Galatia 5 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Galatia 5:1-26

Òmìnira nínú Jesu

1Nítorí náà, ẹ dúró ṣinṣin nínú òmìnira náà èyí tí Kristi fi sọ wá di òmìnira, kí ẹ má sì ṣe tún fi ọrùn bọ̀ àjàgà ẹrú mọ́.

2Kíyèsi i, èmi Paulu ni ó wí fún yín pé, bí a bá kọ yín nílà abẹ́, Kristi kì yóò lérè fún yín ní ohunkóhun. 3Mo sì tún sọ fún olúkúlùkù ènìyàn tí a kọ ní ilà pé, ó di ajigbèsè láti pa gbogbo òfin mọ́. 4A ti yà yín kúrò lọ́dọ̀ Kristi, ẹ̀yin tí ń fẹ́ kí a dá yín láre nípa òfin; pé ẹ ti ṣubú kúrò nínú oore-ọ̀fẹ́. 5Nítorí nípa Ẹ̀mí àwa ń fi ìgbàgbọ́ dúró de ìrètí òdodo. 65.6: 1Kọ 7.19; Ga 6.15.Nítorí nínú Kristi Jesu, ìkọlà kò jẹ́ ohun kan, tàbí àìkọlà; ṣùgbọ́n ìgbàgbọ́ ti ń ṣiṣẹ́ nípa ìfẹ́.

7Ẹ̀yin ti ń sáré dáradára. Ta ni dí yin lọ́wọ́ láti ṣe ìgbọ́ràn sí òtítọ́? 8Ìyípadà yìí kò ti ọ̀dọ̀ ẹni tí ó pè yín wá. 95.9: 1Kọ 5.6.Ìwúkàrà díẹ̀ ní í mú gbogbo ìyẹ̀fun wú. 10Mo ní ìgbẹ́kẹ̀lé sí yín nínú Olúwa pé, ẹ̀yin kì yóò ní èrò ohun mìíràn; ṣùgbọ́n ẹni tí ń yọ yín lẹ́nu yóò ru ìdájọ́ tirẹ̀, ẹnikẹ́ni tí ó wù kí ó jẹ́. 11Ṣùgbọ́n, ará, bí èmi bá ń wàásù ìkọlà síbẹ̀, kín ni ìdí tí a fi ń ṣe inúnibíni sí mi síbẹ̀? Ǹjẹ́ ìkọ̀sẹ̀ àgbélébùú ti kúrò. 12Èmi ìbá fẹ́ kí àwọn tí ń yọ yín lẹ́nu tilẹ̀ gé ẹ̀yà ara wọn kan kúrò.

13Nítorí a ti pè yín sí òmìnira, ará kìkì pé kí ẹ má ṣe lo òmìnira yín bí àǹfààní sípa ti ara, ṣùgbọ́n ẹ máa fi ìfẹ́ sin ọmọnìkejì yín. 145.14: Le 19.18; Ro 13.8-10.Nítorí pé a kó gbogbo òfin já nínú èyí pé, “Ìwọ fẹ́ ọmọnìkejì rẹ gẹ́gẹ́ bí ara rẹ.” 15Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá ń bu ara yín ṣán, tí ẹ sì ń jẹ ara yín run, ẹ kíyèsára kí ẹ má ṣe pa ara yín run.

Ìyè nípa ti ẹ̀mí

16Ǹjẹ́ mo ní, Ẹ máa rìn nípa ti Ẹ̀mí, ẹ̀yin kì yóò sì mú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ti ara ṣẹ. 175.17: Ro 7.15-23.Nítorí ti ara ń ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ lòdì sí Ẹ̀mí, àti Ẹ̀mí lòdì sí ara: àwọn wọ̀nyí sì lòdì sí ara wọn; kí ẹ má ba à lè ṣe ohun tí ẹ̀yin ń fẹ́. 18Ṣùgbọ́n bí a bá ń ti ọwọ́ Ẹ̀mí ṣamọ̀nà yín, ẹ̀yin kò sí lábẹ́ òfin.

