Ẹkun Jeremiah 3 – YCB & NVI-PT

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Ẹkun Jeremiah 3:1-66

1Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú

pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.

2Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn

nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀;

3Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ padà sí mi

síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.

4Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó

ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.

5Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká

pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.

6Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn,

bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.

7Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ;

ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.

8Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́,

ó kọ àdúrà mi.

9Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi;

ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.

10Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀,

bí i kìnnìún tí ó sápamọ́.

11Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀

ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.

12Ó fa ọfà rẹ̀ yọ

ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.

13Ó fa ọkàn mí ya

pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.

14Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi;

wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.

15Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò

àti ìdààmú bí omi.

16Ó ti fi òkúta kán eyín mi;

ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.

17Mo ti jìnnà sí àlàáfíà;

mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.

18Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ

àti ìrètí mi nínú Olúwa.”

19Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi,

ìkorò àti ìbànújẹ́.

20Mo ṣèrántí wọn,

ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.

21Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn

àti nítorí náà ní mo nírètí.

22Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé,

nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.

23Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀;

títóbi ni òdodo rẹ̀.

24Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa;

nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.

25Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀,

sí àwọn tí ó ń wá a.

26Ó dára kí a ní sùúrù

fún ìgbàlà Olúwa.

27Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà

nígbà tí ó wà ní èwe.

28Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́,

nítorí Olúwa ti fi fún un.

29Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku—

ìrètí sì lè wà.

30Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a,

sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.

31Ènìyàn kò di ìtanù

lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.

32Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn,

nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.

33Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá

tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.

34Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀

gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.

35Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀

níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ.

36Láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà,

Ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.

37Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀

tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.

38Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ

ni rere àti búburú tí ń wá?

39Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn

nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?

40Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò,

kí a sì tọ Olúwa lọ.

41Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè

sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé:

42“Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀

ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.

43“Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa;

ìwọ ń parun láìsí àánú.

44Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ

pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.

45Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn

láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.

46“Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn

gbòòrò sí wa.

47Àwa ti jìyà àti ìparun,

nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”

48Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò

nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.

49Ojú mi kò dá fún omijé,

láì sinmi,

50títí ìgbà tí Olúwa yóò ṣíjú wolẹ̀

láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.

51Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi

nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.

52Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí

dẹ mí bí ẹyẹ.

53Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò

wọ́n sì ju òkúta lù mí.

54Orí mi kún fún omi,

mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.

55Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa,

láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.

56Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi: “Má ṣe di etí rẹ

sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”

57O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́,

o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”

58Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò,

o ra ẹ̀mí mi padà.

59O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi

Gbé ẹjọ́ mi ró!

60Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn,

gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.

61Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn

àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi—

62Ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ

sí mi ní gbogbo ọjọ́.

63Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde,

wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.

64Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn

fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.

65Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn,

kí o sì fi wọ́n ré.

66Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú,

lábẹ́ ọ̀run Olúwa.

Nova Versão Internacional

Lamentações 3:1-66

1Eu sou o homem que viu a aflição

trazida pela vara da sua ira.

2Ele me impeliu e me fez andar na escuridão,

e não na luz;

3sim, ele voltou sua mão contra mim

vez após vez, o tempo todo.

4Fez que a minha pele e a minha carne envelhecessem

e quebrou os meus ossos.

5Ele me sitiou e me cercou

de amargura e de pesar.

6Fez-me habitar na escuridão

como os que há muito morreram.

7Cercou-me de muros, e não posso escapar;

atou-me a pesadas correntes.

8Mesmo quando chamo ou grito por socorro,

ele rejeita a minha oração.

9Ele impediu o meu caminho com blocos de pedra;

e fez tortuosas as minhas sendas.

10Como um urso à espreita,

como um leão escondido,

11arrancou-me do caminho e despedaçou-me,

deixando-me abandonado.

12Preparou o seu arco

e me fez alvo de suas flechas.

13Atingiu o meu coração

com flechas de sua aljava.

14Tornei-me objeto de riso de todo o meu povo;

nas suas canções eles zombam de mim o tempo todo.

15Fez-me comer ervas amargas

e fartou-me de fel.

16Quebrou os meus dentes com pedras;

e pisoteou-me no pó.

17Tirou-me a paz;

esqueci-me o que é prosperidade.

