Jeremiah 2 – YCB & NUB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 2:1-37

Israẹli kọ Ọlọ́run sílẹ̀

1Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé: 2“Lọ kí o sì kéde sí etí Jerusalẹmu pé:

“Báyìí ni Olúwa wí,

“ ‘Èmi rántí ìṣeun ìgbà èwe rẹ,

ìfẹ́ ìgbéyàwó rẹ

àti nígbà tí ìwọ tẹ̀lé mi nínú ijù,

nínú ìyàngbẹ ilẹ̀.

3Israẹli jẹ́ mímọ́ sí Olúwa,

àkọ́kọ́ èso ìkórè rẹ̀,

gbogbo ẹnikẹ́ni tí ó jẹ run ni a ó dá lẹ́bi,

ibi yóò sì wá sí orí wọn,’ ”

bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.

4Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ìdílé Jakọbu

àti gbogbo ẹ̀yin ará ilé Israẹli.

5Báyìí ni Olúwa wí:

“Irú àìṣedéédéé wo ni baba yín rí lọ́wọ́ mi?

Tí wọ́n fi jìnnà sí mi?

Wọ́n tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán,

àwọn fúnrawọn sì di asán.

6Wọn kò béèrè, ‘Níbo ni Olúwa wà,

tí ó mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá,

tí ó mú wa la aginjù já,

tí ó mú wa la àárín pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti ihò,

ìyàngbẹ ilẹ̀ àti òkùnkùn biribiri,

ilẹ̀ ibi tí ẹnikẹ́ni kò là kọjá, tí ẹnikẹ́ni kò sì tẹ̀dó sí?’

7Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ ọlọ́ràá

láti máa jẹ èso ibẹ̀ àti ọrọ̀ rẹ̀,

ṣùgbọ́n ẹ̀yin wọ inú rẹ̀, ẹ sì bà á jẹ́,

ẹ sì sọ ogún mi di ohun ìríra.

8Àwọn àlùfáà kò béèrè wí pé,

‘Níbo ni Olúwa wà?’

Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú òfin kò si mọ̀ mí,

àwọn olùṣọ́ sì ṣẹ̀ sí mi.

Àwọn wòlíì sì ń sọtẹ́lẹ̀ nípa òrìṣà Baali,

wọ́n sì ń tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán.

9“Nítorí náà, mo fi ẹ̀sùn kàn yín lẹ́ẹ̀kan sí i,”

ni Olúwa wí.

“Èmi ó sì fi ẹ̀sùn kan àwọn ọmọ ọwọ́ rẹ

10Rékọjá lọ sí erékùṣù àwọn ara Kittimu, kí ẹ sì wò ó,

ránṣẹ́ lọ sí Kedari, kí ẹ sì kíyèsi gidigidi

kí ẹ wò bí irú nǹkan báyìí bá ń bẹ níbẹ̀?

11Orílẹ̀-èdè kan ha á pa Ọlọ́run rẹ̀ dà?

(Síbẹ̀, wọ́n kì í ṣe iṣẹ́ Ọlọ́run)

àwọn ènìyàn mi ti pààrọ̀

ògo wọn fún àwọn ère tí kò níyì.

12Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì

kí ẹ sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù ńlá,”

ni Olúwa wí.

13“Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì

Wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, Èmi

orísun omi ìyè, wọ́n sì ti

ṣe àmù, àmù fífọ́ tí kò lè

gba omi dúró.

14Israẹli ha á jẹ́ ọmọ ọ̀dọ̀

ẹrú nípa ìbí? Kí ló ha a

dé tí ó fi di ìkógun?

15Àwọn kìnnìún ké ramúramù

wọ́n sì ń bú mọ́ wọn

wọ́n ti fi ilẹ̀ rẹ̀ ṣòfò

Ìlú rẹ̀ ti di jíjóná, ó sì

ti di ìkọ̀sílẹ̀.

16Bákan náà, àwọn ọkùnrin

Memfisi àti Tafanesi

wọ́n ti fa adé orí rẹ yọ.

17Ẹ̀yin kò ha a ti fa èyí sórí

ara yín nípa kíkọ Ọlọ́run sílẹ̀

nígbà tí ó tọ́ ọ lójú ọ̀nà?

18Kí ló dé tí o ṣe wá lọ Ejibiti

láti lọ mu omi ní Ṣihori?

