Isaiah 66 – YCB & BDS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 66:1-24

Ìdájọ́ àti ìrètí

166.1-2: Mt 5.34; Ap 7.49-50.Báyìí ni Olúwa wí:

“Ọ̀run ni ìtẹ́ mi,

ayé sì ni àpótí ìtìsẹ̀ mi,

Níbo ni ilé tí ẹ ó kọ́ fún mi wà?

Níbo ní ibi ìsinmi mi yóò gbé wà?

2Kì í ha á ṣe ọwọ́ mi ló tí ṣe nǹkan wọ̀nyí,

bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì wà?”

ni Olúwa wí.

“Eléyìí ni ẹni tí mo kà sí:

ẹni náà tí ó rẹra rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì kẹ́dùn ní ọkàn rẹ̀,

tí ó sì wárìrì sí ọ̀rọ̀ mi.

3Ṣùgbọ́n ẹni tí ó fi akọ màlúù rú ẹbọ

ó dàbí ẹni tí ó pa ènìyàn kan

àti ẹni tí ó bá fi ọ̀dọ́-àgùntàn kan tọrẹ,

dàbí ẹni tí ó bẹ́ ajá kan lọ́rùn;

ẹnikẹ́ni tí ó bá fi irúgbìn ìyẹ̀fun tọrẹ

dàbí ẹni tí ó mú ẹ̀jẹ̀ ẹlẹ́dẹ̀ wá,

ẹni tí ó bá sì sun tùràrí ìrántí,

dàbí ẹni tí ó súre fún òrìṣà.

Wọ́n ti yan ipa ọ̀nà tì wọ́n,

ọkàn wọn pẹ̀lú sì láyọ̀ nínú ohun ìríra wọn;

4Fún ìdí èyí ni èmi pẹ̀lú yóò ṣe fi ọwọ́ líle mú wọn

n ó sì mú ohun tí wọ́n bẹ̀rù rẹ̀ wá sórí wọn.

Nítorí nígbà tí mo pè, kò sí ẹni tí ó dáhùn,

nígbà tí mo sọ̀rọ̀, ẹnikẹ́ni kò tẹ́tí sílẹ̀.

Wọ́n ṣe ohun búburú ní ojú mi

wọ́n sì yan ohun tí mo kórìíra rẹ̀.”

5Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa,

Ẹ̀yin tí ẹ ń wárìrì nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ rẹ̀:

“Àwọn arákùnrin yín tí wọ́n kórìíra yín,

tí wọ́n ta yín nù nítorí orúkọ mi, wí pé,

‘Jẹ́ kí a yin Olúwa lógo,

kí a le rí ayọ̀ yín!’

Ṣùgbọ́n àwọn ni ojú yóò tì.

666.6: If 16.1,17.Gbọ́ rògbòdìyàn láti ìlú wá,

gbọ́ ariwo náà láti tẹmpili wá!

Ariwo tí Olúwa ní í ṣe

tí ó ń san án fún àwọn ọ̀tá rẹ̀ ohun

tí ó tọ́ sí wọn.

766.7: If 12.5.“Kí ó tó lọ sí ìrọbí,

ó ti bímọ;

kí ó tó di pé ìrora dé bá a,

ó ti bí ọmọkùnrin.

8Ta ni ó ti gbọ́ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí?

Ta ni ó ti rí irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí?

Ǹjẹ́ a le bí orílẹ̀-èdè kan níjọ́ kan

tàbí kí orílẹ̀-èdè lalẹ̀hù ní ìṣẹ́jú kan?

Síbẹ̀síbẹ̀ Sioni bẹ̀rẹ̀ rírọbí

bẹ́ẹ̀ ni ó sì bí àwọn ọmọ rẹ̀.

9Ǹjẹ́ èmi a ha máa mú wá sí ìrọbí

kí èmi má sì mú ni bí?”

ni Olúwa wí.

“Ǹjẹ́ èmi a ha máa ṣé ilé ọmọ

nígbà tí mo ń mú ìbí wá?”

Ni Ọlọ́run yín wí.

