2 Kronika 35 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

2 Kronika 35:1-27

Josiah ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá

135.1-19: 2Ọb 23.21-23.Síwájú sí i, Josiah ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá sí Olúwa ní Jerusalẹmu, Ọ̀dọ́-àgùntàn àjọ ìrékọjá náà ni wọ́n sì pa ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kìn-ín-ní. 2Ó sì yàn àwọn àlùfáà sí iṣẹ́ wọn, ó sì gbà wọ́n ní ìyànjú ní ìsìn ilé Olúwa. 3Ó sì wí fún àwọn ọmọ Lefi, ẹni tí ń kọ́ gbogbo àwọn Israẹli ẹni tí a ti yà sí mímọ́ fún Olúwa pé ẹ gbé àpótí ẹ̀rí ìyàsọ́tọ̀ sí ilé Olúwa tí Solomoni ọmọ Dafidi ọba Israẹli ti kọ́. Kò gbọdọ̀ jẹ́ ẹrù àgbéká ní èjìká rẹ̀. Nísinsin yìí ẹ sin Olúwa Ọlọ́run yín àti àwọn ènìyàn rẹ̀ Israẹli. 4Ẹ múra sílẹ̀ nípa ìdílé ní ẹsẹẹsẹ yín gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ tí a kọ́ láti ọwọ́ Dafidi ọba Israẹli àti gẹ́gẹ́ bí ọmọ rẹ̀ Solomoni.

5“Dúró ní ibi mímọ́ pẹ̀lú àkójọpọ̀ àwọn ọmọ Lefi fún ọ̀kọ̀ọ̀kan ìpín àwọn ìdílé àwọn ẹgbẹ́ ará ìlú, àwọn ènìyàn tí ó dùbúlẹ̀. 6Ẹ pa ẹran àjọ ìrékọjá náà, ẹ ya ara yín sọ́tọ̀ kí ẹ sì pèsè ẹran fún àwọn ẹgbẹ́ arákùnrin yín, kí ẹ sì ṣe ohun tí Olúwa paláṣẹ láti ọwọ́ Mose.”

7Josiah sì pàṣẹ fún gbogbo àwọn ènìyàn tí ó dùbúlẹ̀ tí ó wà níbẹ̀ iye rẹ̀ jẹ ẹgbàá-mẹ́dógún ọ̀dọ́-àgùntàn àti ọmọ ewúrẹ́ fún ẹbọ ìrékọjá, àti pẹ̀lú ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n akọ màlúù (3,000) gbogbo wọ̀nyí jẹ́ ohun ìní láti ọ̀dọ̀ ọba.

8Àwọn ìjòyè rẹ̀ fi tinútinú ta àwọn ènìyàn náà ní ọrẹ àti àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi. Hilkiah, Sekariah àti Jehieli, àti àwọn olórí ilé Ọlọ́run, fún àwọn àlùfáà ní ẹgbẹ̀tàlá (2,600) ẹbọ àjọ ìrékọjá àti ọ̀ọ́dúnrún ẹran ọ̀sìn (300). 9Àti pẹ̀lú Konaniah àti pẹ̀lú Ṣemaiah àti Netaneli, àti àwọn arákùnrin rẹ̀, àti Haṣabiah, Jeieli àti Josabadi olórí àwọn ọmọ Lefi, ó sì pèsè ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ẹbọ ìrékọjá (500) àti ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n orí ẹran ọ̀sìn fún àwọn ọmọ Lefi.

