí àwọn ará Babeli.

1351.13: If 17.1.Ìwọ tí o gbé lẹ́bàá odò púpọ̀,

tí o sì ni ọ̀rọ̀ púpọ̀; ìgbẹ̀yìn rẹ ti dé,

àní àsìkò láti ké ọ kúrò!

14Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra fún ara rẹ̀,

Èmi yóò fún ọ ní ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ eṣú,

wọn yóò yọ ayọ̀, ìṣẹ́gun lórí rẹ.

15“Ó dá ilẹ̀ nípa agbára rẹ̀,

o dá ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀,

o sì tẹ́ ọ̀run pẹ̀lú ìmọ̀ rẹ̀.

16Nígbà tí ará omi ọ̀run hó

ó mú kí òfúrufú ru sókè láti ìpẹ̀kun ayé.

Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò,

ó sì mú afẹ́fẹ́ jáde láti ilé ìṣúra rẹ̀.

17“Olúkúlùkù ènìyàn ni kò lọ́pọlọ

tí kò sì ní ìmọ̀, olúkúlùkù

alágbẹ̀dẹ ni a kó ìtìjú bá nípa òrìṣà rẹ̀.

Àwọn ère rẹ jẹ́ ẹ̀tàn wọn kò ní èémí nínú.

18Asán ni wọ́n, àti iṣẹ́ ìsìnà,

nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn ó ṣègbé.

19Ẹni tí ó jẹ́ ìpín Jakọbu kó rí bí ìwọ̀nyí;

nítorí òun ni ó dá ohun gbogbo,

àti gbogbo àwọn ẹ̀yà ajogún,

Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.

20“Ìwọ ni kùmọ̀ ogun ohun èlò ogun mi,

ohun èlò ìjà mi, pẹ̀lú rẹ èmi ó fọ́ orílẹ̀-èdè túútúú,

èmi ó bà àwọn ilé ọba jẹ́.

21Pẹ̀lú rẹ, èmi ó pa ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún pẹ̀lú rẹ̀;

èmi ó ba kẹ̀kẹ́ ogun jẹ́ pẹ̀lú

èmi ó pa awakọ̀

22Pẹ̀lú rẹ, mo pa ọkùnrin àti obìnrin,

pẹ̀lú rẹ, mo pa

àgbàlagbà àti ọmọdé,

Pẹ̀lú rẹ, mo pa ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin.

23Èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ olùṣọ́-àgùntàn,

àti agbo àgùntàn rẹ̀ túútúú,

èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ àgbẹ̀ àti àjàgà màlúù túútúú,

èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ baálẹ̀ àti àwọn ìjòyè rẹ̀ túútúú.

24“Ní ojú rẹ, èmi yóò san án fún Babeli àti gbogbo àwọn olùgbé inú rẹ̀ fún gbogbo ibi tí wọ́n ti ṣe ní Sioni,”

ni Olúwa wí.

25“Mo lòdì sí ọ, ìwọ òkè apanirun

ìwọ ti ba gbogbo ayé jẹ́,”

ni Olúwa wí.

“Èmi ó na ọwọ́ mi sí ọ,

èmi yóò yí ọ kúrò lórí àpáta,

Èmi yóò sọ ọ́ dàbí òkè tí a ti jó.

26A kò ní mú òkúta kankan láti

ọ̀dọ̀ rẹ̀ lò gẹ́gẹ́ bí igun ilé tàbí

fún ìpínlẹ̀ nítorí pé ìwọ yóò di

ahoro títí ayé,”

Olúwa wí.

27“Gbé àsíá sókè ní ilẹ̀ náà!

Fọn ìpè láàrín àwọn orílẹ̀-èdè!

Sọ àwọn orílẹ̀-èdè di mímọ́ sórí rẹ̀,

pe àwọn ìjọba yìí láti dojúkọ ọ́:

Ararati, Minini àti Aṣkenasi.

Yan olùdarí ogun láti kọlù ú,

rán àwọn ẹṣin sí i bí ọ̀pọ̀ eṣú.

28Sọ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú àwọn ọba Media di mímọ́ sórí rẹ̀,

àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀,

àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọ́n jẹ ọba lé lórí.

29Ilẹ̀ wárìrì síhìn-ín sọ́hùn-ún, nítorí pé

ète Olúwa, sí Babeli dúró

láti ba ilẹ̀ Babeli jẹ́ lọ́nà

tí ẹnikẹ́ni kò ní lè gbé inú rẹ̀ mọ́.

