Jeremiah 3 – YCB & BDS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 3:1-25

1“Bí ọkùnrin kan bá sì kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀

tí obìnrin náà sì lọ fẹ́ ọkọ mìíràn,

ǹjẹ́ ọkùnrin náà tún lè tọ̀ ọ́ wá?

Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kò ní di aláìmọ́ bí?

Ṣùgbọ́n ìwọ ti gbé pẹ̀lú onírúurú panṣágà gẹ́gẹ́ bí olùfẹ́,

ṣé ìwọ yóò tún padà sọ́dọ̀ mi bí?”

ni Olúwa wí.

2“Gbé ojú rẹ sókè sí ibi gíga wọ̀n-ọn-nì,

kí o sì wò ó ibi kan ha wà tí a kò bà ọ́ jẹ́?

Ní ojú ọ̀nà, ìwọ jókòó de àwọn olólùfẹ́,

bí i ará Arabia kan nínú aginjù,

ìwọ sì ti ba ilẹ̀ náà jẹ́

pẹ̀lú ìwà àgbèrè àti ìwà búburú rẹ.

3Nítorí náà, a ti fa ọ̀wààrà òjò sẹ́yìn,

kò sì ṣí òjò àrọ̀kúrò.

Síbẹ̀ ìwọ ní ojú líle ti panṣágà,

ìwọ sì kọ̀ láti ní ìtìjú.

4Ǹjẹ́ ìwọ kò ha a pè mí láìpẹ́ yìí pé,

‘Baba mi, ìwọ ọ̀rẹ́ mi láti ìgbà èwe mi.

5Ìwọ yóò ha máa bínú títí?

Ìbínú rẹ yóò ha máa lọ títí láé?’

Báyìí ni o ṣe ń sọ̀rọ̀

ìwọ ṣe gbogbo ibi tí ìwọ le ṣe.”

Israẹli aláìṣòótọ́

6Ní àkókò ìjọba Josiah ọba, Olúwa wí fún mi pé, “Ṣé o ti rí nǹkan tí àwọn Israẹli aláìnígbàgbọ́ ti ṣe? Wọ́n ti lọ sí àwọn òkè gíga àti sí abẹ́ àwọn igi, wọ́n sì ti ṣe àgbèrè níbẹ̀. 7Mo rò pé nígbà tí wọ́n ti ṣe èyí wọn yóò padà, wọn kò padà, Juda aláìgbàgbọ́ arábìnrin rẹ̀ náà sì rí i. 8Mo fún Israẹli aláìnígbàgbọ́ ní ìwé ìkọ̀sílẹ̀, mo sì ké wọn kúrò nítorí gbogbo àgbèrè wọn. Síbẹ̀ mo rí pé Juda tí ó jẹ́ arábìnrin rẹ̀ kò bẹ̀rù, òun náà sì jáde lọ láti lọ ṣe àgbèrè. 9Nítorí ìwà èérí Israẹli kò jọ ọ́ lójú, ó ti ba ilẹ̀ jẹ́, ó sì ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú òkúta àti igi. 10Látàrí gbogbo nǹkan wọ̀nyí Juda arábìnrin rẹ̀ aláìgbàgbọ́ kò padà tọ̀ mí wá pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀, bí kò ṣe nípa fífarahàn bí olóòtítọ́,” ni Olúwa wí.

11Olúwa wí fún mi pé, “Israẹli aláìnígbàgbọ́ ṣe òdodo ju Juda tí ó ní ìgbàgbọ́ lọ. 12Lọ polongo ọ̀rọ̀ náà, lọ sí ìhà àríwá:

“ ‘Yípadà, Israẹli aláìnígbàgbọ́,’ ni Olúwa wí.

‘Ojú mi kì yóò korò sí ọ mọ́,

nítorí mo jẹ́ aláàánú, ni Olúwa wí.

Èmi kì yóò sì bínú mọ́ títí láé

13Sá à ti mọ ẹ̀bi rẹ,

ìwọ ti ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ,

ìwọ ti wá ojúrere rẹ lọ́dọ̀ ọlọ́run àjèjì

lábẹ́ gbogbo igikígi tí ó gbilẹ̀,

ẹ̀yin kò gba ohun mi gbọ́,’ ”

ni Olúwa wí.

