2 Kronika 36 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

2 Kronika 36:1-23

136.1-4: 2Ọb 23.30-34.Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà mú Jehoahasi ọmọ Josiah wọn sì fi jẹ ọba ní Jerusalẹmu ni ipò baba rẹ̀.

Jehoahasi Ọba Juda

2Jehoahasi sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́tàlélógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún oṣù mẹ́ta. 3Ọba Ejibiti yọ kúrò lórí ìtẹ́ ní Jerusalẹmu, ó sì bù fún un lórí Juda, ọgọ́ọ̀rún tálẹ́ǹtì fàdákà (100) àti tálẹ́ǹtì wúrà kan. 4Ọba Ejibiti sì mú Eliakimu, arákùnrin Joahasi, jẹ ọba lórí Juda àti Jerusalẹmu, ó sì yí orúkọ Eliakimu padà sí Jehoiakimu, ṣùgbọ́n Neko mú Joahasi arákùnrin Eliakimu lọ sí Ejibiti.

Jehoiakimu ọba Juda

536.5-8: 2Ọb 23.36–24.6.Jehoiakimu sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún méjìlá. Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀. 6Nebukadnessari ọba Babeli sì mú un, ó sì dè é pẹ̀lú ẹ̀wọ̀n láti mú un lọ sí Babeli. 7Nebukadnessari kó nínú ohun èlò ilé Olúwa lọ si Babeli pẹ̀lú, ó sì fi wọn sí ààfin rẹ̀ ní Babeli.

8Ìyókù iṣẹ́ ìjọba Jehoiakimu, àwọn ohun ìríra tí ó ṣe àti gbogbo ohun tí a rí nípa rẹ̀, ni a kọ sínú ìwé àwọn ọba Israẹli àti Juda. Jehoiakini ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

Jehoiakini ọba Juda

936.9-10: 2Ọb 24.8-17.Jehoiakini sì jẹ́ ẹni ọdún méjì-dínlógún (18) nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ́ ọba ní Jerusalẹmu fún oṣù mẹ́ta àti ọjọ́ mẹ́wàá ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa. 10Ní àkókò òjò, ọba Nebukadnessari ránṣẹ́ sí i ó sì mú un wá sí Babeli, pẹ̀lú ohun èlò dáradára láti ilé Olúwa, ó sì mú arákùnrin Jehoiakini, Sedekiah, jẹ ọba lórí Juda àti Jerusalẹmu.

Sedekiah ọba Juda

11Sedekiah jẹ́ ẹni ọdún mọ́kànlélógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlá. 12Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, kò sì rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ níwájú Jeremiah wòlíì ẹni tí ó sọ̀rọ̀ Olúwa. 13Ó sì tún ṣọ̀tẹ̀ sí ọba Nebukadnessari pẹ̀lú, ẹni tí ó mú kí ó fi orúkọ Ọlọ́run búra. Ó sì di ọlọ́run líle, ó sì mú ọkàn rẹ̀ le láti má lè yípadà sí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli. 14Síwájú sí i gbogbo àwọn olórí àlùfáà àti àwọn ènìyàn sì di ẹni tí ń dẹ́ṣẹ̀ gidigidi, pẹ̀lú gbogbo ìríra àwọn orílẹ̀-èdè wọ́n sì sọ ilé Olúwa di èérí, tí ó ti yà sí mímọ́ ní Jerusalẹmu.

Ìṣubú Jerusalẹmu

15Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wọn ránṣẹ́ sí wọn láti ọwọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ síwájú àti síwájú sí i, nítorí tí ó ní ìyọ́nú sí àwọn ènìyàn rẹ̀ àti sí ibùgbé rẹ̀. 16Ṣùgbọ́n wọ́n ń kùn sí àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run, wọ́n kẹ́gàn ọ̀rọ̀ rẹ̀, wọ́n fi àwọn wòlíì rẹ̀ ṣẹ̀sín títí tí ìbínú Ọlọ́run fi ru sórí wọn, sí àwọn ènìyàn rẹ̀ kò sì ṣí àtúnṣe. 17Ó sì mú wá sórí wọn ọba àwọn ará Babeli tí wọ́n bá àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn jà pẹ̀lú idà ní ilẹ̀ ibi mímọ́, kò sì ní ìyọ́nú sí àgbà ọkùnrin tàbí ọ̀dọ́mọdébìnrin, wúńdíá, tàbí arúgbó. Ọlọ́run sì fi gbogbo wọn lé Nebukadnessari lọ́wọ́. 18Ó sì mú gbogbo ohun èlò láti ilé Ọlọ́run lọ sí Babeli, ńlá àti kékeré àti ìṣúra ilé Olúwa àti ìṣúra ọba àti ìjòyè rẹ̀. 19Wọ́n sì fi iná sun ilé Ọlọ́run, wọ́n sì wó gbogbo ògiri ilé Jerusalẹmu, wọ́n sì jó gbogbo ààfin wọn, wọ́n sì ba gbogbo ohun èlò ibẹ̀ jẹ́.

