Jeremiah 1 – YCB & NUB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 1:1-19

1Èyí ni ọ̀rọ̀ Jeremiah ọmọ Hilkiah ọ̀kan nínú àwọn àlùfáà ní Anatoti ní agbègbè ilẹ̀ Benjamini. 2Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá ní ọdún kẹtàlá ní àkókò ìjọba Josiah ọmọ Amoni ọba Juda, 3Àti títí dé àsìkò Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, títí dé oṣù karùn-ún ọdún kọkànlá Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, nígbà tí àwọn ará Jerusalẹmu lọ sí ìgbèkùn.

Ìpè Jeremiah

4Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé,

51.5: Isa 49.1; Ga 1.15.Kí ó tó di pé mo dá ọ láti inú ni mo ti mọ̀ ọ́n,

kí ó sì tó di pé a bí ọ ni mo ti yà ọ́ sọ́tọ̀.

Mo yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí wòlíì fún àwọn orílẹ̀-èdè.

6Mo sọ pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè, ọmọdé ni mí, èmi kò mọ bí a ṣe é sọ̀rọ̀.”

7Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe sọ pé, ‘Ọmọdé lásán ni mí.’ O gbọdọ̀ ní láti lọ sí ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tí mo rán ọ sí, kí o sì sọ ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.” 81.8: Isa 43.5; Ap 18.9-10.Olúwa sì wí pé má ṣe bẹ̀rù wọn, nítorí tí èmi wà pẹ̀lú rẹ èmi ó sì gbà ọ́.

9Olúwa sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi kàn mí lẹ́nu, ó sì wí fún mi pé nísinsin yìí mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí inú ẹnu rẹ 101.10: If 10.11.Wò ó, mo yàn ọ́ lórí àwọn orílẹ̀-èdè àti ìjọba gbogbo láti fàtu, láti wó lulẹ̀, láti bàjẹ́, láti jágbà, láti máa kọ́, àti láti máa gbìn.

11Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ mí wá wí pé:

“Kí ni o rí Jeremiah?”

Mo sì dáhùn wí pé “Mo rí ẹ̀ka igi almondi.”

12Olúwa sì wí fún mi pé, “Ó ti rí i bí ó ṣe yẹ, nítorí pé mo ti ń ṣọ láti rí i pé ọ̀rọ̀ mi wá sí ìmúṣẹ.”

13Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ mi wá ní ẹ̀ẹ̀kejì pé, “Kí ni o rí?” Mo sì dáhùn pé mo rí ìkòkò gbígbóná, tí ó ń ru láti apá àríwá.

14Olúwa, sì wí fún mi pé, “Láti apá àríwá ni a ó ti mu ìdààmú wá sórí gbogbo àwọn tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà. 15Mo sì ti ṣetán láti pe gbogbo àwọn ènìyàn orílẹ̀-èdè àríwá níjà,” ni Olúwa wí.

Àwọn ọba wọn yóò wá

gbé ìtẹ́ wọn ró ní ojú ọ̀nà àbáwọlé

Jerusalẹmu. Wọn ó sì dìde sí gbogbo

àyíká wọn àti sí gbogbo àwọn

ìlú Juda.

16Èmi yóò sì kéde ìdájọ́ mi lórí àwọn ènìyàn mi

nítorí ìwà búburú wọn nípa kíkọ̀ mí sílẹ̀,

nípa rírúbọ sí ọlọ́run mìíràn

àti sínsin àwọn ohun tí wọ́n fi ọwọ́ wọn ṣe.

17“Wà ní ìmúrasílẹ̀! Dìde dúró kí o sì sọ fún wọn ohunkóhun tí mo bá pàṣẹ fún wọn. Má ṣe jẹ́ kí wọ́n dẹ́rùbà ọ́, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀rù níwájú wọn. 18Ní òní èmi ti sọ ọ́ di ìlú alágbára, òpó irin àti odi idẹ sí àwọn ọba Juda, àwọn ìjòyè rẹ̀, sí àwọn àlùfáà àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà. 19Wọn yóò dojú ìjà kọ ọ́, wọn kì yóò borí rẹ, nítorí wí pé èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì gbà ọ́,” ni Olúwa wí.

Swedish Contemporary Bible

Jeremia 1:1-19

1Detta är ord av Jeremia, Hilkias son, en av prästerna i Anatot i Benjamins land. 2Herrens ord kom till honom under Amons son Josias trettonde regeringsår i Juda, 3och när Josias son Jojakim var kung i Juda, och ända till slutet av det elfte året av Josias son Sidkias regering i Juda, när Jerusalems befolkning i femte månaden fördes bort i fångenskap.

Gud kallar Jeremia

4Herrens ord kom till mig:

5”Jag kände dig innan du formades i din mors liv.

Innan du föddes avskilde jag dig

och utsåg dig till en profet för folken.”

6Jag svarade: ”Min Herre, Herre, jag kan inte tala! Jag är för ung!”

7Då sa Herren till mig: ”Säg inte att du är för ung, utan gå dit jag sänder dig och tala vad jag befaller dig. 8Var inte rädd för dem, för jag är med dig och ska rädda dig, säger Herren.”

9Sedan räckte Herren ut sin hand, rörde vid min mun och sa till mig: ”Se, jag lägger mina ord i din mun. 10Jag sätter dig över folk och riken, för att rycka upp och bryta ner, förgöra och förkasta, bygga upp och plantera.”

11Herrens ord kom till mig: ”Vad ser du, Jeremia?” Jag svarade: ”Jag ser en gren av ett mandelträd1:11 De hebreiska orden för mandelträd (shaked) och vaka (shoked) liknar varandra och utgör en ordlek, något som ofta förekommer framför allt i profetiska texter..” 12Herren sa till mig: ”Du har sett rätt. Jag ska vaka över mitt ord tills det fullföljs.”

13Herrens ord kom till mig en andra gång: ”Vad ser du?” Jag svarade: ”Jag ser en kokande gryta. Den lutar hitåt norrifrån.” 14Herren sa till mig: ”Från norr kommer olycka att dra fram över alla som bor i landet. 15Jag ska kalla samman alla folken från rikena i norr, säger Herren.

De ska komma och sätta upp var och en sin tron

framför Jerusalems portar

och längs dess murar

och vid alla städer i Juda.

16Jag ska döma dem för all deras ondska

för att de har övergett mig,

tänt rökelse åt andra gudar

och tillbett dem som de själva har gjort.

17Gör dig beredd! Stå upp och tala till dem allt som jag befaller dig. Var inte förskräckt för dem, för då kommer jag att förskräcka dig inför dem. 18I dag gör jag dig till en befäst stad, till en järnpelare och en kopparmur mot Juda kungar, dess furstar och präster och folket i landet. 19De ska anfalla dig men inte besegra dig, för jag är med dig, säger Herren, jag ska rädda dig.”