Jeremiah 1 – YCB & BDS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 1:1-19

1Èyí ni ọ̀rọ̀ Jeremiah ọmọ Hilkiah ọ̀kan nínú àwọn àlùfáà ní Anatoti ní agbègbè ilẹ̀ Benjamini. 2Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá ní ọdún kẹtàlá ní àkókò ìjọba Josiah ọmọ Amoni ọba Juda, 3Àti títí dé àsìkò Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, títí dé oṣù karùn-ún ọdún kọkànlá Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, nígbà tí àwọn ará Jerusalẹmu lọ sí ìgbèkùn.

Ìpè Jeremiah

4Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé,

51.5: Isa 49.1; Ga 1.15.Kí ó tó di pé mo dá ọ láti inú ni mo ti mọ̀ ọ́n,

kí ó sì tó di pé a bí ọ ni mo ti yà ọ́ sọ́tọ̀.

Mo yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí wòlíì fún àwọn orílẹ̀-èdè.

6Mo sọ pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè, ọmọdé ni mí, èmi kò mọ bí a ṣe é sọ̀rọ̀.”

7Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe sọ pé, ‘Ọmọdé lásán ni mí.’ O gbọdọ̀ ní láti lọ sí ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tí mo rán ọ sí, kí o sì sọ ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.” 81.8: Isa 43.5; Ap 18.9-10.Olúwa sì wí pé má ṣe bẹ̀rù wọn, nítorí tí èmi wà pẹ̀lú rẹ èmi ó sì gbà ọ́.

9Olúwa sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi kàn mí lẹ́nu, ó sì wí fún mi pé nísinsin yìí mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí inú ẹnu rẹ 101.10: If 10.11.Wò ó, mo yàn ọ́ lórí àwọn orílẹ̀-èdè àti ìjọba gbogbo láti fàtu, láti wó lulẹ̀, láti bàjẹ́, láti jágbà, láti máa kọ́, àti láti máa gbìn.

11Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ mí wá wí pé:

“Kí ni o rí Jeremiah?”

Mo sì dáhùn wí pé “Mo rí ẹ̀ka igi almondi.”

12Olúwa sì wí fún mi pé, “Ó ti rí i bí ó ṣe yẹ, nítorí pé mo ti ń ṣọ láti rí i pé ọ̀rọ̀ mi wá sí ìmúṣẹ.”

13Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ mi wá ní ẹ̀ẹ̀kejì pé, “Kí ni o rí?” Mo sì dáhùn pé mo rí ìkòkò gbígbóná, tí ó ń ru láti apá àríwá.

14Olúwa, sì wí fún mi pé, “Láti apá àríwá ni a ó ti mu ìdààmú wá sórí gbogbo àwọn tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà. 15Mo sì ti ṣetán láti pe gbogbo àwọn ènìyàn orílẹ̀-èdè àríwá níjà,” ni Olúwa wí.

Àwọn ọba wọn yóò wá

gbé ìtẹ́ wọn ró ní ojú ọ̀nà àbáwọlé

Jerusalẹmu. Wọn ó sì dìde sí gbogbo

àyíká wọn àti sí gbogbo àwọn

ìlú Juda.

16Èmi yóò sì kéde ìdájọ́ mi lórí àwọn ènìyàn mi

nítorí ìwà búburú wọn nípa kíkọ̀ mí sílẹ̀,

nípa rírúbọ sí ọlọ́run mìíràn

àti sínsin àwọn ohun tí wọ́n fi ọwọ́ wọn ṣe.

17“Wà ní ìmúrasílẹ̀! Dìde dúró kí o sì sọ fún wọn ohunkóhun tí mo bá pàṣẹ fún wọn. Má ṣe jẹ́ kí wọ́n dẹ́rùbà ọ́, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀rù níwájú wọn. 18Ní òní èmi ti sọ ọ́ di ìlú alágbára, òpó irin àti odi idẹ sí àwọn ọba Juda, àwọn ìjòyè rẹ̀, sí àwọn àlùfáà àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà. 19Wọn yóò dojú ìjà kọ ọ́, wọn kì yóò borí rẹ, nítorí wí pé èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì gbà ọ́,” ni Olúwa wí.