10“Ẹ bá Jerusalẹmu yọ̀ kí inú yín kí ó sì dùn sí i,

gbogbo ẹ̀yin tí ẹ fẹ́ràn rẹ̀;

ẹ yọ̀ gidigidi pẹ̀lú rẹ̀,

gbogbo ẹ̀yin tí ó ti kẹ́dùn fún un.

11Nítorí pé ẹ̀yin yóò mu ẹ o sì ní ìtẹ́lọ́rùn

nínú ọmú rẹ̀ tí ó tu ni lára;

Ẹ̀yin yóò mu àmuyó

ẹ ó sì gbádùn nínú àkúnwọ́sílẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ rẹ̀.”

12Nítorí báyìí ni Olúwa wí:

“Èmi yóò fún un ní àlàáfíà gẹ́gẹ́ bí odò

àti ọrọ̀ orílẹ̀-èdè gẹ́gẹ́ bí ìṣàn omi;

ẹ̀yin yóò mu ọmú, a ó sì gbé yín ní apá rẹ̀

a ó bá yín ṣeré ní orúkún rẹ̀.

13Gẹ́gẹ́ bí ìyá ti í tu ọmọ rẹ̀ nínú,

bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò tù yín nínú

a ó sì tù yín nínú lórí Jerusalẹmu.”

14Nígbà tí ẹ bá rí èyí, inú yín yóò dùn

ẹ̀yin yóò sì gbilẹ̀ gẹ́gẹ́ bí i koríko;

ọwọ́ Olúwa ni a ó sọ di mí mọ̀ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀,

ṣùgbọ́n ìbínú rẹ̀ ni a ó fihàn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀.

15Kíyèsi i, Olúwa ń bọ̀ pẹ̀lú iná

àti kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ tí ó dàbí ìjì líle;

òun yóò mú ìbínú rẹ sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú ìrunú,

àti ìbáwí rẹ̀ pẹ̀lú ahọ́n iná.

16Nítorí pẹ̀lú iná àti idà

ni Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ lórí i gbogbo ènìyàn,

àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí Olúwa yóò pa.

17“Gbogbo àwọn tí wọ́n ya ara wọn sí mímọ́ tí wọ́n sì sọ ara wọn di mímọ́ láti lọ sínú ọgbà, tí wọ́n tẹ̀lé ẹni tí ó wà láàrín àwọn tí ó jẹ ẹran ẹlẹ́dẹ̀ àti èkúté àti àwọn ohun ìríra mìíràn ni wọn yóò bá òpin wọn pàdé papọ̀,” ni Olúwa wí.

18“Àti Èmi, nítorí ìgbésẹ̀ wọn àti èrò wọn, èmi ti múra tán láti wá kó àwọn orílẹ̀-èdè àti ahọ́n jọ, wọn yóò sì wá wo ògo mi.

19“Èmi yóò sì gbé ààmì kan kalẹ̀ láàrín wọn, èmi yóò sì rán díẹ̀ nínú àwọn tí ó sálà lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè Tarṣiṣi, sí àwọn ará Libia àti Ludi, sí Tubali àti ará Giriki, àti sí àwọn erékùṣù tí ó jìnnà réré tí kò tí ìgbọ́ nípa òkìkí mi tàbí kí ó rí ògo mi. Wọn yóò kéde ògo mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè. 20Wọn yóò sì mú àwọn arákùnrin yín wá, láti gbogbo orílẹ̀-èdè, sí òkè mímọ́ mi ní Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ọrẹ sí Olúwa lórí ẹṣin, lórí kẹ̀kẹ́ ẹrù àti ọkọ-ẹṣin, àti lórí ìbáaka àti ìbákasẹ,” ni Olúwa wí. “Wọn yóò kó wọn wá, gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Israẹli ti mú ọrẹ oníhóró wọn wá, sínú Tẹmpili Olúwa nínú ohun èlò mímọ́. 21Àti pé èmi yóò sì yan àwọn kan nínú wọn pẹ̀lú láti jẹ́ àlùfáà àti Lefi,” ni Olúwa wí.

