Habakuku 2 – YCB & OL

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Habakuku 2:1-20

Ìdáhùn Ọlọ́run sí ìráhùn wòlíì Habakuku

12.1: Isa 21.8.Èmi yóò dúró lórí ibusọ́ mi láti máa wòye

Èmi yóò sì gbé ara mi ka orí alóre

Èmi yóò si ṣọ́ láti gbọ́ ohun tí yóò sọ fún mi

àti èsì ti èmi yóò fún ẹ̀sùn yìí nígbà tó bá ń bá mi wí.

Ìdáhùn Olúwa

2Nígbà náà ni Olúwa dáhùn pé:

“Kọ ìṣípayá náà sílẹ̀

kí o sì fi hàn ketekete lórí wàláà

kí ẹni tí ń kà á, lè máa sáré.

32.3: Hb 10.37.Nítorí ìṣípayá náà jẹ́ tí ìgbà kan tí a múra sílẹ̀ dè;

yóò máa yára sí ìgbẹ̀yìn

kí yóò sìsọ èké.

Bí o tilẹ̀ lọ́ra, dúró dè é;

nítorí, dájúdájú, yóò dé, kí yóò sí pẹ́.”

42.4: Ro 1.17; Ga 3.11; Hb 10.38-39.“Kíyèsi, ọkàn rẹ tí ó gbéga;

Ìfẹ́ rẹ̀ kò dúró ṣinṣin nínú rẹ̀,

ṣùgbọ́n olódodo yóò wa nípa ìgbàgbọ́ rẹ̀.

5Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lú, nítorí tí ọtí wáìnì ni ẹ̀tàn,

agbéraga ènìyàn òun, kò sì ní sinmi

ẹni tí ó sọ ìwọra rẹ di gbígbòòrò bí isà òkú,

ó sì dàbí ikú, a kò sì le tẹ́ ẹ lọ́rùn,

ó kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ sí ọ̀dọ̀

ó sì gba gbogbo ènìyàn jọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀.

6“Gbogbo àwọn wọ̀nyí kì yóò máa pa òwe sí i tí wọn yóò sì máa kọ orin òwe sí i wí pé,

“ ‘Ègbé ni fún ẹni tí ń mu ohun tí kì í ṣe tirẹ̀ pọ̀ sí i!

Tí ó sì sọ ara rẹ̀ di ọlọ́rọ̀ nípasẹ̀ ìlọ́nilọ́wọ́gbà!

Eléyìí yóò ha ti pẹ́ tó?’

7Ǹjẹ́ ẹni ti ó yọ ọ́ lẹ́nu, kí yóò ha dìde ní òjijì?

Àti àwọn tí ó wàhálà rẹ kì yóò jí, kí wọn ó sì dẹ́rùbà ọ́?

Nígbà náà ni ìwọ yóò wa dí ìkógun fún wọn.

8Nítorí ìwọ ti kó orílẹ̀-èdè púpọ̀,

àwọn ènìyàn tókù yóò sì kó ọ

nítorí ìwọ tí ta ẹ̀jẹ̀ ènìyàn sílẹ̀; nítorí ẹ̀jẹ̀

Ìwọ tí pa ilẹ̀ àti ìlú ńlá run

àti gbogbo ènìyàn to ń gbé inú rẹ̀.

9“Ègbé ni fún ẹni tí ń jẹ èrè ìjẹkújẹ sí ilé rẹ̀,

tí o sí gbé ìtẹ́ rẹ̀ lórí ibi gíga,

kí a ba le gbà á sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ibi!

10Ìwọ ti gbìmọ̀ ìtìjú sí ilé rẹ

nípa kíké ènìyàn púpọ̀ kúrò;

ìwọ sì ti pàdánù ẹ̀mí rẹ

11Nítorí tí òkúta yóò kígbe jáde láti inú ògiri wá,

àti ìtí igi láti inú igi rírẹ́ wá yóò sì dá a lóhùn.

12“Ègbé ni fún ẹni tí ó fi ẹ̀jẹ̀ kọ́ ìlú,

tí o sì fi àìṣedéédéé tẹ ìlú ńlá dó?

13Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun kò ha ti ṣètò rẹ̀ pé

làálàá àwọn ènìyàn jẹ́ epo fún iná

kí àwọn orílẹ̀-èdè náà sì máa ṣe wàhálà fún asán?

14Nítorí tí ayé yóò kún fún ìmọ̀ ògo Olúwa,

bí omi ti bo Òkun.

15“Ègbé ni fún ẹni tí ó fi ohun mímu fún aládùúgbò rẹ̀,

tí ó sì fi ọtí-lílé rẹ̀ fún un, tí o sì jẹ́ kó mu àmupara,

kí ìwọ kí ó ba lè wo ìhòhò wọn”

16Ìtìjú yóò bò ọ́ dípò ògo, ìwọ náà mu pẹ̀lú

kí ìhòhò rẹ kí ó lè hàn,

ago ọwọ́ ọ̀tún Olúwa, yóò yípadà sí ọ,

ìtìjú yóò sì bo ògo rẹ.

