1Báwo ni wúrà ṣe sọ ògo dídán rẹ̀ nù,
wúrà dídára di àìdán!
Òkúta ibi mímọ́ wá túká
sí oríta gbogbo òpópó.
2Báwo ni àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Sioni tí ó ṣe iyebíye,
tí wọ́n fi wúrà dídára ṣe
wá dàbí ìkòkò amọ̀ lásán
iṣẹ́ ọwọ́ amọ̀kòkò!
3Àwọn ajáko pèsè ọmú wọn
fún ìtọ́jú àwọn ọmọ wọn,
ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi wá láì lọ́kàn
bí ògòǹgò ní aginjù.
4Nítorí òǹgbẹ, ahọ́n àwọn ọmọ ọwọ́
lẹ̀ mọ́ òkè ẹnu wọn;
àwọn ọmọdé bẹ̀bẹ̀ fún oúnjẹ
Ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó fi fún wọn.
5Àwọn tí ó ń jẹ ohun dáradára
di òtòṣì ní òpópó.
Àwọn tí a fi aṣọ dáradára wọ̀
ni wọ́n sùn ní orí òkìtì eérú.
6Ìjìyà àwọn ènìyàn mi
tóbi ju ti Sodomu lọ,
tí a sí ní ipò ní òjijì
láìsí ọwọ́ láti ràn án lọ́wọ́.
7Ọmọ ọba ọkùnrin wọn mọ́ ju òjò-dídì,
wọ́n sì funfun ju wàrà lọ
wọ́n ni ìtọ́jú bí iyùn pupa,
ìrísí wọn dàbí safire.
8Ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n dúdú ju èédú;
wọn kò sì dá wọn mọ̀ ní òpópó.
Ara wọn hun mọ́ egungun;
ó sì gbẹ bí igi gbígbẹ.
9Àwọn tí ó kù nípasẹ̀ idà sàn
ju àwọn tí ìyàn pa;
tí ó wọ àkísà ebi, tí ó ń ṣòfò
fún àìní oúnjẹ láti inú pápá.
10Pẹ̀lú ọwọ́ àwọn obìnrin aláàánú
ni wọ́n ṣe ọmọ wọn jẹ
tí ó di oúnjẹ fún wọn
nígbà tí a pa àwọn ènìyàn mi run.
11Olúwa ti fi ihò kíkún fún ìbínú rẹ̀;
ó sì tú ìbínú gbígbóná rẹ̀ jáde.
Ó da iná ní Sioni
tí ó jó ìpìlẹ̀ rẹ̀ run.
12Àwọn ọba ayé kò gbàgbọ́,
tàbí àwọn ènìyàn ayé,
wí pé àwọn ọ̀tá àti aninilára le wọ
odi ìlú Jerusalẹmu.
13Èyí ṣẹlẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn wòlíì
àti àìṣedéédéé àwọn olórí àlùfáà,
tí ó ta ẹ̀jẹ̀ àwọn olódodo
sílẹ̀ láàrín rẹ̀.
14Nísinsin yìí wọ́n ń rìn kiri ní òpópó
bí ọkùnrin tí ó fọ́jú.
Ẹ̀jẹ̀ ara wọn sọ wọ́n di àbàwọ́n
tí kò sẹ́ni tó láyà láti fọwọ́ kan aṣọ wọn.
15“Lọ kúrò! Ẹ̀yin di aláìmọ́!” ni àwọn ènìyàn ń kígbe sí wọn.
“Ẹ lọ! Ẹ lọ! Ẹ má ṣe fọwọ́ kàn wá!”
Àwọn ènìyàn láàrín orílẹ̀-èdè wí pé,
“Wọn kì yóò tẹ̀dó síbí mọ́.”
16Olúwa ti tú wọn ká fúnrarẹ̀;
kò sí bojútó wọn mọ́.
Kò sí ọ̀wọ̀ fún olórí àlùfáà mọ́,
àti àánú fún àwọn àgbàgbà.
17Síwájú sí i, ojú wa kùnà
fún wíwo ìrànlọ́wọ́ asán;
láti orí ìṣọ́ wa ni à ń wò
fún orílẹ̀-èdè tí kò le gbà wá là.
18Wọ́n ń ṣọ́ wa kiri,
àwa kò sì le rìn ní òpópó wa mọ́.
Òpin wa ti súnmọ́, ọjọ́ wa sì níye
nítorí òpin wa ti dé.
19Àwọn tí ń lé wa yára
ju idì ojú ọ̀run lọ;
wọ́n lé wa ní gbogbo orí òkè
wọ́n sì gẹ̀gùn dè wá ní aginjù.