La Bible du Semeur

Jérémie 1:1-19

1Ce livre contient les paroles de Jérémie, fils de Hilqiya, l’un des prêtres, qui habitait à Anatoth1.1 Anatoth: ville attribuée aux prêtres et aux lévites (Jos 21.18) dans le territoire de Benjamin, à environ 5 kilomètres au nord-est de Jérusalem. Salomon destitua le grand-prêtre Abiatar (1 R 2.26) et le bannit à Anatoth. Depuis lors, les prêtres descendants d’Abiatar (dont Jérémie) n’eurent plus le droit d’accomplir leurs fonctions dans le Temple., dans le territoire de Benjamin.

2L’Eternel lui a parlé la treizième année du règne de Josias1.2 Josias a régné en Juda de 640 à 609 av. J.-C. (voir 2 R 22.1 à 23.30 ; 2 Ch 34 à 35). Cette parole de l’Eternel date donc de 628​627., fils d’Amôn et roi de Juda, 3et sous le règne de Yehoyaqim, fils de Josias, roi de Juda, et jusqu’à la fin de la onzième année du règne de Sédécias, fils de Josias, roi de Juda, jusqu’à la déportation des habitants de Jérusalem au cinquième mois1.3 Sur Yehoyaqim (609 à 598 av. J.-C.) et Sédécias (597 à 587 av. J.-C.), voir 2 R 23.36 à 25.21 ; 2 Ch 36. La déportation des habitants de Jérusalem a eu lieu en 587..

L’appel de Jérémie

4L’Eternel m’adressa la parole en ces termes :

5Avant de t’avoir formé dans le sein de ta mère, je t’ai choisi ; et avant ta naissance, je t’ai consacré : je t’ai destiné à être prophète pour les peuples.

6Je répondis : Hélas, Seigneur Eternel, je ne sais pas m’exprimer, car je suis un adolescent.

7Mais l’Eternel me répondit :

Ne dis pas : « Je suis un adolescent » ; tu iras trouver tous ceux auprès de qui je t’enverrai, et tu leur diras tout ce que je t’ordonnerai. 8N’aie pas peur de ces gens, car je suis avec toi pour te délivrer, l’Eternel le déclare.

9Alors l’Eternel tendit la main et me toucha la bouche, et il me dit : Tu vois : je mets mes paroles dans ta bouche. 10Sache que je te confie aujourd’hui une mission envers les peuples et les royaumes : celle d’arracher et de renverser, de ruiner et de détruire, de construire et de planter1.10 Voir 2 Co 10.8 ; 13.10..

L’arbre-veilleur et le chaudron

11L’Eternel m’adressa encore la parole en ces termes : Que vois-tu, Jérémie ?

Je répondis : Je vois une branche d’amandier.

12– Tu as bien vu, me dit l’Eternel. Eh bien, je veille1.12 En hébreu, le verbe traduit par veiller fait assonance avec le nom de l’amandier. sur ma parole pour accomplir ce que j’ai dit.

13Puis l’Eternel m’adressa une seconde fois la parole : Que vois-tu encore ?

Et je répondis : Je vois un chaudron en train de bouillir et qui se trouve au nord.

14Et l’Eternel me dit :

C’est, en effet, du nord1.14 Voir 6.22 ; 8.16 ; 10.22 ; etc. ╵que le malheur viendra

se déverser ╵sur tous les habitants de ce pays.

15Car je vais appeler ╵tous les peuples des royaumes du Nord,

l’Eternel le déclare.

Ils viendront, et chacun ╵installera son trône

devant les portes de Jérusalem,

face à tous ses remparts,

et à tous ceux ╵des villes de Juda.

16Et je rendrai mon jugement ╵contre les habitants de ce pays

pour tout le mal qu’ils ont commis ;

parce qu’ils m’ont abandonné,

qu’ils offrent de l’encens ╵à d’autres dieux,

et se prosternent ╵devant les dieux ╵qu’ils se sont fabriqués.

17Toi donc, tu mettras ta ceinture1.17 Pour ne pas s’embarrasser dans les plis du vêtement et se préparer à la tâche.

et tu te lèveras, ╵tu leur diras

tout ce que je t’ordonnerai.

Ne te laisse pas terrifier par eux,

sinon c’est moi qui, devant eux, ╵m’en vais te terrifier.

18Et moi dès aujourd’hui, ╵je fais de toi ╵comme une ville fortifiée,

comme un pilier de fer ╵et un rempart de bronze ╵face à tout le pays :

face aux rois de Juda, ╵à ses ministres,

à ses prêtres et à son peuple.

19Ils te feront la guerre,

mais ils ne l’emporteront pas sur toi,

car je suis avec toi, ╵l’Eternel le déclare, ╵je te délivrerai.