Isaiah 65 – YCB & BDS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 65:1-25

Ìdájọ́ àti ìgbàlà

165.1-2: Ro 10.20-21.“Èmi fi ara mi hàn fún àwọn tí kò béèrè fún mi;

Àwọn tí kò wá mi ni wọ́n rí mi.

Sí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò pe orúkọ mi,

Ni èmi wí pé, ‘Èmi nìyìí, Èmi nìyìí.’

2Gbogbo ọjọ́ ni mo ti nawọ́ mi síta

sí àwọn ènìyàn ọlọ́rùn líle,

tí wọn ń rìn lọ́nà tí kò dára,

tí wọ́n sì gbára lé èrò ara wọn

3àwọn ènìyàn tí wọ́n bí mi nínú nígbà gbogbo

lójú ara mi gan an,

wọ́n ń rú ẹbọ nínú ọgbà

wọ́n sì ń sun tùràrí lórí i pẹpẹ bíríkì;

4wọ́n ń jókòó láàrín ibojì

wọ́n sì ń lo òru wọn nínú ìṣọ́ ìkọ̀kọ̀;

tí wọ́n ń jẹ ẹran ẹlẹ́dẹ̀,

tí ìkòkò ọbẹ̀ wọn kún fún ẹran àìmọ́;

5tí ó wí pé, ‘Ẹ sún mẹ́yìn; ẹ má wá sọ́dọ̀ mi,

nítorí mo ti jẹ́ mímọ́ jù fún un yín!’

Àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ jẹ́ èéfín nínú ihò imú mi

iná tí ń fi gbogbo ọjọ́ jó.

6“Kíyèsi i, a ti kọ ọ́ síwájú mi:

Èmi kì yóò dákẹ́,

ṣùgbọ́n èmi yóò san án padà lẹ́kùnrẹ́rẹ́;

Èmi yóò san án padà sí àyà wọn

7àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yín àti tàwọn baba yín,”

ni Olúwa wí.

“Nítorí pé wọ́n sun ẹbọ ní orí òkè ńlá

wọ́n sì ṣe ẹ̀gbin sí mi ní òkè kékeré,

Èmi yóò wọ́n ọ́n sí itan wọn

ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ẹ̀san ohun gbogbo tí wọ́n ṣe tẹ́lẹ̀.”

8Báyìí ni Olúwa wí:

“Gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí oje sì tún wà nínú àpólà àjàrà

tí àwọn ènìyàn sì wí pé, ‘má ṣe bà á jẹ́,

nítorí ìbùkún ń bẹ nínú rẹ̀,’

bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe nítorí ìránṣẹ́ mi;

Èmi kì yóò pa gbogbo wọn run.

9Èmi yóò mú ìrandíran wá láti ìdílé Jakọbu,

àti láti Juda àwọn tí yóò jogún òkè ńlá mi wọ̀n-ọn-nì;

àwọn àyànfẹ́ ènìyàn mi yóò jogún wọn,

ibẹ̀ ni àwọn ìránṣẹ́ mi yóò sì gbé.

10Ṣaroni yóò di pápá oko fún ọ̀wọ́ ẹran,

àti Àfonífojì Akori yóò di ibi ìsinmi fún agbo ẹran,

fún àwọn ènìyàn mi tí ó wá mi.

11“Ṣùgbọ́n fún ẹ̀yin tí ó kọ Olúwa sílẹ̀

tí ó sì gbàgbé òkè ńlá mímọ́ mi,

tí ó tẹ́ tábìlì fún Gadi

tí ẹ sì kún abọ́ pẹ̀lú ọtí wáìnì fún àtubọ̀tán,

12Èmi yóò yà ọ́ sọ́tọ̀ fún idà,

àti pé ẹ̀yin yóò bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀ fún àwọn tí a pa;

nítorí mo pè, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò dáhùn.

Mo sọ̀rọ̀ ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò tẹ́tí sílẹ̀

Ẹ̀yin ṣe búburú ní ojú mi

ẹ sì yan ohun tí ó bà mí lọ́kàn jẹ́.”

13Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí:

“Àwọn ìránṣẹ́ mi yóò jẹun;

ṣùgbọ́n ebi yóò máa pa ẹ̀yin,

àwọn ìránṣẹ́ mi yóò mu,

ṣùgbọ́n òǹgbẹ yóò máa gbẹ ẹ̀yin;

àwọn ìránṣẹ́ mi yóò ṣe àjọyọ̀,

ṣùgbọ́n a ó dójútì yin.

14Àwọn ìránṣẹ́ mi yóò kọrin

láti inú ayọ̀ ọkàn wọn wá,

ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò kígbe sókè

láti inú ìrora ọkàn yín

àti ìpohùnréré ní ìròbìnújẹ́ ọkàn.

15Ẹ̀yin yóò fi orúkọ yín sílẹ̀

fún àwọn àyànfẹ́ mi gẹ́gẹ́ bí ègún;

Olúwa Olódùmarè yóò sì pa yín,

ṣùgbọ́n fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ni òun

yóò fún ní orúkọ mìíràn

16Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbàdúrà ìbùkún ní ilẹ̀ náà

yóò ṣe é nípasẹ̀ Ọlọ́run òtítọ́;

Ẹni tí ó bá búra ní ilẹ̀ náà

yóò búra nípasẹ̀ Ọlọ́run òtítọ́.

