1 Samuẹli 1 – YCB & CARST

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

1 Samuẹli 1:1-28

Ìbí Samuẹli

1Ọkùnrin kan wà, láti Ramataimu-Sofimu, láti ìlú olókè Efraimu, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Elkana, ọmọ Jerohamu, ọmọ Elihu, ọmọ Tohu, ọmọ Sufu, ará Efrata. 2Ó sì ní ìyàwó méjì: orúkọ wọn ni Hana àti Penina: Penina ní ọmọ, ṣùgbọ́n Hana kò ní.

3Ní ọdọọdún, ọkùnrin yìí máa ń gòkè láti ìlú rẹ̀ láti lọ sìn àti láti ṣe ìrúbọ sí Olúwa àwọn ọmọ-ogun jùlọ ní Ṣilo, níbi tí àwọn ọmọkùnrin Eli méjèèjì, Hofini àti Finehasi ti jẹ́ àlùfáà Olúwa. 4Nígbàkígbà tí ó bá kan Elkana láti ṣe ìrúbọ, òun yóò bù lára ẹran fún aya rẹ̀ Penina àti fún gbogbo àwọn ọmọ ọkùnrin àti obìnrin. 5Ṣùgbọ́n ó máa ń pín ìlọ́po fun Hana nítorí pé ó fẹ́ràn rẹ̀ àti pé Olúwa ti sé e nínú. 6Nítorí pé Olúwa ti sé e nínú, orogún rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí ní fín níràn láti lè mú kí ó bínú. 7Eléyìí sì máa ń ṣẹlẹ̀ ní ọdọọdún. Nígbàkígbà tí Hana bá gòkè lọ sí ilé Olúwa, orogún rẹ̀ a máa fín níràn títí tí yóò fi máa sọkún tí kò sì ní lè jẹun. 8Elkana ọkọ rẹ̀ yóò sọ fún un pé, “Hana èéṣe tí ìwọ fi ń sọkún? Èéṣe tí ìwọ kò fi jẹun? Èéṣe tí ìwọ fi ń ba ọkàn jẹ́? Èmi kò ha ju ọmọ mẹ́wàá lọ fún ọ bí?”

9Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti jẹ, tí wọ́n tún mu tán ní Ṣilo, Hana dìde wá síwájú Olúwa. Nígbà náà, Eli àlùfáà wà lórí àga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa ní ibi tí ó máa ń jókòó. 10Pẹ̀lú ẹ̀dùn ọkàn Hana sọkún gidigidi, ó sì gbàdúrà sí Olúwa. 11Ó sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, jùlọ tí ìwọ bá le bojú wo ìránṣẹ́bìnrin rẹ kí ìwọ sì rántí rẹ̀, tí ìwọ kò sì gbàgbé ìránṣẹ́ rẹ ṣùgbọ́n tí ìwọ yóò fún un ní ọmọkùnrin, nígbà náà èmi yóò sì fi fún Olúwa ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀ a kì yóò sì fi abẹ kàn án ní orí.”

12Bí ó sì ṣe ń gbàdúrà sí Olúwa, Eli sì kíyèsi ẹnu rẹ̀. 13Hana ń gbàdúrà láti inú ọkàn rẹ̀, ṣùgbọ́n ètè rẹ̀ ni ó ń mì, a kò gbọ́ ohùn rẹ̀. Eli rò wí pé ó ti mu ọtí yó. 14Eli sì wí fún un pé, “Yóò ti pẹ́ fún ọ tó tí ìwọ yóò máa yó? Mú ọtí wáìnì rẹ̀ kúrò.”

15Hana dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, Olúwa mi,” “Èmi ni obìnrin oníròbìnújẹ́. Èmi kò mu ọtí wáìnì tàbí ọtí líle; Èmi ń tú ọkàn mi jáde sí Olúwa ni. 16Má ṣe mú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí obìnrin búburú. Èmi ti ń gbàdúrà níhìn-ín nínú ìrora ọkàn àti ìbànújẹ́ mi.”