Kí ló dé tí o sì fi lọ sí Asiria

láti lọ mú omi ni odò Eufurate náà?

19Iṣẹ́ búburú yín yóò fìyà jẹ yín

ìpadàsẹ́yìn rẹ yóò sì bá ọ wí

mọ̀ kí o sì rí i wí pé ibi àti

ohun búburú yóò sì jẹ́ tìrẹ

nígbà tí o ti kọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀,

ẹ kò sì ní ìbẹ̀rù fún mi,”

ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

20“Nígbà àtijọ́, o ti fọ́ àjàgà

rẹ sọnù, ìwọ sì já ìdè rẹ

ìwọ wí pé, ‘Èmi kì yóò sìn ọ́!’

Lóòtítọ́, lórí gbogbo òkè gíga ni

àti lábẹ́ igi tí ó tànkálẹ̀

ni ìwọ dùbúlẹ̀ sí gẹ́gẹ́ bí panṣágà.

21Èmi ti gbìn ọ́ gẹ́gẹ́ bí

àjàrà ọ̀tọ̀, gẹ́gẹ́ bí ìṣúra ọlọ́lá,

Báwo wá ni ìwọ ṣe yípadà sí mi

di àjàrà búburú àti aláìmọ́?

22Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o wẹ ara rẹ pẹ̀lú sódà

tí o sì lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọṣẹ

síbẹ̀síbẹ̀ èérí ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ níwájú,”

ni Olúwa Olódùmarè wí.

23“Báwo ni ìwọ ṣe wí pé, ‘Èmi kò ṣe aláìmọ́;

Èmi kò sá à tẹ̀lé àwọn Baali’?

Wo bí o ṣe hùwà ní àfonífojì;

wo ohun tí o ṣe.

Ìwọ jẹ́ abo ìbákasẹ

tí ń sá síhìn-ín sọ́hùn-ún.

24Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń gbé aginjù

tí ń fa ẹ̀fúùfù ìfẹ́ sí i mu rẹ,

ta ni ó le è mú dúró ní àkókò rẹ̀?

Kí gbogbo àwọn akọ ẹran tí o wá a kiri kì ó má ṣe dá ara wọn lágara,

nítorí wọn yóò rí ní àkókò oṣù rẹ̀.

25Dá ẹsẹ̀ dúró láìwọ bàtà,

àti ọ̀fun rẹ nínú òǹgbẹ.

Ṣùgbọ́n ìwọ wí pé, ‘Asán ni!

Èmi fẹ́ràn àwọn ọlọ́run àjèjì,

àwọn ni èmi yóò tọ̀ lẹ́yìn.’

26“Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń dójútì olè nígbà tí a bá mú u,

bẹ́ẹ̀ náà ni ojú yóò ti ilé Israẹli—

àwọn ọba àti àwọn ìjòyè wọn,

àwọn àlùfáà àti wòlíì wọn pẹ̀lú.

27Wọ́n sọ fún igi pé, ‘Ìwọ ni baba mi,’

àti sí òkúta wí pé, ‘Ìwọ ni ó bí mi,’

wọ́n ti kọ ẹ̀yìn wọn sí mi,

wọn kò kọ ojú sí mi

síbẹ̀ nígbà tí wọ́n bá wà nínú ìṣòro,

wọn yóò wí pé, ‘Wá kí o sì gbà wá!’

28Níbo wá ni àwọn ọlọ́run tí

ẹ ṣe fúnrayín ha a wà?

Jẹ́ kí wọ́n wá kí wọ́n sì

gbà yín nígbà tí ẹ bá

wà nínú ìṣòro! Nítorí pé

ẹ̀yin ní àwọn ọlọ́run púpọ̀, gẹ́gẹ́

bí ẹ ti ṣe ni àwọn ìlú, ìwọ Juda.

29“Kí ló dé tí o ṣe wá ń fi ẹ̀sùn kàn mí?

Gbogbo yín ni ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi,”

ni Olúwa wí.

30“Nínú asán mo fìyà jẹ àwọn ènìyàn yín,

wọn kò sì gba ìbáwí.

Idà yín ti pa àwọn wòlíì yín run,

gẹ́gẹ́ bí kìnnìún tí ń bú ramúramù.

