1Báwo ni Olúwa ṣe bo ọmọbìnrin Sioni
pẹ̀lú àwọsánmọ̀ ìbínú rẹ̀!
Ó sọ ògo Israẹli kalẹ̀
Láti ọ̀run sí ayé;
kò rántí àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀
ní ọjọ́ ìbínú rẹ̀.
2Láìní àánú ni Olúwa gbé
ibùgbé Jakọbu mì;
nínú ìrunú rẹ̀, ni ó wó
ibi gíga ọmọbìnrin Juda lulẹ̀.
Ó ti mú ìjọba àti àwọn ọmọ-aládé ọkùnrin
lọ sínú ilẹ̀ ní àìlọ́wọ̀.
3Ní ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó ké
gbogbo ìwo Israẹli.
Ó ti mú ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ kúrò
nígbà tí àwọn ọ̀tá dé.
Ó run ní Jakọbu bí ọ̀wọ́-iná
ní àgọ́ àwọn ọmọbìnrin Sioni.
4Ó na ọfà rẹ̀ bí ọ̀tá;
ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ sì múra
Bí ti ọ̀tá tí ó ti parun
ó tú ìbínú rẹ̀ jáde bí iná
sórí àgọ́ ọmọbìnrin Sioni.
5Olúwa dàbí ọ̀tá;
ó gbé Israẹli mì.
Ó ti gbé gbogbo ààfin rẹ̀ mì
ó pa ibi gíga rẹ̀ run.
Ó sọ ìmí ẹ̀dùn àti ìbànújẹ́ di púpọ̀
fún àwọn ọmọbìnrin Juda.
6Ó mú ìparun bá ibi mímọ́,
ó pa ibi ìpàdé rẹ̀ run.
Olúwa ti mú Sioni gbàgbé
àjọ̀dún tí a yàn àti ọ̀sẹ̀ tí ó yàn;
nínú ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó run
ọba àti olórí àlùfáà.
7Olúwa ti kọ̀ pẹpẹ rẹ̀ sílẹ̀
ó sì ti kọ̀ ibi mímọ́ rẹ̀.
Ó sì fi lé ọ̀tá lọ́wọ́
àwọn odi ààfin rẹ̀;
wọ́n sì kígbe ní ilé Olúwa
gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ àpèjẹ tí a yàn.
8Olúwa pinnu láti fa
ògiri tí ó yí ọmọbìnrin Sioni ya.
Ó gbé wọn sórí òṣùwọ̀n,
kò sì fa ọwọ́ rẹ̀ padà kúrò nínú ìparun wọn.
Ó mú kí ilé ìṣọ́ àti odi rẹ̀ ṣọ̀fọ̀
wọ́n ṣòfò papọ̀.
9Ẹnu-ọ̀nà rẹ̀ ti wọ inú ilẹ̀;
òpó rẹ̀ ni ó wó tí ó sì ti bàjẹ́.
Ọba àti ọmọ ọbakùnrin rẹ̀ wà ní ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
kò sí òfin mọ́,
àwọn wòlíì rẹ̀ kò rí
ìran láti ọ̀dọ̀ Olúwa mọ́.
10Àwọn àgbàgbà ọmọbìnrin Sioni
jókòó sílẹ̀ ní ìdákẹ́rọ́rọ́;
wọ́n da eruku sí orí wọn
wọ́n sì wọ aṣọ àkísà.
Àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Jerusalẹmu
ti tẹrí wọn ba sí ilẹ̀.
11Ojú mi kọ̀ láti sọkún,
mo ń jẹ ìrora nínú mi,
mo tú ọkàn mi jáde sí ilẹ̀
nítorí a pa àwọn ènìyàn mí run,
nítorí àwọn ọmọdé àti ọmọ ọwọ́ ń kú
ní òpópó ìlú.
12Wọ́n wí fún àwọn ìyá wọn,
“Níbo ni ọkà àti wáìnì wà?” Wò ó
bí wọ́n ṣe ń kú lọ bí àwọn ọkùnrin tí a ṣe léṣe
ní àwọn òpópónà ìlú,
bí ayé wọn ṣe ń ṣòfò
láti ọwọ́ ìyá wọn.
13Kí ni mo le sọ fún ọ?
Pẹ̀lú kí ni mo lè fi ọ́ wé,
Ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu?