17Eli dáhùn pé, “Máa lọ ní àlàáfíà, kí Ọlọ́run Israẹli fi ohun tí ìwọ ti béèrè ní ọwọ́ rẹ̀ fún ọ.”

18Ó wí pé, “Kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ rí oore-ọ̀fẹ́ lójú rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin náà bá tirẹ̀ lọ, ó sì jẹun, kò sì fa ojú ro mọ́.

19Wọ́n sì dìde ni kùtùkùtù òwúrọ̀, wọn wólẹ̀ sìn níwájú Olúwa, wọn padà wa sí ilé wọn ni Rama: Elkana si mọ Hana aya rẹ̀: Olúwa sì rántí rẹ̀. 20Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ rẹ̀ pé, lẹ́yìn ìgbà tí Hana lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Samuẹli, pé, “Nítorí tí mo béèrè rẹ̀ lọ́wọ́ Olúwa.”

A ya Samuẹli sí mímọ́ fún Olúwa

21Ọkùnrin náà Elkana, àti gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, gòkè lọ láti rú ẹbọ ọdún sí Olúwa, àti láti sán ẹ̀jẹ́ rẹ̀. 22Ṣùgbọ́n Hana kò gòkè lọ; nítorí tí ó sọ fún ọkọ rẹ̀ pé, “Ó di ìgbà tí mo bá gba ọmú lẹ́nu ọmọ náà, nígbà náà ni èmi yóò mú un lọ, kí òun lè fi ara hàn níwájú Olúwa, kí ó sí máa gbé ibẹ̀ títí láé.”

23Elkana ọkọ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Ṣe èyí tí ó tọ́ lójú rẹ. Dúró títí ìwọ yóò fi gba ọmú lẹ́nu rẹ̀; ṣùgbọ́n kí Olúwa sá à mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin náà sì jókòó, ó sì fi ọmú fún ọmọ rẹ̀ títí ó fi gbà á lẹ́nu rẹ̀.

24Nígbà tí ó sì gba ọmú lẹ́nu rẹ̀, ó sì mú un gòkè lọ pẹ̀lú ara rẹ̀. Pẹ̀lú ẹgbọrọ màlúù mẹ́ta, àti ìyẹ̀fun efa kan, àti ìgò ọtí wáìnì kan, ó sì mú un wá sí ilé Olúwa ní Ṣilo: ọmọ náà sì wà ní ọmọdé. 25Wọ́n pa ẹgbọrọ màlúù, wọ́n sì mú ọmọ náà tọ Eli wá. 26Hana sì wí pé, “Olúwa mi, bí ọkàn rẹ ti wà láààyè, Olúwa mi, èmi ni obìnrin náà tí ó dúró lẹ́bàá ọ̀dọ̀ rẹ níhìn-ín tí ń tọrọ lọ́dọ̀ Olúwa. 27Ọmọ yìí ni mo ń tọrọ; Olúwa sì fi ìdáhùn ìbéèrè tí mo béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀ fún mi. 28Nítorí náà pẹ̀lú, èmi fi í fún Olúwa; ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀: nítorí tí mo ti béèrè rẹ̀ fún Olúwa.” Wọn si wólẹ̀ sin Olúwa níbẹ̀.

Священное Писание (Восточный перевод), версия для Таджикистана

1 Царств 1:1-28

Семья Элканы

1Был некий человек из Раматаима, цуфит1:1 Или: «из Раматаим-Цуфима». из нагорий Ефраима, которого звали Элкана. Он был сыном Иерохама, сына Элиху, сына Тоху, сына Цуфа, и жил на земле, принадлежащей ефраимитам. 2У Элканы было две жены. Одну звали Ханна, а другую – Фенанна. У Фенанны были дети, у Ханны же их не было.

