1 Samuẹli 2 – YCB & CARST

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

1 Samuẹli 2:1-36

Àdúrà Hana

1Hana sì gbàdúrà pé:

“Ọkàn mi yọ̀ sí Olúwa;

Ìwo agbára mi ni a sì gbé sókè sí Olúwa.

Ẹnu mi sì gbòòrò lórí àwọn ọ̀tá mi,

nítorí ti èmi yọ̀ ni ìgbàlà rẹ̀.

2“Kò sí ẹni tí ó mọ́ bi Olúwa;

kò sí ẹlòmíràn bí kò ṣe ìwọ;

kò sì sí àpáta bi Ọlọ́run wa.

3“Má ṣe halẹ̀;

má ṣe jẹ́ kí ìgbéraga ti ẹnu yín jáde

nítorí pé Ọlọ́run olùmọ̀ ni Olúwa,

láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá ni a ti ń wọn ìwà.

4“Ọ̀run àwọn alágbára ti ṣẹ́,

àwọn tí ó ṣe aláìlera ni a fi agbára dì ní àmùrè.

5Àwọn tí ó yọ̀ fún oúnjẹ ti fi ara wọn ṣe alágbàṣe,

àwọn tí ebi ń pa kò sì ṣe aláìní.

Tó bẹ́ẹ̀ tí àgàn fi bí méje.

Ẹni tí ó bímọ púpọ̀ sì di aláìlágbára.

6Olúwa pa ó sì sọ di ààyè;

ó mú sọ̀kalẹ̀ lọ sí isà òkú, ó sì gbé dìde.

7Olúwa sọ di tálákà; ó sì sọ di ọlọ́rọ̀;

ó rẹ̀ sílẹ̀, ó sì gbé sókè.

8Ó gbé tálákà sókè láti inú erùpẹ̀ wá,

ó gbé alágbe sókè láti orí òkìtì eérú wá,

láti mú wọn jókòó pẹ̀lú àwọn ọmọ-aládé,

láti mu wọn jogún ìtẹ́ ògo:

“Nítorí pé ọ̀wọ́n ayé ti Olúwa ni,

ó sì ti gbé ayé ka orí wọn

9Yóò pa ẹsẹ̀ àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ mọ́,

àwọn ènìyàn búburú ni yóò dákẹ́ ní òkùnkùn.

“Nípa agbára kò sí ọkùnrin tí yóò borí.

10A ó fọ́ àwọn ọ̀tá Olúwa túútúú;

láti ọ̀run wá ni yóò sán àrá sí wọn;

Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ òpin ayé.

“Yóò fi agbára fún ọba rẹ̀,

yóò si gbé ìwo ẹni ààmì òróró rẹ̀ sókè.”

11Elkana sì lọ sí Rama sí ilé rẹ̀, Ọmọ náà sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún Olúwa níwájú Eli àlùfáà.

Àwọn ọmọ Eli búburú

12Àwọn ọmọ Eli sì jẹ́ ọmọ Beliali; wọn kò mọ Olúwa. 13Iṣẹ́ àwọn àlùfáà pẹ̀lú àwọn ènìyàn ni pé nígbà tí ẹnìkan bá ṣe ìrúbọ, ìránṣẹ́ àlùfáà á dé, nígbà tí ẹran náà bá ń hó lórí iná, pẹ̀lú ọ̀pá-ẹran náà oníga mẹ́ta ní ọwọ́ rẹ̀. 14Òun a sì fi gún inú apẹ, tàbí àgé tàbí ọpọ́n, tàbí ìkòkò, gbogbo èyí tí ọ̀pá-ẹran oníga náà bá mú wá sí òkè, àlùfáà á mú un fún ara rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń ṣe sí gbogbo Israẹli tí ó wá sí ibẹ̀ ní Ṣilo. 15Pẹ̀lú, kí wọn tó sun ọ̀rá náà, ìránṣẹ́ àlùfáà á dé, á sì wí fún ọkùnrin tí ó ń ṣe ìrúbọ pé, “Fi ẹran fún mi láti sun fún àlùfáà; nítorí tí kì yóò gba ẹran sísè lọ́wọ́ rẹ, bí kò ṣe tútù.”