2266.22: Isa 65.17; 2Pt 3.13; If 21.1.“Gẹ́gẹ́ bí àwọn ọ̀run tuntun àti ayé tuntun tí mo dá yóò ṣe wà níwájú mi títí láé,” ni Olúwa wí, “Bẹ́ẹ̀ ni orúkọ yín àti ìrandíran yín yóò pegedé. 23Láti oṣù tuntun kan dé òmíràn àti láti ọjọ́ ìsinmi kan dé òmíràn, ni gbogbo ọmọ ènìyàn yóò wá, wọn yóò sì tẹríba níwájú mi,” ni Olúwa wí. 2466.24: Mk 9.48.“Wọn yóò sì jáde lọ wọn yóò sì lọ wo òkú àwọn tí wọ́n dìtẹ̀ sí mi; kòkòrò wọn kì yóò kú, bẹ́ẹ̀ ni iná wọn ni a kì yóò pa, bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò sì jẹ́ ohun ìríra fún gbogbo ọmọ ènìyàn.”

La Bible du Semeur

Esaïe 66:1-24

Le nouveau peuple de Dieu

Pour un vrai culte

1Voici ce que dit l’Eternel :

Mon trône, c’est le ciel,

et mon marchepied, c’est la terre66.1 Allusion en Mt 5.34-35 ; 23.22..

Quelle est donc la maison ╵que vous me bâtiriez,

quelle demeure ╵pour mon lieu de repos ?

2Toutes ces choses, ╵c’est moi qui les ai faites66.2 Les v. 1-2 sont cités en Ac 7.49-50.

et ainsi elles sont venues ╵à l’existence,

l’Eternel le déclare.

Voici sur qui je porterai ╵un regard favorable :

sur celui qui est humilié, ╵et qui a l’esprit abattu,

sur celui qui tremble à ma parole.

3Celui qui sacrifie un bœuf,

tue aussi bien un homme ;

celui qui immole un agneau,

rompt la nuque à un chien ;

celui qui présente une offrande

offre du sang de porc ;

et celui qui fait brûler de l’encens,

c’est une idole qu’il bénit.

Comme ils ont tous choisi ╵de suivre leurs propres chemins

et qu’ils prennent plaisir ╵à leurs idoles ╵abominables,

4je choisis moi aussi ╵de les abandonner ╵à leurs caprices,

et je les frapperai ╵des malheurs qu’ils redoutent,

puisque j’ai appelé

et que personne ╵n’a répondu,

oui, puisque j’ai parlé

et que personne ╵n’a écouté,

puisqu’ils ont fait ╵ce que je trouve mal,

et qu’ils se sont complu ╵à ce qui me déplaît.

5Ecoutez la parole ╵de l’Eternel,

vous qui tremblez à sa parole :

Voici, ceux de vos frères

qui vous haïssent ╵et vous ont rejetés

à cause de mon nom

ont dit : « Que l’Eternel ╵manifeste sa gloire

afin que nous soyons ╵témoins de votre joie ! »

Mais ils perdront la face !

6Ecoutez ce tumulte ╵s’élevant de la ville,

cette clameur ╵venant du Temple :

il s’agit de la voix de l’Eternel

qui fait payer ses ennemis ╵comme ils l’ont mérité.

Jérusalem rétablie

7Avant d’être en travail,

Sion a enfanté :

avant d’éprouver des douleurs,

elle a donné le jour ╵à un garçon.

8Qui donc a entendu ╵pareille chose,

et qui a déjà vu ╵chose semblable ?

Un pays peut-il naître ╵en un seul jour ?

Ou peut-on enfanter ╵un peuple en une seule fois ?

Or, à peine en travail ╵Sion a mis des fils au monde !

9Eh quoi ! Déclencherais-je ╵le travail de la femme enceinte

sans la faire enfanter ?

dit l’Eternel.

Moi qui fais enfanter,

empêcherais-je ╵cette venue au monde ?

a dit ton Dieu.

10Réjouissez-vous ╵avec Jérusalem,

et soyez tous dans l’allégresse ╵à son sujet,

vous qui l’aimez !

Prenez part à sa joie,

vous tous qui avez pris ╵le deuil à cause d’elle !

