Galatia 4 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Galatia 4:1-31

1Ǹjẹ́ ohun tí mo ń wí ni pé, níwọ̀n ìgbà tí àrólé náà bá wà ní èwe, kò yàtọ̀ nínú ohunkóhun sí ẹrú bí ó tilẹ̀ jẹ́ Olúwa ohun gbogbo. 2Ṣùgbọ́n ó wà lábẹ́ olùtọ́jú àti ìríjú títí àkókò tí baba ti yàn tẹ́lẹ̀. 34.3: Kl 2.20.Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ sì ni àwa, nígbà tí àwa wà ní èwe, àwa wà nínú ìdè lábẹ́ ìpilẹ̀ṣẹ̀ ayé. 4Ṣùgbọ́n nígbà tí àkókò kíkún náà dé, Ọlọ́run rán ọmọ rẹ̀ jáde wá, ẹni tí a bí nínú obìnrin tí a bí lábẹ́ òfin. 5Láti ra àwọn tí ń bẹ lábẹ́ òfin padà, kí àwa lè gba ìsọdọmọ, 64.6: Ro 8.15.Àti nítorí tí ẹ̀yin jẹ́ ọmọ, Ọlọ́run sì ti rán Ẹ̀mí Ọmọ rẹ̀ wá sínú ọkàn yín, tí ń ké pé, “Ábbà, Baba.” 7Nítorí náà ìwọ kì í ṣe ẹrú, bí kò ṣe ọmọ; àti bí ìwọ bá ń ṣe ọmọ, ǹjẹ́ ìwọ di àrólé Ọlọ́run nípasẹ̀ Kristi.

Ìtara Paulu fún àwọn ará Galatia

8Tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀, nígbà tí ẹ̀yin kò tí i mọ Ọlọ́run, ẹ̀yin ti ṣe ẹrú fún àwọn tí kì í ṣe Ọlọ́run nípa ìṣẹ̀dá. 9Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, nígbà tí ẹ̀yin ti mọ Ọlọ́run tan tàbí kí a sá kúkú wí pé ẹ di mímọ́ fún Ọlọ́run, èéha ti rí tí ẹ tún fi yípadà sí aláìlera àti agbára ìpilẹ̀ṣẹ̀ ẹ̀dá, lábẹ́ èyí tí ẹ̀yin tún fẹ́ padà wá ṣe ẹrú? 10Ẹ̀yin ń kíyèsi ọjọ́ àti àkókò, àti ọdún. 11Ẹ̀rù yin ń bà mí, kí o má bà ṣe pé lásán ni mo ṣe làálàá lórí yín.

12Ará, mo bẹ̀ yín, ẹ dàbí èmi: nítorí èmi dàbí ẹ̀yin: ẹ̀yin kò ṣe mí ní ibi kan. 134.13: Ap 16.6.Ẹ̀yin mọ̀ pé nínú àìlera ni mo wàásù ìhìnrere fún yín ní àkọ́kọ́. 14Èyí tí ó sì jẹ́ ìdánwò fún yín ní ara mi ni ẹ kò kẹ́gàn, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò sì kọ̀; ṣùgbọ́n ẹ̀yin gbà mí bí angẹli Ọlọ́run, àní bí Kristi Jesu. 15Ǹjẹ́ ayọ̀ yín ìgbà náà ha dà? Nítorí mo gba ẹ̀rí yín pé, bi o bá ṣe é ṣe, ẹ̀ ò bá yọ ojú yín jáde, ẹ̀ bá sì fi wọ́n fún mi. 16Ǹjẹ́ mo ha di ọ̀tá yín nítorí mo sọ òtítọ́ fún yín bí?

17Wọ́n ń fi ìtara wá yin, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún rere; wọ́n ń fẹ́ já yin kúrò, kí ẹ̀yin lè máa wá wọn. 18Ṣùgbọ́n ó dára láti máa fi ìtara wá ni fún ohun rere nígbà gbogbo, kì í sì í ṣe nígbà tí mo wà pẹ̀lú yín nìkan. 194.19: 1Kọ 4.15.Ẹ̀yin ọmọ mi kéékèèkéé, ẹ̀yin tí mo tún ń rọbí títí a ó fi ṣe ẹ̀dá Kristi nínú yín. 20Ìbá wù mí láti wà lọ́dọ̀ yín nísinsin yìí, kí èmi sì yí ohùn mi padà nítorí pé mo dààmú nítorí yín.

Hagari àti Sara

21Ẹ wí fún mi, ẹ̀yin tí ń fẹ́ wà lábẹ́ òfin, ẹ ko ha gbọ́ òfin ohun ti òfin sọ. 224.22: Gẹ 16.15; 21.2,9.Nítorí a ti kọ ọ́ pé, Abrahamu ní ọmọ ọkùnrin méjì, ọ̀kan láti ọ̀dọ̀ ẹrúbìnrin, àti ọ̀kan láti ọ̀dọ̀ òmìnira obìnrin. 234.23: Ro 9.7-9.Ṣùgbọ́n a bí èyí tí ṣe ti ẹrúbìnrin nípa ti ara: ṣùgbọ́n èyí ti òmìnira obìnrin ni a bí nípa ìlérí.