16Bí ọkùnrin náà bá sì wí fún un pé, “Jẹ́ kí wọn ó sun ọ̀rá náà nísinsin yìí, kí o sì mú iyekíye tí ọkàn rẹ̀ bá fẹ́,” nígbà náà ni yóò dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n kí ìwọ ó fi í fún mi nísinsin yìí, bí kó ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ó fi agbára gbà á.”

17Ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì tóbi gidigidi níwájú Olúwa: nítorí tí àwọn ènìyàn kórìíra ẹbọ Olúwa.

18Ṣùgbọ́n Samuẹli ń ṣe ìránṣẹ́ níwájú Olúwa, ọmọdé, ti a wọ̀ ní efodu ọ̀gbọ̀. 19Pẹ̀lúpẹ̀lú, ìyá rẹ̀ máa ń dá aṣọ ìlekè péńpé fún un, a sì máa mú wá fún un lọ́dọọdún, nígbà tí ó bá bá ọkọ rẹ̀ gòkè wá láti ṣe ìrúbọ ọdún. 20Eli súre fún Elkana àti aya rẹ̀ pé, “Kí Olúwa fún ọ ní irú-ọmọ láti ara obìnrin yìí wá, nítorí ẹ̀bùn tí ó béèrè tí ó sì tún fún Olúwa.” Wọ́n sì lọ sí ilé wọn. 21Olúwa si bojú wo Hana, ó sì lóyún, ó bí ọmọkùnrin mẹ́ta àti ọmọbìnrin méjì. Samuẹli ọmọ náà sì ń dàgbà níwájú Olúwa.

22Eli sì di arúgbó gidigidi, ó sì gbọ́ gbogbo èyí ti àwọn ọmọ rẹ̀ ṣe sí gbogbo Israẹli; àti bi wọ́n ti máa ń bá àwọn obìnrin sùn, tí wọ́n máa ń péjọ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ. 23Ó sì wí fún wọn pé, kí ni ó ti ri “Èétirí tí èmi fi ń gbọ́ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ sí yín? Nítorí tí èmi ń gbọ́ iṣẹ́ búburú yín láti ọ̀dọ̀ gbogbo ènìyàn. 24Bẹ́ẹ̀ kọ́ ẹ̀yin ọmọ mi, nítorí kì ṣe ìròyìn rere èmi gbọ́; ẹ̀yin mú ènìyàn Ọlọ́run dẹ́ṣẹ̀. 25Bí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí ẹnìkejì, onídàájọ́ yóò ṣe ìdájọ́ rẹ̀: ṣùgbọ́n bí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí Olúwa, ta ni yóò bẹ̀bẹ̀ fún un?” Wọn kò sì fi etí sí ohùn baba wọn, nítorí tí Olúwa ń fẹ́ pa wọ́n.

26Ọmọ náà Samuẹli ń dàgbà, ó sì rí ojúrere lọ́dọ̀ Olúwa, àti ènìyàn pẹ̀lú.

Wòlíì sọtẹ́lẹ̀ nípa ilé Eli

27Ènìyàn Ọlọ́run kan tọ Eli wá, ó sì wí fún un pé, “Báyìí ni Olúwa wí, ‘Èmi fi ara mi hàn ní gbangba fún ilé baba rẹ, nígbà tí wọ́n ń bẹ ní Ejibiti nínú ilé Farao. 28Èmi sì yàn án kúrò láàrín gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti jẹ́ àlùfáà mi, láti rú ẹbọ lórí pẹpẹ mi, láti fi tùràrí jóná, láti wọ efodu níwájú mi, èmi sì fi gbogbo ẹbọ tí ọmọ Israẹli máa ń fi iná sun fún ìdílé baba rẹ̀. 29Èéha ṣe tí ẹ̀yin fi tàpá sí ẹbọ àti ọrẹ mi, tí mo pàṣẹ ní ibùjókòó mi: ìwọ sì bu ọlá fún àwọn ọmọ rẹ jù mí lọ, tí ẹ sì fi gbogbo àṣàyàn ẹbọ Israẹli àwọn ènìyàn mi mú ara yín sanra.’

