Habakuku 3 – YCB & OL

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Habakuku 3:1-19

Àdúrà Habakuku

1Àdúrà wòlíì Habakuku gẹ́gẹ́ bí sígónótì. Ohun èlò orin.

2Olúwa mo tí gbọ́ ohùn rẹ;

ẹ̀rù sì ba mi fún iṣẹ́ rẹ Olúwa

sọ wọn di ọ̀tún ní ọjọ́ ti wa,

ní àkókò tiwa, jẹ́ kó di mí mọ̀;

ni ìbínú, rántí àánú.

3Ọlọ́run yóò wa láti Temani,

ibi mímọ́ jùlọ láti Òkè Parani

ògo rẹ̀ sí bo àwọn ọ̀run,

ilé ayé sì kún fún ìyìn rẹ

4Dídán rẹ sí dàbí ìmọ́lẹ̀ oòrùn

ìtànṣán ìmọ́lẹ̀ jáde wa láti ọwọ́ rẹ,

níbi tí wọn fi agbára rẹ̀ pamọ́ sí.

5Àjàkálẹ̀-ààrùn ń lọ ni iwájú rẹ;

ìyọnu sí ń tọ ẹsẹ̀ rẹ lọ.

6Ó dúró, ó sì mi ayé;

ó wò, ó sì mú àwọn orílẹ̀-èdè wárìrì

a sì tú àwọn òkè ńlá ayérayé ká,

àwọn òkè kéékèèkéé ayérayé sì tẹríba:

ọ̀nà rẹ ayérayé ni.

7Mo rí àgọ́ Kuṣani nínú ìpọ́njú

àti àwọn ibùgbé Midiani nínú ìrora.

8Ǹjẹ́ ìwọ ha ń bínú sí àwọn Odò nì, Olúwa?

Ǹjẹ́ ìbínú rẹ wa lórí àwọn odò ṣíṣàn bí?

Ìbínú rẹ ha wá sórí Òkun

tí ìwọ fi ń gun ẹṣin,

àti kẹ̀kẹ́ ìgbàlà rẹ?

9A ṣí ọrun rẹ sílẹ̀ pátápátá,

gẹ́gẹ́ bí ìbúra àwọn ẹ̀yà, àní ọ̀rọ̀ rẹ,

ìwọ sì fi odò pín ilẹ̀ ayé.

10Àwọn òkè ńlá ri ọ wọn sì wárìrì

àgbàrá òjò ń sàn án kọjá lọ;

ibú ń ké ramúramù

ó sì gbé irú omi sókè.

11Òòrùn àti Òṣùpá dúró jẹ́ẹ́jẹ́ ni ibùgbé wọn,

pẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ ọfà rẹ ni wọn yára lọ,

àti ni dídán ọ̀kọ̀ rẹ ti ń kọ mànà.

12Ní ìrunú ni ìwọ rin ilẹ̀ náà já,

ní ìbínú ni ìwọ tí tẹ́ àwọn orílẹ̀-èdè rẹ.

13Ìwọ jáde lọ láti tú àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀,

àti láti gba ẹni ààmì òróró rẹ là;

Ìwọ ti run àwọn olórí kúrò nínú ilẹ̀ àwọn ènìyàn búburú,

ó sì bọ ìhámọ́ra rẹ láti orí de ẹsẹ̀

14Pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀ kí ó fi gún orí rẹ

nígbà tí àwọn jagunjagun rẹ̀

jáde láti tú wá ká:

ayọ̀ wọn sì ni láti jẹ tálákà run ní ìkọ̀kọ̀.

15Ìwọ fi ẹṣin rẹ rìn Òkun já,

ó sì da àwọn omi ńlá ru.

16Mo gbọ́, ọkàn mi sì wárìrì,

ètè mi sì gbọ̀n sí ìró náà;

ìbàjẹ́ sì wọ inú egungun mi lọ,

ẹsẹ̀ mi sì wárìrì,

mo dúró ni ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ fún ọjọ́ ìdààmú

láti de sórí àwọn ènìyàn tó ń dojúkọ wá.