11Car vous serez nourris ╵à son sein qui console

jusqu’à en être rassasiés,

et vous boirez, avec délices,

la plénitude de sa gloire !

12Car ainsi parle l’Eternel :

Je vais faire affluer la paix ╵vers elle comme un fleuve,

la gloire des nations ╵tout comme un torrent qui déborde.

Vous serez allaités,

et portés sur la hanche,

bercés sur les genoux.

13Comme un homme que sa mère console,

je vous consolerai.

Oui, dans Jérusalem, ╵vous serez consolés.

14Vous en serez témoins ╵et votre cœur se réjouira,

votre corps reprendra vigueur ╵tout comme une herbe qui verdit.

Le jugement de Dieu

On verra l’Eternel intervenir ╵en faveur de ses serviteurs,

et manifester son indignation ╵contre ses ennemis.

15Car l’Eternel

va venir dans le feu

et ses chars surviendront ╵comme un vent d’ouragan

pour verser sa colère ╵avec fureur

et pour accomplir ses menaces ╵avec d’ardentes flammes.

16Car, c’est avec le feu ╵que l’Eternel ╵exercera son jugement

et avec son épée ╵qu’il châtiera tous les humains,

et l’Eternel fera ╵un très grand nombre de victimes.

17Ceux qui se préparent et qui se purifient pour accéder aux jardins sacrés66.17 Allusion à des cérémonies païennes pour lesquelles les participants se préparent par divers rites de purification (voir 65.3, 5). suivant en procession celui qui se tient au milieu, et qui mangent du porc, des animaux immondes et même des souris, ceux-là périront tous ensemble, l’Eternel le déclare. 18Car moi, je [connais bien66.18 Les mots entre crochets manquent dans l’hébreu. Le texte semble corrompu car il manque le verbe.] leurs desseins et leurs actes.

Tous les peuples honoreront l’Eternel

Voici, je vais venir66.18 D’après l’ancienne version grecque, la version syriaque et la Vulgate. Le texte hébreu traditionnel est obscur. rassembler tous les peuples et des gens de toutes langues. Ils viendront et verront ma gloire. 19Je placerai un signe au milieu d’eux et j’enverrai certains de leurs rescapés66.19 D’autres comprennent : des rescapés de mon peuple. vers d’autres peuples, à Tarsis, Poul et Loud66.19 Tarsis: l’Espagne. Poul et Loud sont deux peuples de l’Afrique (Somalie et Libye)., dont les gens bandent l’arc, à Toubal, à Yavân66.19 Toubal: peuple d’Asie Mineure au sud-est de la mer Noire. Yavân: la Grèce et ses îles. ; vers les îles et les régions côtières qui sont au loin, qui n’ont pas encore entendu parler de moi et n’ont pas vu ma gloire. Ils feront connaître ma gloire à ces peuples. 20Et ils ramèneront, de chez tous les peuples, tous ceux qui sont vos frères sur des chevaux, des chars ou des chariots couverts, sur le dos des mulets ou sur des dromadaires jusqu’à Jérusalem, à ma montagne sainte, comme une offrande à l’Eternel : ce sera une offrande, dit l’Eternel, semblable à celles qu’apportent les Israélites, dans des récipients purifiés, au temple de l’Eternel. 21Et même, parmi eux, j’en prendrai certains pour être des prêtres ou des lévites, dit l’Eternel.

22Comme le nouveau ciel et la nouvelle terre66.22 Voir Es 65.17 ; 2 P 3.13 ; Ap 21.1. que je vais faire subsisteront par-devant moi, l’Eternel le déclare, ainsi subsisteront votre postérité et votre nom. 23Il adviendra alors que, régulièrement, à chaque nouvelle lune et à chaque sabbat, tous les humains viendront se prosterner devant moi, déclare l’Eternel. 24Et quand ils sortiront, ils verront les cadavres des hommes qui se sont révoltés contre moi ; et le ver qui rongera ces hommes ne mourra pas, le feu qui les dévorera ne s’éteindra jamais66.24 Allusion en Mc 9.48., et ils feront horreur à tout être vivant.