Kí sì ni mo lè fi ọ́ wé,
kí n lè tù ọ́ nínú,
Ìwọ wúńdíá obìnrin Sioni?
Ọgbẹ́ rẹ jì bí Òkun.
Ta ni yóò wò ọ́ sàn?
14Ìran àwọn wòlíì rẹ
jẹ́ kìkì ẹ̀tàn láìní ìwọ̀n;
wọn kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ hàn
tí yóò mú ìgbèkùn kúrò fún ọ.
Àwọn òrìṣà tí wọ́n fún ọ
jẹ́ èké àti ìmúniṣìnà.
15Àwọn tí ó gba ọ̀nà ọ̀dọ̀ rẹ
pàtẹ́wọ́ lé ọ lórí;
wọ́n kẹ́gàn wọ́n ju orí wọn
sí ọmọbìnrin Jerusalẹmu:
“Èyí ha ni ìlú tí à ń pè ní
àṣepé ẹwà,
ìdùnnú gbogbo ayé?”
16Gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ la ẹnu wọn
gbòòrò sí ọ;
wọ́n kẹ́gàn, wọ́n sì payínkeke
wọ́n wí pé, “A ti gbé e mì tán.
Èyí ni ọjọ́ tí a ti ń retí;
tí a sì wá láti rí.”
17Olúwa ti ṣe ohun tí ó pinnu;
ó ti mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ,
tí ó sì pàṣẹ ní ọjọ́ pípẹ́.
Ó ti ṣí ọ ní ipò láì láàánú,
ó fún ọ̀tá ní ìṣẹ́gun lórí rẹ,
ó ti gbé ìwo àwọn ọ̀tá rẹ̀ ga.
18Ọkàn àwọn ènìyàn
kígbe jáde sí Olúwa.
Odi ọmọbìnrin Sioni,
jẹ́ kí ẹkún rẹ̀ sàn bí odò
ní ọ̀sán àti òru;
má ṣe fi ara rẹ fún ìtura,
ojú rẹ fún ìsinmi.
19Dìde, kígbe sókè ní àṣálẹ́,
bí ìṣọ́ òru ti bẹ̀rẹ̀
tú ọkàn rẹ̀ jáde bí omi
níwájú Olúwa.
Gbé ọwọ́ yín sókè sí i
nítorí ẹ̀mí àwọn èwe rẹ̀
tí ó ń kú lọ nítorí ebi
ní gbogbo oríta òpópó.
20“Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó:
Ta ni ìwọ ti fìyà jẹ bí èyí
Ǹjẹ́ àwọn obìnrin yóò ha jẹ ọmọ wọn,
àwọn ọmọ tí wọn ń ṣe ìtọ́jú fún?
Ǹjẹ́ kí a pa olórí àlùfáà àti àwọn wòlíì
ní ibi mímọ́ Olúwa?
21“Ọmọdé àti àgbà ń sùn papọ̀
sínú eruku àwọn òpópó;
àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin mi
ti ṣègbé nípa idà.
Ìwọ pa wọ́n run ní ọjọ́ ìbínú rẹ;
Ìwọ pa wọ́n láìní àánú.
22“Bí ó ti ṣe ní ọjọ́ àsè,
bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe fi ẹ̀rù sí ẹ̀gbẹ́ mi.
Ní ọjọ́ ìbínú Olúwa
kò sí ẹni tí ó sálà tí ó sì yè;
àwọn tí mo ti tọ́jú tí mo sì fẹ́ràn,
ni ọ̀tá mi parun.”
1O Senhor cobriu a cidade de Sião
com a nuvem da sua ira!
Lançou por terra o esplendor de Israel,
que se elevava para os céus;
não se lembrou do estrado dos seus pés
no dia da sua ira.
2Sem piedade o Senhor devorou
todas as habitações de Jacó;
em sua ira destruiu as fortalezas
da filha de Judá.
Derrubou ao chão e desonrou
o seu reino e os seus líderes.
3Em sua flamejante ira,
cortou todo o poder2.3 Hebraico: chifre; também no versículo 17. de Israel.
Retirou a sua mão direita
diante da aproximação do inimigo.
Queimou Jacó como um fogo ardente
que consome tudo ao redor.
4Como um inimigo, preparou o seu arco;
como um adversário,
a sua mão direita está pronta.
