Jeremiah 2 – YCB & BDS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 2:1-37

Israẹli kọ Ọlọ́run sílẹ̀

1Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé: 2“Lọ kí o sì kéde sí etí Jerusalẹmu pé:

“Báyìí ni Olúwa wí,

“ ‘Èmi rántí ìṣeun ìgbà èwe rẹ,

ìfẹ́ ìgbéyàwó rẹ

àti nígbà tí ìwọ tẹ̀lé mi nínú ijù,

nínú ìyàngbẹ ilẹ̀.

3Israẹli jẹ́ mímọ́ sí Olúwa,

àkọ́kọ́ èso ìkórè rẹ̀,

gbogbo ẹnikẹ́ni tí ó jẹ run ni a ó dá lẹ́bi,

ibi yóò sì wá sí orí wọn,’ ”

bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.

4Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ìdílé Jakọbu

àti gbogbo ẹ̀yin ará ilé Israẹli.

5Báyìí ni Olúwa wí:

“Irú àìṣedéédéé wo ni baba yín rí lọ́wọ́ mi?

Tí wọ́n fi jìnnà sí mi?

Wọ́n tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán,

àwọn fúnrawọn sì di asán.

6Wọn kò béèrè, ‘Níbo ni Olúwa wà,

tí ó mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá,

tí ó mú wa la aginjù já,

tí ó mú wa la àárín pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti ihò,

ìyàngbẹ ilẹ̀ àti òkùnkùn biribiri,

ilẹ̀ ibi tí ẹnikẹ́ni kò là kọjá, tí ẹnikẹ́ni kò sì tẹ̀dó sí?’

7Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ ọlọ́ràá

láti máa jẹ èso ibẹ̀ àti ọrọ̀ rẹ̀,

ṣùgbọ́n ẹ̀yin wọ inú rẹ̀, ẹ sì bà á jẹ́,

ẹ sì sọ ogún mi di ohun ìríra.

8Àwọn àlùfáà kò béèrè wí pé,

‘Níbo ni Olúwa wà?’

Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú òfin kò si mọ̀ mí,

àwọn olùṣọ́ sì ṣẹ̀ sí mi.

Àwọn wòlíì sì ń sọtẹ́lẹ̀ nípa òrìṣà Baali,

wọ́n sì ń tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán.

9“Nítorí náà, mo fi ẹ̀sùn kàn yín lẹ́ẹ̀kan sí i,”

ni Olúwa wí.

“Èmi ó sì fi ẹ̀sùn kan àwọn ọmọ ọwọ́ rẹ

10Rékọjá lọ sí erékùṣù àwọn ara Kittimu, kí ẹ sì wò ó,

ránṣẹ́ lọ sí Kedari, kí ẹ sì kíyèsi gidigidi

kí ẹ wò bí irú nǹkan báyìí bá ń bẹ níbẹ̀?

11Orílẹ̀-èdè kan ha á pa Ọlọ́run rẹ̀ dà?

(Síbẹ̀, wọ́n kì í ṣe iṣẹ́ Ọlọ́run)

àwọn ènìyàn mi ti pààrọ̀

ògo wọn fún àwọn ère tí kò níyì.

12Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì

kí ẹ sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù ńlá,”

ni Olúwa wí.

13“Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì

Wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, Èmi

orísun omi ìyè, wọ́n sì ti

ṣe àmù, àmù fífọ́ tí kò lè

gba omi dúró.

14Israẹli ha á jẹ́ ọmọ ọ̀dọ̀

ẹrú nípa ìbí? Kí ló ha a

dé tí ó fi di ìkógun?

15Àwọn kìnnìún ké ramúramù

wọ́n sì ń bú mọ́ wọn

wọ́n ti fi ilẹ̀ rẹ̀ ṣòfò

Ìlú rẹ̀ ti di jíjóná, ó sì

ti di ìkọ̀sílẹ̀.

16Bákan náà, àwọn ọkùnrin

Memfisi àti Tafanesi

wọ́n ti fa adé orí rẹ yọ.

17Ẹ̀yin kò ha a ti fa èyí sórí

ara yín nípa kíkọ Ọlọ́run sílẹ̀

nígbà tí ó tọ́ ọ lójú ọ̀nà?