31“Ẹ̀yin ìran yìí, ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ Olúwa:

“Mo ha ti di aginjù sí Israẹli

tàbí mo jẹ ilẹ̀ olókùnkùn biribiri?

Èéṣe tí àwọn ènìyàn mi ṣe wí pé,

‘A ní àǹfààní láti máa rìn kiri;

àwa kì yóò tọ̀ ọ́ wá mọ́?’

32Wúńdíá ha le gbàgbé ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀,

tàbí ìyàwó ohun ọ̀ṣọ́ ìgbéyàwó rẹ̀?

Síbẹ̀, àwọn ènìyàn mi ti gbàgbé mi ní ọjọ́ àìníye.

33Ìwọ ti jẹ́ ọlọ́gbọ́n tó nípa ọ̀rọ̀ ìfẹ́!

Àwọn obìnrin búburú yóò kẹ́kọ̀ọ́ nípa ọ̀nà rẹ

34Lórí aṣọ rẹ ni wọ́n bá ẹ̀jẹ̀

àwọn tálákà aláìṣẹ̀

bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò ká wọn mọ́

níbi tí wọ́n ti ń rùn wọlé

35Síbẹ̀ nínú gbogbo èyí

ìwọ sọ wí pé, ‘Èmi jẹ́ aláìṣẹ̀

kò sì bínú sí mi.’

Èmi yóò mú ìdájọ́ mi wá sórí rẹ

nítorí pé ìwọ wí pé, ‘Èmi kò dẹ́ṣẹ̀.’

36Èéṣe tí ìwọ fi ń lọ káàkiri

láti yí ọ̀nà rẹ padà?

Ejibiti yóò dójútì ọ́

gẹ́gẹ́ bí i ti Asiria

37Ìwọ yóò sì fi ibẹ̀ sílẹ̀

pẹ̀lú kíkáwọ́ rẹ lé orí rẹ,

nítorí pé Olúwa ti kọ̀ àwọn

tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé sílẹ̀,

kì yóò sí ìrànlọ́wọ́ kankan

fún ọ láti ọ̀dọ̀ wọn.

Swedish Contemporary Bible

Jeremia 2:1-37

Varningar och förmaningar till Juda

(2:1—29:32)

Guds folks trolöshet

1Herrens ord kom till mig: 2”Gå och förkunna för Jerusalem: Så säger Herren:

’Jag minns hur hängiven du var i ungdomen,

hur du älskade mig som brud

och hur du följde mig genom öknen,

genom ett land där ingen sår något.

3Israel var heligt för Herren,

det första av hans skörd.

Alla som åt av det

drog på sig skuld

och blev drabbade av olycka, säger Herren.’ ”

4Hör Herrens ord, Jakobs ätt, Israels alla släkter! 5Så säger Herren:

”Vad var det för fel era fäder fann hos mig,

eftersom de gick bort från mig

och följde de värdelösa avgudarna

och själva blev värdelösa?

6De frågade inte: ’Var är Herren,

som ledde oss ut ur Egypten,

genom öknen,

genom ett öde, oländigt land,

torkans och skuggornas land,

ett land som ingen vill passera igenom

och där ingen vill bo?’

7Jag ledde er till ett bördigt land,

för att ni skulle få äta av dess frukt och dess goda.

Men när ni kom dit orenade ni mitt land

och gjorde min egendom avskyvärd.

8Prästerna frågade inte:

’Var är Herren?’

De som hade hand om lagen

kände mig inte,

ledarna satte sig upp mot mig,

profeterna profeterade i Baals namn

och följde värdelösa avgudar.

9Därför kommer jag att gå till rätta med er än en gång, säger Herren,

ja, även med era barn i kommande generationer ska jag gå till rätta.

10Dra bort till kittéernas2:10 Syftar på Cypern. kuster

och se efter,

sänd någon till Kedar

för att noga undersöka

om något sådant har skett:

11Har något annat folk någonsin bytt ut sina gudar,

som ändå inte är några gudar?

Men mitt folk har bytt bort sin härlighet2:11 En urtida skriftlärd tradition som är omnämnd i den masoretiska texten visar att den ursprungliga formuleringen löd: min härlighet.

mot en värdelös avgud.

12Häpna över detta, ni himlar,

rys och bäva, säger Herren.

13Mitt folk har begått en dubbel synd:

Det har övergett mig,

källan med det levande vattnet,

och de har grävt dåliga brunnar åt sig,

brunnar som inte håller vatten.