30Gbogbo àwọn jagunjagun

Babeli tó dáwọ́ ìjà dúró sínú àgọ́ wọn.

Agbára wọn ti tán, wọ́n ti dàbí obìnrin.

Ibùgbé rẹ̀ ni a ti dáná sun,

gbogbo irin ẹnu-ọ̀nà wọn ti di fífọ́.

31Ìránṣẹ́ kan ń tẹ̀lé òmíràn

láti sọ fún ọba Babeli pé

gbogbo ìlú rẹ̀ ni a ti kó ní ìgbèkùn.

32Odò tí ó sàn kọjá kò sàn mọ́

ilẹ̀ àbàtà gbiná, àwọn jagunjagun sì wárìrì.”

33Ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli sọ nìyìí:

“Ọmọbìnrin Babeli dàbí ìpakà àsìkò láti kórè rẹ̀ kò ní pẹ́ dé mọ́.”

34“Nebukadnessari ọba Babeli tó jẹ wá run,

ó ti mú kí ìdààmú bá wa,

ó ti sọ wá di àgbá òfìfo.

Gẹ́gẹ́ bí ejò, ó ti gbé wa mì.

Ó fi oúnjẹ àdídùn wa kún inú rẹ̀,

lẹ́yìn náà ni ó pọ̀ wá jáde.

35Kí gbogbo ìparun tí ó ṣe sí ẹran-ara wa wà lórí Babeli,”

èyí tí àwọn ibùgbé Sioni wí.

“Kí ẹ̀jẹ̀ wa wà lórí gbogbo àwọn tí ń gbé Babeli,”

ni Jerusalẹmu wí.

36Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí:

“Wò ó, èmi yóò tì ọ́ lẹ́yìn lórí

ohun tí o fẹ́ ṣe. Èmi ó sì gbẹ̀san,

èmi yóò mú kí omi Òkun rẹ̀ àti orísun omi rẹ̀ gbẹ.

37Babeli yóò parun pátápátá,

yóò sì di ihò àwọn akátá,

ohun ẹ̀rù àti àbùkù, ibi tí ènìyàn kò gbé.

38Àwọn ènìyàn inú rẹ̀ bú ramúramù

bí ọmọ kìnnìún.

39Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkàn wọn bá ru sókè,

èmi yóò ṣe àsè fún wọn,

èmi yóò jẹ́ kí wọn mutí yó

tí wọn yóò máa kọ fun ẹ̀rín,

lẹ́yìn náà, wọn yóò sun oorun, wọn kì yóò jí,”

ni Olúwa wí.

40“Èmi yóò fà wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́-àgùntàn

tí a fẹ́ pa, gẹ́gẹ́ bí àgbò àti ewúrẹ́.

41“Báwo ni Ṣeṣaki yóò ṣe dí mímú, ìfọ́nnu gbogbo àgbáyé.

Irú ìpayà wo ni yóò bá

Babeli láàrín àwọn orílẹ̀-èdè!

42Òkun yóò ru borí Babeli,

gbogbo rírú rẹ̀ yóò borí Babeli.

43Àwọn ìlú rẹ̀ yóò di ahoro,

ilẹ̀ tí ó gbẹ, ilẹ̀ tí ènìyàn

kò gbé tí ènìyàn kò sì rin ìrìnàjò.

44Èmi yóò fi ìyà jẹ Beli ti Babeli

àti pé èmi yóò jẹ́ kí ó pọ gbogbo àwọn ohun tí ó gbé mì.

Àwọn orílẹ̀-èdè kì yóò jùmọ̀ sàn lọ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ mọ́.

Ní òótọ́ odi Babeli yóò sì wó.

45“Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀

ẹ̀yin ènìyàn mi!

Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ!

Sá fún ìbínú ńlá Ọlọ́run.

46Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ dàrú

tàbí kí o bẹ̀rù nígbà tí

a bá gbọ́ àhesọ ọ̀rọ̀ ní ilẹ̀ wa;

àhesọ ọ̀rọ̀ kan wá ní ọdún yìí,

òmíràn ní ọdún mìíràn àhesọ ọ̀rọ̀ ni ti ìwà ipá

ní ilẹ̀ náà àti tí aláṣẹ kan sí aláṣẹ kejì.

47Nítorí ìgbà náà yóò wá

dandan nígbà tí èmi

yóò fi ìyà jẹ àwọn

òrìṣà Babeli, gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ni a ó dójútì

gbogbo àwọn tí a pa yóò sì ṣubú ní àárín rẹ̀.