3Из года в год Элкана ходил из своего города в Шило1:3 В это время в Шило (к северу от Иерусалима, на территории рода Ефраима) находился священный шатёр., чтобы поклониться и принести жертву Вечному1:3 Вечный – на языке оригинала: «Яхве». Под этим именем Всевышний открылся Мусо и народу Исроила (см. Исх. 3:13-15). См. пояснительный словарь., Повелителю Сил. Хофни и Пинхас, два сына Илия, были там священнослужителями Вечного. 4Всякий раз, когда Элкана приносил жертву, он давал часть жертвенного мяса своей жене Фенанне и всем её сыновьям и дочерям. 5Но Ханне он давал двойную часть, потому что любил её, хотя Вечный и не давал ей детей. 6И оттого что Вечный не давал Ханне детей, её соперница жестоко изводила и унижала её. 7Так продолжалось из года в год. Всякий раз, когда Ханна ходила в дом Вечного, соперница изводила её, и та плакала и не ела.

8Элкана говорил ей:

– Ханна, почему ты плачешь? Почему не ешь? Почему скорбит твоё сердце? Разве я не значу для тебя больше, чем десять сыновей?

Обет Ханны и рождение Самуила

9Однажды, когда они уже поели и попили в Шило, Ханна встала. А священнослужитель Илий сидел у дверей святилища Вечного. 10Скорбя душой, Ханна горько плакала и молилась Вечному. 11Она дала обет, говоря:

– О Вечный, Повелитель Сил, если Ты только посмотришь на горе Своей рабыни и вспомнишь меня, если не забудешь Свою рабыню, но дашь ей сына, то я отдам его Тебе на всю его жизнь, и бритва никогда не коснётся его головы1:11 Ханна обещала посвятить своего сына Вечному, т. е. она дала за него обет назорейства, но не на время, как это обычно практиковалось, а на всю жизнь. Об обете назорейства см. Чис. 6:1-21..

12Пока она молилась Вечному, Илий следил за её губами. 13Ханна молилась в сердце, её губы двигались, но голоса слышно не было. Илий подумал, что она пьяна, 14и сказал ей:

– Долго ли ты ещё будешь пьяной? Протрезвись от вина!

15– Нет, мой господин, – ответила Ханна, – я глубоко скорблю. Я не пила ни вина, ни пива. Я изливаю душу перед Вечным. 16Не думай, что твоя рабыня – нечестивая женщина, я молилась здесь из-за великой боли и печали.

17Илий ответил:

– Иди с миром, и пусть Бог Исроила даст тебе то, о чём ты Его просила.

18Она сказала:

– Пусть твоя рабыня найдёт расположение в твоих глазах.

Затем она пошла своей дорогой, поела, и лицо её уже больше не было печально.

19На следующее утро они встали рано, поклонились Вечному и пустились в обратный путь к себе домой, в Раму.

Элкана лёг со своей женой Ханной, и Вечный исполнил её просьбу. 20Через некоторое время Ханна забеременела и родила сына. Она назвала его Самуил («выпрошенный у Всевышнего»)1:20 О переводе имён и названий см. приложение VI., говоря: «Я назвала его так, потому что просила его у Вечного».

Ханна посвящает Самуила Вечному

21В следующий раз, когда Элкана вместе со всей своей семьёй отправился принести жертву Вечному и исполнить обет, 22Ханна не пошла.

Она сказала мужу:

– После того как ребёнок будет отнят от груди, я отведу его в Шило, чтобы он предстал перед Вечным. Он останется там жить навсегда.

23– Поступай, как тебе угодно, – сказал ей муж. – Оставайся здесь, пока не отнимешь его от груди. И пусть Вечный утвердит твоё слово.

Она оставалась дома и кормила своего сына до тех пор, пока не настало время отнимать его от груди. 24После того как он был отнят от груди, она повела мальчика в Шило в дом Вечного. Ханна взяла с собой трёхлетнего быка1:24 Или: «трёх быков»., небольшой мешок1:24 Букв.: «одну ефу». муки и бурдюк вина.

25Заколов быка и взяв его, Ханна с мальчиком пришли к Илию, 26и она сказала священнослужителю:

– Верно, как и то, что ты жив, мой господин, – я та самая женщина, которая стояла здесь, рядом с тобой, молясь Вечному. 27Я молилась об этом ребёнке, и Вечный дал мне то, о чём я Его просила. 28Теперь я отдаю его Вечному. Пусть он принадлежит Вечному всю его жизнь.

И они поклонились там Вечному.