18Kí ló dé tí o ṣe wá lọ Ejibiti

láti lọ mu omi ní Ṣihori?

Kí ló dé tí o sì fi lọ sí Asiria

láti lọ mú omi ni odò Eufurate náà?

19Iṣẹ́ búburú yín yóò fìyà jẹ yín

ìpadàsẹ́yìn rẹ yóò sì bá ọ wí

mọ̀ kí o sì rí i wí pé ibi àti

ohun búburú yóò sì jẹ́ tìrẹ

nígbà tí o ti kọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀,

ẹ kò sì ní ìbẹ̀rù fún mi,”

ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

20“Nígbà àtijọ́, o ti fọ́ àjàgà

rẹ sọnù, ìwọ sì já ìdè rẹ

ìwọ wí pé, ‘Èmi kì yóò sìn ọ́!’

Lóòtítọ́, lórí gbogbo òkè gíga ni

àti lábẹ́ igi tí ó tànkálẹ̀

ni ìwọ dùbúlẹ̀ sí gẹ́gẹ́ bí panṣágà.

21Èmi ti gbìn ọ́ gẹ́gẹ́ bí

àjàrà ọ̀tọ̀, gẹ́gẹ́ bí ìṣúra ọlọ́lá,

Báwo wá ni ìwọ ṣe yípadà sí mi

di àjàrà búburú àti aláìmọ́?

22Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o wẹ ara rẹ pẹ̀lú sódà

tí o sì lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọṣẹ

síbẹ̀síbẹ̀ èérí ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ níwájú,”

ni Olúwa Olódùmarè wí.

23“Báwo ni ìwọ ṣe wí pé, ‘Èmi kò ṣe aláìmọ́;

Èmi kò sá à tẹ̀lé àwọn Baali’?

Wo bí o ṣe hùwà ní àfonífojì;

wo ohun tí o ṣe.

Ìwọ jẹ́ abo ìbákasẹ

tí ń sá síhìn-ín sọ́hùn-ún.

24Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń gbé aginjù

tí ń fa ẹ̀fúùfù ìfẹ́ sí i mu rẹ,

ta ni ó le è mú dúró ní àkókò rẹ̀?

Kí gbogbo àwọn akọ ẹran tí o wá a kiri kì ó má ṣe dá ara wọn lágara,

nítorí wọn yóò rí ní àkókò oṣù rẹ̀.

25Dá ẹsẹ̀ dúró láìwọ bàtà,

àti ọ̀fun rẹ nínú òǹgbẹ.

Ṣùgbọ́n ìwọ wí pé, ‘Asán ni!

Èmi fẹ́ràn àwọn ọlọ́run àjèjì,

àwọn ni èmi yóò tọ̀ lẹ́yìn.’

26“Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń dójútì olè nígbà tí a bá mú u,

bẹ́ẹ̀ náà ni ojú yóò ti ilé Israẹli—

àwọn ọba àti àwọn ìjòyè wọn,

àwọn àlùfáà àti wòlíì wọn pẹ̀lú.

27Wọ́n sọ fún igi pé, ‘Ìwọ ni baba mi,’

àti sí òkúta wí pé, ‘Ìwọ ni ó bí mi,’

wọ́n ti kọ ẹ̀yìn wọn sí mi,

wọn kò kọ ojú sí mi

síbẹ̀ nígbà tí wọ́n bá wà nínú ìṣòro,

wọn yóò wí pé, ‘Wá kí o sì gbà wá!’

28Níbo wá ni àwọn ọlọ́run tí

ẹ ṣe fúnrayín ha a wà?

Jẹ́ kí wọ́n wá kí wọ́n sì

gbà yín nígbà tí ẹ bá

wà nínú ìṣòro! Nítorí pé

ẹ̀yin ní àwọn ọlọ́run púpọ̀, gẹ́gẹ́

bí ẹ ti ṣe ni àwọn ìlú, ìwọ Juda.

29“Kí ló dé tí o ṣe wá ń fi ẹ̀sùn kàn mí?