48Ọ̀run àti ayé àti gbogbo ohun tí ó wà nínú wọn,

yóò sì kọrin lórí Babeli:

nítorí àwọn afiniṣèjẹ yóò wá sórí rẹ̀ láti àríwá,”

ni Olúwa wí.

49“Babiloni gbọdọ̀ ṣubú nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni Israẹli,

gẹ́gẹ́ bí àwọn ti a pa ní gbogbo ayé nítorí Babeli.

50Ẹ̀yin tí ó ti bọ́ lọ́wọ́ idà, ẹ lọ, ẹ má dúró:

Ẹ rántí Olúwa ní òkèrè,

ẹ sì jẹ́ kí Jerusalẹmu wá sí ọkàn yín.”

51“Ojú tì wá, nítorí pé àwa ti gbọ́ ẹ̀gàn:

ìtìjú ti bò wá lójú

nítorí àwọn àjèjì wá sórí ohun mímọ́ ilé Olúwa.”

52“Nítorí náà, wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí,

“tí èmi yóò ṣe ìbẹ̀wò lórí àwọn ère fínfín rẹ̀:

àti àwọn tí ó gbọgbẹ́ yóò sì máa kérora já gbogbo ilẹ̀ rẹ̀

53Bí Babeli tilẹ̀ gòkè lọ sí ọ̀run,

bí ó sì ṣe ìlú olódi ní òkè agbára rẹ,

síbẹ̀ àwọn afiniṣèjẹ yóò ti ọ̀dọ̀ mi tọ̀ ọ́ wá,”

Olúwa wí.

54“Ìró igbe láti Babeli,

àti ìparun láti ilẹ̀ àwọn ará Kaldea!

55Nítorí pé Olúwa ti ṣe Babeli ní ìjẹ,

ó sì ti pa ohun ńlá run kúrò nínú rẹ̀;

àwọn ọ̀tá wọn sì ń hó bi omi púpọ̀, a gbọ́ ariwo ohùn wọn.

56Nítorí pé afiniṣèjẹ dé sórí rẹ̀,

àní sórí Babeli;

a mú àwọn akọni rẹ̀, a ṣẹ́ gbogbo ọrun wọn:

nítorí Ọlọ́run ẹ̀san ni Olúwa,

yóò san án nítòótọ́.

57Èmi ó sì mú kí àwọn ìjòyè rẹ̀ yó bí ọ̀mùtí,

àti àwọn ọlọ́gbọ́n rẹ̀

àti àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti àwọn akọni rẹ̀,

wọn ó sì sun oorun láéláé, wọn kì ó sì jí mọ́,”

ní ọba wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.

58Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí:

“Odi Babeli gbígbòòrò ní a ó wó lulẹ̀ pátápátá,

ẹnu-bodè gíga rẹ̀ ní a ó sì fi iná sun:

tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ènìyàn ti ṣiṣẹ́ lásán,

àti àwọn orílẹ̀-èdè ti ṣiṣẹ́ fún iná,

tí àárẹ̀ sì mú wọn.”

59Ọ̀rọ̀ tí Jeremiah wòlíì pàṣẹ fún Seraiah, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, nígbà tí o ń lọ ni ti Sedekiah, ọba Juda, sí Babeli ní ọdún kẹrin ìjọba rẹ̀. Seraiah yìí sì ní ìjòyè ibùdó. 60Jeremiah sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ ibi tí yóò wá sórí Babeli sínú ìwé kan, àní gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí tí a kọ sí Babeli. 61Jeremiah sì sọ fún Seraiah pé, “nígbà tí ìwọ bá dé Babeli, kí ìwọ kí ó sì wò, kí ìwọ kí ó sì ka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí. 62Kí ìwọ kí ó sì wí pé, ‘Olúwa ìwọ ti sọ̀rọ̀ sí ibí yí, láti ké e kúrò, kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé inú rẹ̀, àti ènìyàn àti ẹran, nítorí pé yóò di ahoro láéláé.’ 6351.63-64: If 18.21.Yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ bá parí kíka ìwé yìí tán kí ìwọ kí ó di òkúta mọ́ ọn, kí ó sì sọ ọ́ sí àárín odò Eufurate. 64Kí ìwọ sì wí pé, ‘Báyìí ní Babeli yóò rì, kí yóò sì tún dìde kúrò nínú ibi tí èmi ó mú wá sórí rẹ̀: àárẹ̀ yóò sì mú wọn.’ ”

Títí dé ìhín ni ọ̀rọ̀ Jeremiah.