20Ẹni ààmì òróró Olúwa, èémí ìyè wa,
ni wọ́n fi tàkúté wọn mú.
Àwa rò pé lábẹ́ òjìji rẹ̀
ni àwa yóò máa gbé láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
21Ẹ yọ̀ kí inú yín sì dùn, ẹ̀yin ọmọbìnrin Edomu,
ẹ̀yin tó ń gbé ní ilẹ̀ Usi.
Ṣùgbọ́n, a ó gbé ago náà kọjá sọ́dọ̀ rẹ pẹ̀lú;
ìwọ yóò yó bí ọ̀mùtí, ìwọ yóò sì rìn ní ìhòhò.
22Ìwọ ọmọbìnrin Sioni, ìjìyà rẹ yóò dópin;
kò ní mú ìgbèkùn rẹ pẹ́ mọ́.
Ṣùgbọ́n, ìwọ ọmọbìnrin Edomu, yóò jẹ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ní yà
yóò sì fi àìṣedéédéé rẹ hàn kedere.
1Como o ouro perdeu o brilho!
Como o ouro fino ficou embaçado!
As pedras sagradas estão espalhadas
pelas esquinas de todas as ruas.
2Como os preciosos filhos de Sião,
que antes valiam seu peso em ouro,
hoje são considerados como vasos de barro,
obra das mãos de um oleiro!
3Até os chacais oferecem o peito
para amamentar os seus filhotes,
mas o meu povo não tem mais coração;
é como as avestruzes do deserto.
4De tanta sede, a língua dos bebês
gruda no céu da boca;
as crianças imploram pelo pão,
mas ninguém as atende.
5Aqueles que costumavam comer comidas finas
passam necessidade nas ruas.
Aqueles que se adornavam de púrpura
hoje estão prostrados sobre montes de cinza.
6A punição do meu povo
é maior que a de Sodoma,
que foi destruída num instante
sem que ninguém a socorresse.
7Seus príncipes eram mais brilhantes que a neve,
mais brancos do que o leite;
e tinham a pele mais rosada que rubis;
e sua aparência lembrava safiras.
8Mas agora estão mais negros do que o carvão;
não são reconhecidos nas ruas.
Sua pele enrugou-se sobre os seus ossos;
agora parecem madeira seca.
9Os que foram mortos à espada
estão melhor do que os que morreram de fome,
os quais, tendo sido torturados pela fome,
definham pela falta de produção das lavouras.
10Com as próprias mãos,
mulheres bondosas cozinharam seus próprios filhos,
que se tornaram sua comida
quando o meu povo foi destruído.
11O Senhor deu vazão total à sua ira;
derramou a sua grande fúria.
Ele acendeu em Sião um fogo
que consumiu os seus alicerces.
12Os reis da terra e os povos de todo o mundo
não acreditavam que os inimigos
e os adversários pudessem entrar
pelas portas de Jerusalém.
13Dentro da cidade
foi derramado o sangue dos justos,
por causa do pecado dos seus profetas
e das maldades dos seus sacerdotes.
14Hoje eles tateiam pelas ruas como cegos,
e tão sujos de sangue estão
que ninguém ousa tocar em suas vestes.
15“Vocês estão imundos!”, o povo grita para eles.
“Afastem-se! Não nos toquem!”
Quando eles fogem e andam errantes,
os povos das outras nações dizem:
“Aqui eles não podem habitar”.
16O próprio Senhor os espalhou;
ele já não cuida deles.
Ninguém honra os sacerdotes
nem respeita os líderes.
17Nossos olhos estão cansados
de buscar ajuda em vão;
de nossas torres ficávamos à espera
de uma nação que não podia salvar-nos.
18Cada passo nosso era vigiado;
nem podíamos caminhar por nossas ruas.
Nosso fim estava próximo,
nossos dias estavam contados;
o nosso fim já havia chegado.
19Nossos perseguidores eram mais velozes
que as águias nos céus;
perseguiam-nos por sobre as montanhas,
ficavam de tocaia contra nós no deserto.
20O ungido do Senhor,
o próprio fôlego da nossa vida,
foi capturado em suas armadilhas.
E nós que pensávamos que sob a sua sombra
viveríamos entre as nações!
21Alegre-se e exulte, ó terra de Edom,
você que vive na terra de Uz.
Mas a você também será servido o cálice:
você será embriagada e as suas roupas serão arrancadas.
22Ó cidade de Sião, o seu castigo terminará;
o Senhor não prolongará o seu exílio.
Mas você, ó terra de Edom, ele punirá o seu pecado
e porá à mostra a sua perversidade.