Habakuku 1 – YCB & OL

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Habakuku 1:1-17

1Àsọtẹ́lẹ̀ tí wòlíì Habakuku rí.

Ìráhùn Habakuku

21.2: Isa 13.1–14.23; 47; Jr 50–51.Olúwa, èmi yóò ti ké pẹ́ tó fún ìrànlọ́wọ́,

Ṣùgbọ́n ti ìwọ kò ni fetí sí mi?

Tàbí kígbe sí ọ ní ti, “Ìwà ipá!”

ṣùgbọ́n tí ìwọ kò sì gbàlà?

3Èéṣe tí ìwọ fi mú mi rí àìṣedéédéé

Èéṣe tí ìwọ sì fi ààyè gba ìwà ìkà?

Ìparun àti ìwà ipá wà ní iwájú mi;

ìjà ń bẹ, ìkọlù sì wà pẹ̀lú.

4Nítorí náà, òfin di ohun àìkàsí,

ìdájọ́ òdodo kò sì borí.

Àwọn ẹni búburú yí àwọn olódodo ká,

Nítorí náà ni ìdájọ́ òdodo ṣe yí padà.

Ìdáhùn Olúwa

51.5: Ap 13.41.“Ẹ wo inú àwọn kèfèrí, ki ẹ sí wòye,

Kí háà kí ó sì ṣe yin gidigidi.

Nítorí èmi ó ṣe ohun kan ní ọjọ́ yín

tí ẹ̀yin kò jẹ́ gbàgbọ́,

bí a tilẹ̀ sọ fún yin.

61.6: If 20.9.Nítorí pé, èmi yóò gbé àwọn ara Babeli dìde,

àwọn aláìláàánú àti onínú-fùfù ènìyàn

tí ó rin gbogbo ilẹ̀ ayé já

láti fi agbára gbà àwọn ibùgbé tí kì í ṣe tiwọn.

7Wọn jẹ́ ènìyàn ti a bẹ̀rù, tí a sì páyà,

ìdájọ́ wọn, àti ọláńlá wọn,

Yóò máa ti inú wọn jáde.

8Ẹṣin wọn yára ju ẹkùn lọ,

wọ́n sì gbóná jú ìkookò àṣálẹ́ lọ

àwọn ẹlẹ́ṣin wọn yóò sí tan ara wọn ká;

wọn yóò sì wá láti ọ̀nà jíjìn réré,

wọn yóò sí fò bí ẹyẹ igún tí ń wá láti jẹrun

9Gbogbo wọn sì wà fún ìwà ipá

ìwò ojú wọn yóò sì wá síwájú;

wọn sì ko ìgbèkùn jọ bí iyanrìn.

10Wọn ó si máa fi àwọn ọba ṣẹ̀sín

wọn ó sì tún kẹ́gàn àwọn aládé.

Wọn yóò sì fi gbogbo ìlú odi alágbára nì rẹ́rìn-ín;

Nítorí pé, wọn yóò ko erùpẹ̀ jọ, wọn yóò sì gbà á

11Nígbà náà ni inú rẹ̀ yóò yípadà,

yóò sì rékọjá, yóò si ṣẹ̀ ní kíka agbára rẹ̀ yìí sí iṣẹ́ òrìṣà rẹ̀.”

Ìráhùn lẹ́ẹ̀kejì Habakuku

12Olúwa, ǹjẹ́ láti ayérayé kọ ni ìwọ tí wà?

Olúwa Ọlọ́run mi. Ẹni mímọ́ mi, àwa kì yóò kú

Olúwa, ìwọ tí yàn wọn fún ìdájọ́;

Ọlọ́run alágbára, ìwọ tí fi ẹsẹ̀ wọn múlẹ̀ fún ìbáwí

13Ojú rẹ mọ́ tónítóní láti wo ibi;

ìwọ kò le gbà ìwà ìkà

nítorí kí ni ìwọ ṣe gba àwọn alárékérekè láààyè?