14Är Israel en tjänare eller född till slav?

Varför har han blivit ett byte?

15Lejonen ryter och morrar mot honom.

De har lagt hans land öde

och bränt ner hans städer,

så att ingen kan bo i dem.

16Män från Memfis och Tachpanches

betar din hjässa kal.

17Är det inte du själv som har dragit detta över dig

genom att du övergav Herren, din Gud,

när han ville leda dig på vägen?

18Varför ska du nu gå till Egypten

för att dricka Shichors vatten?

Och varför gå till Assyrien

för att dricka av Eufratflodens vatten?

19Din ondska kommer att straffa dig,

ditt avfall att tukta dig.

Besinna och inse därför

hur ont och bittert det är

att du överger Herren, din Gud,

och inte fruktar mig längre, säger Herren, härskarornas Herre.

20För länge sedan bröt jag sönder ditt ok

och slet av dina band.2:20 Enligt Septuaginta: …bröt du sönder ditt ok…

Du sa: ’Jag vill inte tjäna.’

På varje höjd och under varje grönskande träd

lade du dig ner och prostituerade dig.

21Jag planterade dig som ett ädelt vin

av allra bästa slag.

Hur har du kunnat förvandlas för mig

till en oduglig, vildvuxen ranka?

22Även om du tvättar dig med lut

och rikligt med såpa

består din synds fläckar inför mig,” säger Herren, Herren.

23”Hur kan du säga:

’Jag har inte orenat mig

och inte sprungit efter baalsgudarna’?

Tänk efter hur du bar dig åt i dalen,

beakta vad du har gjort.

Du är som ett oroligt kamelsto,

som irrar hit och dit,

24som en vildåsna, van vid öken,

som flåsar under parningstiden.

Vem kan tygla dess begär?

Ingen behöver springa sig trött efter den,

i parningstiden är den lätt att finna.

25Akta dig, så du inte springer av dig skorna

och får din strupe torr.

Men du säger:

’Det är ingen idé.

Jag älskar främmande gudar,

och dem måste jag följa.’

26Som en tjuv tagen på bar gärning

ska Israel stå där med skam,

med sina kungar, furstar,

präster och profeter,

27de som säger till en trästolpe: ’Du är min far’

och till en sten: ’Du har fött mig.’

De vänder ryggen mot mig,

inte ansiktet,

men när olyckan kommer ropar de:

’Kom och rädda oss!’

28Var är då de gudar som du har gjort åt dig själv?

Låt dem nu komma till din räddning i olyckan, om de kan!

Du har ju lika många gudar

som du har städer, Juda.

29Varför vill ni gå till rätta med mig?

Ni har ju alla gjort uppror mot mig, säger Herren.

30Till ingen nytta har jag straffat era söner,

de tog inte emot någon tillrättavisning.

Som rovlystna lejon

har ert svärd ätit upp profeterna.

31Ni släkte, ge akt på Herrens ord!

Har jag varit en öken för Israel,

ett mörkrets land?

Varför säger mitt folk:

’Vi går vart vi vill,

vi kommer inte mer tillbaka till dig.’

32Skulle en ung flicka kunna glömma sina smycken,

eller en brud sin gördel?

Men av mitt folk har jag varit glömd i alla tider.

33Hur skickligt hittar du inte vägen

i ditt sökande efter kärlek!

Till och med de sämsta bland kvinnorna

har en hel del att lära av dig.2:33 Grundtextens innebörd är osäker. Tanken kan också vara: Därför har du också vant dig vid ondskans vägar.

34Dina kläder är fläckade av blod

från fattiga och oskyldiga.

De ertappades inte vid inbrott.

Trots allt detta2:34 Grundtextens innebörd är osäker, men det är troligt att sista satsen i versen hör ihop med början av nästa vers.

35säger du: ’Jag är oskyldig.

Han är inte vred på mig längre.’

Jag ska döma dig,

därför att du säger att du inte har syndat.

36Varför far du än hit och än dit,

för att ta en annan väg?

Du ska bli besviken på Egypten

på samma sätt som du blev besviken på Assyrien.

37Också därifrån kommer du att få gå

med händerna över huvudet.

Herren har förkastat dem som du litade på,

och du ska inte ha framgång med hjälp av dem.