18Por isso, digo: “Meu esplendor já se foi,

bem como tudo o que eu esperava do Senhor”.

19Lembro-me da minha aflição e do meu delírio,

da minha amargura e do meu pesar.

20Lembro-me bem disso tudo,

e a minha alma desfalece dentro de mim.

21Todavia, lembro-me também

do que pode me dar esperança:

22Graças ao grande amor do Senhor

é que não somos consumidos,

pois as suas misericórdias são inesgotáveis.

23Renovam-se cada manhã;

grande é a sua fidelidade!

24Digo a mim mesmo: A minha porção é o Senhor;

portanto, nele porei a minha esperança.

25O Senhor é bom para com aqueles

cuja esperança está nele,

para com aqueles que o buscam;

26é bom esperar tranquilo

pela salvação do Senhor.

27É bom que o homem suporte o jugo

enquanto é jovem.

28Leve-o sozinho e em silêncio,

porque o Senhor o pôs sobre ele.

29Ponha o seu rosto no pó;

talvez ainda haja esperança.

30Ofereça o rosto a quem o quer ferir,

e engula a desonra.

31Porque o Senhor

não o desprezará para sempre.

32Embora ele traga tristeza, mostrará compaixão,

tão grande é o seu amor infalível.

33Porque não é do seu agrado trazer aflição

e tristeza aos filhos dos homens,

34esmagar com os pés

todos os prisioneiros da terra,

35negar a alguém os seus direitos,

enfrentando o Altíssimo,

36impedir a alguém o acesso à justiça;

não veria o Senhor tais coisas?

37Quem poderá falar e fazer acontecer,

se o Senhor não o tiver decretado?

38Não é da boca do Altíssimo que vêm

tanto as desgraças como as bênçãos?

39Como pode um homem reclamar

quando é punido por seus pecados?

40Examinemos e coloquemos à prova os nossos caminhos

e depois voltemos ao Senhor.

41Levantemos o coração e as mãos

para Deus, que está nos céus, e digamos:

42“Pecamos e nos rebelamos,

e tu não nos perdoaste.

43“Tu te cobriste de ira e nos perseguiste,

massacraste-nos sem piedade.

44Tu te escondeste atrás de uma nuvem

para que nenhuma oração chegasse a ti.

45Tu nos tornaste escória

e refugo entre as nações.

46“Todos os nossos inimigos

escancaram a boca contra nós.

47Sofremos terror e ciladas,

ruína e destruição”.

48Rios de lágrimas correm dos meus olhos

porque o meu povo foi destruído.

49Meus olhos choram sem parar,

sem nenhum descanso,

50até que o Senhor contemple dos céus

e veja.

51O que eu enxergo enche-me a alma de tristeza,

de pena de todas as mulheres da minha cidade.

52Aqueles que, sem motivo, eram meus inimigos

caçaram-me como a um passarinho.

53Procuraram fazer minha vida acabar na cova

e me jogaram pedras;

54as águas me encobriram a cabeça,

e cheguei a pensar que o fim de tudo tinha chegado.

55Clamei pelo teu nome, Senhor,

das profundezas da cova.

56Tu ouviste o meu clamor:

“Não feches os teus ouvidos aos meus gritos de socorro”.

57Tu te aproximaste quando a ti clamei,

e disseste: “Não tenha medo”.

58Senhor, tu assumiste a minha causa;

e redimiste a minha vida.

59Tu tens visto, Senhor, o mal que me tem sido feito.

Toma a teu cargo a minha causa!

60Tu viste como é terrível a vingança deles,

todas as suas ciladas contra mim.

61Senhor, tu ouviste os seus insultos,

todas as suas ciladas contra mim,

62aquilo que os meus inimigos sussurram

e murmuram o tempo todo contra mim.

63Olha para eles! Sentados ou em pé,

zombam de mim com as suas canções.

64Dá-lhes o que merecem, Senhor,

conforme o que as suas mãos têm feito.

65Coloca um véu sobre os seus corações

e esteja a tua maldição sobre eles.

66Persegue-os com fúria e elimina-os

de debaixo dos teus céus, ó Senhor.