Nítorí ìyọnu àtijọ́ yóò di ìgbàgbé

yóò sì fi ara sin kúrò lójú mi.

Àwọn ọrun tuntun àti ayé tuntun

17“Kíyèsi i, Èmi yóò dá

àwọn ọ̀run tuntun àti ayé tuntun

A kì yóò rántí ohun àtẹ̀yìnwá mọ́,

tàbí kí wọn wá sí ọkàn.

18Ṣùgbọ́n ẹ yọ̀ kí inú yín dùn títí láé

nínú ohun tí èmi yóò dá,

nítorí èmi yóò dá Jerusalẹmu láti jẹ́ ohun ìdùnnú

àti àwọn ènìyàn rẹ̀, ohun ayọ̀.

19Èmi yóò ṣe àjọyọ̀ lórí Jerusalẹmu

n ó sì ní inú dídùn nínú àwọn ènìyàn mi;

ariwo ẹkún àti igbe

ni a kì yóò gbọ́ nínú rẹ̀ mọ́.

20“Títí láé a kì yóò gbọ́ nínú rẹ̀

ọmọ ọwọ́ tí yóò gbé fún ọjọ́ díẹ̀,

tàbí àgbàlagbà tí kì yóò lo ọjọ́ ayé rẹ̀ tán;

ẹni tí ó bá kú ní ìwọ̀n ọgọ́rùn-ún

ni a ó pè ní ọ̀dọ́mọdé;

ẹni tí kò ba le pé ọgọ́rùn-ún kan

ni a ó pè ní ẹni ìfibú.

21Wọn yó ò kọ́ ilé, wọn yóò sì gbé nínú wọn

wọn yóò gbin ọgbà àjàrà, wọn yóò sì jẹ èso wọn.

22Wọn kì yóò kọ́ ilé fún ẹlòmíràn láti gbé,

tàbí kí wọn gbìn fún ẹlòmíràn láti jẹ,

Nítorí gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ orí igi kan,

bẹ́ẹ̀ ní ọjọ́ àwọn ènìyàn mi yóò rí;

àwọn àyànfẹ́ mi yóò jẹ iṣẹ́ ọwọ́

wọn fún ìgbà pípẹ́.

23Wọn kì yóò ṣe iṣẹ́ lásán,

wọn kí yóò bímọ fún wàhálà;

nítorí wọn yóò jẹ́ àwọn ènìyàn ti Olúwa bùkún fún,

àwọn àti àwọn ìrandíran wọn pẹ̀lú wọn.

24Kí wọn tó pè, èmi yóò dáhùn;

nígbà tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, èmi yóò gbọ́.

2565.25: Isa 11.6-9.Ìkookò àti ọ̀dọ́-àgùntàn yóò jẹun pọ̀,

kìnnìún yóò sì jẹ koríko gẹ́gẹ́ bí akọ màlúù,

ṣùgbọ́n erùpẹ̀ ni yóò jẹ́ oúnjẹ ejò.

Wọn kì yóò pa ni lára tàbí pa ni run

ní gbogbo òkè mímọ́ mi,”

ni Olúwa wí.

La Bible du Semeur

Esaïe 65:1-25

La nouvelle création

Le jugement qui vient

1Je me suis laissé consulter

par des personnes ╵qui ne demandaient rien,

et je me suis laissé trouver

par des personnes ╵qui ne me cherchaient pas.

J’ai dit : « Je suis là, je suis là ! »

aux gens d’un peuple ╵qui n’était pas appelé par mon nom65.1 Autre traduction : qui n’étaient pas appelés par mon nom. Les v. 1-2 sont cités en Rm 10.20-21 d’après l’ancienne version grecque..

2Par contre, j’ai tendu les mains, ╵à longueur de journée, ╵vers un peuple rebelle

qui suivait un chemin ╵qui n’est pas bon,

au gré de ses pensées,

3un peuple qui, sans cesse, ╵provoque ma colère ╵ouvertement.

Ses habitants offrent des sacrifices ╵dans les jardins sacrés,

et brûlent des parfums ╵sur des autels de briques.

4Ils s’asseyent parmi les tombeaux ╵pour consulter les morts

et passent la nuit dans les grottes.

Ils consomment du porc

et remplissent leurs plats ╵de mets impurs.

5Ils crient : « Reste où tu es

et ne m’approche pas,

car je suis trop sacré pour toi65.5 Autre traduction : je te rendrais sacré.. »

Ces choses sont pour moi ╵comme de la fumée ╵qui me monte aux narines,

un feu qui brûle tout le jour.

6Mais tout cela ╵reste écrit devant moi ;

je ne me tairai plus, ╵je le leur ferai payer jusqu’au bout.