30“Nítorí náà Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí pé, ‘Èmi ti wí nítòótọ́ pé, ilé rẹ àti ilé baba rẹ, yóò máa rìn níwájú mi títí.’ Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa wí pé, ‘Kí á má rí i! Àwọn tí ó bú ọlá fún mi ni èmi yóò bu ọlá fún, àti àwọn tí kò kà mí sí ni a ó sì ṣe aláìkàsí. 31Kíyèsi i, àwọn ọjọ́ ń bọ̀ tí èmi ó gé agbára rẹ kúrò, àti agbára baba rẹ, tí kì yóò sí arúgbó kan nínú ilé rẹ. 32Ìwọ yóò rí wàhálà ti Àgọ́, nínú gbogbo ọlá tí Ọlọ́run yóò fi fún Israẹli; kì yóò sí arúgbó kan nínú ilé rẹ láéláé. 33Ọkùnrin tí ó jẹ́ tìrẹ, tí èmi kì yóò gé kúrò ní ibi pẹpẹ mi ni a ó dá sí láti sọkún yọ lójú àti láti banújẹ́: Ṣùgbọ́n gbogbo irú-ọmọ ilé rẹ̀ ni a ó fi idà pa ní ààbọ̀ ọjọ́ wọn.

34“ ‘Kí ni ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí àwọn ọmọ ọkùnrin rẹ̀ méjèèjì, Hofini àti Finehasi, yóò jẹ́ ààmì fún ọ—àwọn méjèèjì yóò kú ní ọjọ́ kan náà. 35Èmi yóò dìde fún ara mi láti gbé àlùfáà olódodo dìde fún ara mi ẹni tí yóò ṣe gẹ́gẹ́ bí ohun tí ó wà ní ọkàn mi àti inú mi: Èmi yóò fi ẹsẹ̀ ilé rẹ̀ múlẹ̀ gbọningbọnin òun yóò sì ṣe òjíṣẹ́ níwájú ẹni òróró mi ní ọjọ́ gbogbo. 36Nígbà náà olúkúlùkù ẹnikẹ́ni tí ó bá kù ní ìdílé yín, yóò jáde wá yóò sì foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀ nítorí ẹyọ fàdákà àti nítorí èépá àkàrà àti ẹ̀bẹ̀ pé, “Jọ̀wọ́ yàn mí sí ọ̀kan nínú iṣẹ́ àwọn àlùfáà, kí èmi kí ó le máa rí oúnjẹ jẹ.” ’ ”

Священное Писание (Восточный перевод), версия для Таджикистана

1 Царств 2:1-36

Молитва Ханны

1Молясь, Ханна сказала:

– Возликовало моё сердце в Вечном,

в Вечном обрела я силу2:1 Букв.: «вознёсся мой рог». Рог был символом могущества, власти и силы. То же в ст. 10. свою.

Я смеюсь над своими врагами

и радуюсь, что Ты избавил меня.

2Нет столь святого, как Вечный;

нет другого, кроме Тебя;

нет скалы, подобной нашему Богу.

3Не говорите больше надменно,

не давайте своим устам говорить с такой дерзостью,

ведь Вечный – Бог, знающий всё,

оценивающий все дела.

4Сломаны луки воинов,

а слабые становятся сильными.

5Те, кто был сыт, теперь нанимаются работать за пищу,

а те, кто голодал, больше не голодают.

Когда-то бесплодная – родила семерых,

а имевшая много сыновей – изнемогает.

6Вечный умерщвляет и оживляет,

низводит в мир мёртвых и выводит из него.

7Вечный делает нищим и даёт богатство;

Он смиряет и возносит.

8Он поднимает бедного из праха

и возносит нищего с груды пепла.

Сажает их с вождями

и даёт им наследовать престол славы.

Ведь основания земли устроены Вечным,

на них Он поставил мир.

9Он охраняет пути верных Ему,

а нечестивые сгинут во мраке.

Сила им не поможет:

10противники Вечного будут рассеяны.

Он разразится на них громом с небес;

Вечный будет судить до края земли.

Он даст мощь Своему царю,

силу – Своему помазаннику.

11Элкана пошёл к себе домой в Раму, а мальчик остался служить перед Вечным при священнослужителе Илии.

Нечестивые сыновья Илия

12Сыновья Илия были нечестивцами. Им не было дела ни до Вечного, 13ни до долга священнослужителей по отношению к народу. Всякий раз, когда кто-нибудь приносил жертву, в то время, когда мясо ещё варилось, приходил слуга священнослужителей с трёхзубой вилкой в руке. 14Он опускал её в кастрюлю, сковороду, котёл или горшок и брал себе всё, что попадалось на вилку. Так священнослужители поступали со всяким жертвенным мясом, которое приносили исроильтяне, приходившие в Шило. 15Мало этого, ещё до того, как сжигали жир, слуга священнослужителя приходил и говорил человеку, который приносил жертву: «Дай священнослужителю мяса для жаркого. Он не возьмёт у тебя варёное мясо, только сырое». 16Если человек говорил ему: «Пусть вначале сожгут жир, а потом ты возьмёшь всё, что хочешь», то слуга отвечал: «Нет, давай сейчас. А если нет, я возьму силой».

