Jeremiah 3 – YCB & NUB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 3:1-25

1“Bí ọkùnrin kan bá sì kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀

tí obìnrin náà sì lọ fẹ́ ọkọ mìíràn,

ǹjẹ́ ọkùnrin náà tún lè tọ̀ ọ́ wá?

Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kò ní di aláìmọ́ bí?

Ṣùgbọ́n ìwọ ti gbé pẹ̀lú onírúurú panṣágà gẹ́gẹ́ bí olùfẹ́,

ṣé ìwọ yóò tún padà sọ́dọ̀ mi bí?”

ni Olúwa wí.

2“Gbé ojú rẹ sókè sí ibi gíga wọ̀n-ọn-nì,

kí o sì wò ó ibi kan ha wà tí a kò bà ọ́ jẹ́?

Ní ojú ọ̀nà, ìwọ jókòó de àwọn olólùfẹ́,

bí i ará Arabia kan nínú aginjù,

ìwọ sì ti ba ilẹ̀ náà jẹ́

pẹ̀lú ìwà àgbèrè àti ìwà búburú rẹ.

3Nítorí náà, a ti fa ọ̀wààrà òjò sẹ́yìn,

kò sì ṣí òjò àrọ̀kúrò.

Síbẹ̀ ìwọ ní ojú líle ti panṣágà,

ìwọ sì kọ̀ láti ní ìtìjú.

4Ǹjẹ́ ìwọ kò ha a pè mí láìpẹ́ yìí pé,

‘Baba mi, ìwọ ọ̀rẹ́ mi láti ìgbà èwe mi.

5Ìwọ yóò ha máa bínú títí?

Ìbínú rẹ yóò ha máa lọ títí láé?’

Báyìí ni o ṣe ń sọ̀rọ̀

ìwọ ṣe gbogbo ibi tí ìwọ le ṣe.”

Israẹli aláìṣòótọ́

6Ní àkókò ìjọba Josiah ọba, Olúwa wí fún mi pé, “Ṣé o ti rí nǹkan tí àwọn Israẹli aláìnígbàgbọ́ ti ṣe? Wọ́n ti lọ sí àwọn òkè gíga àti sí abẹ́ àwọn igi, wọ́n sì ti ṣe àgbèrè níbẹ̀. 7Mo rò pé nígbà tí wọ́n ti ṣe èyí wọn yóò padà, wọn kò padà, Juda aláìgbàgbọ́ arábìnrin rẹ̀ náà sì rí i. 8Mo fún Israẹli aláìnígbàgbọ́ ní ìwé ìkọ̀sílẹ̀, mo sì ké wọn kúrò nítorí gbogbo àgbèrè wọn. Síbẹ̀ mo rí pé Juda tí ó jẹ́ arábìnrin rẹ̀ kò bẹ̀rù, òun náà sì jáde lọ láti lọ ṣe àgbèrè. 9Nítorí ìwà èérí Israẹli kò jọ ọ́ lójú, ó ti ba ilẹ̀ jẹ́, ó sì ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú òkúta àti igi. 10Látàrí gbogbo nǹkan wọ̀nyí Juda arábìnrin rẹ̀ aláìgbàgbọ́ kò padà tọ̀ mí wá pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀, bí kò ṣe nípa fífarahàn bí olóòtítọ́,” ni Olúwa wí.

11Olúwa wí fún mi pé, “Israẹli aláìnígbàgbọ́ ṣe òdodo ju Juda tí ó ní ìgbàgbọ́ lọ. 12Lọ polongo ọ̀rọ̀ náà, lọ sí ìhà àríwá:

“ ‘Yípadà, Israẹli aláìnígbàgbọ́,’ ni Olúwa wí.

‘Ojú mi kì yóò korò sí ọ mọ́,

nítorí mo jẹ́ aláàánú, ni Olúwa wí.

Èmi kì yóò sì bínú mọ́ títí láé

13Sá à ti mọ ẹ̀bi rẹ,

ìwọ ti ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ,

ìwọ ti wá ojúrere rẹ lọ́dọ̀ ọlọ́run àjèjì

lábẹ́ gbogbo igikígi tí ó gbilẹ̀,

ẹ̀yin kò gba ohun mi gbọ́,’ ”

ni Olúwa wí.

