Galatia 6 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Galatia 6:1-18

Ṣíṣe dáradára sí gbogbo ènìyàn

1Ará, bí a tilẹ̀ mú ènìyàn nínú ẹ̀ṣẹ̀ kan, kí ẹ̀yin tí í ṣe ti Ẹ̀mí mú irú ẹni bẹ́ẹ̀ bọ̀ sípò nínú ẹ̀mí ìwà tútù; kí ìwọ tìkára rẹ̀ máa kíyèsára, kí a má ba à dán ìwọ náà wò pẹ̀lú. 2Ẹ máa ru ẹrù ọmọnìkejì yín, kí ẹ sì fi bẹ́ẹ̀ mú òfin Kristi ṣẹ. 3Nítorí bí ènìyàn kan bá ń ro ara rẹ̀ sí ẹnìkan, nígbà tí kò jẹ́ nǹkan, ó ń tan ara rẹ̀ jẹ. 4Ṣùgbọ́n kí olúkúlùkù yẹ iṣẹ́ ara rẹ̀ wò, nígbà náà, ohun ìmú-ṣogo rẹ̀ yóò jẹ́ nínú ti ara rẹ̀ nìkan, kì yóò sì jẹ nínú ti ọmọnìkejì rẹ̀. 5Nítorí pé olúkúlùkù ni yóò ru ẹrù ara rẹ̀. 6Ṣùgbọ́n kí ẹni tí a ń kọ́ nínú ọ̀rọ̀ náà máa pèsè ohun rere gbogbo fún ẹni tí ń kọ́ni.

7Kí a má ṣe tàn yín jẹ; a kò lè gan Ọlọ́run: nítorí ohunkóhun tí ènìyàn bá fúnrúgbìn, òhun ni yóò sì ká. 8Nítorí ẹni tí ó bá ń fúnrúgbìn sípa ti ara yóò ká ìdíbàjẹ́ ti ara ṣùgbọ́n ẹni tí ń fúnrúgbìn sípa ti ẹ̀mí yóò ti inú ẹ̀mí ká ìyè àìnípẹ̀kun. 9Ẹ má sì jẹ́ kí àárẹ̀ ọkàn mú wa ní ṣíṣe rere, nítorí tí a ó kórè nígbà tí àkókò bá dé, bí a kò bá ṣe àárẹ̀. 10Ǹjẹ́ bí a ti ń rí àǹfààní gba, ẹ jẹ́ kí a máa ṣoore fún gbogbo ènìyàn, àti pàápàá fún àwọn tí í ṣe ará ilé ìgbàgbọ́.

Kì í ṣe ìkọlà bí kò ṣe ẹ̀dá tuntun

116.11: 1Kọ 16.21.Ẹ wo bí mo ti fi ọwọ́ ara mi kọ̀wé gàdàgbà-gàdàgbà sí yín.

12Iye àwọn tí ń fẹ́ ṣe àṣehàn ni ara wọn ń rọ yín láti kọlà; kìkì nítorí pé kí a má ba à ṣe inúnibíni sí wọn nítorí àgbélébùú Kristi. 13Nítorí àwọn tí a kọ ní ilà pàápàá kò pa òfin mọ́, ṣùgbọ́n wọ́n ń fẹ́ mú yin kọlà, kí wọn lè máa ṣògo nínú ara yín. 14Ṣùgbọ́n kí a má ṣe rí i pé èmi ń ṣògo, bí kò ṣe nínú àgbélébùú Jesu Kristi Olúwa wa, nípasẹ̀ ẹni tí a ti kan ayé mọ́ àgbélébùú fún mi, àti èmi fún ayé. 15Nítorí pé nínú Kristi Jesu, ìkọlà kò jẹ́ ohun kan, tàbí àìkọlà, bí kò ṣe ẹ̀dá tuntun. 166.16: Sm 125.5.Kí àlàáfíà àti àánú wà lórí gbogbo àwọn tí ń rìn ní ìlànà yìí, àti lórí Israẹli Ọlọ́run.

17Láti ìsinsin yìí lọ, kí ẹnikẹ́ni má ṣe yọ mí lẹ́nu mọ́; nítorí èmi ń ru àpá Jesu Olúwa kiri ní ara mi.

Oore-ọ̀fẹ́

18Ará, oore-ọ̀fẹ́ Jesu Kristi Olúwa wa, kí ó wà pẹ̀lú ẹ̀mí yín. Àmín.

New International Reader’s Version

Galatians 6:1-18

Do Good to Everyone

1Brothers and sisters, what if someone is caught in a sin? Then you who live by the Spirit should correct that person. Do it in a gentle way. But be careful. You could be tempted too. 2Carry one another’s heavy loads. If you do, you will fulfill the law of Christ. 3If anyone thinks they are somebody when they are nobody, they are fooling themselves. 4Each person should test their own actions. Then they can take pride in themselves. They won’t be comparing themselves to someone else. 5Each person should carry their own load. 6But those who are taught the word should share all good things with their teacher.

7Don’t be fooled. You can’t outsmart God. A man gathers a crop from what he plants. 8Some people plant to please their desires controlled by sin. From these desires they will harvest death. Others plant to please the Holy Spirit. From the Spirit they will harvest eternal life. 9Let us not become tired of doing good. At the right time we will gather a crop if we don’t give up. 10So when we can do good to everyone, let us do it. Let’s try even harder to do good to the family of believers.

Not Circumcision but the New Creation

11Look at the big letters I’m using as I write to you with my own hand!

12Some people are worried about how things look on the outside. They are trying to force you to be circumcised. They do it for only one reason. They don’t want to suffer by being connected with the cross of Christ. 13Even those who are circumcised don’t obey the law. But they want you to be circumcised. Then they can brag about what has been done to your body. 14I never want to brag about anything except the cross of our Lord Jesus Christ. Through that cross the ways of the world have been crucified as far as I am concerned. And I have been crucified as far as the ways of the world are concerned. 15Circumcision and uncircumcision don’t mean anything. What really counts is that the new creation has come. 16May peace and mercy be given to all who follow this rule. May peace and mercy be given to the Israel that belongs to God.

17From now on, let no one cause trouble for me. My body has marks that show I belong to Jesus.

18Brothers and sisters, may the grace of our Lord Jesus Christ be with your spirit. Amen.