10Nítorí náà, a múra ìsìn náà sílẹ̀, àwọn àlùfáà sì dúró ní ipò wọn pẹ̀lú àwọn ọmọ Lefi nípa iṣẹ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ọba ti pa á láṣẹ. 11Ní ti àjọ ìrékọjá a sì pa ẹran, àwọn àlùfáà sì wọ́n ẹ̀jẹ̀ náà tí wọ́n gbé sí ọwọ́ wọn, nígbà tí àwọn ọmọ Lefi sì bọ ẹranko. 12Wọ́n sì ya àwọn ẹbọ sísun sí apá kan láti fi wọ́n fún gẹ́gẹ́ bí ìpín àwọn ìdílé àwọn ènìyàn láti rú ẹbọ sí Olúwa. Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sínú ìwé Mose. Wọ́n sì ṣe bákan náà pẹ̀lú àwọn ẹran ọ̀sìn. 13Wọ́n sì fi sun àjọ ìrékọjá lórí iná gẹ́gẹ́ bí ìlànà, wọ́n sì bọ ẹbọ mímọ́ nínú ìkòkò, nínú ọpọ́n àti nínú agbada, wọ́n sì pín wọn kíákíá fún gbogbo àwọn ènìyàn. 14Lẹ́yìn èyí, wọ́n sì múra sílẹ̀ fún ara wọn àti fún àwọn àlùfáà nítorí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Aaroni, ni wọ́n rú ẹbọ sísun àti ọ̀rá títí di àṣálẹ́. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Lefi sì múra sílẹ̀ fún ara wọn àti fún àwọn ọmọ Aaroni àlùfáà.

15Àwọn akọrin, àwọn ọmọ Asafu, ni wọ́n wà ní ipò wọn tí a sì paláṣẹ fún wọn láti ọwọ́ Dafidi, Asafu, Hemani àti Jedutuni àwọn aríran ọba àti àwọn olùṣọ́nà ní olúkúlùkù ẹnu-ọ̀nà kò gbọdọ̀ fi ojú ọ̀nà wọn sílẹ̀, nítorí àwọn ẹgbẹ́ ọmọ lefi ti múra sílẹ̀ fún wọn.

16Bẹ́ẹ̀ ni àsìkò náà gbogbo àwọn ìsìn Olúwa ni wọ́n gbé jáde fún iṣẹ́ ìrántí àjọ ìrékọjá àti láti rú ẹbọ sísun lórí pẹpẹ Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ọba Josiah ti pa á láṣẹ. 17Àwọn ọmọ Israẹli tí ó gbé kalẹ̀ ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá ní àkókò náà àti àjọ àkàrà àìwú fún ọjọ́ méje. 18Àjọ ìrékọjá náà kò sì tí ì sí èyí tí ó dàbí i rẹ̀ ní Israẹli títí dé ọjọ́ wòlíì Samuẹli, kò sì sí ọ̀kan lára àwọn ọba Israẹli tí ó pa irú àjọ ìrékọjá bẹ́ẹ̀ mọ́ gẹ́gẹ́ bí Josiah ti ṣe, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àwọn ọmọ Lefi àti gbogbo àwọn Juda àti Israẹli tí ó wà níbẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu. 19Àjọ ìrékọjá yìí ni a ṣe ìrántí ní ọdún kejì-dínlógún ìjọba Josiah.

Ikú Josiah

20Lẹ́yìn gbogbo èyí nígbà tí Josiah ti tún ilẹ̀ náà ṣetán, Neko ọba Ejibiti gòkè lọ láti bá Karkemiṣi jà lórí odo Eufurate, Josiah sì jáde lọ láti pàdé rẹ̀ ní ibi ìjà. 21Ṣùgbọ́n Neko rán ìránṣẹ́ sí i wí pé, “Ìjà wo ni ó ń bẹ láàrín èmi àti ìwọ, ọba Juda? Kì í ṣe ìwọ ni èmi tọ̀ wá ní àkókò yìí, ṣùgbọ́n, ilé pẹ̀lú èyí ti mo bá níjà. Ọlọ́run ti sọ fún mi láti yára àti láti dúró nípa ṣíṣe ìdènà Ọlọ́run, ẹni tí ó wà pẹ̀lú mi, kí òun má bá a pa ọ́ run.”