Gbogbo yín ni ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi,”

ni Olúwa wí.

30“Nínú asán mo fìyà jẹ àwọn ènìyàn yín,

wọn kò sì gba ìbáwí.

Idà yín ti pa àwọn wòlíì yín run,

gẹ́gẹ́ bí kìnnìún tí ń bú ramúramù.

31“Ẹ̀yin ìran yìí, ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ Olúwa:

“Mo ha ti di aginjù sí Israẹli

tàbí mo jẹ ilẹ̀ olókùnkùn biribiri?

Èéṣe tí àwọn ènìyàn mi ṣe wí pé,

‘A ní àǹfààní láti máa rìn kiri;

àwa kì yóò tọ̀ ọ́ wá mọ́?’

32Wúńdíá ha le gbàgbé ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀,

tàbí ìyàwó ohun ọ̀ṣọ́ ìgbéyàwó rẹ̀?

Síbẹ̀, àwọn ènìyàn mi ti gbàgbé mi ní ọjọ́ àìníye.

33Ìwọ ti jẹ́ ọlọ́gbọ́n tó nípa ọ̀rọ̀ ìfẹ́!

Àwọn obìnrin búburú yóò kẹ́kọ̀ọ́ nípa ọ̀nà rẹ

34Lórí aṣọ rẹ ni wọ́n bá ẹ̀jẹ̀

àwọn tálákà aláìṣẹ̀

bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò ká wọn mọ́

níbi tí wọ́n ti ń rùn wọlé

35Síbẹ̀ nínú gbogbo èyí

ìwọ sọ wí pé, ‘Èmi jẹ́ aláìṣẹ̀

kò sì bínú sí mi.’

Èmi yóò mú ìdájọ́ mi wá sórí rẹ

nítorí pé ìwọ wí pé, ‘Èmi kò dẹ́ṣẹ̀.’

36Èéṣe tí ìwọ fi ń lọ káàkiri

láti yí ọ̀nà rẹ padà?

Ejibiti yóò dójútì ọ́

gẹ́gẹ́ bí i ti Asiria

37Ìwọ yóò sì fi ibẹ̀ sílẹ̀

pẹ̀lú kíkáwọ́ rẹ lé orí rẹ,

nítorí pé Olúwa ti kọ̀ àwọn

tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé sílẹ̀,

kì yóò sí ìrànlọ́wọ́ kankan

fún ọ láti ọ̀dọ̀ wọn.

La Bible du Semeur

Jérémie 2:1-37

Prophéties sur Juda et Jérusalem

L’infidélité de Juda

Juda a abandonné l’Eternel

1L’Eternel m’adressa la parole en ces termes :

2Va à Jérusalem et crie à ses oreilles :

Voici ce que déclare l’Eternel :

Je me souviens de ton amour ╵au temps de ta jeunesse2.2 Lors de l’établissement de l’alliance au mont Sinaï (voir Os 2.16-22).,

et comment tu m’aimais ╵au temps où tu étais ╵une jeune mariée,

lorsque tu me suivais, ╵à travers le désert,

dans une terre inculte.

3Car Israël, ╵tu étais alors consacré ╵à l’Eternel,

tout comme les prémices ╵d’une récolte.

Tous ceux qui en mangeaient ╵étaient châtiés :

et le malheur les atteignait,

l’Eternel le déclare.

4Vous, communauté de Jacob,

et toutes les familles ╵du peuple d’Israël,

écoutez la parole ╵que l’Eternel prononce.

5Voici ce que dit l’Eternel :

En quoi donc vos ancêtres ╵m’ont-ils trouvé en tort

pour s’éloigner de moi,

pour s’en aller après des dieux ╵qui ne sont que du vent

et n’être plus eux-mêmes que du vent2.5 Voir 2 R 17.15. ?

6Ils n’ont pas demandé : ╵« Où donc est l’Eternel

qui nous a fait sortir d’Egypte

et qui nous a conduits ╵à travers le désert,

au pays de la steppe ╵rempli de fondrières,

dans une terre aride ╵où règnent les ténèbres,

et dans une région ╵où ne passe personne,

où n’habite personne ? »

7Or, je vous ai conduits ╵vers un pays fertile

pour en manger les fruits : ╵des produits excellents.

