Ẹkun Jeremiah 1 – YCB & CCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Ẹkun Jeremiah 1:1-22

1Báwo ni ìlú ṣe jókòó nìkan,

nígbà kan tí ó sì kún fún ènìyàn!

Ó ti fìgbà kan jẹ́ ìlú olókìkí láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,

tí ó wà ní ipò opó,

Ẹni tí ó jẹ́ ọmọ ọbabìnrin láàrín ìlú

ni ó padà di ẹrú.

2Ọ̀gànjọ́ òru ni ó fi máa ń sọkún kíkorò

pẹ̀lú omijé ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀ tí ó dúró sí ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀.

Nínú gbogbo àwọn olólùfẹ́ rẹ̀

kò sí ọ̀kan nínú wọn láti rẹ̀ ẹ́ lẹ́kún.

Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ ti jọ̀wọ́ rẹ̀

wọ́n ti di alátakò rẹ̀.

3Lẹ́yìn ìjìyà àti ìpọ́njú nínú oko ẹrú,

Juda lọ sí àjò

Ó tẹ̀dó láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,

ṣùgbọ́n kò rí ibi ìsinmi.

Àwọn tí ó ń tẹ̀lé ká á mọ́

ibi tí kò ti le sá àsálà.

4Gbogbo ọ̀nà tí ó wọ Sioni ń ṣọ̀fọ̀,

nítorí ẹnìkan kò wá sí àjọ̀dún tí a yàn.

Gbogbo ẹnu-bodè rẹ̀ dahoro,

àwọn àlùfáà rẹ̀ kẹ́dùn,

àwọn wúńdíá rẹ̀ sì ń káàánú,

òun gan an wà ní ọkàn kíkorò.

5Àwọn aninilára rẹ̀ gbogbo di olúwa rẹ̀,

nǹkan sì rọrùn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀,

Olúwa ti fún un ní ìjìyà tó tọ́

nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.

Àwọn ẹ̀ṣọ́ wẹ́wẹ́ rẹ̀ lọ sí oko ẹrú,

ìgbèkùn níwájú àwọn ọ̀tá.

6Gbogbo ẹwà ti di ohun ìgbàgbé

kúrò lọ́dọ̀ ọmọbìnrin Sioni.

Àwọn ìjòyè rẹ̀ dàbí i àgbọ̀nrín

tí kò rí ewé tútù jẹ;

nínú àárẹ̀ wọ́n sáré

níwájú ẹni tí ó ń lé wọn.

7Ní ọjọ́ ìpọ́njú àti àrìnká rẹ̀ ni

Jerusalẹmu rántí àwọn ohun ìní dáradára rẹ̀

tí ó jẹ́ tirẹ̀ ní ọjọ́ pípẹ́.

Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ṣubú ṣọ́wọ́ àwọn ọ̀tá,

kò sì ṣí olùrànlọ́wọ́ fún un.

Àwọn ọ̀tá rẹ̀ wò ó

wọ́n sì ń fi ìparun rẹ̀ ṣẹlẹ́yà.

8Jerusalẹmu sì ti dẹ́ṣẹ̀ púpọ̀

ó sì ti di aláìmọ́.

Àwọn tí ó ń tẹríba fún un sì kẹ́gàn rẹ̀,

nítorí wọ́n ti rí ìhòhò rẹ̀;

ó kérora fúnrarẹ̀,

ó sì lọ kúrò.

9Ìdọ̀tí wà ní etí aṣọ rẹ̀,

bẹ́ẹ̀ ni kò wo ọjọ́ iwájú rẹ̀,

Ìṣubú rẹ̀ ya ni lẹ́nu;

olùtùnú kò sì ṣí fún un.

“Wo ìpọ́njú mi, Olúwa,

nítorí àwọn ọ̀tá ti borí.”

10Ọ̀tá ti gbọ́wọ́ lé

gbogbo ìní rẹ;

o rí pé àwọn orílẹ̀-èdè

tí wọ́n wọ ibi mímọ́ rẹ—

àwọn tí o ti kọ̀sílẹ̀

láti wọ ìpéjọpọ̀ rẹ.

11Àwọn ènìyàn rẹ̀ ń kérora

bí wọ́n ti ń wá oúnjẹ;

wọ́n fi ohun ìní wọn ṣe pàṣípàrọ̀ oúnjẹ

láti mú wọn wà láààyè.

“Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó,

nítorí a kọ̀ mí sílẹ̀.”

12“Kò ha jẹ́ nǹkan kan sí i yín?

Gbogbo ẹ̀yin tí ń rékọjá,

Ǹjẹ́ ẹnìkan ń jìyà bí èmi ti ń jìyà

tí a fi fún mi, ti

Olúwa mú wá fún mi

ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná rẹ̀.

13“Ó rán iná láti òkè

sọ̀kalẹ̀ sínú egungun ara mi.

Ó dẹ àwọ̀n fún ẹsẹ̀ mi,

ó sì yí mi padà.

Ó ti pa mí lára

mó ń kú lọ ní gbogbo ọjọ́.

14“Ẹ̀ṣẹ̀ mi ti di sísopọ̀ sí àjàgà;

ọwọ́ rẹ̀ ni a fi hun ún papọ̀.

Wọ́n ti yí ọrùn mi ká

Olúwa sì ti dín agbára mi kù.

Ó sì ti fi mí lé

àwọn tí n kò le dojúkọ lọ́wọ́.

15“Olúwa kọ

àwọn akọni mi sílẹ̀,

ó rán àwọn ológun lòdì sí mi

kí wọn pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin mi run.

Nínú ìfúntí wáìnì rẹ̀ Olúwa tẹ́

àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Juda.