22Josiah, kò yípadà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ó pa ara rẹ̀ dà kí ó le bá a jà, kó sì fi etí sí ọ̀rọ̀ Neko láti ẹnu Ọlọ́run wá, ó sì wá jagun ní Àfonífojì Megido.

23Tafàtafà sì ta ọfà sí ọba Josiah, ó sì sọ fún àwọn ìjòyè pé, “Ẹ gbé mi kúrò, èmi ti gba ọgbẹ́ gidigidi.” 24Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì gbé e jáde kúrò nínú kẹ̀kẹ́ náà, wọ́n sì gbé e sínú kẹ̀kẹ́ mìíràn, wọ́n sì gbé e wá sí Jerusalẹmu, níbi tí ó ti kú, wọ́n sì sin ín sínú ọ̀kan nínú àwọn ibojì àwọn baba rẹ̀, gbogbo Juda àti gbogbo Jerusalẹmu sì ṣọ̀fọ̀ Josiah.

25Jeremiah sì pohùnréré ẹkún fún Josiah, gbogbo àwọn akọrin ọkùnrin àti gbogbo àwọn akọrin obìnrin sì ń sọ ti Josiah nínú orin ẹkún wọn ní Israẹli títí di òní. Èyí sì di àṣà ní Jerusalẹmu, a sì kọ ọ́ sínú àwọn orin ẹkún.

26Ìyókù iṣẹ́ ìjọba Josiah àti ìwà rere rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí èyí tí a ti kọ sínú ìwé òfin Olúwa. 27Gbogbo iṣẹ́ náà, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin ni a kọ sínú ìwé àwọn ọba Israẹli àti Juda.

Nouă Traducere În Limba Română

2 Cronici 35:1-27

Celebrarea Paștelui

(2 Regi 23:21-23)

1Iosia a ținut Paștele Domnului la Ierusalim. Oamenii au înjunghiat mieii de Paște în a paisprezecea zi a lunii întâi. 2El le‑a dat preoților îndatoririle lor și i‑a încurajat în ce privește slujba Casei Domnului. 3El le‑a zis leviților, care dădeau învățătură întregului Israel și care erau sfinți pentru Domnul, următoarele:

„Puneți Chivotul cel sfânt în Casa zidită de Solomon, fiul lui David, regele lui Israel! Să nu mai fie pentru voi o povară pe umeri! Acum, slujiți Domnului, Dumnezeul vostru, și poporului Său Israel. 4Așezați‑vă potrivit familiilor voastre și potrivit cetelor voastre, după cum a scris David, regele lui Israel, și după cum a scris fiul său Solomon. 5Ocupați‑vă locurile în Lăcaș, câte o parte a familiei leviților pentru fiecare ceată a clanurilor fraților voștri, cei din popor. 6Înjunghiați mieii de Paște, sfințiți‑vă și pregătiți jertfele pentru frații voștri, împlinind Cuvântul Domnului dat prin Moise.“

7Iosia a oferit fiilor poporului, tuturor celor prezenți, oi, miei și iezi, toți pentru Paște, în număr de treizeci de mii, precum și trei mii de viței. Acestea erau din averea regelui. 8Căpeteniile regelui au oferit și ei de bunăvoie daruri poporului, preoților și leviților. Hilchia, Zaharia și Iehiel, conducătorii Casei lui Dumnezeu, le‑au dat preoților două mii șase sute de miei pentru Paște și trei sute de viței. 9Conania și frații săi, Șemaia și Netanel, precum și Hașabia, Ieiel și Iozabad, căpetenii ale leviților, le‑au dăruit leviților cinci mii de miei pentru Paște și cinci sute de vite. 10Slujba a fost pregătită, preoții și‑au ocupat locurile, iar leviții s‑au așezat în cete, după cum poruncise regele.