24Nǹkan wọ̀nyí jẹ́ àpẹẹrẹ: nítorí pé àwọn obìnrin wọ̀nyí ní májẹ̀mú méjèèjì; ọ̀kan láti orí òkè Sinai wá, tí a bí lóko ẹrú, tí í ṣe Hagari. 25Nítorí Hagari yìí ni òkè Sinai Arabia, tí ó sì dúró fún Jerusalẹmu tí ó wà nísinsin yìí, tí ó sì wà lóko ẹrú pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀. 26Ṣùgbọ́n Jerusalẹmu ti òkè jẹ́ òmìnira, èyí tí í ṣe ìyá wa. 274.27: Isa 54.1.Nítorí a ti kọ ọ́ pé,

“Máa yọ̀, ìwọ obìnrin àgàn

tí kò bímọ,

bú sí ayọ̀ kí o sì kígbe sókè,

ìwọ tí kò rọbí rí;

nítorí àwọn ọmọ obìnrin náà tí a kọ̀sílẹ̀

yóò pọ̀ ju ti obìnrin tó ní ọkọ lọ.”

28Ǹjẹ́ ará, ọmọ ìlérí ni àwa gẹ́gẹ́ bí Isaaki. 294.29: Gẹ 21.9.Ṣùgbọ́n bí èyí tí a bí nípa ti ara ti ṣe inúnibíni nígbà náà sí èyí tí a bí nípa ti Ẹ̀mí, bẹ́ẹ̀ sì ni nísinsin yìí. 304.30: Gẹ 21.10-12.Ṣùgbọ́n ìwé mímọ́ ha ti wí, “Lé ẹrúbìnrin yìí àti ọmọ rẹ̀ jáde, nítorí ọmọ ẹrúbìnrin kì yóò bá ọmọ òmìnira obìnrin jogún pọ̀.” 31Nítorí náà, ará, àwa kì í ṣe ọmọ ẹrúbìnrin bí kò ṣe ti òmìnira obìnrin.

New International Reader’s Version

Galatians 4:1-31

1Here is what I have been saying. As long as your own children are young, they are no different from slaves in your house. They are no different, even though they will own all the property. 2People are in charge of the property. And other people are in charge of the children. The children remain under their care until they become adults. At that time their fathers give them the property. 3It is the same with us. When we were children, we were slaves to the basic spiritual powers of the world. 4But then the chosen time came. God sent his Son. A woman gave birth to him. He was born under the authority of the law. 5He came to set free those who were under the authority of the law. He wanted us to be adopted as children with all the rights children have. 6Because you are his children, God sent the Spirit of his Son into our hearts. He is the Holy Spirit. By his power we call God Abba. Abba means Father. 7So you aren’t a slave any longer. You are God’s child. Because you are his child, God gives you the rights of those who are his children.

Paul’s Concern for the Believers in Galatia

8At one time you didn’t know God. You were slaves to gods that are really not gods at all. 9But now you know God. Even better, God knows you. So why are you turning back to those weak and worthless powers? Do you want to be slaves to them all over again? 10You are observing special days and months and seasons and years! 11I am afraid for you. I am afraid that somehow I have wasted my efforts on you.

12I make my appeal to you, brothers and sisters. I’m asking you to become like me. After all, I became like you. You didn’t do anything wrong to me. 13Remember when I first preached the good news to you? Remember I did that because I was sick. 14And my sickness was hard on you. But you weren’t mean to me. You didn’t make fun of me. Instead, you welcomed me as if I were an angel of God. You welcomed me as if I were Christ Jesus himself. 15So why aren’t you treating me the same way now? Suppose you could have torn out your own eyes and given them to me. Then you would have done it. I am a witness to this. 16Have I become your enemy now by telling you the truth?

17Those people are trying hard to win you over. But it is not for your good. They want to take you away from us. They want you to commit yourselves to them. 18It is fine to be committed to something, if the purpose is good. And you shouldn’t be committed only when I am with you. You should always be committed. 19My dear children, I am in pain for you like I was when we first met. I have pain like a woman giving birth. And my pain will continue until Christ makes you like himself. 20I wish I could be with you now. I wish I could change my tone of voice. As it is, I don’t understand you.

Hagar and Sarah

21You who want to be under the authority of the law, tell me something. Don’t you know what the law says? 22It is written that Abraham had two sons. The slave woman gave birth to one of them. The free woman gave birth to the other one. 23Abraham’s son by the slave woman was born in the usual way. But his son by the free woman was born because of God’s promise.

24These things are examples. The two women stand for two covenants. One covenant comes from Mount Sinai. It gives birth to children who are going to be slaves. It is Hagar. 25Hagar stands for Mount Sinai in Arabia. She stands for the present city of Jerusalem. That’s because she and her children are slaves. 26But the Jerusalem that is above is free. She is our mother. 27It is written,

“Be glad, woman,

you who have never had children.

Shout for joy and cry out loud,

you who have never had labor pains.

The woman who is all alone has more children

than the woman who has a husband.” (Isaiah 54:1)

28Brothers and sisters, you are children because of God’s promise just as Isaac was. 29At that time, the son born in the usual way tried to hurt the other son. The other son was born by the power of the Holy Spirit. It is the same now. 30But what does Scripture say? “Get rid of the slave woman. Get rid of her son. The slave woman’s son will never have a share of the family’s property. He’ll never share it with the free woman’s son.” (Genesis 21:10) 31Brothers and sisters, we are not the slave woman’s children. We are the free woman’s children.