Nítorí kí ni ìwọ ṣe dákẹ́ nígbà tí ẹni búburú ń pa

ẹni tí i ṣe olódodo ju wọn lọ run?

14Ìwọ sì tí sọ ènìyàn di bí ẹja inú Òkun,

bí ohun tí ń rákò tí wọn ko ni alákòóso

15Àwọn ènìyàn búburú fi àwọ̀n wọn gbé wọn sókè

ó sì kó wọn jọ nínú àwọ̀n ńlá rẹ̀;

nítorí náà, ó dunnú, ó sì yọ̀ pẹ̀lú.

16Nítorí náà, ó rú ẹbọ sí àwọ̀n rẹ̀,

ó sì ń sun tùràrí fún àwọ̀n ńlá rẹ̀

nítorí pẹ̀lú àwọ̀n rẹ̀ ni ó fi ń gbé ní ìgbádùn

tí ó sì ń gbádùn pẹ̀lú oúnjẹ tí ó bá wù ú.

17Ǹjẹ́ wọn yóò ha máa pa àwọ̀n wọn mọ́ ní òfìfo bí,

tí wọn yóò sì pa orílẹ̀-èdè run láìsí àánú?

O Livro

Habacuque 1:1-17

A queixa de Habacuque

1Esta é a mensagem que foi dirigida ao profeta Habacuque numa visão da parte de Deus.

2Ó Senhor, quanto tempo terei eu ainda de esperar até que me ouças? Até quando denunciarei diante de ti a violência, sem que nos venhas salvar? 3Porque me fazes ver a iniquidade e a injustiça? Para onde quer que me volte, apenas vejo destruição e violência, gente que só está satisfeita em contender, em contestar o que é justo. 4A lei não é acatada; não se respeita a justiça nos tribunais. Os maus prevalecem claramente sobre os retos. Predomina o suborno e a corrupção.

A resposta do Senhor

5Responde o Senhor: “Olhem para as nações! Vejam e maravilhem-se com o que veem, pois vou mostrar nos vossos dias uma obra tal que nem acreditariam, ainda que vo-la contassem. 6Suscitarei os caldeus, uma nação cruel, violenta, que atravessará o mundo, apoderando-se de tudo o que não é seu. 7São um povo terrível e espantoso. Fazem o que imaginam, sem que ninguém os impeça. 8Têm cavalos; são mais rápidos que leopardos, mais ferozes que lobos ao anoitecer. Avançam com a sua cavalaria vindo de terras afastadas. Como águias, em voo picado, caem sobre a presa. 9Todos os que se lhes opõem, só com o terror, derretem-se diante deles. Amontoam cativos como se fosse areia. 10Riem-se dos reis e dos governantes; troçam dos lugares fortificados. Amontoam simplesmente terra em rampas, junto às muralhas, e já estão capturadas! 11Contudo, passarão rapidamente como o vento. A sua culpa é enorme, visto atribuírem o poder que têm aos seus falsos deuses.”

A segunda queixa de Habacuque

12Ó Senhor, meu Deus, meu santo, tu que és eterno! Será que o teu plano a nosso respeito é dispersar-nos para longe? Com certeza que não! Ó Deus, nossa rocha, foste tu mesmo quem decretou o levantamento destes caldeus para nos ferirem e castigarem, por causa dos nossos terríveis pecados. 13Nós somos maus, mas eles são muito mais! Será que tu, que não suportas o pecado sob nenhuma forma, vais ficar indiferente enquanto nos engolem vivos? Ficarás silencioso enquanto uns malvados destroem aqueles que são melhores do que eles?

14Seremos nós como peixes, que servem para ser apanhados e comidos, que não têm quem os governe, ou como répteis que são apanhados e esmagados? 15Prendem-nos no seu anzol; somos apanhados nos seus ardis e depois ficam a rir-se de nós. 16Acabam por adorar as suas próprias redes e por lhes queimar incenso! “São estes os deuses que nos tornaram poderosos”, dizem eles.

17Vais permitir que continuem assim para sempre? Irão prosperar nessa guerra cruel?