14“Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́,” ni Olúwa wí, “nítorí èmi ni ọkọ rẹ. Èmi ó yàn ọ́, ọ̀kan láti ìlú àti méjì láti ẹ̀yà. Èmi ó sì mú ọ wá sí Sioni. 15Lẹ́yìn èyí, èmi ó fún ọ ní àwọn olùṣọ́-àgùntàn láti inú ọkàn mi, tí wọn yóò ṣáájú yín pẹ̀lú òye àti ìmọ̀. 16Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, tí ẹ̀yin bá pọ̀ sí i lórí ilẹ̀ náà,” ni Olúwa wí, “àwọn ènìyàn kò tún lè sọ pé, ‘Àpótí ẹ̀rí Olúwa’ kò ní wá sí ìrántí wọn mọ́, a kì yóò pàdánù rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò sì tún kan òmíràn mọ́. 17Ní ìgbà náà, wọn yóò pe Jerusalẹmu ní ìtẹ́ Olúwa gbogbo orílẹ̀-èdè yóò péjọ sí Jerusalẹmu láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ Olúwa, wọn kì yóò sì tún tẹ̀lé àyà líle búburú wọn mọ́. 18Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ni ilé Juda yóò darapọ̀ mọ́ ilé Israẹli. Wọn yóò sì wá láti ilẹ̀ àríwá wá sí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá yín gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní.

19“Èmi fúnra mi sọ wí pé,

“ ‘Báwo ni inú mi yóò ti dùn tó, kí èmi kí ó tọ́ ọ bí ọmọkùnrin

kí n sì fún ọ ní ilẹ̀ tí ó tó.’

Mo rò pé ìwọ yóò pè mí ní ‘Baba mi’

o kò sì ní ṣàì tọ̀ mí lẹ́yìn.

20Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí aláìgbàgbọ́ obìnrin sí ọkọ rẹ̀,

bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ o jẹ́ aláìgbàgbọ́ sí mi.

Ìwọ ilé Israẹli”

ni Olúwa wí.

21A gbọ́ ohùn àgàn láti ibi gíga,

ẹkún àti ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli,

nítorí wọ́n ti yí ọ̀nà wọn po,

wọ́n sì ti gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn.

22“Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́,

Èmi ó wo ìpadàsẹ́yìn kúrò ní ọ̀nà títọ́ rẹ sàn.”

“Bẹ́ẹ̀, ni a ó wá sọ́dọ̀ rẹ

nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run wa.

23Nítòótọ́, asán ni ìbọ̀rìṣà àti ìrúkèrúdò tí ó wà ní àwọn orí òkè

kéékèèkéé àti àwọn òkè gíga;

Nítòótọ́, nínú Olúwa Ọlọ́run

wa ni ìgbàlà Israẹli wà.

24Láti ìgbà èwe wa ni àwọn òrìṣà ìtìjú ti

jẹ èso iṣẹ́ àwọn baba wa run,

ọ̀wọ́ ẹran wọn àti agbo ẹran wọn,

ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.

25Jẹ́ kí a dùbúlẹ̀ nínú ìtìjú wa,

kí ìtìjú wa bò wá mọ́lẹ̀.

A ti ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa,

àwa àti àwọn baba wa,

láti ìgbà èwe wa títí di òní

a kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa.”

Swedish Contemporary Bible

Jeremia 3:1-25

1Om en man skiljer sig från sin hustru

och hon går ifrån honom

och gifter om sig,

får han gå tillbaka till henne?

Blir inte landet då helt vanhelgat?

Du har bedrivit otukt med många älskare,

skulle du då få komma tillbaka till mig? säger Herren.

2Lyft blicken mot de kala höjderna och se:

Var har du inte våldfört dig i otukt?

Du har suttit vid vägkanten

och väntat på dem

som en arab i öknen.

Du har vanhelgat landet

med din prostitution och din ondska.

