Esra 1 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Esra 1:1-11

Kirusi ran àwọn tí a kó nígbèkùn lọ́wọ́ láti padà

11.1-3: Es 5.13; 6.3; 2Ki 36.22,23.Ní ọdún kìn-ín-ní Kirusi, ọba Persia, kí a lè mú ọ̀rọ̀ Olúwa tí Jeremiah sọ ṣẹ, Olúwa ru ọkàn Kirusi ọba Persia sókè láti ṣe ìkéde jákèjádò gbogbo agbègbè ìjọba rẹ̀, kí ó sì ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ pé:

2“Èyí ni ohun tí Kirusi ọba Persia wí pé:

“ ‘Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, ti fún mi ní gbogbo ìjọba ayé. Ó sì ti yàn mí láti kọ́ tẹmpili Olúwa fún un ní Jerusalẹmu tí ó wà ní Juda. 3Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ènìyàn rẹ̀ láàrín yín—kí Ọlọ́run rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀, kí ó sì gòkè lọ sí Jerusalẹmu tí ó wà ní Juda, láti kọ́ tẹmpili Olúwa Ọlọ́run Israẹli, Ọlọ́run tí ó wà ní Jerusalẹmu. 4Kí àwọn ènìyàn ní ibikíbi tí ẹni náà bá ń gbé kí ó fi fàdákà àti wúrà pẹ̀lú ohun tí ó dára àti ẹran ọ̀sìn, pẹ̀lú ọrẹ àtinúwá ràn án lọ́wọ́ fún tẹmpili Ọlọ́run ní Jerusalẹmu.’ ”

5Nígbà náà àwọn olórí ìdílé Juda àti Benjamini àti àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi—olúkúlùkù ẹni tí Ọlọ́run ti fọwọ́ tọ́ ọkàn rẹ̀—múra láti gòkè lọ láti kọ ilé Olúwa ní Jerusalẹmu. 6Gbogbo àwọn aládùúgbò wọn ràn wọ́n lọ́wọ́ pẹ̀lú ohun èlò ti fàdákà àti wúrà, pẹ̀lú onírúurú ohun ìní àti ẹran ọ̀sìn àti pẹ̀lú àwọn ẹ̀bùn iyebíye, ní àfikún si gbogbo àwọn ọrẹ àtinúwá.

7Ní àfikún, ọba Kirusi mú àwọn ohun èlò tí ó jẹ́ ti ilé Olúwa jáde wá, tí Nebukadnessari ti kó lọ láti Jerusalẹmu tí ó sì ti kó sí ilé òrìṣà rẹ̀. 8Kirusi ọba Persia pàṣẹ fún Mitredati olùṣọ́ ilé ìṣúra láti kó wọn jáde, ó sì kà wọ́n fún Ṣeṣbassari ìjòyè Juda.

9Èyí ni iye wọn:

Ọgbọ̀n àwo wúrà 30Ẹgbẹ̀rún àwo fàdákà 1,000Àwo ìrúbọ fàdákà mọ́kàn-dínlọ́gbọ̀n 2910Ọgbọ̀n àdému wúrà 30Irínwó ó-lé-mẹ́wàá oríṣìí àdému fàdákà mìíràn 410Ẹgbẹ̀rún kan àwọn ohun èlò mìíràn 1,000

11Gbogbo ohun èlò wúrà àti ti fàdákà ní àpapọ̀ jẹ́ ẹgbẹ̀rún márùn-ún ó-lé-irínwó (5,400).

Ṣeṣbassari kó gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí wá pẹ̀lú àwọn ìgbèkùn tí ó gòkè wá láti Babeli sí Jerusalẹmu.

Nouă Traducere În Limba Română

Ezra 1:1-11

Edictul de repatriere a evreilor

(2 Cron. 36:22-23)

1În primul an al lui Cirus1 Cirus II cel Mare, care a domnit între anii 559–530 î.Cr. Textul face referire la anul 539–538 î.Cr., primul an după cucerirea Babilonului., împăratul Persiei, ca să se împlinească Cuvântul Domnului spus prin1 Lit.: Cuvântul Domnului din gura lui. Ieremia1 Vezi Ier. 25:11-12; 29:10-14., Domnul a trezit duhul lui Cirus, împăratul Persiei, și acesta a pus să se vestească prin viu grai și în scris în toată împărăția sa următoarele:

2Așa vorbește Cirus, împăratul Persiei:

Domnul, Dumnezeul cerurilor, Care mi‑a dat toate regatele pământului, m‑a numit să‑I zidesc o Casă la Ierusalim, în Iuda. 3Cine dintre voi este din poporul Lui? Dumnezeul lui să fie cu el! Lăsați‑l să se suie la Ierusalim, în Iuda, ca să zidească acolo Casa Domnului, Dumnezeul lui Israel. El este Dumnezeul Care locuiește la Ierusalim. 4Fiecare supraviețuitor, în orice loc s‑ar afla, să fie ajutat de oamenii din acele locuri cu argint, cu aur, cu diferite bunuri și cu vite, precum și cu daruri de bunăvoie pentru Casa lui Dumnezeu din Ierusalim.“

5Atunci căpeteniile familiilor lui Iuda și ale lui Beniamin, preoții, leviții – toți aceia al căror duh l‑a trezit Dumnezeu – s‑au ridicat ca să meargă să zidească în Ierusalim Casa Domnului. 6Toți cei dimprejurul lor i‑au sprijinit cu argint, cu aur, cu bunuri, cu vite și cu lucruri scumpe, pe lângă tot felul de daruri de bunăvoie. 7Împăratul Cirus a adus obiectele Casei Domnului, cele care fuseseră luate de Nebucadnețar7 Nebucadnețar (Nabucodonosor, cf. LXX, Vulgata), împărat al Babilonului, care a domnit între anii 604–561 î.Cr. de la Ierusalim și puse în casa dumnezeilor săi. 8Cirus, împăratul Persiei, le‑a adus prin mâna vistiernicului Mitredat, iar acesta le‑a numărat înaintea lui Șeșbațar, prințul iudeilor. 9Iată care este numărul lor:

treizeci de vase de aur,

o mie de vase de argint,

douăzeci și nouă de cuțite9 Sensul termenului ebraic este nesigur.,

10treizeci de cupe de aur,

patru sute zece cupe de argint șlefuit,

o mie de alte obiecte.

11Toate obiectele de aur și de argint erau în număr de cinci mii patru sute. Șeșbațar le‑a adus pe toate acestea atunci când exilații s‑au suit din Babilon la Ierusalim.