11Apoi au înjunghiat mieii de Paște. Preoții au stropit sângele, luându‑l de la leviții care jupuiseră animalele. 12Au pus deoparte arderile‑de‑tot, ca să le dea fiilor poporului să le ofere Domnului, potrivit cetelor lor, potrivit familiilor părinților lor, după cum este scris în Cartea lui Moise. Tot așa au făcut și cu vitele. 13Au fript jertfa de Paște la foc, după rânduială, iar celelalte jertfe sfinte le‑au fiert în oale, cazane și cratițe și le‑au împărțit în grabă întregului popor. 14După aceea, leviții au pregătit ce era pentru ei și pentru preoți – căci preoții, urmașii lui Aaron, aduseseră arderile‑de‑tot și grăsimile până seara, astfel că leviții au trebuit să facă pregătiri de Paște atât pentru ei, cât și pentru preoți, urmașii lui Aaron.

15Cântăreții, urmașii lui Asaf, erau la locul lor, așa cum poruncise David, Asaf, Heman și Iedutun, văzătorul regelui, iar portarii erau la fiecare poartă. Ei nu au trebuit să‑și întrerupă slujba, deoarece leviții, frații lor, au pregătit jertfa de Paște pentru ei.

16Astfel a fost pregătită în ziua aceea întreaga slujbă a Domnului, ca să se poată sărbători Paștele și să se poată aduce arderile‑de‑tot pe altarul Domnului, după porunca regelui Iosia. 17Fiii lui Israel, aflați atunci la Ierusalim, au sărbătorit Paștele și Sărbătoarea Azimelor timp de șapte zile. 18Paște ca acesta nu se mai sărbătorise în Israel din zilele profetului Samuel. Niciun rege al lui Israel nu mai sărbătorise un Paște precum cel sărbătorit de Iosia, alături de preoți, leviți, toți cei din Iuda și din Israel, care se aflau acolo, și locuitorii Ierusalimului. 19Acest Paște a fost sărbătorit în al optsprezecelea an al domniei lui Iosia.

Împrejurările morții lui Iosia

(2 Regi 23:28-30)

20După toate acestea, când Iosia pusese deja în ordine Casa, Neco20 Neco sau Nekau II (610–595 î.Cr.), al doilea faraon al Dinastiei XXVI., regele Egiptului, s‑a suit să lupte împotriva Carchemișului, pe Eufrat. Iosia i‑a ieșit împotrivă. 21Neco i‑a trimis mesageri, zicând: „Ce am eu de‑a face cu tine, rege al lui Iuda? Nu împotriva ta vin astăzi, ci împotriva unei Case cu care sunt în război, iar Dumnezeu mi‑a zis să mă grăbesc. Nu te împotrivi lui Dumnezeu, Care este cu mine, ca să nu te distrugă!“ 22Dar Iosia nu s‑a întors, ci s‑a deghizat ca să lupte împotriva acestuia. El nu a ascultat cuvintele lui Neco, care veneau din gura lui Dumnezeu, astfel că s‑a dus să lupte în valea Meghido. 23Arcașii l‑au lovit pe regele Iosia, și regele le‑a zis slujitorilor săi: „Luați‑mă, căci sunt grav rănit!“ 24Slujitorii lui l‑au luat din carul de luptă, l‑au transportat cu un alt car al lui și l‑au adus la Ierusalim. El a murit și a fost înmormântat în mormintele părinților lui. Toți cei din Iuda și din Ierusalim l‑a bocit pe Iosia.

25Ieremia a compus o cântare de jale pentru Iosia și, până în ziua aceasta, toți cântăreții și cântărețele amintesc de Iosia în cântările lor de jale. Ele au ajuns un obicei în Israel și s‑au păstrat scrise în „Cântările de jale“.

26Celelalte fapte ale lui Iosia, dovezile sale de credincioșie, făcute după cum scrie în Legea Domnului, 27cele dintâi și cele de pe urmă isprăvi ale lui sunt scrise în „Cartea regilor lui Israel și ai lui Iuda“.