3Därför hölls regnskurarna tillbaka,

och något vårregn kom inte.

Du var fräck som en hora,

men du skämdes inte.

4Och ändå har du nu ropat till mig:

’Far, du har varit min vän ända sedan jag var ung!

5Kan en vän vredgas för evigt,

hålla fast vid sin vrede för alltid?’

Så talar du,

men du gör allt ont du kan.”

Israel och Juda som trolösa systrar

6I kung Josias tid sa Herren till mig: Har du sett vad det avfälliga Israel har gjort? Hon har gått upp på alla höga berg och in under alla grönskande träd och bedrivit otukt där. 7Jag trodde att hon skulle vända tillbaka till mig efter att ha gjort allt detta. Men hon kom aldrig tillbaka. Hennes trolösa syster Juda såg det. 8Jag såg att trots att jag skilt mig från det avfälliga Israel och gett henne ett skilsmässobrev för hennes otukts skull, skrämdes inte hennes trolösa syster Juda av det, utan gick ut hon också och bedrev otukt. 9Hon orenade landet genom sin lättsinniga otukt och begick äktenskapsbrott med sten och trä. 10Trots detta vände hennes trolösa syster Juda inte tillbaka till mig helhjärtat utan låtsades bara, säger Herren.

11Herren sa till mig: ”Det avfälliga Israel är rättfärdigare än det trolösa Juda. 12Gå och förkunna detta budskap mot norr:

’Vänd tillbaka, du avfälliga Israel,

säger Herren,

jag ska inte se på er med ovilja,

för jag är nådig,

säger Herren.

Jag ska inte vara vred i all evighet.

13Men erkänn din skuld!

Du har gjort uppror mot Herren, din Gud,

och löpt hit och dit efter främmande gudar

under alla grönskande träd

och inte lyssnat på mig, säger Herren.’

14Vänd om, ni trolösa barn, säger Herren. För jag är er herre3:14 Ordagrant: …jag var deras make. och ska hämta er, en från varje stad och två från varje släkt, och föra er till Sion. 15Jag ska ge er herdar som följer min vilja och leder er med kunskap och visdom. 16När ni då förökar er och landet blir rikt befolkat, säger Herren, ska man inte mer tala om Herrens förbundsark, inte tänka på den eller komma ihåg den. Ingen ska sakna den eller göra någon ny. 17Vid den tiden ska man kalla Jerusalem Herrens tron, och alla folk ska samlas där, för att ära Herrens namn i Jerusalem. De ska inte längre följa sina egna onda och hårda hjärtan. 18På den tiden ska folket från Juda slå sig samman med Israels folk, och tillsammans ska de komma från landet i norr till det land jag gav era förfäder som arv.

Maning till bättring

19Jag tänkte:

’Hur gärna vill jag inte behandla dig som ett barn

och ge dig ett underbart land,

det härligaste arvet bland folken.’

Jag tänkte att du skulle kalla mig din Far

och aldrig mer vända dig bort från mig.

20Men som en hustru är otrogen mot sin man,

så var du, Israel, otrogen mot mig, säger Herren.

21Rop hörs från de kala höjderna,

gråt och böner från Israels folk.

De har gått på villovägar

och glömt Herren, sin Gud.

22Vänd om, ni avfälliga barn,

jag ska bota er från er trolöshet!”

”Vi kommer till dig,

för du är Herren, vår Gud.

23Vår avgudadyrkan uppe på kullarna var verkligen ett svek,

liksom vårt larmande däruppe på höjderna.

Bara i Herren, vår Gud,

finns räddning för Israel.

24Alltsedan vår ungdom har den skamliga avguden3:24 Eller skammen, skamguden; syftar troligen på Baal.

slukat frukten av våra fäders arbete,

deras boskap och fårhjordar,

deras söner och döttrar.

25Låt oss lägga oss ner i skam,

låt vanära täcka oss.

För vi har syndat mot Herren, vår Gud,

vi och våra fäder,

och från vår ungdom ända fram till denna dag

har vi inte lyssnat till Herren, vår Gud.”