7Je leur ferai payer leurs crimes

dit l’Eternel,

en même temps ╵que ceux de leurs ancêtres,

car ils ont brûlé des parfums ╵sur les montagnes

et ils m’ont outragé ╵sur les collines !

Oui, je leur ferai payer jusqu’au bout

ce que mérite ╵leur conduite passée.

8Voici ce que dit l’Eternel :

De même que l’on dit, ╵quand on trouve une grappe bien juteuse ╵sur une vigne :

« Ne la détruisez pas

car il y a en elle ╵quelque chose de bon »,

moi, je ferai de même ╵à cause de mes serviteurs.

Pour ne pas tout détruire,

9je ferai sortir de Jacob ╵une postérité,

oui, de Juda, des gens ╵qui prendront possession ╵de mes montagnes.

Mes élus les posséderont,

mes serviteurs ╵y feront leur demeure.

10La plaine du Saron ╵sera un pâturage ╵pour le menu bétail,

et la vallée d’Akor65.10 La plaine du Saron, en bordure de la mer Méditerranée, était réputée pour sa fertilité. La vallée d’Akor se trouve au nord-ouest de la mer Morte. ╵un gîte pour les bœufs

au profit de mon peuple ╵qui se sera tourné vers moi.

11Mais quant à vous ╵qui abandonnez l’Eternel,

et qui négligez ma montagne sainte,

qui dressez une table ╵au dieu de la Fortune

et remplissez la coupe ╵pour le dieu du Destin,

12je vous destine au glaive,

et vous vous courberez ╵pour passer tous à l’abattoir,

puisque j’ai appelé

et que vous ne m’avez pas répondu,

et puisque j’ai parlé

et que vous ne m’avez pas écouté,

puisque vous avez fait ╵ce que je trouve mal,

et que vous vous êtes complu ╵dans ce qui me déplaît.

13C’est pourquoi, voici ce que dit ╵le Seigneur, l’Eternel :

Mes serviteurs ╵auront de quoi manger,

et vous, vous aurez faim.

Mes serviteurs boiront,

et vous, vous aurez soif.

Mes serviteurs ╵seront dans l’allégresse,

et vous, vous serez dans la honte !

14Mes serviteurs crieront de joie

car ils connaîtront le bonheur.

Quant à vous, vous crierez

le cœur plein de douleur,

vous vous lamenterez,

l’esprit tout abattu.

15Votre nom restera ╵dans les imprécations ╵de mes élus ;

le Seigneur, l’Eternel, ╵fera que vous mouriez,

mais à ses serviteurs ╵il donnera un nom nouveau.

16Et celui qui voudra ╵être béni sur terre

invoquera sur lui ╵une bénédiction ╵au nom du Dieu de vérité,

et sur la terre, ╵qui prêtera serment ╵jurera par le Dieu de vérité.

Nouveaux cieux, nouvelle terre

En effet, les maux du passé ╵seront tous oubliés,

ils disparaîtront de ma vue.

17Je vais créer ╵un ciel nouveau,

une nouvelle terre ;

on ne se rappellera plus ╵les choses d’autrefois,

on n’y pensera plus65.17 Voir Es 66.22 ; 2 P 3.13 ; Ap 21.1..

18Réjouissez-vous plutôt

et soyez à toujours ╵tout remplis d’allégresse

à cause de ce que je crée.

Oui, car je vais créer ╵une Jérusalem ╵remplie de joie

et son peuple plein d’allégresse.

19J’exulterai moi-même ╵à cause de Jérusalem

et je me réjouirai ╵au sujet de mon peuple.

On n’y entendra plus de pleurs

ni de cris de détresse65.19 Voir Ap 21.4..

20Là, plus de nourrisson

emporté en bas âge,

ni de vieillard qui meure ╵avant d’avoir atteint ╵le nombre de ses ans.

Ce sera mourir jeune ╵de mourir centenaire ;

si un pécheur ╵ne dépasse pas les cent ans65.20 Autre traduction : Si quelqu’un n’atteint pas l’âge de cent ans., ╵c’est qu’il aura été maudit.

21Ils se construiront des maisons

et les habiteront ;

ils planteront des vignes

et ils en mangeront les fruits ;

22ils ne bâtiront plus ╵des maisons pour qu’un autre ╵y habite à leur place,

ils ne planteront plus de vignes

pour qu’un autre en mange les fruits.

Car les gens de mon peuple ╵vivront aussi longtemps qu’un arbre.

Mes élus jouiront ╵du fruit de leur travail.

23Ils ne peineront plus pour rien

et les enfants ╵auxquels ils donneront naissance ╵ne seront plus destinés au malheur.

Ils seront une race ╵bénie par l’Eternel,

et leur postérité ╵le sera avec eux.

24Alors, avant qu’ils ne m’invoquent,

je les exaucerai ;

ils parleront encore,

que j’aurai déjà entendu.

25Les loups et les agneaux ╵paîtront ensemble,

le lion mangera du fourrage ╵tout comme le bétail ;

le serpent mordra la poussière.

Il ne se fera plus ╵ni mal, ni destruction,

sur toute ma montagne sainte,

dit l’Eternel65.25 Reprend Es 11.6-9. !