16“Ìdí nìyí tí mo fi ń sọkún

tí omijé sì ń dà lójú mi,

Olùtùnú àti ẹni tí ó le mú ọkàn mi sọjí jìnnà sí mi,

kò sí ẹni tí yóò dá ẹ̀mí mi padà.

Àwọn ọmọ mi di aláìní

nítorí ọ̀tá ti borí.”

17Sioni na ọwọ́ jáde,

ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún un.

Olúwa ti pàṣẹ fún Jakọbu

pé àwọn ará ilé rẹ̀ di ọ̀tá fún un

Jerusalẹmu ti di

ohun aláìmọ́ láàrín wọn.

18“Olóòtítọ́ ni Olúwa,

ṣùgbọ́n mo ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀.

Ẹ gbọ́, gbogbo ènìyàn;

ẹ wò mí wò ìyà mi.

Gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin mi

ni a ti kó lọ sí ìgbèkùn.

19“Mo pe àwọn ọ̀rẹ́ mi

ṣùgbọ́n wọ́n dà mí.

Àwọn olórí àlùfáà àti àgbàgbà mi

ṣègbé sínú ìlú

nígbà tí wọ́n ń wá oúnjẹ

tí yóò mú wọn wà láààyè.

20Olúwa, wò ó, bí mo ti wà nínú ìnira!

Tí mo sì ń jẹ̀rora nínú mi,

ìdààmú dé bá ọkàn mi

nítorí pé a ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi gidigidi.

Ní gbangba ni idà ń parun;

ikú wà nínú ilé pẹ̀lú.

21“Àwọn ènìyàn ti gbọ́ ìrora mi,

ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún mi.

Àwọn ọ̀tá mi ti gbọ́ ìparun mi;

wọ́n yọ̀ sí ohun tí o ṣe.

Kí o mú ọjọ́ tí o ti kéde,

kí wọ́n le dàbí tèmi.

22“Jẹ́ kí ìwà ìkà wọn wá síwájú rẹ;

jẹ wọ́n ní yà

bí o ṣe jẹ mí ní yà

nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi.

Ìrora mi pọ̀

ọkàn mi sì rẹ̀wẹ̀sì.”

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

耶利米哀歌 1:1-22

凄惨的耶路撒冷

1从前人烟稠密的城,

现在何其荒凉!

从前扬威万邦的强国,

现在竟像寡妇一样。

从前在诸省做公主的,

现在却沦为奴婢。

2她在夜间痛哭,泪流满面。

情人中没有一个前来安慰。

朋友都出卖她,与她为敌。

3犹大饱受苦难和奴役,

被掳往远方,流落异邦,

找不到安居之所。

她在走投无路之际被追敌擒获。

4通往锡安1:4 锡安”又称“耶路撒冷”。的道路满目凄凉,

因为无人前去过节。

她的城门冷落,

她的祭司悲叹,

她的少女哀伤,她痛苦不已。

5敌人做了她的主人,

兴旺发达。

因为她作恶多端,

耶和华叫她饱受困苦,

她的孩子被敌人掳去。

6锡安的尊荣消逝,

她的首领像找不到草吃的鹿,

无力逃脱敌人的追赶。

7在困苦流离中,

耶路撒冷想起昔日的荣华。

如今,她的人民落在敌人手中,

无人援救。

仇敌看见她,都嘲笑她的灭亡。

8耶路撒冷罪大恶极,

沦为污秽之物。

从前尊重她的人看见她赤身裸体,就蔑视她。

她只能哀叹、退避。

9她的裙子沾满污秽,

她未曾想过自己的结局。

她的败落无比凄惨,

无人安慰。

她哭喊道:“耶和华啊,

仇敌已经获胜,

求你垂顾我的苦难!”

10敌人伸手夺去她的一切珍宝。

她目睹外族人闯入圣殿——那是耶和华禁止他们进入的地方。

11她的人民呻吟着四处觅食,

用珍宝换取粮食维生。

耶路撒冷的哀叹

她说:“耶和华啊,求你眷顾我,

因为我被人蔑视。

12“路人啊,你们都无动于衷吗?

你们看看,

耶和华向我发烈怒,降祸于我,

还有谁比我更痛苦呢?

13“祂从高天降下火来,

焚烧我的骨头;

祂在我脚前设下网罗,

使我返回;

祂使我凄凉孤寂,终日痛苦。

14“我的罪恶连接成轭,

祂亲手把它们编在一起,

绑在我的颈项上,

使我筋疲力尽。

主把我交给我无力抵挡的敌人。

15“主藐视我所有的勇士,

召集军队攻击我,

打垮我的青年。

主践踏犹大1:15 犹大人”希伯来文是“犹大的纯洁少女”。

如同在榨酒池踩踏。

16“我为此哭泣,

泪流满面,

却无人安慰、鼓励我。

我的儿女凄凉孤苦,

因为仇敌已经得胜。”

17锡安伸手求助,却无人理睬。

耶和华已命四周邻国与雅各为敌。

耶路撒冷在他们当中成了污秽之物。

18“但耶和华是公义的,

因为我违背了祂的命令。

万国啊,请听我的话,

看看我的痛苦!

我的年轻男女都被掳去。

19“我向情人们求助,

他们却欺骗我。

我的祭司和长老在觅食求生时,

倒毙在城中。

20“耶和华啊,

看看我是多么痛苦!

我的内脏搅动,

我的心灵翻腾,

因为我背叛了你。

街上有屠杀,

家中有死亡。

21“人们听见我的哀叹,

却无人安慰我。

敌人看见你降给我的灾难,

都幸灾乐祸。

愿你应许的审判之日来临,

叫他们像我一样受苦!

22“愿他们的恶行都摆在你眼前!

你怎样因我的罪恶而惩罚我,

愿你也照样惩罚他们!

我叹息不绝,心中哀伤。”