Mais une fois arrivés là, ╵vous avez souillé ce pays

et fait de mon domaine ╵un lieu abominable.

8Les prêtres n’ont pas demandé : ╵« Où donc est l’Eternel ? »

Les spécialistes de la Loi ╵ne me connaissent pas,

les dirigeants du peuple ╵se sont révoltés contre moi.

Et les prophètes même ╵proclament leurs messages ╵au nom du dieu Baal.

Ils vont après des dieux ╵qui ne servent à rien.

9C’est pourquoi je vous intente un procès,

à vous et à vos descendants.

L’Eternel le déclare.

10Rendez-vous donc ╵dans les îles de Chypre, ╵et regardez !

Ou envoyez ╵des hommes à Qédar2.10 Qédar: tribu nomade du désert d’Arabie, à l’est du pays d’Israël. ╵et qu’ils observent bien !

Voyez si jamais il arrive ╵une chose pareille :

11existe-t-il un peuple ╵qui ait changé de dieux ?

Et pourtant ces dieux-là ╵ne sont pas de vrais dieux !

Mon peuple, quant à lui, ╵a échangé celui qui fait sa gloire2.11 C’est-à-dire Dieu (voir Ps 106.20).

contre ce qui ne sert à rien !

12Cieux, étonnez-vous-en,

soyez-en horrifiés ╵et consternés,

l’Eternel le déclare.

13Car mon peuple a commis un double mal :

il m’a abandonné, ╵moi, la source d’eaux vives,

et il s’est creusé des citernes, ╵des citernes fendues

et qui ne retiennent pas l’eau.

Les conséquences de l’abandon

14Israël est-il donc ╵un esclave acheté

ou né dans la maison ?

Pourquoi est-il mis au pillage2.14 Pillé par les Assyriens et les Egyptiens (voir v. 15-16). ?

15De jeunes lions ╵rugissent contre lui,

et leur voix retentit,

ils ont dévasté son pays,

ses villes sont brûlées, ╵et n’ont plus d’habitants.

16Et même les habitants de Memphis ╵avec ceux de Daphné2.16 Deux villes égyptiennes du delta du Nil.

vous ont brisé2.16 brisé: autre traduction : rasé. le crâne.

17Pourquoi donc tout cela ╵t’arrive-t-il ?

N’est-ce pas pour avoir ╵délaissé l’Eternel ton Dieu,

alors même qu’il te guidait ╵sur le chemin ?

18Maintenant, que te sert ╵de partir en Egypte,

pour aller boire ╵les eaux du Nil2.18 En hébreu, le Shihor : le Nil ou l’un de ses affluents. ?

Et que te sert de prendre ╵la route pour te rendre ╵en Assyrie,

pour aller boire ╵les eaux du Fleuve2.18 C’est-à-dire l’Euphrate. Dans ce verset, Jérémie fait certainement allusion à des tentatives d’alliance avec ces peuples païens (voir v. 36). ?

19Car ta méchanceté ╵entraînera ton châtiment,

ton infidélité ╵fera venir ta punition.

Sache et vois bien ╵combien il est mauvais, ╵combien il est amer

de t’être détourné ╵de l’Eternel, ton Dieu,

de ne plus avoir peur de moi.

L’Eternel le déclare, ╵le Seigneur des armées célestes.

Juda, l’infidèle

20Voici : depuis toujours, ╵tu as brisé ton joug,

tu as rompu tes liens

en disant : « Je ne veux plus être esclave ! »

Mais, sur toute haute colline

et sous tout arbre vert,

toi, tu t’es allongée

tout comme une prostituée2.20 Le culte des faux dieux est qualifié par les prophètes de prostitution. Très souvent, l’idolâtrie cananéenne s’accompagnait de prostitution sacrée, liée au culte de la fécondité. !

21Moi, je t’avais plantée ╵comme un cep excellent

d’une variété sûre.

Comment se fait-il donc ╵que tu te sois changée ╵à mon égard

en plant dégénéré ╵d’une vigne sauvage ?