17Грех этих молодых людей, сыновей Илия, был очень велик перед Вечным, ведь они относились с презрением к приношениям Вечному.

18Но Самуил служил перед Вечным. Он был мальчиком, носящим льняной ефод2:18 Простой льняной ефод (своего рода передник) был облачением всех священнослужителей (см. 22:18), за исключением верховного священнослужителя, который носил ефод из дорогой материи (см. Исх. 28:6-30).. 19Каждый год мать шила для него маленький плащ и приносила ему, когда приходила с мужем для приношения ежегодной жертвы. 20Илий благословлял Элкану и его жену, говоря:

– Пусть Вечный даст тебе детей от этой женщины вместо того, о ком она молилась и кого отдала Вечному.

Потом они возвращались домой. 21Вечный был милостив к Ханне, и она родила ещё троих сыновей и двух дочерей. Тем временем Самуил рос в присутствии Вечного.

22Илий же, который был очень стар, слышал обо всём, что его сыновья делают с Исроилом и что они спят с женщинами, которые служат у входа в шатёр встречи.

23Он сказал им:

– Что вы делаете? От всего народа я слышу о ваших нечестивых делах. 24Нет, мои сыновья, не хороша молва, которая, как я слышу, распространяется среди народа Вечного. 25Если человек согрешит против другого, то Всевышний может стать посредником между ними, но если человек согрешит против Вечного, кто заступится2:25 Или: «помолится». за него?

Но сыновья не прислушивались к отцовским упрёкам, потому что в воле Вечного было предать их смерти.

26А Самуил взрослел. Его любили и люди, и Вечный.

Пророчество о семье Илия

27И вот пришёл к Илию пророк и сказал ему:

– Так говорит Вечный: «Разве Я не открывался ясно твоему предку Хоруну и его семье, когда они ещё были в Египте под властью фараона? 28Я выбрал Хоруна из всех родов Исроила, чтобы он был Моим священнослужителем, восходил к Моему жертвеннику, возжигал благовония и носил предо Мною ефод2:28 На ефод золотыми цепочками крепился нагрудник, в котором находился священный жребий, урим («свет») и туммим («совершенство»). С помощью этих предметов определяли волю Всевышнего, но как именно, сегодня не известно. По всей вероятности, именно в этой связи упоминается в данном стихе ефод (см. также 14:2-3, 18-19; 23:6-12; 30:7-8).. Ещё Я дал ему и его семье все огненные жертвы исроильтян. 29Почему же вы попираете ногами Мои жертвы и приношения, которые Я установил для Своего жилища? Почему ты предпочитаешь Мне своих сыновей, жирея от лучших частей каждого приношения, совершаемого Моим народом, Исроилом?»

30Поэтому Вечный, Бог Исроила, возвещает: «Я обещал, что твоя семья и твоё родство будут служить передо Мной вечно». Но теперь Вечный возвещает: «Да не будет так! Тех, кто чтит Меня, буду чтить и Я, но тем, кто презирает Меня, будет плохо. 31Наступит время, когда Я лишу силы твою семью и твоё родство, и никто в твоём семействе не доживёт до старости. 32Ты увидишь бедствие в Моём жилище. Хотя Исроил будет благоденствовать, никто в твоём семействе никогда не будет доживать до старости. 33Всякий, кого Я не отрешу от жертвенника, будет сбережён только для того, чтобы наполнять слезами твои глаза и печалить твоё сердце, и все твои потомки будут умирать во цвете лет.

34А то, что случится с двумя твоими сыновьями, Хофни и Пинхасом, будет знаком для тебя – оба они умрут в один день. 35Я поставлю Себе верного священнослужителя, который будет поступать по сердцу Моему. Я утвержу его дом, и он всегда будет ходить перед Моим помазанником. 36Тогда всякий оставшийся из твоего дома придёт, склонится перед ним за грамм2:36 Букв.: «за геру». серебра и корку хлеба и взмолится: „Дай мне какую-нибудь должность священнослужителя, чтобы у меня было пропитание“».