17Nítorí ìwà ipá tí ó tí hù sí Lebanoni yóò bò ọ́,

àti ìparun àwọn ẹranko yóò dẹ́rùbà ọ́ mọ́lẹ̀

Nítorí ìwọ tí ta ẹ̀jẹ̀ ènìyàn sílẹ̀;

ìwọ tí pa ilẹ̀ náà àti ìlú ńlá run àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.

18“Èrè kí ni òrìṣà ni, tí oníṣọ̀nà rẹ̀ fi gbẹ́ ẹ,

ère dídá ti ń kọ ni èké?

Nítorí ti ẹni ti ó dá a gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé ohun tí ó fúnrarẹ̀ dá;

ó sì mọ ère tí kò le fọhùn.

19Ègbé ni fún ẹni ti ń sọ fún igi pé, ‘di alààyè?’

Fún òkúta tí kò lè fọhùn pé, ‘Dìde’

Ǹjẹ́ òun lè tọ́ ni sí ọ̀nà?

Wúrà àti fàdákà ni a fi bò ó yíká;

kò sì sí èémí kan nínú rẹ.”

202.20: Sf 1.7; Sk 2.13.Ṣùgbọ́n Olúwa wà nínú tẹmpili mímọ́ rẹ̀;

Ẹ jẹ́ kí gbogbo ayé parọ́rọ́ níwájú rẹ.

O Livro

Habacuque 2:1-20

1Subirei à minha torre de vigia, como sentinela, e esperarei para ouvir o que Deus irá dizer e que resposta irá dar à minha queixa.

A resposta do Senhor

2E o Senhor disse-me: “Escreve a minha resposta em tábuas de barro, de forma legível e clara, para que até aquele que passa a correr consiga ler. 3No entanto, ainda não chegou o tempo de se realizar esta visão; mas vai-se aproximando o tempo e, por fim, a visão se cumprirá. Espera mais um pouco, mesmo que pareça demorar, pois certamente virá e não demorará!

4Toma nota disto: o ímpio está cada vez mais arrogante; mas o justo pela sua fé viverá! 5Mais ainda, estes arrogantes caldeus são atraiçoados pelo vinho a que se entregam, que é uma bebida enganadora. Na sua voracidade conquistaram muitas nações, mas à semelhança da morte e do mundo dos mortos2.5 Sheol., nunca ficam satisfeitos. 6Virá o tempo em que todos os seus cativos os insultarão dizendo: ‘Ladrões! A justiça acabou por apanhar-vos! Hão de ser duramente recompensados pela opressão e pela rapina que praticaram!’

7De repente, os vossos devedores levantar-se-ão com raiva contra vocês e levarão tudo o que possuem, enquanto vocês ficam isolados, tremendo. 8Arruinaram muitas nações; agora serão elas que vos destruirão, por causa do sangue que derramaram e da vossa violência contra a terra, a cidade e os seus habitantes.

9Ai de vocês, que se enriqueceram por processos fraudulentos, pensando que podiam viver sem riscos! 10Pelos assassínios que praticaram mancharam o vosso nome e fizeram perder-se as vossas almas. 11As próprias pedras das vossas casas clamam contra vocês e as traves do teto ecoam os mesmos dizeres.

12Ai de vocês que constroem cidades com o dinheiro obtido pelo assassinato e pelo roubo! 13Não decretou o Senhor dos exércitos que o trabalho das nações sem Deus se desfará em cinzas nas suas mãos? Trabalham duramente, mas tudo em vão! 14Há de vir o tempo em que a Terra se encherá do conhecimento da glória do Senhor, tal como as águas enchem o mar!

15Ai de vocês, que fazem os vossos vizinhos cambalear e cair como os bêbedos, sob os vossos golpes, e depois escarnecem da sua nudez! 16Em breve a vossa glória será substituída pelo opróbrio. Terão de beber o copo do julgamento do Senhor, até ficarem tontos e caírem! 17Fizeram violência contra o Líbano destruindo as suas florestas; com violência serão abatidos. Aterrorizaram os animais selvagens que prendiam nas vossas redes de armadilhas; agora será o terror que vos cairá em cima, em recompensa pela morte e violência que trouxeram a tantas partes do mundo.

18Que proveito tiveram em adorar todos esses ídolos feitos por mãos de homens? Que loucura pensarem que esses objetos de metal podiam ser de alguma ajuda! Que estupidez confiarem naquilo que vocês mesmos fabricaram, ídolos mudos e inúteis! 19Ai dos que dizem a ídolos sem vida, feitos de madeira, para se erguerem! Ai dos que clamam a pedaços de pedra, que não podem falar, para lhes dizer o que hão de fazer. Poderão imagens esculpidas falar em nome de Deus? Estão cobertas de ouro e de prata, mas não há espírito nelas!”

20O Senhor, sim, está no seu santo templo! Que toda a Terra se cale diante dele!