195.19: Ro 1.28.Ǹjẹ́ àwọn iṣẹ́ tí ara farahàn, tí í ṣe wọ̀nyí; panṣágà, àgbèrè, ìwà èérí, wọ̀bìà, 20Ìbọ̀rìṣà, oṣó, ìkórìíra, ìjà, ìlara, ìbínú, ìmọtaraẹni nìkan, ìyapa, ẹ̀kọ́ òdì. 21Àrankàn, ìpànìyàn, ìmutípara, ìréde òru, àti irú ìwọ̀nyí; àwọn ohun tí mo ń wí fún yín tẹ́lẹ̀, gẹ́gẹ́ bí mo ti wí fún yín tẹ́lẹ̀ rí pé, àwọn tí ń ṣe nǹkan báwọ̀nyí kì yóò jogún ìjọba Ọlọ́run.

22Ṣùgbọ́n èso ti Ẹ̀mí ni ìfẹ́, ayọ̀, àlàáfíà, ìpamọ́ra, ìwà pẹ̀lẹ́, ìṣoore, ìgbàgbọ́, 23ìwà tútù, àti ìkóra-ẹni níjanu: òfin kan kò lòdì sí irú wọ̀nyí, 24Àwọn tí í ṣe ti Kristi Jesu ti kan ara wọn mọ́ àgbélébùú pẹ̀lú ìfẹ́ àti ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ̀. 25Bí àwa bá wà láààyè sípa ti Ẹ̀mí, ẹ jẹ́ kí a sì máa rìn nípa ti Ẹ̀mí. 26Ẹ má ṣe jẹ́ kí a máa ṣe ògo asán, kí a má mú ọmọnìkejì wa bínú, kí a má ṣe ìlara ọmọnìkejì wa.

New International Reader’s Version

Galatians 5:1-26

Christ Sets Us Free

1Christ has set us free to enjoy our freedom. So remain strong in the faith. Don’t let the chains of slavery hold you again.

2Here is what I, Paul, say to you. Don’t let yourselves be circumcised. If you do, Christ won’t be of any value to you. 3I say it again. Every man who lets himself be circumcised must obey the whole law. 4Some of you are trying to be made right with God by obeying the law. You have been separated from Christ. You have fallen away from God’s grace. 5But we long to be made completely holy because of our faith in Christ. Through the Holy Spirit we wait for this in hope. 6Circumcision and uncircumcision aren’t worth anything to those who believe in Christ Jesus. The only thing that really counts is faith that shows itself through love.

7You were running a good race. Who has kept you from obeying the truth? 8The God who chooses you does not keep you from obeying the truth. 9You should know that “just a little yeast works its way through the whole batch of dough.” 10The Lord makes me certain that you will see the truth of this. The one who has gotten you all mixed up will have to pay the price. This will happen no matter who has done it. 11Brothers and sisters, I no longer preach that people must be circumcised. If I did, why am I still being opposed? If I preached that, then the cross wouldn’t upset anyone. 12So then, what about troublemakers who try to get others to be circumcised? I wish they would go the whole way! I wish they would cut off everything that marks them as men!

Living by the Holy Spirit’s Power

13My brothers and sisters, you were chosen to be free. But don’t use your freedom as an excuse to live under the power of sin. Instead, serve one another in love. 14The whole law is fulfilled by obeying this one command. “Love your neighbor as you love yourself.” (Leviticus 19:18) 15If you say or do things that harm one another, watch out! You could end up destroying one another.

16So I say, live by the Holy Spirit’s power. Then you will not do what your desires controlled by sin want you to do. 17The desires controlled by sin do not want what the Spirit delights in. And the Spirit does not want what the desires controlled by sin delight in. The two are at war with each other. That’s why you are not supposed to do whatever you want. 18But if you are led by the Spirit, you are not under the authority of the law.

19The result of sin’s control in our lives is clear. It includes sexual sins, impure acts and wild living. 20It includes worshiping statues of gods and worshiping evil powers. It also includes hatred and fighting, jealousy and fits of anger. Sinful desire is interested only in getting ahead. It stirs up trouble. It separates people into their own little groups. 21It wants what others have. It gets drunk and takes part in wild parties. It does many things of that kind. I warn you now as I did before. People who live like this will not receive God’s kingdom.

22But the fruit the Holy Spirit produces is love, joy and peace. It is being patient, kind and good. It is being faithful 23and gentle and having control of oneself. There is no law against things of that kind. 24Those who belong to Christ Jesus have nailed their sinful desires to his cross. They don’t want these things anymore. 25Since we live by the Spirit, let us keep in step with the Spirit. 26Let us not become proud. Let us not make each other angry. Let us not want what belongs to others.