22Quand tu te laverais ╵avec de la potasse

et que tu emploierais ╵des quantités de soude,

la tache de ta faute ╵resterait devant moi.

C’est là ce que déclare ╵le Seigneur, l’Eternel.

23Comment oses-tu dire : ╵« Je ne me suis jamais souillée,

je ne suis pas allée ╵après les Baals » ?

Va observer dans la vallée2.23 Certainement la vallée de Ben-Hinnom où avaient lieu des pratiques idolâtres (voir Jr 7.31-32 ; 32.35 ; 2 R 23.10). ╵les traces de tes pas !

Reconnais ce que tu as fait,

chamelle écervelée, ╵qui vagabonde ╵dans tous les sens,

24oui, ânesse sauvage ╵qui a l’habitude de vivre ╵dans les steppes désertes !

Le feu de sa passion ╵lui fait renifler l’air.

Qui pourrait réfréner ╵l’ardeur de ses désirs ?

Tous ceux qui la recherchent ╵n’auront pas à se fatiguer,

car ils la trouveront ╵quand elle est en chaleur.

25Prends garde que ton pied ╵ne se déchausse pas !

Prends garde à ton gosier ╵qui va se dessécher !

Mais toi, tu réponds : « C’est peine perdue !

J’aime les étrangers,

c’est eux que je veux suivre. »

26Comme un voleur a honte ╵lorsqu’il est découvert,

ainsi seront couverts de honte ╵la communauté d’Israël,

ses rois et ses ministres,

ses prêtres, ses prophètes.

27Ils disent à du bois : ╵« Tu es mon père2.27 Voir 3.4. ! »

et à la pierre : ╵« Toi, tu m’as mis au monde ! »

Ils m’ont tourné le dos, ╵ne m’ont pas regardé en face,

mais au jour du malheur, ils disent :

« Lève-toi, sauve-nous ! »

28Mais où donc sont les dieux ╵que tu t’es fabriqués ?

Qu’ils se lèvent, donc, eux, ╵s’ils peuvent te sauver ╵quand le malheur t’atteint !

Car, ô Juda : ╵autant tu as de villes, ╵autant tu as de dieux2.28 Voir 11.13. !

Juda a oublié son Dieu

29Pourquoi m’intenter un procès ?

Vous vous êtes tous ╵révoltés contre moi,

l’Eternel le déclare.

30J’ai frappé vos enfants, ╵mais c’est peine perdue !

Car ils n’ont pas voulu ╵accepter la leçon.

Vous avez mis à mort ╵par l’épée vos prophètes

comme un lion destructeur.

31Gens d’aujourd’hui,

voyez ce que dit l’Eternel :

Suis-je pour Israël ╵une terre déserte,

un pays de ténèbres ?

Pourquoi mon peuple dit-il donc :

« Nous errerons où nous voulons,

et nous ne voulons plus ╵avoir affaire à toi » ?

32Quoi donc, la jeune fille ╵oublierait-elle ses bijoux,

ou la jeune mariée ╵sa ceinture tressée ?

Or, mon peuple m’oublie

depuis des jours sans nombre.

33Oh ! comme tu sais bien

rechercher tes amants !

Par ta conduite, ╵tu en remontrerais ╵à la pire des femmes !

34Et jusque sur les pans ╵de tes habits,

on voit le sang de pauvres ╵qui étaient innocents :

tu ne les avais pas surpris ╵en flagrant délit d’effraction2.34 Voir Ex 22.1. !

35Et malgré tout cela, tu dis :

« Moi, je suis innocente.

La colère divine ╵va très certainement ╵se détourner de moi ! »

Eh bien, moi, je vais te juger

parce que tu prétends ╵que tu n’as pas péché.

36Comme tu t’avilis

à changer de conduite !

Te tourner vers l’Egypte,

comme vers l’Assyrie2.36 Voir v. 18 et note., ╵cela t’attirera la honte,

37et tu en reviendras

en te cachant la face ╵avec les mains.

Car l’Eternel rejette ╵ceux sur lesquels tu comptes2.37 L’Egypte et l’Assyrie. ;

ce n’est pas avec eux ╵que tu aboutiras à quelque chose.