20Ó sì kó èyí tí ó kù lọ sí Babeli àwọn tí ó rí ibi sá kúrò lẹ́nu idà wọ́n sì di ìránṣẹ́ fún un àti àwọn ọmọ rẹ̀ títí tí ìjọba Persia fi gba agbára. 21Ilẹ̀ náà sì gbádùn ìsinmi rẹ̀, ní gbogbo ìgbà ìdahoro, òun sì ń sinmi títí àádọ́rin ọdún (70) fi pé ní ìmúṣẹ ọ̀rọ̀ Olúwa tí a sọ láti ẹnu Jeremiah.

2236.22,23: Es 1.1-3.Ní ọdún kìn-ín-ní Kirusi ọba Persia, kí ọ̀rọ̀ Olúwa tí a tẹnu Jeremiah sọ bá à le ṣẹ pé, Olúwa run ẹ̀mí Kirusi ọba Persia láti ṣe ìkéde ní gbogbo ìjọba rẹ̀, ó sì kọ ọ́ sínú ìwé pẹ̀lú.

23“Èyí ni ohun tí Kirusi ọba Persia sọ wí pé:

“ ‘Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, ti fún mí ní gbogbo ìjọba ayé yìí, ó sì ti yàn mí láti kọ́ ilé Olúwa fún òun ní Jerusalẹmu ti Juda. Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ènìyàn rẹ̀ láàrín yín le gòkè lọ pẹ̀lú rẹ̀; kí Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ kí ó wà pẹ̀lú rẹ̀.’ ”

Nouă Traducere În Limba Română

2 Cronici 36:1-23

Domnia lui Ioahaz peste Iuda

(2 Regi 23:31-35)

1Apoi poporul țării l‑a luat pe Iehoahaz, fiul lui Iosia, și l‑a făcut rege în locul tatălui său, la Ierusalim.

2Iehoahaz era în vârstă de douăzeci și trei de ani când a devenit rege și a domnit la Ierusalim timp de trei luni. 3Regele Egiptului l‑a detronat la Ierusalim și a cerut țării un tribut de o sută de talanți3 Aproximativ 3 t. de argint și un talant3 Aproximativ 30 kg. de aur. 4Regele Egiptului l‑a făcut rege peste Iuda și Ierusalim, pe Eliachim, fratele lui Iehoahaz, și i‑a schimbat numele în Iehoiachim. Iar pe fratele său, Iehoahaz, Neco l‑a luat și l‑a dus în Egipt.

Domnia lui Iehoiachim peste Iuda

(2 Regi 23:36–24:7)

5Iehoiachim era în vârstă de douăzeci și cinci de ani când a devenit rege și a domnit la Ierusalim timp de unsprezece ani. El a făcut ce este rău în ochii Domnului, Dumnezeul său. 6Nebucadnețar6 Nebucadnețar (Nabucodonosor, cf. LXX, Vulgata). [604–561 î.Cr.], împăratul Babilonului, s‑a suit împotriva acestuia și l‑a legat cu lanțuri de bronz ca să‑l ducă în Babilon. 7Nebucadnețar a adus în Babilon unele din obiectele Casei Domnului și le‑a pus în templul7 Sau: palatul. său din Babilon. 8Celelalte fapte ale lui Iehoiachim, toate urâciunile pe care le‑a săvârșit și ceea ce a fost găsit împotriva lui, iată, ele sunt scrise în „Cartea regilor lui Israel și ai lui Iuda“. Și în locul lui a domnit fiul său Iehoiachin.