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

耶利米书 51:1-64

1耶和华说:

“看啊,我要使毁灭的暴风袭击巴比伦和住在立加米的人。

2毁灭巴比伦人的日子一到,

我要差遣外族人从四面八方攻击、消灭他们,

如同狂风卷走碎秸。

3不要让他们的弓箭手有机会射箭,

不要让他们的战士有机会穿铠甲,

不要放过他们的青年,

要使他们全军覆没。

4他们将被刀剑刺透,

倒毙在自己的土地上,

横尸街头。

5虽然以色列犹大充满罪恶,

得罪了他们的圣者,

但他们的上帝——万军之耶和华却没有撇弃他们。

6“离开巴比伦,各自逃命吧!

不要让她的罪恶连累你们,

以致你们灭亡,

这是耶和华报应她的时候,

耶和华要惩罚她。

7巴比伦在耶和华手中曾是灌醉天下的金杯,

列国喝了她的酒都变得癫狂。

8转瞬之间,巴比伦必毁灭。

你们要为她哀悼,

拿药为她止痛,

或许可以治好她。

9寄居在巴比伦的人说,

‘我们试过了,却没有治好。

我们离开她,各自返回故乡吧!

因为她罪恶滔天,必受审判。

10耶和华已为我们申冤。

来吧!我们要在锡安述说我们上帝耶和华的作为。’

11“因为巴比伦人毁灭了耶和华的殿,

耶和华要使玛代诸王毁灭他们。

玛代人啊,

要磨尖箭头,拿起盾牌,

12竖起旗帜,

攻打巴比伦的城墙;

要加强防卫,

派人巡逻,设下埋伏。

因为耶和华言出必行,

一定要惩罚巴比伦人。

13住在河边、拥有财宝的巴比伦人啊,

你们的结局到了,

你们的末日来了。”

14万军之耶和华凭自己起誓说:

“我要使敌人如蝗虫一样铺天盖地而来,

占据你们的家园,

欢呼胜利。”

15耶和华用自己的能力创造大地,

以自己的智慧建立世界,

凭自己的聪明铺展穹苍。

16祂一声令下,天上便大水澎湃;

祂使云雾从地极上升,

使闪电在雨中划过,

使风从祂的仓库吹出。

17世人都愚昧无知,

工匠都因所制的偶像而羞愧,

因为神像没有生命气息,

是虚假的,

18毫无益处,荒唐可笑,

刑罚一到,必被毁灭。

19雅各的上帝51:19 雅各的上帝”希伯来文是“雅各的产业”。却迥然不同,

因为祂创造万物,

以色列人是祂的产业,

祂名叫“万军之耶和华”。

20耶和华说:

巴比伦啊!你是我的锤子,

我作战的兵器,

我要用你打碎列国,

毁灭列邦。

21我要用你打碎战马和骑士,

22打碎战车和车夫,

打碎男人和妇女,

打碎老人和小孩,

打碎少男和少女,

23打碎牧人和牲畜,

打碎农夫和耕牛,

打碎省长和总督。”

24耶和华说:“我要当着我子民的面报应巴比伦51:24 巴比伦人”希伯来文是“巴比伦和迦勒底人”。,因为他们在锡安犯罪作恶。

25“毁灭天下的大山——巴比伦啊,

我与你为敌,

我要伸手攻击你,

把你从悬崖上滚下去,

使你化为灰烬。

这是耶和华说的。

26再无人用你的石头做房角石或基石,

你要永远荒凉。

这是耶和华说的。

27“要在大地上竖起旌旗,

在列国吹响号角,

让他们预备攻打巴比伦

要召集亚拉腊人、米尼人、

亚实基拿人,

使他们派遣将领率骑兵如蝗虫一样铺天盖地而来,

攻打巴比伦

28要让列国预备攻打巴比伦

使玛代的诸王及其省长、总督和所统治的人攻打巴比伦

29大地要颤抖,痛苦地扭动,

因为耶和华决意要攻击巴比伦

使她荒无人烟。

30巴比伦的勇士不再作战,

躲在堡垒里,

士气消沉,像妇女一样无力;