14“Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́,” ni Olúwa wí, “nítorí èmi ni ọkọ rẹ. Èmi ó yàn ọ́, ọ̀kan láti ìlú àti méjì láti ẹ̀yà. Èmi ó sì mú ọ wá sí Sioni. 15Lẹ́yìn èyí, èmi ó fún ọ ní àwọn olùṣọ́-àgùntàn láti inú ọkàn mi, tí wọn yóò ṣáájú yín pẹ̀lú òye àti ìmọ̀. 16Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, tí ẹ̀yin bá pọ̀ sí i lórí ilẹ̀ náà,” ni Olúwa wí, “àwọn ènìyàn kò tún lè sọ pé, ‘Àpótí ẹ̀rí Olúwa’ kò ní wá sí ìrántí wọn mọ́, a kì yóò pàdánù rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò sì tún kan òmíràn mọ́. 17Ní ìgbà náà, wọn yóò pe Jerusalẹmu ní ìtẹ́ Olúwa gbogbo orílẹ̀-èdè yóò péjọ sí Jerusalẹmu láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ Olúwa, wọn kì yóò sì tún tẹ̀lé àyà líle búburú wọn mọ́. 18Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ni ilé Juda yóò darapọ̀ mọ́ ilé Israẹli. Wọn yóò sì wá láti ilẹ̀ àríwá wá sí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá yín gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní.

19“Èmi fúnra mi sọ wí pé,

“ ‘Báwo ni inú mi yóò ti dùn tó, kí èmi kí ó tọ́ ọ bí ọmọkùnrin

kí n sì fún ọ ní ilẹ̀ tí ó tó.’

Mo rò pé ìwọ yóò pè mí ní ‘Baba mi’

o kò sì ní ṣàì tọ̀ mí lẹ́yìn.

20Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí aláìgbàgbọ́ obìnrin sí ọkọ rẹ̀,

bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ o jẹ́ aláìgbàgbọ́ sí mi.

Ìwọ ilé Israẹli”

ni Olúwa wí.

21A gbọ́ ohùn àgàn láti ibi gíga,

ẹkún àti ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli,

nítorí wọ́n ti yí ọ̀nà wọn po,

wọ́n sì ti gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn.

22“Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́,

Èmi ó wo ìpadàsẹ́yìn kúrò ní ọ̀nà títọ́ rẹ sàn.”

“Bẹ́ẹ̀, ni a ó wá sọ́dọ̀ rẹ

nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run wa.

23Nítòótọ́, asán ni ìbọ̀rìṣà àti ìrúkèrúdò tí ó wà ní àwọn orí òkè

kéékèèkéé àti àwọn òkè gíga;

Nítòótọ́, nínú Olúwa Ọlọ́run

wa ni ìgbàlà Israẹli wà.

24Láti ìgbà èwe wa ni àwọn òrìṣà ìtìjú ti

jẹ èso iṣẹ́ àwọn baba wa run,

ọ̀wọ́ ẹran wọn àti agbo ẹran wọn,

ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.

25Jẹ́ kí a dùbúlẹ̀ nínú ìtìjú wa,

kí ìtìjú wa bò wá mọ́lẹ̀.

A ti ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa,

àwa àti àwọn baba wa,

láti ìgbà èwe wa títí di òní

a kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa.”

La Bible du Semeur

Jérémie 3:1-25

L’appel au retour

Une épouse infidèle

1Que dire ? ╵Si un mari ╵répudie son épouse,

qu’elle le quitte ╵pour appartenir à un autre,

est-ce que son ancien mari ╵retournera vers elle3.1 Voir la loi de Dt 24.1-4. ?

Le pays n’en serait-il pas souillé ?

Or, toi, qui t’es prostituée ╵avec de nombreux partenaires,

tu reviendrais à moi !

déclare l’Eternel.

2Lève les yeux, regarde ╵les hauteurs du pays :

y a-t-il un endroit ╵où tu ne te sois pas ╵livrée à l’inconduite ?

Tu guettais tes amants, assise ╵sur le bord des chemins,

comme le Bédouin guette ses victimes ╵dans le désert.

Et tu as souillé le pays

par tes prostitutions ╵et actes mauvais !

3C’est pourquoi les averses ╵ont été retenues,

et les pluies de printemps ╵ont cessé de tomber.

Mais tu as eu le front ╵d’une prostituée

et tu as refusé ╵de rougir de ta honte3.3 Voir Am 4.7-8. !

4Maintenant, n’est-ce pas,

tu m’appelles : « Mon père,

tu es l’époux de ma jeunesse3.4 Voir 2.2, 27. ! »

5Et tu demandes même : ╵« Sera-t-il toujours en colère ?

Et son ressentiment, ╵le gardera-t-il à jamais ? »

Voilà ce que tu dis,

tout en continuant ╵à commettre le mal

autant que tu le peux !