Ele massacrou tudo o que era
agradável contemplar;
derramou sua ira como fogo
sobre a tenda da cidade de Sião.
5O Senhor é como um inimigo;
ele tem devorado Israel.
Tem devorado todos os seus palácios
e destruído as suas fortalezas.
Tem feito multiplicar os prantos
e as lamentações da filha de Judá.
6Ele destroçou a sua morada
como se fosse um simples jardim;
destruiu o seu local de reuniões.
O Senhor fez esquecidas em Sião
suas festas fixas e seus sábados;
em seu grande furor rejeitou o rei e o sacerdote.
7O Senhor rejeitou o seu altar
e abandonou o seu santuário.
Entregou aos inimigos os muros dos seus palácios,
e eles deram gritos na casa do Senhor,
como fazíamos nos dias de festa.
8O Senhor está decidido
a derrubar os muros da cidade de Sião.
Esticou a trena e não poupou a sua mão destruidora.
Fez com que os muros e as paredes se lamentassem;
juntos eles desmoronaram.
9Suas portas caíram por terra;
suas trancas ele quebrou e destruiu.
O seu rei e os seus líderes
foram exilados para diferentes nações,
e a lei já não existe;
seus profetas já não recebem
visões do Senhor.
10Os líderes da cidade de Sião
sentam-se no chão em silêncio;
despejam pó sobre a cabeça
e usam vestes de lamento.
As moças de Jerusalém
inclinam a cabeça até o chão.
11Meus olhos estão cansados de chorar,
minha alma está atormentada,
meu coração se derrama,
porque o meu povo está destruído,
porque crianças e bebês desmaiam
pelas ruas da cidade.
12Eles clamam às suas mães:
“Onde estão o pão e o vinho?”
Ao mesmo tempo em que desmaiam
pelas ruas da cidade, como os feridos,
e suas vidas se desvanecem
nos braços de suas mães.
13Que posso dizer a seu favor?
Com que posso compará-la, ó cidade de Jerusalém?
Com que posso assemelhá-la,
a fim de trazer-lhe consolo, ó virgem, ó cidade de Sião?
Sua ferida é tão profunda quanto o oceano;
quem pode curá-la?
14As visões dos seus profetas
eram falsas e inúteis;
eles não expuseram o seu pecado
para evitar o seu cativeiro.
As mensagens que eles lhe deram
eram falsas e enganosas.
15Todos os que cruzam o seu caminho batem palmas;
eles zombam e meneiam a cabeça
diante da cidade de Jerusalém:
“É esta a cidade que era chamada a perfeição da beleza,
a alegria de toda a terra?”
16Todos os seus inimigos escancaram a boca contra você;
eles zombam, rangem os dentes
e dizem: “Nós a devoramos.
Este é o dia que esperávamos;
e eis que vivemos até vê-lo chegar!”
17O Senhor fez o que planejou;
cumpriu a sua palavra, que há muito havia decretado.
Derrubou tudo sem piedade,
permitiu que o inimigo zombasse de você,
exaltou o poder dos seus adversários.
18O coração do povo clama ao Senhor.
Ó muro da cidade de Sião,
corram como um rio as suas lágrimas dia e noite;
não se permita nenhum descanso
nem dê repouso à menina dos seus olhos.
19Levante-se, grite no meio da noite,
quando começam as vigílias noturnas;
derrame o seu coração como água
na presença do Senhor.
Levante para ele as mãos
em favor da vida de seus filhos,
que desmaiam de fome
nas esquinas de todas as ruas.
20“Olha, Senhor, e considera:
A quem trataste dessa maneira?
Deverão as mulheres comer seus próprios filhos,
que elas criaram com tanto amor?
Deverão os profetas e os sacerdotes
ser assassinados no santuário do Senhor?
21“Jovens e velhos espalham-se
em meio ao pó das ruas;
meus jovens e minhas virgens
caíram mortos à espada.
Tu os sacrificaste no dia da tua ira;
tu os mataste sem piedade.
22“Como se faz convocação para um dia de festa,
convocaste contra mim terrores por todos os lados.
No dia da ira do Senhor,
ninguém escapou nem sobreviveu;
aqueles dos quais eu cuidava e que eu fiz crescer,
o meu inimigo destruiu.”