巴比伦的房屋被火焚烧,

城门被攻破。

31报信的人接踵而来,

巴比伦王禀告,

‘整座城已失守,

32渡口被占,

沼泽地被烧,

战士惊慌失措。’”

33以色列的上帝——万军之耶和华说:

巴比伦城快要被毁灭了,

它要被夷为平地,

好像被踏平的麦场一样。”

34以色列人说:

巴比伦尼布甲尼撒吞噬我们、击垮我们,

把我们洗劫一空。

他像海怪一样吞吃我们,

饱餐我们的美物,

然后把我们赶走。”

35锡安的居民说:

巴比伦人残暴地对待我们,

愿他们受报应。”

耶路撒冷人说:

“愿迦勒底人偿还我们的血债。”

36耶和华说:

“我的子民啊,

我要为你们申冤,

替你们报仇;

我要使巴比伦的江河枯竭,

泉源干涸。

37巴比伦必沦为废墟,杳无人迹,

沦为豺狼出没的地方,

令人惊惧、嗤笑。

38迦勒底人像群狮一样怒吼,

又像幼狮一样咆哮。

39他们食欲大振时,

我要为他们设盛宴,

使他们酩酊大醉,狂欢乱叫,

长眠不起。

这是耶和华说的。

40我要把他们像羊羔、

公绵羊和公山羊一样带往宰杀之地。

41巴比伦51:41 巴比伦”希伯来文是“示沙克”,巴比伦的别名。怎么沦陷了!

天下引以为傲的怎么被攻占了!

巴比伦的下场让列国恐惧!

42海水涨溢,汹涌的波涛淹没了巴比伦

43她的城邑沦为干旱的荒漠,

杳无人迹。

44我要惩罚巴比伦的神明彼勒

使他吐出所吞噬的。

巴比伦的城墙要倒塌,

万国必不再涌向她。

45“我的子民啊,你们要离开巴比伦

各自逃命,躲避耶和华的烈怒。

46境内谣言四起时,

你们不要惊慌害怕,

因为今年传这风声,

明年却传那风声,

说境内必有暴乱,

官长要互相残杀。

47“看啊,时候将到,我必惩罚巴比伦的神像,

使巴比伦全国蒙羞,

尸横遍野。

48毁灭者要从北方前来攻击巴比伦

那时天地万物都要因巴比伦的灭亡而欢呼。

这是耶和华说的。

49巴比伦必灭亡,

因为她大肆屠杀以色列人和其他各国的人。

50“刀下逃生的人啊,

你们快走吧!

不要停留!

在远方要记住耶和华,

要追想耶路撒冷

51你们说巴比伦人闯入了耶和华殿的圣所,

使你们蒙受耻辱,满面羞愧。

52“看啊,时候将到,我要惩罚巴比伦的神像,

使巴比伦到处都是受伤者的呻吟。

这是耶和华说的。

53即使巴比伦城高耸入云,

堡垒坚不可摧,

我仍要差遣毁灭者攻击它。

这是耶和华说的。

54“从巴比伦——迦勒底人的土地上传来哭喊声和毁灭声,

55因为耶和华正在毁灭巴比伦

要使城中的喧嚣变成一片死寂。

毁灭巴比伦的敌人呐喊着如波涛一样涌来。

56毁灭者正前来攻打巴比伦

擒拿她的勇士,

折断他们的弓弩。

耶和华是追讨罪恶、

报应恶人的上帝。

57我要使她的首领、谋士、省长、

总督和勇士都酩酊大醉,

长眠不醒。”

这是君王——万军之耶和华说的。

58万军之耶和华说:

巴比伦宽阔的城墙要被夷为平地,

高大的城门要被付之一炬,

人们一切的辛劳都是徒然,

列国劳碌的成果都化为灰烬。”

59-60耶利米把所有将要发生在巴比伦的灾祸,就是有关巴比伦的事都写在卷轴上。犹大西底迦执政第四年,玛西雅的孙子、尼利亚的儿子、宫廷总管西莱雅犹大王一同前往巴比伦的时候, 61耶利米西莱雅说:“你到巴比伦后要大声宣读这卷轴上的一切话, 62并且要说,‘耶和华啊!你曾说要毁灭这地方,使这里人兽绝迹、永远荒凉。’ 63读完后,你要把卷轴绑在一块石头上,扔进幼发拉底河, 64然后说,‘耶和华降的灾祸必使巴比伦像这卷轴一样沉没、永不复兴,巴比伦人必灭亡。’”

耶利米的话到此为止。