Domnia lui Iehoiachin peste Iuda

(2 Regi 24:8-17)

9Iehoiachin era în vârstă de optsprezece ani când a devenit rege și a domnit la Ierusalim timp de trei luni și zece zile. El a făcut ce este rău în ochii Domnului. 10În anul următor, împăratul Nebucadnețar a trimis să‑l aducă la Babilon împreună cu obiectele scumpe ale Casei Domnului, iar în locul lui l‑a făcut rege peste Iuda și peste Ierusalim pe unchiul10 Cf. 2 Regi 24:17. Lit.: fratele, termen care se referă adesea la o rudă apropiată. său, Zedechia.

Domnia lui Zedechia peste Iuda

(2 Regi 24:18–25:18; Ier. 52:1-3)

11Zedechia era în vârstă de douăzeci și unu de ani când a devenit rege și a domnit la Ierusalim timp de unsprezece ani. 12El a făcut ce este rău în ochii Domnului, Dumnezeul său, și nu s‑a smerit înaintea profetului Ieremia care vorbea din partea Domnului. 13S‑a răsculat chiar împotriva împăratului Nebucadnețar, care‑l pusese să jure pe Dumnezeu. Și‑a înțepenit ceafa și și‑a împietrit inima, ca să nu se întoarcă la Domnul, Dumnezeul lui Israel. 14Toate căpeteniile preoților, precum și poporul și‑au înmulțit și ei nelegiuirile, luându‑se după toate urâciunile neamurilor și au pângărit Casa Domnului, pe care El o sfințise la Ierusalim. 15Domnul, Dumnezeul părinților lor, Și‑a trimis mesagerii la ei dis‑de‑dimineață; i‑a trimis pentru că Îi era milă de poporul Lui și de Locuința Sa. 16Ei însă i‑au luat în derâdere pe mesagerii lui Dumnezeu, I‑au disprețuit cuvintele și I‑au batjocorit profeții, până când a venit mânia Domnului peste poporul Său și n‑a mai fost vindecare.

Căderea Ierusalimului

(2 Regi 25:1-21; Ier. 39:1-10; 52:4-27)

17Domnul l‑a ridicat împotriva lor pe împăratul caldeenilor.17 Sau: babilonienilor. El le‑a ucis tinerii cu sabia chiar în Casa Sfântului lor Lăcaș. Nu a avut milă nici de feciori, nici de fecioare, nici de bătrâni, nici de gârbovi. Domnul i‑a dat pe toți în mâna sa. 18Toate obiectele Casei lui Dumnezeu, mari și mici, tezaurul Casei Domnului, bogățiile regelui și ale căpeteniilor sale, pe toate le‑a dus în Babilon. 19Au dat foc Casei lui Dumnezeu, au dărâmat zidul Ierusalimului, au dat foc tuturor palatelor și au distrus toate obiectele prețioase.

20Pe cei ce au scăpat de sabie, i‑a dus în captivitate la Babilon, iar aceștia au devenit robii lui și ai fiilor lui, până când a ajuns la putere împărăția Persiei, 21adică până când țara s‑a bucurat de Sabatele ei, împlinindu‑se astfel Cuvântul Domnului spus prin Ieremia. Tot timpul cât a rămas pustiită, țara s‑a odihnit până când s‑au împlinit șaptezeci de ani.

Edictul de repatriere a evreilor

(Ezra 1:1-3)

22În primul an al lui Cirus22 Cirus II cel Mare (559–530 î.Cr.). Cu referire la anul 539 î.Cr., primul an după cucerirea Babilonului., împăratul Persiei, ca să se împlinească Cuvântul Domnului spus prin Ieremia, Domnul a trezit duhul lui Cirus, împăratul Persiei, și acesta a pus să se vestească prin viu grai și în scris în toată împărăția sa următoarele:

23„Așa vorbește Cirus, împăratul Persiei:

«Domnul, Dumnezeul cerurilor, Care mi‑a dat toate regatele pământului, m‑a numit să‑I zidesc o Casă la Ierusalim, în Iuda. Cine dintre voi este din poporul Lui? Domnul, Dumnezeul lui, să fie cu el! Lăsați‑l să se suie!»“