17Bí igi ọ̀pọ̀tọ́ ko tilẹ̀ tanná,

tí èso kò sí nínú àjàrà;

tí igi olifi ko le so,

àwọn oko ko sì mú oúnjẹ wá;

tí a sì ké agbo ẹran kúrò nínú agbo,

tí kò sì sí ọwọ́ ẹran ni ibùso mọ́,

18síbẹ̀, èmi ó láyọ̀ nínú Olúwa,

èmi yóò sí máa yọ nínú Ọlọ́run ìgbàlà mi.

19Olúwa Olódùmarè ni agbára mi,

òun yóò sí ṣe ẹsẹ̀ mi bí ẹsẹ̀ abo àgbọ̀nrín,

yóò sí mú mi rìn lórí ibi gíga.

O Livro

Habacuque 3:1-19

A oração de Habacuque

1Esta é a oração que o profeta Habacuque cantou, em forma de lamentação:

2Ó Senhor, agora ouvi a tua palavra

e adoro-te pelas coisas tremendas que realizaste!

Nestes tempos de profunda angústia,

ajuda-nos novamente, como fizeste em anos passados.

Mostra-nos o teu poder em nos socorrer!

Na tua ira, lembra-te da misericórdia!

3Deus veio de Temã,

do monte Parã veio o Deus santo. Pausa

O seu brilho é como o de um relâmpago.

A sua glória enche o céu.

Tudo na Terra justifica o louvor que lhe é dado!

Que Deus maravilhoso ele é!

4Da sua mão saem relâmpagos fulgurantes.

Não conhecemos toda a extensão do seu imenso poder.

5Adiante dele vai a peste

e a praga segue no seu encalço.

6Parou e a Terra estremeceu, ficou um momento fitando-a.

Por um momento, olhou e fez tremer todas as nações;

abalou as montanhas eternas e nivelou os outeiros.

Os caminhos dele são eternos!

7Vejo o povo de Cuchan cheio de pavor

e os habitantes de Midiã em terror mortal.

8Acaso é contra os rios, Senhor,

e contra os ribeiros que estás irado?

Estava contra o mar, o teu furor,

quando cavalgaste nos teus cavalos sobre as nuvens,

nos teus carros de vitória?

9Tu tiras o teu arco do saco

e enches a aljava de flechas!

10As montanhas viram-no e tremeram.

O mar ruge e as suas ondas levantam-se alto.

11O Sol e a Lua param a sua carreira perante os raios

e relâmpagos da tua lança.

12Caminhaste pela Terra com indignação,

pisaste as nações com a tua ira.

13Saíste para salvar o teu povo escolhido.

Esmagaste a cabeça do ímpio,

deixando-lhe só ossos dos pés à cabeça.

14Destruíste com as suas próprias armas

os que vieram como um furacão sobre Israel,

a fim de nos espalhar com maligno prazer,

como se estivessem prestes a devorar o necessitado em seu abrigo.

15Os teus cavaleiros atravessaram o mar

e tornaram as águas revoltas.

16Tremi quando ouvi tudo isso;

os meus lábios tremeram de medo;

as pernas foram-se abaixo e fiquei todo tremendo.

No entanto, esperarei calmamente o dia da angústia,

na esperança de que Deus se voltará contra o invasor.

17Ainda que na figueira tenham sido destruídos todos os figos,

e na videira não haja fruto,

ainda que a oliveira seque e os campos se tornem estéreis,

ainda que os rebanhos morram no meio das pastagens

e os currais fiquem vazios,

18contudo, eu me alegrarei no Senhor,

serei feliz no Deus da minha salvação!

19O Senhor Deus é a minha força;

torna os meus pés ligeiros como os da gazela

e guarda-me em segurança nos lugares altos.