Israël-l’infidèle et Juda-la-perfide

6L’Eternel me dit au temps du roi Josias3.6 Voir 1.2 et note. : As-tu vu ce qu’a fait Israël-l’infidèle ? Elle qui allait sur toute montagne élevée et sous tout arbre vert pour s’y prostituer. 7Et moi, je me disais : Après avoir fait tout cela, elle reviendra à moi. Mais elle n’est pas revenue, et sa sœur, Juda-la-perfide, en a été témoin. 8Elle a bien vu3.8 D’après plusieurs manuscrits de l’ancienne version grecque et la version syriaque. Le texte hébreu traditionnel a : j’ai vu que. que j’ai répudié Israël-l’infidèle et que je lui ai donné sa lettre de divorce à cause de tous les adultères qu’elle avait commis3.8 sa lettre de divorce: voir Dt 24.1, 3.. Mais sa sœur, Juda-la-perfide, n’en a ressenti aucune crainte ; au contraire, elle est allée se prostituer à son tour3.8 Allusion à la déportation des habitants du royaume du Nord par les Assyriens en 722 av. J.-C.. 9Par sa légèreté à se débaucher, Israël a souillé tout le pays, commettant l’adultère avec des idoles de bois et de pierre. 10Et malgré tout cela, sa sœur, Juda-la-perfide, n’est pas revenue à moi de tout son cœur : son retour n’était qu’un leurre, l’Eternel le déclare.

11Et l’Eternel me dit : Israël-l’infidèle paraît plus juste que Juda-la-perfide. 12Va, et crie ces paroles, en direction du nord3.12 Vers les pays où Israël a été déporté. :

Reviens, Israël-l’infidèle !

l’Eternel le demande.

Je n’aurai plus pour toi ╵un visage sévère,

car je suis bienveillant,

l’Eternel le déclare,

et je ne serai pas ╵en colère à toujours.

13Mais reconnais ta faute :

c’est contre l’Eternel ton Dieu

que tu t’es révoltée

et tu as prodigué ╵tes faveurs çà et là ╵à des dieux étrangers

sous tous les arbres verts.

Et tu ne m’as pas écouté,

l’Eternel le déclare.

Revenez, enfants rebelles !

14Revenez donc, enfants rebelles ! L’Eternel le demande, car c’est moi votre maître. Et je vous prends, un d’une ville et deux d’une famille, pour vous amener à Sion. 15Là, je vous donnerai des bergers à ma convenance, ils vous dirigeront avec compétence et discernement. 16Or, quand dans le pays, vous vous serez multipliés – l’Eternel le déclare – oui, lorsque vous aurez proliféré, alors on ne parlera plus du coffre de l’alliance de l’Eternel. On n’y pensera plus et l’on ne s’en souviendra plus. Il ne manquera à personne et l’on n’en fera pas un autre3.16 Pour le coffre de l’alliance, voir Ex 25.22 ; 1 S 4.3.. 17En ce temps-là, on nommera Jérusalem : « Trône de l’Eternel », et tous les peuples s’assembleront en elle au nom de l’Eternel, oui, à Jérusalem. Ils ne persisteront plus à suivre les penchants de leur cœur obstiné et mauvais3.17 Voir Ap 21.22.. 18En ces jours-là, la communauté de Juda rejoindra celle d’Israël et, du pays du nord, elles reviendront ensemble vers le pays que j’ai donné en patrimoine à vos ancêtres.

19Et moi, qui me disais :

Je voudrais vous traiter ╵comme des fils !

J’aimerais vous donner ╵un pays de délices,

le plus beau patrimoine ╵parmi ceux des nations.

Je me disais aussi :

Vous m’appellerez : « Père »

et vous ne cesserez pas de me suivre.

20Mais vous m’avez trahi ╵ô communauté d’Israël,

comme une femme ╵qui trompe son mari,

l’Eternel le déclare.

21Un cri se fait entendre ╵sur les lieux élevés :

ce sont les pleurs ╵et les supplications ╵des gens du peuple d’Israël,

car ils ont adopté ╵une conduite corrompue,

ils ont oublié l’Eternel leur Dieu.

22Revenez donc, ╵enfants rebelles,

et je vous guérirai ╵de vos égarements.

Le retour à Dieu

– Nous voici, nous voici, ╵nous revenons à toi

car toi, tu es ╵l’Eternel notre Dieu !

23Oui, on nous a trompés ╵là-haut sur les collines, ╵par le tapage ╵entendu sur les monts.

Mais, c’est l’Eternel notre Dieu

qui accomplit le salut d’Israël.

24Depuis notre jeunesse,

les idoles honteuses ╵ont dévoré, ╵tout ce qu’avait produit ╵le travail de nos pères,

leurs brebis et leurs bœufs,

ainsi que leurs fils et leurs filles3.24 Sur les sacrifices d’enfants à cette époque, voir 2 R 16.3 ; 17.17 ; 21.6 ; 23.10 ; cf. Jr 7.31 ; 19.5 ; 32.35. La loi les interdisait : Lv 18.21 ; Dt 18.10..

25Couchés dans notre honte,

nous avons l’infamie ╵pour couverture.

Car nous et nos ancêtres,

depuis notre jeunesse ╵et jusqu’à aujourd’hui,

nous avons tous péché ╵contre l’Eternel, notre Dieu,

et nous n’avons pas obéi

à l’Eternel, lui, notre Dieu.